< Genesis 45 >

1 Josẹfu kò sì le è pa á mọ́ra mọ́ níwájú gbogbo àwọn tí ó dúró tì í. Ó sì sọkún sókè tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn tí ó wà ní àyíká gbọ́ ohun ẹkún rẹ̀. “Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.” Kò sì sí ẹnikẹ́ni lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí ó fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
Hĩndĩ ĩyo Jusufu akĩremwo nĩ kwĩyũmĩrĩria mbere ya arĩa othe maamũtungataga, akĩanĩrĩra na mũgambo mũnene, akiuga atĩrĩ, “Andũ othe nĩmehere harĩ niĩ!” Tondũ ũcio, hatiarĩ mũndũ o na ũmwe warĩ na Jusufu rĩrĩa emenyithanirie kũrĩ ariũ a ithe.
2 Ó sì sọkún sókè kíkankíkan tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Ejibiti gbọ́ ohùn ẹkún rẹ̀, àwọn ilé Farao pẹ̀lú sì gbọ́ nípa rẹ̀.
Na akĩrĩra anĩrĩire o nginya andũ a Misiri makĩmũigua, o na andũ a nyũmba ya Firaũni makĩigua ũhoro wa kĩrĩro kĩu.
3 Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èmi ni Josẹfu! Ṣe baba mi sì wà láààyè?” Ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin rẹ̀ kò le è dá a lóhùn nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n níwájú rẹ̀.
Jusufu akĩĩra ariũ a ithe atĩrĩ, “Nĩ niĩ Jusufu! Baba arĩ o muoyo?” No ariũ a ithe matiahotire kũmũcookeria, nĩgũkorwo nĩmamakĩte mũno marĩ mbere yake.
4 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe bẹ́ẹ̀, ó wí pé, “Èmi ni Josẹfu arákùnrin yín tí ẹ tà sí ilẹ̀ Ejibiti!
Ningĩ Jusufu akĩĩra ariũ a ithe atĩrĩ, “Ta nguhĩrĩriai.” Meeka ũguo-rĩ, akĩmeera atĩrĩ, “Nĩ niĩ mũrũ wa thoguo Jusufu, ũrĩa mwendirie Misiri!
5 Ṣùgbọ́n báyìí, ẹ má ṣe banújẹ́, ẹ má sì ṣe bínú sí ara yín ní títà tí ẹ tà mí sí ìhín, nítorí, ọ̀nà àti gba ẹ̀mí yín là ni Ọlọ́run ṣe rán mi sí ìhín ṣáájú yín.
Na rĩu, mũtigathĩĩnĩke kana mwĩrakarĩre nĩkũnyendia gũkũ, tondũ nĩ Ngai wandũmire njũke mbere yanyu nĩgeetha honokie mĩoyo.
6 Ìyàn tí ó ti mú láti ọdún méjì sẹ́yìn yìí yóò tẹ̀síwájú fún ọdún márùn-ún sí i nínú èyí tí ẹnikẹ́ni kò ní gbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ni kórè.
Handũ-inĩ ha mĩaka ĩĩrĩ rĩu gũkoretwo na ngʼaragu bũrũri-inĩ, na mĩaka ĩtano ĩgũũka gũtigũkorwo na kũrĩma kana kũgetha.
7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run rán mi ṣáájú yín sí ìhín láti da irú-ọmọ yín sí fún un yín lórí ilẹ̀ ayé àti láti fi ìgbàlà ńlá gba ẹ̀mí yín là.
No Ngai aandũmire mbere yanyu nĩguo ndũme matigari manyu matũũre gũkũ thĩ, na honokie mĩoyo yanyu na kũhonokania kũnene.
8 “Nítorí náà, kì í ṣe ẹ̀yin ni ó rán mi wá sí ibí yìí, bí kò ṣe Ọlọ́run. Ó fi mí ṣe baba, Olùdámọ̀ràn fún Farao, olúwa fún gbogbo ilé Farao àti alákòóso gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
“Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, ti inyuĩ mwandũmire gũkũ, no nĩ Ngai. Na nĩanduĩte ta ithe wa Firaũni, na mwathi wa nyũmba yake yothe o na mwathi wa bũrũri wothe wa Misiri.
9 Nísinsin yìí, ẹ yára padà sọ́dọ̀ baba mi kí ẹ sì wí fun un pé, èyí ni ohun tí Josẹfu ọmọ rẹ wí, Ọlọ́run ti fi mí ṣe olúwa fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, ẹ sọ̀kalẹ̀ wá láì jáfara.
Na rĩu hiũhai mũcooke kũrĩ baba mũmwĩre atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo mũrũguo Jusufu ekuuga: Ngai nĩanduĩte mwathi wa bũrũri wa Misiri guothe. Ikũrũka ũũke kũrĩ niĩ; ndũgaikare.
10 Ìwọ yóò gbé ní agbègbè Goṣeni, ìwọ kì yóò jìnnà sí mi, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ, àwọn agbo ẹran rẹ àti agbo màlúù rẹ àti gbogbo ohun tí ìwọ ní.
Ũgũtũũra bũrũri wa Gosheni na ũkorwo ũrĩ hakuhĩ na niĩ, wee na ciana ciaku, na ciana cia ciana ciaku, na ndũũru ciaku cia mbũri na cia ngʼombe, na kĩrĩa gĩothe ũrĩ nakĩo.
11 Èmi yóò pèsè fún yín níbẹ̀. Nítorí ó ṣì ku ọdún márùn-ún gbáko ti ìyàn yóò fi mú. Kí ìwọ àti ilé rẹ àti ohun tí í ṣe tìrẹ má ba à di aláìní.
Kũu nĩkuo ndĩrĩgũteithagĩria tondũ kũrĩ na mĩaka ĩngĩ ĩtano ya ngʼaragu ĩtigarĩte. Kwaga ũguo wee na nyũmba yaku na andũ arĩa othe makwĩgiĩ nĩmũgũtuĩka athĩĩnĩki.’
12 “Ẹ̀yin fúnra yín àti Benjamini arákùnrin mi pẹ̀lú rí i pé, lóòótọ́ lóòótọ́, èmi Josẹfu ni mo ń bá a yín sọ̀rọ̀.
“Inyuĩ nĩmũreyonera, o na Benjamini mũrũ wa maitũ akeyonera, atĩ nĩ niĩ mwene ndĩramwarĩria.
13 Ẹ sọ fún baba mi nípa gbogbo ọlá tí a fún mi ní ilẹ̀ Ejibiti àti ohun gbogbo tí ẹ̀yin ti rí, kí ẹ sì mú baba mi tọ̀ mí wá sí ìhín yìí kíákíá.”
Na mwĩre baba ũhoro wa gĩtĩĩo kĩrĩa gĩothe heetwo gũkũ Misiri, na ũrĩa wothe mwĩoneire, na mũikũrũkie baba gũkũ narua.”
14 Nígbà náà ni ó dì mọ́ Benjamini arákùnrin rẹ̀, ó sì sọkún, Benjamini náà sì dì mọ́ ọn, pẹ̀lú omijé lójú.
Ningĩ akĩhĩmbĩria mũrũ wa nyina Benjamini na akĩrĩra, o nake Benjamini akĩmũhĩmbĩria akĩrĩraga.
15 Ó sì tún fẹnu ko gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ lẹ́nu, ó sì sọkún sí wọn lára. Lẹ́yìn èyí, Josẹfu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ̀rọ̀ pọ̀.
Na akĩmumunya ariũ a ithe othe na akĩmahĩmbĩria akĩrĩraga. Thuutha ũcio ariũ a ithe makĩaranĩria nake.
16 Nígbà tí ìròyìn náà dé ààfin Farao pé àwọn arákùnrin Josẹfu dé, inú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ dùn.
Na rĩrĩa ũhoro ũcio waiguirwo nyũmba-inĩ ya ũthamaki ya Firaũni, atĩ ariũ a ithe na Jusufu nĩmokĩte-rĩ, Firaũni na anene ake othe magĩkena.
17 Farao wí fún Josẹfu pé, “Wí fún àwọn arákùnrin rẹ pé, ‘Èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ di ẹrù lé ẹranko yín kí ẹ sì padà sí ilẹ̀ Kenaani,
Firaũni akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “Ĩra ariũ a thoguo atĩrĩ, ‘Ĩkai ũũ: Igĩrĩrai nyamũ cianyu mĩrigo mũcooke bũrũri wa Kaanani,
18 kí ẹ sì mú baba yín àti ìdílé yín tọ̀ mí wá. Èmi yóò fún un yín ní ibi tí ó dára jùlọ ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sì le è gbádùn ilẹ̀ yìí.’
na mũndehere ithe wanyu na andũ a nyũmba cianyu. Na niĩ nĩngamũhe kũndũ kũrĩa kwega mũno bũrũri-inĩ wa Misiri, na mũkenagĩre ũnoru wa bũrũri ũyũ.’
19 “A pàṣẹ fún ọ láti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe èyí. ẹ mú kẹ̀kẹ́ ẹrù láti ilẹ̀ Ejibiti fún àwọn ọmọ yín àti àwọn aya yín. Kí ẹ sì mú baba yín tọ mí wá.
“Ningĩ nĩwathĩrĩrio ũmeere atĩrĩ: ‘Ĩkai ũũ: Oyai makaari mamwe kuuma gũkũ Misiri nĩ ũndũ wa ciana na atumia anyu, mũgĩĩre ithe wanyu mũũke.
20 Ẹ má ṣe àníyàn nípa ohun ìní yín nítorí èyí tí ó dára jù nínú ilẹ̀ Ejibiti yóò jẹ́ tiyín.’”
Na mũtigatindanĩre na indo cianyu tondũ maũndũ mothe marĩa mega mũno ma Misiri megũtuĩka manyu.’”
21 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí. Josẹfu fún wọn ni kẹ̀kẹ́ ẹrù bí Farao ti pàṣẹ, ó sì fún wọn ní oúnjẹ fún ìrìnàjò wọn pẹ̀lú.
Nĩ ũndũ ũcio ariũ a Isiraeli magĩĩka o ro ũguo. Jusufu akĩmahe makaari o ta ũrĩa Firaũni aathanĩte na agĩcooka akĩmahe rĩĩgu wa rũgendo rwao.
22 Ó fún ẹni kọ̀ọ̀kan wọn ní aṣọ tuntun. Ṣùgbọ́n Benjamini ni ó fún ní ọ̀ọ́dúnrún ẹyọ owó idẹ fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ márùn-ún.
Ningĩ akĩhe o mũndũ o mũndũ wao nguo njerũ, no Benjamini-rĩ, akĩmũhe betha magana matatũ, na nguo ithano cia kũgarũrĩra.
23 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó ránṣẹ́ sí baba rẹ̀: kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru àwọn ohun mèremère ilẹ̀ Ejibiti àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru ọkà àti oríṣìíríṣìí oúnjẹ.
Na indo ici nĩcio aatũmĩire ithe: Ndigiri ikũmi ikuuĩte indo iria njega mũno cia Misiri, na ndigiri ingĩ ikũmi cia mĩgoma ikuuĩte ngano na mĩgate na rĩĩgu wake wa rũgendo.
24 Nígbà náà ni ó rán àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, bí wọ́n ṣe ń pínyà, ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jà ní ọ̀nà o!”
Agĩcooka akiumagaria ariũ a ithe, na magĩthiĩ akĩmeera atĩrĩ, “Mũtikanegenanie mũrĩ njĩra-inĩ!”
25 Báyìí ni wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wá sí ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani.
Nĩ ũndũ ũcio makĩambata makiuma Misiri, magĩthiĩ magĩkinya kũrĩ ithe wao Jakubu kũu bũrũri-inĩ wa Kaanani.
26 Wọn wí fún un pé, “Josẹfu ṣì wà láààyè! Kódà òun ni alákòóso ilẹ̀ Ejibiti.” Ẹnu ya Jakọbu, kò sì gbà wọ́n gbọ́.
Nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Jusufu arĩ o muoyo! Na nĩwe mwathi wa bũrũri wothe wa Misiri.” Jakubu akĩgegeara; akĩaga kũmetĩkia.
27 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n sọ ohun gbogbo tí Josẹfu ti sọ fún wọn fún un tí ó sì rí kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Josẹfu fi ránṣẹ́ láti gbé e padà wá, iyè Jakọbu, baba wọn sọ.
No rĩrĩa maamwĩrire maũndũ marĩa mothe Jusufu aamerĩte, na rĩrĩa onire makaari marĩa Jusufu aatũmĩte ma kũmũkuua mamũtware Misiri-rĩ, roho wa Jakubu ithe wao ũkĩarahũka.
28 Israẹli sì wí pé, “Mo gbà dájúdájú wí pé, Josẹfu ọmọ mi wà láààyè. Èmi ó lọ rí i kí n tó kú.”
Nake Isiraeli akiuga atĩrĩ, “Nĩndetĩkia! Mũrũ wakwa Jusufu arĩ o muoyo. Nĩngũthiĩ ngamuone itanakua.”

< Genesis 45 >