< Genesis 45 >

1 Josẹfu kò sì le è pa á mọ́ra mọ́ níwájú gbogbo àwọn tí ó dúró tì í. Ó sì sọkún sókè tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn tí ó wà ní àyíká gbọ́ ohun ẹkún rẹ̀. “Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.” Kò sì sí ẹnikẹ́ni lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí ó fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
És nem tartóztathatá magát tovább József mindazok előtt, kik körűlötte állának és felkiálta: Vezessetek ki minden embert mellőlem. És nem marada senki nála, mikor megismerteté magát József az ő atyjafiaival.
2 Ó sì sọkún sókè kíkankíkan tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Ejibiti gbọ́ ohùn ẹkún rẹ̀, àwọn ilé Farao pẹ̀lú sì gbọ́ nípa rẹ̀.
És hangos sírásra fakada, úgy hogy meghallák az Égyiptombeliek, és meghallá a Faraó háznépe is.
3 Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èmi ni Josẹfu! Ṣe baba mi sì wà láààyè?” Ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin rẹ̀ kò le è dá a lóhùn nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n níwájú rẹ̀.
És monda József az ő atyjafiainak: Én vagyok József, él-e még az én atyám? És nem felelhetének néki az ő atyjafiai, mert megrettentek vala tőle.
4 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe bẹ́ẹ̀, ó wí pé, “Èmi ni Josẹfu arákùnrin yín tí ẹ tà sí ilẹ̀ Ejibiti!
Monda azért József az ő atyjafiainak: Jőjjetek közelebb hozzám! És közelebb menének. Akkor monda: Én vagyok József, a ti testvéretek, kit eladtatok vala Égyiptomba.
5 Ṣùgbọ́n báyìí, ẹ má ṣe banújẹ́, ẹ má sì ṣe bínú sí ara yín ní títà tí ẹ tà mí sí ìhín, nítorí, ọ̀nà àti gba ẹ̀mí yín là ni Ọlọ́run ṣe rán mi sí ìhín ṣáájú yín.
És most ne bánkódjatok, és ne bosszankodjatok azon, hogy engem ide eladtatok; mert a ti megmaradástokért küldött el engem Isten ti előttetek.
6 Ìyàn tí ó ti mú láti ọdún méjì sẹ́yìn yìí yóò tẹ̀síwájú fún ọdún márùn-ún sí i nínú èyí tí ẹnikẹ́ni kò ní gbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ni kórè.
Mert immár két esztendeje, hogy éhség van e földön, de még öt esztendő van hátra, melyben sem szántás, sem aratás nem lesz.
7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run rán mi ṣáájú yín sí ìhín láti da irú-ọmọ yín sí fún un yín lórí ilẹ̀ ayé àti láti fi ìgbàlà ńlá gba ẹ̀mí yín là.
Az Isten küldött el engem ti előttetek, hogy míveljem a ti megmaradásotokat e földön, és hogy megmenthesselek titeket nagy szabadítással.
8 “Nítorí náà, kì í ṣe ẹ̀yin ni ó rán mi wá sí ibí yìí, bí kò ṣe Ọlọ́run. Ó fi mí ṣe baba, Olùdámọ̀ràn fún Farao, olúwa fún gbogbo ilé Farao àti alákòóso gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Nem ti küldöttetek azért engem ide, hanem az Isten, ki engem a Faraó atyjává tett, és egész házának urává, és Égyiptom egész földének fejedelmévé.
9 Nísinsin yìí, ẹ yára padà sọ́dọ̀ baba mi kí ẹ sì wí fun un pé, èyí ni ohun tí Josẹfu ọmọ rẹ wí, Ọlọ́run ti fi mí ṣe olúwa fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, ẹ sọ̀kalẹ̀ wá láì jáfara.
Siessetek és menjetek fel atyámhoz, és mondjátok néki: Ezt mondja a te fiad József: Az Isten engem egész Égyiptomnak urává tett, jőjj le én hozzám, ne késsél.
10 Ìwọ yóò gbé ní agbègbè Goṣeni, ìwọ kì yóò jìnnà sí mi, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ, àwọn agbo ẹran rẹ àti agbo màlúù rẹ àti gbogbo ohun tí ìwọ ní.
És Gósen földén lakozol, és én hozzám közel leszesz, mind te, mind fiaid, mind fiaidnak fiai, juhaid, barmaid, és mindened, a mid van.
11 Èmi yóò pèsè fún yín níbẹ̀. Nítorí ó ṣì ku ọdún márùn-ún gbáko ti ìyàn yóò fi mú. Kí ìwọ àti ilé rẹ àti ohun tí í ṣe tìrẹ má ba à di aláìní.
És eltartalak ott téged, mert még öt esztendei éhség lesz, hogy tönkre ne juss te, és házadnépe, és semmi, a mid van.
12 “Ẹ̀yin fúnra yín àti Benjamini arákùnrin mi pẹ̀lú rí i pé, lóòótọ́ lóòótọ́, èmi Josẹfu ni mo ń bá a yín sọ̀rọ̀.
És ímé a ti szemeitek látják, és az én atyámfiának Benjáminnak szemei, hogy az én szám szól hozzátok.
13 Ẹ sọ fún baba mi nípa gbogbo ọlá tí a fún mi ní ilẹ̀ Ejibiti àti ohun gbogbo tí ẹ̀yin ti rí, kí ẹ sì mú baba mi tọ̀ mí wá sí ìhín yìí kíákíá.”
Beszéljétek hát el atyámnak minden én dicsőségemet Égyiptomban, és mindazt, a mit láttatok. És siessetek s hozzátok ide az én atyámat.
14 Nígbà náà ni ó dì mọ́ Benjamini arákùnrin rẹ̀, ó sì sọkún, Benjamini náà sì dì mọ́ ọn, pẹ̀lú omijé lójú.
És nyakába borúla az ő öccsének Benjáminnak és síra; Benjámin is síra az ő nyakán.
15 Ó sì tún fẹnu ko gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ lẹ́nu, ó sì sọkún sí wọn lára. Lẹ́yìn èyí, Josẹfu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ̀rọ̀ pọ̀.
És megcsókolá mind az ő testvéreit és síra ő rajtok; azután beszédbe ereszkedének vele az ő testvérei.
16 Nígbà tí ìròyìn náà dé ààfin Farao pé àwọn arákùnrin Josẹfu dé, inú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ dùn.
És eljuta a hír a Faraó házába is, mondván: Eljöttek a József atyjafiai; és tetszék e dolog mind a Faraónak, mind az ő szolgáinak.
17 Farao wí fún Josẹfu pé, “Wí fún àwọn arákùnrin rẹ pé, ‘Èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ di ẹrù lé ẹranko yín kí ẹ sì padà sí ilẹ̀ Kenaani,
És monda a Faraó Józsefnek: Mondd meg a te atyádfiainak: Ezt cselekedjétek: Terheljétek meg a ti barmaitokat, és eredjetek, menjetek el Kanaán földére;
18 kí ẹ sì mú baba yín àti ìdílé yín tọ̀ mí wá. Èmi yóò fún un yín ní ibi tí ó dára jùlọ ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sì le è gbádùn ilẹ̀ yìí.’
És vegyétek fel atyátokat és házatok népét, és jőjjetek hozzám; és én néktek adom Égyiptom földének javát, hogy éljétek e földnek zsírját.
19 “A pàṣẹ fún ọ láti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe èyí. ẹ mú kẹ̀kẹ́ ẹrù láti ilẹ̀ Ejibiti fún àwọn ọmọ yín àti àwọn aya yín. Kí ẹ sì mú baba yín tọ mí wá.
Ez is parancsolatúl legyen néked: Ezt míveljétek, vigyetek magatokkal Égyiptom földéről szekereket gyermekeitek és feleségeitek számára, és vegyétek fel atyátokat és jőjjetek.
20 Ẹ má ṣe àníyàn nípa ohun ìní yín nítorí èyí tí ó dára jù nínú ilẹ̀ Ejibiti yóò jẹ́ tiyín.’”
A ti házi eszközeitekre pedig ne tekintsetek sóhajtva; mert egész Égyiptom földének a legjava a tiétek.
21 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí. Josẹfu fún wọn ni kẹ̀kẹ́ ẹrù bí Farao ti pàṣẹ, ó sì fún wọn ní oúnjẹ fún ìrìnàjò wọn pẹ̀lú.
És aképen cselekedének Izráel fiai; és ada nékik József szekereket a Faraó parancsolatja szerint; és enni valót is ada nékik az útra.
22 Ó fún ẹni kọ̀ọ̀kan wọn ní aṣọ tuntun. Ṣùgbọ́n Benjamini ni ó fún ní ọ̀ọ́dúnrún ẹyọ owó idẹ fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ márùn-ún.
Valamennyien valának, mindegyiknek ada egy-egy öltöző ruhát: Benjáminnak pedig ada háromszáz ezüst pénzt és öt öltöző ruhát.
23 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó ránṣẹ́ sí baba rẹ̀: kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru àwọn ohun mèremère ilẹ̀ Ejibiti àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru ọkà àti oríṣìíríṣìí oúnjẹ.
Atyjának pedig külde ilyenképen: tíz szamarat égyiptomi javakkal terhelve, és tíz nőstény szamarat gabonával, kenyérrel és egyéb élelemmel terhelve, az ő atyjának az útra.
24 Nígbà náà ni ó rán àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, bí wọ́n ṣe ń pínyà, ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jà ní ọ̀nà o!”
És elbocsátá az ő testvéreit, és elmenének, és monda nékik: Ne háborogjatok az úton.
25 Báyìí ni wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wá sí ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani.
Feljövének azért Égyiptomból: és eljutának Kanaán földére az ő atyjokhoz, Jákóbhoz.
26 Wọn wí fún un pé, “Josẹfu ṣì wà láààyè! Kódà òun ni alákòóso ilẹ̀ Ejibiti.” Ẹnu ya Jakọbu, kò sì gbà wọ́n gbọ́.
És mikor tudtára adák, mondván: József még él, és hogy uralkodik egész Égyiptom földén; az ő szíve elalélt, mert nem hisz vala nékik.
27 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n sọ ohun gbogbo tí Josẹfu ti sọ fún wọn fún un tí ó sì rí kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Josẹfu fi ránṣẹ́ láti gbé e padà wá, iyè Jakọbu, baba wọn sọ.
Elbeszélék azért néki József minden beszédét, a melyeket velök beszélt vala, és látá a szekereket is, a melyeket József küldött vala, hogy őt elvigyék; akkor fölélede az ő atyjoknak, Jákóbnak lelke.
28 Israẹli sì wí pé, “Mo gbà dájúdájú wí pé, Josẹfu ọmọ mi wà láààyè. Èmi ó lọ rí i kí n tó kú.”
És monda Izráel: Elég nékem, hogy József az én fiam még él: lemegyek hát, hogy meglássam őt minekelőtte meghalok.

< Genesis 45 >