< Genesis 44 >

1 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
Andin u ɵz ɵyini baxⱪuridiƣan ƣojidariƣa buyrup: — Bu kixilǝrning taƣarlirini elip kɵtürǝligüdǝk axliⱪ ⱪaqilap, ⱨǝrbirining pulini taƣirining aƣziƣa selip ⱪoyƣin;
2 Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
andin mening jamimni, yǝni kümüx jamni axliⱪning puli bilǝn billǝ ǝng kiqikining taƣirining aƣziƣa selip ⱪoyƣin, — dedi. U adǝm Yüsüpning deginidǝk ⱪildi.
3 Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
Ətisi tang yoriƣanda, ular exǝkliri bilǝn billǝ yolƣa selip ⱪoyuldi.
4 Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
Lekin ular xǝⱨǝrdin qiⱪip anqǝ uzun mangmayla, Yüsüp ƣojidariƣa: — Ornungdin tur, bu adǝmlǝrning kǝynidin ⱪoƣliƣin; ularƣa yetixkiningdǝ ularƣa: «Nemixⱪa yahxiliⱪⱪa yamanliⱪ ⱪayturdunglar?
5 Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
Hojam xu [jamda] xarab iqidu ⱨǝmdǝ uningda pal aqidu ǝmǝsmu?! Mundaⱪ ⱪilƣininglar rǝzillik ⱪilƣininglar bolmamdu!» degin, — dedi.
6 Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
Bu adǝm ularning kǝynidin yetixip berip, ularƣa bu sɵzlǝrni ⱪildi.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
Ular uningƣa jawabǝn: — Hojimiz nemixⱪa mundaⱪ gǝp ⱪilidu? Mundaⱪ ixni ⱪilix kǝminiliridin neri bolsun!
8 A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
Biz ǝslidǝ taƣarlirimizning aƣzidin tapⱪan pulnimu Ⱪanaan zeminidin silining ⱪaxliriƣa ⱪayturup berixkǝ ǝkǝlgǝniduⱪ. Xundaⱪ turuⱪluⱪ ⱪandaⱪmu hojilirining ɵyidin altun-kümüxni oƣrilayli?
9 Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
Kǝminiliringning arisida kimdin bu [jam] tepilsa, xu ɵlümgǝ mǝⱨkum bolsun, bizmu hojimizning ⱪulliri bolayli, — dedi.
10 Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
Ƣojidar jawabǝn: — Eytⱪan sɵzliringlardǝk bolsun; jam kimning yenidin tepilsa, xu kixi ⱪulum bolup ⱪelip ⱪalsun, ⱪalƣanliringlar bigunaⱨ bolisilǝr, — dedi.
11 Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
Xuning bilǝn ular aldirap-tenǝp, taƣarlirini yǝrgǝ qüxürüp, ⱨǝrbiri ɵz taƣirini eqip bǝrdi.
12 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
Ƣojidar qonginingkidin baxlap kiqikiningkigiqǝ ahturdi, jam Binyaminning taƣiridin tepildi.
13 Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
Buni kɵrüp ular kiyimlirini yirtixip, ⱨǝrbiri exikigǝ ⱪaytidin yükni artip, xǝⱨǝrgǝ ⱪaytti.
14 Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Xundaⱪ ⱪilip Yǝⱨuda wǝ ⱪerindaxliri Yüsüpning ɵyigǝ kǝldi; u tehi xu yǝrdǝ idi. Ular uning aldiƣa kelip ɵzlirini yǝrgǝ etixti.
15 Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
Yüsüp ularƣa: — Bu silǝrning zadi nemǝ ⱪilƣininglar? Meningdǝk adǝmning qoⱪum pal aqalaydiƣanliⱪini bilmǝmtinglar? — dedi.
16 Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
Yǝⱨuda jawabǝn: — Biz hojimizƣa nemimu deyǝlǝymiz? Nemǝ gǝp ⱪilalaymiz, ⱪandaⱪ ⱪilip ɵzimizni aⱪliyalaymiz? Huda kǝminlirining ⱪǝbiⱨlikini axkara ⱪildi. Mana, biz wǝ ⱪolidin jamliri tepilƣan kixi ⱨǝmmimiz hojimizƣa ⱪul bolidiƣan bolduⱪ, — dedi.
17 Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
Lekin Yüsüp: — Mundaⱪ ⱪilix mǝndin neri bolsun! Bǝlki jam kimning ⱪolidin tepilƣan bolsa pǝⱪǝt xu kixi mening ⱪulum bolidu. Lekin ⱪalƣanliringlar aman-esǝn atanglarning ⱪexiƣa ketinglar, — dedi.
18 Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
Andin Yǝⱨuda uningƣa yeⱪin berip mundaⱪ dedi: — Əy hojam, kǝminilirigǝ ⱪulaⱪ selip hojamning ⱪuliⱪiƣa bir eƣiz gǝp ⱪilixⱪa ijazǝt bǝrgǝyla. Ƣǝzǝpliri kǝminilirigǝ tutaxmiƣay; qünki ɵzliri Pirǝwngǝ ohxax ikǝnla.
19 Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
Əslidǝ hojam kǝminiliridin: «Atanglar ya ininglar barmu?» dǝp soriwidila,
20 Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
biz hojimizƣa jawabǝn: «Bizning bir ⱪeri atimiz bar wǝ u ⱪeriƣanda tapⱪan, yax bir balisimu bar. Bu balining bir anisidin bolƣan akisi ɵlüp ketip, u ɵzi yalƣuz ⱪaldi; uning atisi uni intayin sɵyidu» desǝk,
21 “Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
Sili kǝminilirigǝ: «Uning ɵzini ⱪeximƣa elip kelinglar, mǝn uni ɵz kɵzüm bilǝn kɵrǝy» dedilǝ.
22 A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
Biz hojimizƣa jawab berip: «Yigit atisidin ayrilalmaydu; ǝgǝr atisidin ayrilsa, atisi ɵlüp ketidu» desǝk,
23 Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
Sili yǝnila kǝminilirigǝ: «Əgǝr kiqik ininglar silǝr bilǝn billǝ kǝlmisǝ, yüzümni yǝnǝ kɵrimiz dǝp hiyal ⱪilmanglar» degǝnidila.
24 Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
Xuning bilǝn biz kǝminiliri atimizning ⱪexiƣa barƣanda hojamning sɵzlirini uningƣa eyttuⱪ;
25 “Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
andin atimiz yǝnǝ: «Yǝnǝ berip, bizgǝ azraⱪ axliⱪ elip kelinglar» dewidi,
26 Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
Biz jawabǝn: «Biz xu yǝrgǝ ⱪaytidin qüxǝlmǝymiz; ǝgǝr kiqik inimiz biz bilǝn billǝ bolsa, undaⱪta barimiz; qünki kiqik inimiz biz bilǝn billǝ bolmisa, u zatning yüzi aldida turalmaymiz», deduⱪ.
27 “Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
Silining ⱪulliri bizning atimiz bizgǝ yǝnǝ: «silǝrgǝ mǝlumki, ayalim manga ikki oƣul tuƣup bǝrgǝnidi.
28 Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
Biri mening yenimdin qiⱪip, yoⱪ bolup kǝtti; mǝn: u jǝzmǝn titma-titma ⱪiliwetiliptu, dǝp oylidim, xundaⱪla uni bügüngiqǝ kɵrmidim.
29 Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol h7585)
Əmdi silǝr bunimu mening ⱪeximdin elip ketip, uningƣa bir kelixmǝslik kelip ⱪalsa, silǝr mǝndǝk bir aⱪ qaqliⱪ adǝmni dǝrd-ǝlǝm bilǝn tǝhtisaraƣa qüxüriwetisilǝr», degǝnidi. (Sheol h7585)
30 “Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
Əmdi mǝn silining ⱪulliri mening atamning ⱪexiƣa barƣanda, xu bala biz bilǝn bolmisa uning jeni balining jeniƣa baƣlanƣan bolƣaqⱪa,
31 Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol h7585)
xundaⱪ boliduki, u balining yoⱪluⱪini kɵrsǝ, jǝzmǝn ɵlüp ketidu; xuning bilǝn silining ⱪulliri bizning atimiz bolƣan bu aⱪ qaqni dǝrd-ǝlǝm iqidǝ tǝⱨtisaraƣa qüxürüwǝtkǝn bolimiz. (Sheol h7585)
32 Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
Qünki mǝnki kǝminiliri atamƣa bu yigit üqün kepil bolup: «Əgǝr mǝn uni ⱪexingƣa ⱪayturup kǝlmisǝm pütkül ɵmrümdǝ atamning aldida gunaⱨkar bolay» degǝnidim.
33 “Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
Xunga ⱨazir ɵtünüp ⱪalay, mǝnki kǝminiliri u yigitning ornida hojamning ⱪexida ⱪul bolup tursam, u yigit ⱪerindaxliri bilǝn billǝ ⱪaytip kǝtsǝ!
34 Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”
Qünki yigit mǝn bilǝn bolmisa, mǝn ⱪandaⱪmu atamning ⱪexiƣa baralaymǝn? Atamƣa xundaⱪ azab-oⱪubǝtning qüxüxini kɵzüm kɵrgüqi bolmisun! — dedi.

< Genesis 44 >