< Genesis 44 >

1 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
Şi a poruncit administratorului casei sale, spunând: Umple sacii bărbaţilor cu hrană, atât cât pot căra; şi pune banii fiecărui bărbat la gura sacului său.
2 Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
Şi pune paharul meu, paharul de argint, la gura sacului celui mai tânăr şi banii lui pentru grâne. Iar el a făcut conform cuvântului pe care Iosif l-a spus.
3 Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
Imediat ce s-a luminat de dimineaţă, bărbaţii au fost trimişi, ei şi măgarii lor.
4 Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
Şi după ce au ieşit din cetate şi nu erau încă departe, Iosif a spus administratorului său: Ridică-te, urmăreşte bărbaţii aceia; şi după ce îi ajungi, spune-le: Pentru ce aţi răsplătit rău pentru bine?
5 Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
Nu este acesta, paharul din care domnul meu bea, şi prin care într-adevăr el ghiceşte? Aţi făcut rău făcând astfel.
6 Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
Şi i-a ajuns şi le-a vorbit aceste cuvinte.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
Iar ei i-au spus: Pentru ce spune domnul meu aceste cuvinte? Nicidecum nu vor face servitorii tăi conform acestui lucru.
8 A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
Iată, banii pe care noi i-am găsit la gura sacilor noştri, i-am adus din nou la tine din ţara lui Canaan; cum atunci am fura noi argint sau aur din casa domnului tău?
9 Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
La oricare din servitorii tăi ar fi găsită, deopotrivă el să moară, iar noi de asemenea vom fi robii domnului meu.
10 Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
Iar el a spus: Acum de asemenea aceasta să fie conform cuvintelor voastre, cel la care paharul este găsit va fi robul meu, iar voi veţi fi fără vină.
11 Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
Atunci ei îndată şi-au coborât la pământ fiecare sacul său şi fiecare şi-a deschis sacul.
12 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
Şi a căutat începând de la cel mai în vârstă şi a terminat la cel mai tânăr, şi paharul s-a găsit în sacul lui Beniamin.
13 Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
Atunci ei şi-au rupt hainele şi fiecare bărbat şi-a încărcat măgarul şi s-au întors în cetate.
14 Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Şi Iuda şi fraţii săi au venit la casa lui Iosif, căci el era încă acolo; şi au căzut înaintea lui la pământ.
15 Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
Şi Iosif le-a spus: Ce faptă este aceasta pe care aţi făcut-o? Sau nu ştiţi că un astfel de om ca mine poate cu adevărat ghici?
16 Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
Şi Iuda a spus: Ce să spunem domnului meu? Ce să vorbim? Sau cum să ne dezvinovăţim? Dumnezeu a descoperit nelegiuirea servitorilor tăi; iată, noi suntem servitorii domnului meu, deopotrivă noi şi de asemenea cel cu care paharul a fost găsit.
17 Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
Iar el a spus: Nicidecum nu voi face astfel; ci bărbatul în a cărui mână a fost găsit paharul, acela va fi servitorul meu; şi cât despre voi, urcaţi-vă în pace la tatăl vostru.
18 Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
Atunci Iuda s-a apropiat de el şi a spus: Vai domnul meu, lasă pe servitorul tău, te rog, să vorbească un cuvânt în urechile domnului meu şi nu lăsa mânia ta să se aprindă împotriva servitorului tău, căci tu eşti întocmai ca Faraon.
19 Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
Domnul meu a întrebat pe servitorii săi, spunând: Aveţi voi un tată, sau un frate?
20 Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
Şi noi am spus domnului meu: Avem un tată, un om bătrân, şi un copil al bătrâneţii lui, unul mic; şi fratele lui este mort şi numai el a rămas de la mama sa; şi tatăl său îl iubeşte.
21 “Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
Şi tu ai spus servitorilor tăi: Aduceţi-l jos la mine, ca să îmi pun ochii mei peste el.
22 A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
Şi noi am spus domnului meu: Tânărul nu poate părăsi pe tatăl său, căci dacă el va părăsi pe tatăl său, tatăl său va muri.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
Şi tu ai spus servitorilor tăi: Dacă fratele vostru cel mai tânăr nu coboară cu voi, nu îmi veţi mai vedea faţa.
24 Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
Şi s-a întâmplat când noi am urcat la servitorul tău, tatăl meu, că i-am spus cuvintele domnului meu.
25 “Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
Şi tatăl nostru a spus: Mergeţi din nou şi cumpăraţi-ne puţină hrană.
26 Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
Iar noi am spus: Nu putem coborî decât dacă fratele nostru cel mai tânăr este cu noi, atunci vom coborî; căci nu putem vedea faţa bărbatului, decât dacă fratele nostru cel mai tânăr este cu noi.
27 “Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
Şi servitorul tău, tatăl meu, ne-a spus: Ştiţi că soţia mea mi-a născut doi fii;
28 Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
Şi unul a plecat de la mine şi am spus: Cu adevărat este sfâşiat în bucăţi; şi nu l-am văzut de atunci.
29 Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol h7585)
Şi dacă îl luaţi şi pe acesta de la mine şi i se întâmplă nenorocire veţi coborî perii mei cărunţi cu întristare în mormânt. (Sheol h7585)
30 “Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
Acum de aceea când eu ajung la servitorul tău, tatăl meu, şi tânărul nu este cu noi, văzând că viaţa lui este legată de viaţa tânărului,
31 Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol h7585)
Se va întâmpla, când el vede că tânărul nu este cu noi, că va muri; şi servitorii tăi vor coborî perii cărunţi ai servitorului tău, tatăl nostru, cu întristare în mormânt. (Sheol h7585)
32 Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
Căci servitorul tău a devenit garanţie pentru tânăr pentru tatăl meu, spunând: Dacă nu îl aduc la tine, atunci voi suporta vina faţă de tatăl meu pentru totdeauna.
33 “Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
Acum de aceea, te rog, lasă pe servitorul tău să rămână în locul tânărului ca rob domnului meu; şi lasă tânărul să urce cu fraţii săi.
34 Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”
Căci cum voi urca la tatăl meu şi băiatul să nu fie cu mine? Ca nu cumva să văd răul ce va veni peste tatăl meu!

< Genesis 44 >