< Genesis 44 >

1 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
Därefter bjöd han sin hovmästare och sade: »Fyll männens säckar med säd, så mycket de kunna rymma, och lägg vars och ens penningar överst i hans säck.
2 Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
Och min bägare, silverbägaren, skall du lägga överst i den yngstes säck, tillika med penningarna för hans säd.» Och han gjorde såsom Josef hade sagt.
3 Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
Om morgonen, då det blev dager, fingo männen fara med sina åsnor.
4 Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
Men när de hade kommit ett litet stycke utom staden, sade Josef till sin hovmästare: »Stå upp och sätt efter männen; och när du hinner upp dem, så säg till dem: 'Varför haven I lönat gott med ont?
5 Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
Det är ju just den bägaren som min herre dricker ur, och som han plägar spå med. Det är en ond gärning I haven gjort.'»
6 Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
När han nu hann upp dem, sade han detta till dem.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
Då svarade de honom: »Varför talar min herre så? Bort det, att dina tjänare skulle göra sådant!
8 A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
De penningar som vi funno överst i våra säckar hava vi ju fört tillbaka till dig från Kanaans land. Huru skulle vi då kunna vilja stjäla silver eller guld ur din herres hus?
9 Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
Den bland dina tjänare, som den finnes hos, han må dö; därtill vilja vi andra bliva min herres trälar.»
10 Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
Han svarade: »Ja, vare det såsom I haven sagt; den som den finnes hos, han skall bliva min träl. Men I andra skolen vara utan skuld.»
11 Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
Och de skyndade sig att lyfta ned var och en sin säck på jorden, och öppnade var och en sin säck.
12 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
Och han begynte att söka hos den äldste och slutade hos den yngste; och bägaren fanns i Benjamins säck.
13 Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
Då revo de sönder sina kläder och lastade åter var och en sin åsna och vände tillbaka till staden.
14 Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Och Juda och hans bröder gingo in i Josefs hus, där denne ännu var kvar; och de föllo ned till jorden för honom.
15 Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
Då sade Josef till dem: »Vad haven I gjort! Förstoden I icke att en man sådan som jag kan spå?»
16 Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
Juda svarade: Vad skola vi säga till min herre, vad skola vi tala, och huru skola vi rättfärdiga oss? Gud har funnit dina tjänares missgärning. Se, vi äro min herres trälar, vi andra såväl som den som bägaren har blivit funnen hos.»
17 Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
Men han sade: »Bort det, att jag skulle så göra! Den som bägaren har blivit funnen hos, han skall bliva min träl. Men I andra mån i frid fara hem till eder fader.»
18 Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
Då trädde Juda fram till honom och sade: »Hör mig, herre; låt din tjänare tala ett ord inför min herre, och må din vrede icke upptändas mot din tjänare; ty du är såsom Farao.
19 Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
Min herre frågade sina tjänare och sade: 'Haven I eder fader eller någon broder ännu därhemma?'
20 Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
Och vi svarade min herre: 'Vi hava en åldrig fader och en son till honom, en som är född på hans ålderdom och ännu är ung; men en broder till denne är död, så att han allena är kvar efter sin moder, och hans fader har honom kär.'
21 “Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
Då sade du till dina tjänare: 'Fören honom hitned till mig, så att jag kan låta mitt öga vila på honom.'
22 A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
Och vi svarade min herre: 'Ynglingen kan icke lämna sin fader, ty om han lämnade sin fader, så skulle denne dö.'
23 Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
Men du sade till dina tjänare: 'Om eder yngste broder icke följer med eder hitned, så fån I icke mer komma inför mitt ansikte.'
24 Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
När vi därefter hade kommit hem till din tjänare, min fader, berättade vi för honom vad min herre hade sagt.
25 “Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
Och när sedan vår fader sade: 'Faren tillbaka och köpen litet säd till föda åt oss',
26 Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
svarade vi: 'Vi kunna icke fara ditned; allenast på det villkoret vilja vi fara, att vår yngste broder följer med oss; ty vi få icke komma inför mannens ansikte om vår yngste broder icke är med oss.
27 “Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
Men din tjänare, min fader, sade till oss: 'I veten själva att min hustru har fött åt mig två söner,
28 Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
och den ene gick bort ifrån mig, och jag sade: förvisso är han ihjälriven. Och jag har icke sett honom sedan den tiden.
29 Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol h7585)
Om I nu tagen också denne ifrån mig och någon olycka händer honom, så skolen I bringa mina grå hår med jämmer ned i dödsriket.' (Sheol h7585)
30 “Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
Om jag alltså kommer hem till din tjänare, min fader, utan att vi hava med oss ynglingen, som vår faders hjärta är så fäst vid,
31 Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol h7585)
då bliver det hans död, när han ser att ynglingen icke är med; och dina tjänare skulle så bringa din tjänares, vår faders, grå hår med sorg ned i dödsriket. (Sheol h7585)
32 Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
Ty jag, din tjänare, har lovat min fader att ansvara för ynglingen och har sagt, att om jag icke för denne till honom igen, så vill jag vara en syndare inför min fader i all min tid.
33 “Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
Låt nu därför din tjänare stanna kvar hos min herre såsom träl, i ynglingens ställe, men låt ynglingen fara hem med sina bröder.
34 Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”
Ty huru skulle jag kunna fara hem till min fader utan att hava ynglingen med mig? Jag förmår icke se den jämmer som då skulle komma över min fader.»

< Genesis 44 >