< Genesis 44 >
1 Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
Ahnimouh ni imkaringkung koevah, ahnimouh ni aphu thai yit touh, cawngko pakawi pouh nateh, amamae tangka rip hah amamae cawngko som koe lengkaleng tat pouh.
2 Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
Hahoi kaie manang, ngun manang hah a cahnoung e cawngko som dawkvah cakang phu tangka hoi na ta pouh han, telah kâ a poe.
3 Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
Khodai tahma vah ahnimouh teh amamae lanaw hoi a kamthaw awh.
4 Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
Kho thung hoi a kamthaw awh teh ahlapoungnae koe a pha awh hoehnahlan, Joseph ni imkaringkung koe thaw nateh ahnimanaw hah pâlei haw. Hahoi na pha toteh ahnimouh koe, bangkongmaw hawinae hah hawihoehnae hoi na patho awh.
5 Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
Hot hah, kaie bawipa e misur neinae hoi hma lae ka tho hane kong a panuenae nahoehmaw. Het patet lae na o awh e heh puenghoi na payon awh, na ti pouh han.
6 Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
Hahoi, rek a pha toteh hottelah a dei pouh.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
Ahnimouh ni ahni koe, bawipa, bangkongmaw het patet lae lawk na dei, na sannaw ni hot patet e hno ka sak awh hoeh.
8 A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
Khenhaw! kaimae cawngko som dawk ka hmu awh e tangka hoi Kanaan kho hoi nang koe bout ka thokhai awh nahoehmaw. Bangtelamaw na bawipa im e tangka hoi sui teh ka paru thai awh han namaw.
9 Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
Na sannaw thung dawk hote hno na hmunae pueng dout seh. Kaimouh hai bawipa e san lah ka o awh yawkaw han, ati awh.
10 Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
Ahni ni bokheiyah, atu hai nangmae lawk patetlah lawiseh, hno ka hmunae tami hah ka san lah ao vaiteh, nangmouh teh toun kaawm hoeh lah na o awh han telah ati.
11 Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
Hat nah tahma vah amamae cawngko lengkaleng a patue awh teh lengkaleng a paawng awh.
12 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
Ahni ni kacuepoung koehoi kanawpoung totouh a tawng pouh. Hattoteh Benjamin e cawngko dawk manang teh a hmu.
13 Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
Hat nah tahma vah a khohna a phi awh, lanaw a phu sak awh teh kho dawk a ban awh.
14 Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Judah hoi a hmaunawnghanaw teh Joseph im a pha awh, ama teh haw vah a la o rah. Hahoi a hmalah a tabo awh.
15 Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
Hahoi Joseph ni bangmaw na sak awh. Kai patetlae tami ni hmalah ka tho hane hno a panue han tie na panuek awh hoeh maw, telah ati.
16 Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
Judah ni ka bawipa nang koe bangvai ka dei awh toung. Bangmaw ka pâpha thai awh han. Cathut ni na sannaw yonnae teh a hmu toe. Khenhaw! ka bawipa kaimouh hoi ahnie kut dawk manang a hmu e hoi na san lah doeh ka o awh toe telah ati.
17 Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
Hatei ahni ni, hottelah khoeroe ka sak mahoeh, a kut dawk manang a hmunae dueng doeh ka san lah ao vaiteh nangmouh teh na pa koe karoumcalah cet awh, telah ati.
18 Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
Hat nah tahma vah, Judah ni Joseph hah a hnai teh, Oe ka bawipa, pahren lahoi na san heh, ka bawipa na san heh na hnâthainae koe lawk kam touh na dei sak haw. Na lungkhueknae hah na san koe kaman sak hanh. Bangtelah tetpawiteh, nang teh Faro patetlah doeh na o.
19 Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
Ka bawipa nang ni, na pa nakunghai, hmaunawngha nakunghai na tawn maw telah na sannaw hah na pacei.
20 Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
Kaimouh ni nang koe ka matawngpoung e na pa ka tawn awh. Matawng sawi a sak e camoca ka tawn awh teh buet touh teh a due toe, a manu ni a khe e dawk ahni dueng ao teh a na pa ni a pahren poung, ka ti awh.
21 “Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
Nang ni, ahni ka hmu thai nahanlah kai koe thokhai awh ati.
22 A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
Ka bawipa kaimouh ni tongpaca ni a na pa cettakhai thai mahoeh, bangkongtetpawiteh, a na pa cettakhai pawiteh a na pa a due han doeh ka ti awh.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
Hatei, nang ni na nawngha cahnoung nangmouh koe tho van hoehpawiteh, ka mei na hmawt awh mahoeh toe, ati.
24 Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
Hahoi, na sannaw apa koe ka pha awh toteh, ka bawipa, bawipa nange lawk hah ka dei pouh awh.
25 “Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
Apa ni bout cet awh nateh, mamouh hanelah cakang youn touh bout ran awh, ati.
26 Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
Hatei kaimouh ni ka cet thai awh mahoeh, nawngha cahnoung kaimouh koe tho van pawiteh dueng doeh ka cei awh han. Bangkongtetpawiteh, nawngha cahnoung kaimouh koe tho van hoehpawiteh ahnie mei ka hmawt thai awh mahoeh toe, telah ka ti pouh awh.
27 “Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
Na san kaimae na pa ni, ka yu ni capa kahni touh na khe pouh tie na panue awh.
28 Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
Buet touh teh kai koehoi a tâco teh koung paset e lah ao mue toe, hahoi teh ahni ka hmawt boihoeh toe.
29 Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol )
Hahoi hete camo heh kai koe hoi na ceikhai teh, runae kâhmo pawiteh, ka sampo hah lungmathoenae lahoi phuen dawk na loum sak awh toe, telah ati. (Sheol )
30 “Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
Hatdawkvah, tongpaca heh kaimouh koe tho van laipalah na san apa koe ka tho pawiteh, a hringnae hoi tongpaca e hringnae mekkawme lah ao dawkvah,
31 Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol )
tongpaca tho van hoeh tie hah a panue tahma kadout han doeh. Hattoteh na sannaw ni na san apa e sampo hah lungmathoenae hoi phuen koe ka loum sak yawkaw han doeh. (Sheol )
32 Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
Bangtelah tetpawiteh, na san ni nang koe ka thokhai hoehpawiteh, a yungyoe na hmalah yonpen e lah ka o han telah apa koe tongpaca kong dawk thoe yo ka bo toe.
33 “Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
Pahren lahoi na san hah tongpaca yueng lah ka bawipa, na san lah na awm sak nateh, tongpaca heh a hmaunaw hoi ban sak leih.
34 Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”
Bangkongtetpawiteh, kai koe tongpaca tho van hoehpawiteh bangtelamaw apa koe ka cei thai awh han vaw. Telah hoehpawiteh, apa koe ka phat hane thoenae teh ka hmu payon awh han doeh, telah ati.