< Genesis 45 >

1 Josẹfu kò sì le è pa á mọ́ra mọ́ níwájú gbogbo àwọn tí ó dúró tì í. Ó sì sọkún sókè tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn tí ó wà ní àyíká gbọ́ ohun ẹkún rẹ̀. “Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.” Kò sì sí ẹnikẹ́ni lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí ó fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
Тогава Иосиф не може вече да се стърпи пред всички ония, които стояха пред него, и извика: Изведете всички отпред мене. И не остана никой при Иосифа, когато той се откри на братята си.
2 Ó sì sọkún sókè kíkankíkan tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn Ejibiti gbọ́ ohùn ẹkún rẹ̀, àwọn ilé Farao pẹ̀lú sì gbọ́ nípa rẹ̀.
И заплака с глас, та египтяните чуха; чу още и Фараоновият дом.
3 Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èmi ni Josẹfu! Ṣe baba mi sì wà láààyè?” Ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin rẹ̀ kò le è dá a lóhùn nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n níwájú rẹ̀.
И Иосиф каза на братята си: Аз съм Иосиф. Баща ми жив ли е още? Но братята му не можаха да му отговорят, защото се смутиха от присъствието му.
4 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe bẹ́ẹ̀, ó wí pé, “Èmi ni Josẹfu arákùnrin yín tí ẹ tà sí ilẹ̀ Ejibiti!
Тогава Иосиф рече на братята си: Елате близо до мен, моля ви. И те се приближиха. И рече: Аз съм брат ви Иосиф, когото вие продадохте в Египет.
5 Ṣùgbọ́n báyìí, ẹ má ṣe banújẹ́, ẹ má sì ṣe bínú sí ara yín ní títà tí ẹ tà mí sí ìhín, nítorí, ọ̀nà àti gba ẹ̀mí yín là ni Ọlọ́run ṣe rán mi sí ìhín ṣáájú yín.
Сега, не скърбете, нито се окайвайте, че ме продадохте тук, понеже Бог ме изпрати пред вас, за да опази живота.
6 Ìyàn tí ó ti mú láti ọdún méjì sẹ́yìn yìí yóò tẹ̀síwájú fún ọdún márùn-ún sí i nínú èyí tí ẹnikẹ́ni kò ní gbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ni kórè.
Защото вече две години гладът върлува в страната; а остават още пет години, в които не ще има ни оране, ни жетва.
7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run rán mi ṣáájú yín sí ìhín láti da irú-ọmọ yín sí fún un yín lórí ilẹ̀ ayé àti láti fi ìgbàlà ńlá gba ẹ̀mí yín là.
Бог ме изпрати пред вас, за да съхраня от вас остатъка на земята и да опазя живота ви чрез голямо избавление.
8 “Nítorí náà, kì í ṣe ẹ̀yin ni ó rán mi wá sí ibí yìí, bí kò ṣe Ọlọ́run. Ó fi mí ṣe baba, Olùdámọ̀ràn fún Farao, olúwa fún gbogbo ilé Farao àti alákòóso gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
И тъй, не ме изпратихте вие тук, но Бог, който ме и направи отец на Фараона, господар на целия му дом и управител на цялата Египетска земя.
9 Nísinsin yìí, ẹ yára padà sọ́dọ̀ baba mi kí ẹ sì wí fun un pé, èyí ni ohun tí Josẹfu ọmọ rẹ wí, Ọlọ́run ti fi mí ṣe olúwa fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, ẹ sọ̀kalẹ̀ wá láì jáfara.
Бързайте, идете при баща ми и му речете: Така казва синът ти Иосиф: Бог ме постави господар над целия Египет; ела при мене незабавно.
10 Ìwọ yóò gbé ní agbègbè Goṣeni, ìwọ kì yóò jìnnà sí mi, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ, àwọn agbo ẹran rẹ àti agbo màlúù rẹ àti gbogbo ohun tí ìwọ ní.
Ти ще живееш в Гесенската земя и ще бъдеш близо при мене, ти, чадата ти, и внуците ти, стадата ти, добитъкът ти и всичко що имаш.
11 Èmi yóò pèsè fún yín níbẹ̀. Nítorí ó ṣì ku ọdún márùn-ún gbáko ti ìyàn yóò fi mú. Kí ìwọ àti ilé rẹ àti ohun tí í ṣe tìrẹ má ba à di aláìní.
Там ще те храня, (защото остават още пет години на глад), за да не изпаднеш в немотия, ти, домът ти и всичко що имаш.
12 “Ẹ̀yin fúnra yín àti Benjamini arákùnrin mi pẹ̀lú rí i pé, lóòótọ́ lóòótọ́, èmi Josẹfu ni mo ń bá a yín sọ̀rọ̀.
И гледайте, вашите очи и очите на брата ми Вениамина виждат, че моите уста ви говорят.
13 Ẹ sọ fún baba mi nípa gbogbo ọlá tí a fún mi ní ilẹ̀ Ejibiti àti ohun gbogbo tí ẹ̀yin ti rí, kí ẹ sì mú baba mi tọ̀ mí wá sí ìhín yìí kíákíá.”
И разкажете на баща ми всичката ми слава в Египет и всичко що видяхте; и бързо доведете баща ми тука.
14 Nígbà náà ni ó dì mọ́ Benjamini arákùnrin rẹ̀, ó sì sọkún, Benjamini náà sì dì mọ́ ọn, pẹ̀lú omijé lójú.
Тогава падна на врата на брата си Вениамина и плака, плака и Вениамина на неговия врат.
15 Ó sì tún fẹnu ko gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ lẹ́nu, ó sì sọkún sí wọn lára. Lẹ́yìn èyí, Josẹfu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ̀rọ̀ pọ̀.
И целуна всичките си братя и плака над тях; и след това братята му се разговаряха с него.
16 Nígbà tí ìròyìn náà dé ààfin Farao pé àwọn arákùnrin Josẹfu dé, inú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ dùn.
И известие за това се чу във Фараоновия дом, като казаха: Иосифовите братя са дошли; и това стана угодно на Фараона и на слугите му.
17 Farao wí fún Josẹfu pé, “Wí fún àwọn arákùnrin rẹ pé, ‘Èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ di ẹrù lé ẹranko yín kí ẹ sì padà sí ilẹ̀ Kenaani,
И Фараон рече на Иосифа: Кажи на братята си: Така направете: натоварете животните си и тръгнете, идете в Ханаанската земя.
18 kí ẹ sì mú baba yín àti ìdílé yín tọ̀ mí wá. Èmi yóò fún un yín ní ibi tí ó dára jùlọ ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sì le è gbádùn ilẹ̀ yìí.’
И като вземете баща си и челядите си, елате при мене; и аз ще ви дам благата на Египетската земя, и ще се храните с тлъстината на земята.
19 “A pàṣẹ fún ọ láti sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe èyí. ẹ mú kẹ̀kẹ́ ẹrù láti ilẹ̀ Ejibiti fún àwọn ọmọ yín àti àwọn aya yín. Kí ẹ sì mú baba yín tọ mí wá.
А на тебе заповядвам да им речеш: Така сторете: вземете коли от Египетската земя за децата си и за жените си и доведете баща си и елате.
20 Ẹ má ṣe àníyàn nípa ohun ìní yín nítorí èyí tí ó dára jù nínú ilẹ̀ Ejibiti yóò jẹ́ tiyín.’”
При това, не жалете вещите си, защото благата на цялата Египетска земя ще бъдат ваши.
21 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí. Josẹfu fún wọn ni kẹ̀kẹ́ ẹrù bí Farao ti pàṣẹ, ó sì fún wọn ní oúnjẹ fún ìrìnàjò wọn pẹ̀lú.
И синовете на Израиля сториха така; и Иосиф им даде коли, според Фараоновата заповед, даде им и храна за из пътя.
22 Ó fún ẹni kọ̀ọ̀kan wọn ní aṣọ tuntun. Ṣùgbọ́n Benjamini ni ó fún ní ọ̀ọ́dúnrún ẹyọ owó idẹ fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ márùn-ún.
На всеки от тях даде дрехи за премяна; а на Вениамина даде триста сребърника и дрехи за пет премени.
23 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó ránṣẹ́ sí baba rẹ̀: kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru àwọn ohun mèremère ilẹ̀ Ejibiti àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru ọkà àti oríṣìíríṣìí oúnjẹ.
И на баща си изпрати десет осли натоварени с Египетски блага, десет ослици натоварени с жито и хляб, и храна за баща си за из пътя.
24 Nígbà náà ni ó rán àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, bí wọ́n ṣe ń pínyà, ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jà ní ọ̀nà o!”
Така изпрати братята си та си отидоха; и поръча им: Да не се карате по пътя.
25 Báyìí ni wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wá sí ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani.
И тъй, те излязоха от Египет та дойдоха в Ханаанската земя, при баща си Якова.
26 Wọn wí fún un pé, “Josẹfu ṣì wà láààyè! Kódà òun ni alákòóso ilẹ̀ Ejibiti.” Ẹnu ya Jakọbu, kò sì gbà wọ́n gbọ́.
И известиха му, казвайки: Иосиф е още жив и е управител на цялата Египетска земя. А сърцето му примря, защото не ги вярваше.
27 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n sọ ohun gbogbo tí Josẹfu ti sọ fún wọn fún un tí ó sì rí kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Josẹfu fi ránṣẹ́ láti gbé e padà wá, iyè Jakọbu, baba wọn sọ.
Но те му разказаха всичко, което Иосиф им беше говорил; и като видя колите, които Иосиф бе изпратил да го вземат, духът на баща им Якова се съживи.
28 Israẹli sì wí pé, “Mo gbà dájúdájú wí pé, Josẹfu ọmọ mi wà láààyè. Èmi ó lọ rí i kí n tó kú.”
И рече Израил: Доволно е; син ми Иосиф е още жив, ще ида и ще го видя преди да умра.

< Genesis 45 >