< Genesis 44 >

1 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
Wtedy [Józef] rozkazał zarządcy swego domu: Napełnij wory tych ludzi zbożem, ile tylko mogą unieść, a pieniądze każdego włóż na wierzch jego wora.
2 Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
Mój kielich też, kielich srebrny, włóż na wierzch wora najmłodszego razem z pieniędzmi za zboże. I zrobił według słów Józefa, jak mu rozkazał.
3 Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
O świcie wyprawiono tych ludzi razem z ich osłami.
4 Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
Gdy wyszli z miasta i byli niedaleko, Józef powiedział do zarządcy swego domu: Wstań, goń tych ludzi, a gdy ich dogonisz, powiedz do nich: Czemu oddaliście złem za dobro?
5 Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
Czy to nie jest [kielich], z którego pija mój pan i z którego wróży? Źle postąpiliście, dopuszczając się tego.
6 Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
[Ten] dogonił ich więc i powiedział do nich te słowa.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
Ale [oni] mu odpowiedzieli: Dlaczego mój pan mówi takie słowa? Nie daj Boże, aby twoi słudzy mieli tak postąpić.
8 A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
Przecież pieniądze, które znaleźliśmy na wierzchu naszych worów, przynieśliśmy do ciebie z powrotem z ziemi Kanaan. Jakże mielibyśmy kraść z domu twego pana srebro lub złoto?
9 Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
U którego z twoich sług to się znajdzie, niech umrze, a my będziemy niewolnikami mego pana.
10 Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
[On] powiedział: Niech będzie tak, jak mówicie. Przy którym znajdzie się kielich, ten będzie niewolnikiem, a wy będziecie niewinni.
11 Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
Wtedy każdy szybko zdjął swój wór na ziemię i rozwiązał go.
12 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
I szukał, zaczynając od starszego, a kończąc na najmłodszym. I znalazł kielich w worze Beniamina.
13 Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
Wtedy rozdarli swoje szaty, każdy załadował swego osła i wrócili do miasta.
14 Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Przyszedł więc Juda i jego bracia do domu Józefa, który tam jeszcze był. I upadli przed nim na ziemię.
15 Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
I Józef zapytał ich: Co zrobiliście? Czy nie wiedzieliście, że [taki] człowiek jak ja potrafi wróżyć?
16 Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
Wtedy Juda odpowiedział: Cóż możemy odpowiedzieć memu panu? Co możemy mówić i jak mamy się usprawiedliwić? Bóg znalazł nieprawość u twoich sług. Oto jesteśmy niewolnikami mego pana, zarówno my, jak i ten, u którego znalazł się kielich.
17 Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
A on odpowiedział: Nie daj Boże, abym miał tak uczynić. Człowiek, w którego ręku znaleziono kielich, będzie moim niewolnikiem. Wy zaś jedźcie w pokoju do waszego ojca.
18 Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
Wtedy Juda podszedł do niego i powiedział: Mój panie! [Pozwól] twemu słudze mówić słowo do uszu mego pana, a niech nie zapala się twój gniew na twego sługę, gdyż ty jesteś jak sam faraon.
19 Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
Mój pan pytał swoich sług: Czy macie ojca albo brata?
20 Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
Wtedy odpowiedzieliśmy memu panu: Mamy ojca, starca, i chłopca małego [spłodzonego] w jego starości. Jego brat umarł i tylko on został [po] swej matce, i jego ojciec go kocha.
21 “Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
Potem mówiłeś [do nas], swoich sług: Przyprowadźcie go do mnie, abym mógł go zobaczyć własnymi oczyma.
22 A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
I mówiliśmy do mego pana: Chłopiec nie będzie mógł opuścić swego ojca, bo gdyby opuścił swego ojca, ten by umarł.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
Wtedy powiedziałeś do swoich sług: Jeśli nie przyjdzie z wami wasz najmłodszy brat, więcej nie zobaczycie mojej twarzy.
24 Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
Gdy więc przyszliśmy do twego sługi, mego ojca, powtórzyliśmy mu te słowa mego pana.
25 “Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
Wtedy nasz ojciec powiedział: Jedźcie znowu i kupcie nam trochę żywności.
26 Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
I powiedzieliśmy: Nie możemy [tam] iść. Lecz jeśli [będzie] z nami nasz najmłodszy brat, wtedy pojedziemy. Bo nie będziemy mogli zobaczyć twarzy tego człowieka, jeśli nie będzie z nami naszego najmłodszego brata.
27 “Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
I twój sługa, mój ojciec, powiedział do nas: Wy wiecie, że moja żona urodziła mi dwóch [synów].
28 Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
Jeden wyszedł ode mnie i powiedziałem: Na pewno został rozszarpany [przez zwierzę] i nie widziałem go do dziś.
29 Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol h7585)
A jeśli zabierzecie mi też tego i spotka go nieszczęście, wtedy w żalu doprowadzicie mnie, osiwiałego, do grobu. (Sheol h7585)
30 “Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
Dlatego jeśli przyjdę do twego sługi, mojego ojca, a nie będzie z nami chłopca, z którym jest bardzo związany;
31 Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol h7585)
Stanie się tak, że jak tylko zobaczy, że chłopca nie ma, umrze. A twoi słudzy doprowadzą twego sługę, naszego ojca, osiwiałego, z żalu do grobu. (Sheol h7585)
32 Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
Bo twój sługa wziął na siebie odpowiedzialność przed ojcem i mówił: Jeśli go nie przyprowadzę, będę po wszystkie dni winien grzechu przeciw mojemu ojcu.
33 “Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
Teraz więc, proszę, niech twój sługa zostanie niewolnikiem mego pana zamiast tego chłopca, a niech chłopak idzie ze swymi braćmi.
34 Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”
Bo jak ja mam wrócić do mego ojca, gdy nie będzie ze mną tego chłopca? Nie chciałbym patrzeć na rozpacz, która by dotknęła mego ojca.

< Genesis 44 >