< Genesis 44 >

1 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
Sen jälkeen Joosef käski huoneenhaltijaansa sanoen: "Täytä miesten säkit viljalla, niin paljon kuin he voivat kuljettaa, ja pane itsekunkin raha hänen säkkinsä suuhun.
2 Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
Ja nuorimman säkin suuhun pane minun maljani, tuo hopeamalja, ynnä hänen viljarahansa." Ja hän teki, niinkuin Joosef käski.
3 Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
Aamulla päivän valjetessa miehet saivat aaseinensa lähteä matkalle.
4 Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
Mutta kun he olivat ehtineet vähän matkaa kaupungin ulkopuolelle, sanoi Joosef huoneenhaltijalleen: "Nouse ja aja miehiä takaa, ja kun saavutat heidät, sano heille: 'Minkätähden olette palkinneet hyvän pahalla?
5 Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
Onhan se juuri se, josta isäntäni juo ja josta hän salaisia tiedustelee. Te olette pahoin tehneet menetellessänne näin.'"
6 Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
Kun hän sitten saavutti heidät, puhui hän heille nämä sanat.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
He vastasivat hänelle: "Minkätähden herramme puhuu näin? Pois se, että palvelijasi tekisivät niin!
8 A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
Katso, rahan, jonka löysimme säkkiemme suusta, me olemme tuoneet takaisin sinulle Kanaanin maasta; kuinka siis olisimme varastaneet hopeata tai kultaa herrasi talosta?
9 Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
Se palvelijoistasi, jolta se löydetään, kuolkoon; ja me muut tulemme herramme orjiksi."
10 Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
Hän vastasi: "Olkoon niin, kuin olette puhuneet; se, jolta se löydetään, olkoon minun orjani. Mutta te muut pääsette vapaiksi."
11 Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
Ja he laskivat nopeasti säkkinsä maahan, ja jokainen avasi säkkinsä.
12 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
Ja hän etsi, alkaen vanhimmasta ja lopettaen nuorimpaan, ja malja löytyi Benjaminin säkistä.
13 Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
Silloin he repäisivät vaatteensa, kuormasivat kukin tavaransa aasinsa selkään ja palasivat kaupunkiin.
14 Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Ja Juuda meni veljinensä Joosefin taloon, jossa tämä vielä oli, ja he lankesivat maahan hänen eteensä.
15 Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
Silloin Joosef sanoi heille: "Mitä olettekaan tehneet! Ettekö tienneet, että minun kaltaiseni mies saa salatut ilmi?"
16 Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
Juuda vastasi: "Mitä sanoisimmekaan herralleni, mitä puhuisimme ja millä puolustautuisimme! Jumala on paljastanut palvelijaisi syyllisyyden. Katso, me olemme herrani orjat, niin hyvin me muut kuin se, jolta malja löytyi."
17 Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
Hän sanoi: "Pois se, että minä tekisin niin! Se, jolta malja löytyi, olkoon minun orjani, mutta te muut menkää rauhassa kotiin isänne luo."
18 Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
Silloin Juuda astui hänen eteensä ja sanoi: "Oi herrani, salli palvelijasi puhua sananen herrani kuullen, älköönkä vihasi syttykö palvelijaasi kohtaan, sillä sinä olet niinkuin itse farao!
19 Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
Herrani kysyi palvelijoiltaan sanoen: 'Onko teillä isää tai veljeä?'
20 Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
Me vastasimme herralleni: 'Meillä on kotona vanha isä ja veli, joka on syntynyt hänen vanhoilla päivillänsä ja on vielä nuori; mutta tämän veli on kuollut, ja niin hän on jäänyt yksin äidistänsä, ja hänen isänsä rakastaa häntä'.
21 “Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
Niin sinä sanoit palvelijoillesi: 'Tuokaa hänet tänne minun luokseni, että silmäni saisivat katsella häntä'.
22 A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
Me vastasimme herralleni: 'Nuorukainen ei saata jättää isäänsä, sillä jos hän jättäisi isänsä, niin tämä kuolisi'.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
Mutta sinä sanoit palvelijoillesi: 'Jos nuorin veljenne ei tule tänne teidän kanssanne, niin älkää enää näyttäytykö minun kasvojeni edessä'.
24 Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
Ja me menimme kotiin palvelijasi, minun isäni, luo ja kerroimme hänelle herrani sanat.
25 “Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
Niin isämme sanoi: 'Menkää jälleen ostamaan meille vähän elintarpeita'.
26 Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
Me sanoimme: 'Emme voi lähteä sinne; ainoastaan jos nuorin veljemme seuraa mukanamme, me lähdemme, sillä me emme voi näyttäytyä sen miehen kasvojen edessä, jollei nuorin veljemme ole mukanamme'.
27 “Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
Niin palvelijasi, minun isäni, sanoi meille: 'Tiedättehän itse, että vaimoni synnytti minulle kaksi poikaa.
28 Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
Toinen lähti pois luotani, ja minä sanoin: Varmaan hänet on raadeltu kuoliaaksi, enkä minä ole häntä siitä päivin nähnyt.
29 Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol h7585)
Jos te nyt viette minulta tämänkin ja jos onnettomuus kohtaa häntä, niin te saatatte minun harmaat hapseni vaipumaan tuskalla tuonelaan.' (Sheol h7585)
30 “Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
Jos minä siis tulisin kotiin palvelijasi, isäni, luo eikä meillä olisi mukanamme nuorukaista, johon hän on kaikesta sielustaan kiintynyt,
31 Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol h7585)
niin hän nähdessään, ettei nuorukainen ole kanssamme, kuolisi, ja me, sinun palvelijasi, saattaisimme palvelijasi, isämme, harmaat hapset vaipumaan murheella tuonelaan. (Sheol h7585)
32 Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
Sillä palvelijasi on luvannut isälleen vastata nuorukaisesta ja sanonut: 'Jos en tuo häntä takaisin luoksesi, niin minä olen syyllinen isäni edessä kaiken elinaikani'.
33 “Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
Ja jääköön siis palvelijasi herralleni orjaksi nuorukaisen sijaan, ja nuorukainen menköön kotiin veljiensä kanssa.
34 Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”
Sillä kuinka minä voisin mennä kotiin isäni luo, jollei nuorukainen olisi kanssani? En voisi nähdä sitä surkeutta, joka tulisi isäni osaksi."

< Genesis 44 >