< Genesis 43 >

1 Báyìí, ìyàn náà sì mú gidigidi ní ilẹ̀ náà.
Şi foametea era aspră în ţară.
2 Nígbà tí wọ́n sì ti jẹ gbogbo ọkà tí wọ́n rà ní Ejibiti tan, baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ ra oúnjẹ díẹ̀ si wá fún wa.”
Şi s-a întâmplat, după ce au terminat de mâncat grânele pe care le-au adus din Egipt, că tatăl lor le-a spus: Mergeţi din nou, cumpăraţi-ne puţină hrană.
3 Ṣùgbọ́n Juda wí fún un pé, “Ọkùnrin náà tẹnumọ́ ọn nínú ìkìlọ̀ rẹ̀ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́, àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá’.
Şi Iuda i-a vorbit, spunând: Bărbatul ne-a avertizat hotărât, spunând: Nu îmi veţi vedea faţa decât dacă fratele vostru va fi cu voi.
4 Tí ìwọ yóò bá rán Benjamini arákùnrin wa lọ pẹ̀lú wa, a ó lọ ra oúnjẹ wá fún ọ.
Dacă voieşti să-l trimiţi pe fratele nostru cu noi, vom coborî şi vom cumpăra pentru tine hrană;
5 Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ni jẹ́ kí ó bá wa lọ, àwa kì yóò lọ, nítorí ọkùnrin náà sọ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́ àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá.’”
Dar dacă nu voieşti să îl trimiţi, nu vom coborî, pentru că acel bărbat ne-a spus: Nu veţi vedea faţa mea, decât dacă fratele vostru va fi cu voi.
6 Israẹli béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi kó ìdààmú yìí bá mi nípa sísọ fún ọkùnrin náà wí pé ẹ ní arákùnrin mìíràn?”
Şi Israel a spus: Pentru ce aţi lucrat aşa de rău cu mine, încât să spuneţi acelui bărbat că mai aveţi un frate?
7 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin náà fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ wádìí lọ́wọ́ wa nípa ìdílé wa àti àwa fúnra wa. Ó béèrè pé, ‘Ṣe baba yín ṣì wà láààyè? Ǹjẹ́ ẹ tún ní arákùnrin mìíràn?’ A kàn dáhùn ìbéèrè rẹ̀ ni. Báwo ni a ṣe le mọ̀ pé yóò wí pé, ‘Ẹ mú arákùnrin yín wá’?”
Iar ei au spus: Acel bărbat ne-a întrebat cu de-amănuntul despre starea noastră şi despre rudenia noastră, spunând: Este tatăl vostru încă în viaţă? Mai aveţi vreun alt frate? Şi noi i-am spus conform cu tonul acestor cuvinte, puteam noi să ştim cu adevărat că el va spune: Coborâţi pe fratele vostru aici?
8 Juda sì wí fún Israẹli baba rẹ̀, “Jẹ́ kí ọmọkùnrin náà lọ pẹ̀lú mi, a ó sì lọ ní kíákíá, kí àwa àti ìwọ àti àwọn ọmọ wa le yè, kí a má sì kú.
Şi Iuda i-a spus lui Israel, tatăl său: Trimite băiatul cu mine şi ne vom ridica şi vom merge; ca să trăim şi să nu murim deopotrivă noi şi tu şi micuţii noştri.
9 Èmi fúnra mi yóò ṣe onídùúró fún un, èmi ni kí o gbà pé o fi lé lọ́wọ́. Bí n kò bá sì mú un padà tọ̀ ọ́ wá, jẹ́ kí ẹ̀bi rẹ̀ kí ó jẹ́ tèmi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi níwájú rẹ.
Eu voi fi garanţie pentru el; din mâna mea îl vei cere; dacă nu ţi-l aduc şi nu îl pun înaintea ta, atunci să suport eu vina pentru totdeauna;
10 Bí ó bá ṣe pé a kò fi falẹ̀ ni, àwa ìbá ti lọ, à bá sì ti padà ní ìgbà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀.”
Căci dacă nu am fi întârziat, cu adevărat acum am fi întorşi şi de această a doua oară.
11 Nígbà náà ni Israẹli baba wọn wí fún wọn, “Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ mú àwọn ohun dáradára ilẹ̀ yìí lọ́wọ́ lọ bí ẹ̀bùn fún ọkùnrin náà—ìkunra díẹ̀, oyin díẹ̀, tùràrí àti òjìá, èso pisitakio àti èso almondi
Şi tatăl lor, Israel, le-a spus: Dacă aşa trebuie să fie acum, faceţi aceasta; luaţi din cele mai bune roade din ţară în vasele voastre şi duceţi-i înapoi un dar acelui bărbat, puţin balsam şi puţină miere, mirodenii şi smirnă, nuci şi migdale;
12 ìlọ́po owó méjì ni kí ẹ mú lọ́wọ́, nítorí ẹ gbọdọ̀ dá owó tí ẹ bá lẹ́nu àpò yín padà. Bóyá ẹnìkan ló ṣèèṣì fi síbẹ̀.
Şi luaţi dublul banilor în mâna voastră; şi banii care au fost aduşi înapoi la gura sacilor voştri, duceţi-i înapoi în mâna voastră; poate aceasta a fost o neatenţie.
13 Ẹ mú arákùnrin yín lọ́wọ́ pẹ̀lú ki ẹ sì tọ arákùnrin náà lọ.
Luaţi de asemenea pe fratele vostru şi ridicaţi-vă, mergeţi din nou la acel bărbat;
14 Kí Ọlọ́run alágbára jẹ́ kí ẹ rí àánú gbà lọ́dọ̀ ọkùnrin náà kí ó ba à le jẹ́ kí arákùnrin yín tí ó wà lọ́hùn ún àti Benjamini padà wá pẹ̀lú yín. Ní tèmi, bí mo bá pàdánù àwọn ọmọ mi, n ó ṣọ̀fọ̀ wọn náà ni.”
Şi Dumnezeu cel Atotputernic să vă dea milă înaintea acelui bărbat, ca el să trimită pe celălalt frate al vostru şi pe Beniamin. Dacă este să fiu văduvit de copiii mei, eu sunt văduvit.
15 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹ̀bùn náà àti owó ìlọ́po méjì àti Benjamini, wọ́n sì yára lọ sí ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Josẹfu.
Şi bărbaţii au luat acel dar şi au luat dublul banilor în mâna lor şi pe Beniamin; şi s-au ridicat şi au coborât în Egipt şi au stat înaintea lui Iosif.
16 Nígbà tí Josẹfu rí Benjamini pẹ̀lú wọn, ó sọ fún ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, “Mú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí lọ sí ilé mi, pa ẹran kí o sì ṣe àsè; wọn ó jẹun ọ̀sán pẹ̀lú mi.”
Şi când Iosif a văzut pe Beniamin cu ei, a spus administratorului casei sale: Adu aceşti bărbaţi în casă şi înjunghie animale şi pregăteşte, pentru că aceşti bărbaţi vor mânca cu mine la amiază.
17 Ọkùnrin náà sì ṣe bí Josẹfu ti wí fún un, ó sì mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu.
Şi bărbatul a făcut cum Iosif a cerut; şi bărbatul a adus bărbaţii în casa lui Iosif.
18 Ẹ̀rù sì ba àwọn ọkùnrin náà nígbà tí wọ́n mú wọn lọ sí ilé Josẹfu. Wọ́n rò ó pé, “A mú wa wá sí ìhín nítorí owó tí a fi sí inú àpò wa ní ìgbà àkọ́kọ́. Ó fẹ́ bá wa jà, kí ó mú wa lẹ́rú kí ó sì gba àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa.”
Şi bărbaţii s-au temut, deoarece au fost aduşi în casa lui Iosif; şi au spus: Din cauza banilor care au fost întorşi înapoi în sacii noştri de prima dată suntem aduşi înăuntru; ca el să caute motiv împotriva noastră şi să cadă asupra noastră şi să ne ia ca robi şi măgarii noştri.
19 Nítorí náà wọ́n lọ bá ìránṣẹ́ Josẹfu, wọ́n sì ba sọ̀rọ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ilé náà.
Şi s-au apropiat de administratorul casei lui Iosif şi au vorbit îndeaproape cu el la uşa casei,
20 Wọ́n wí pé, “Jọ̀wọ́ ọ̀gá, ní òtítọ́ ni àwa ti sọ̀kalẹ̀ síyìn-ín láti wá ra oúnjẹ ní ìṣáájú.
Şi au spus: Vai, domnule, noi, într-adevăr, am coborât de prima dată pentru a cumpăra hrană.
21 Ṣùgbọ́n níbi tí a ti dúró ní ọ̀nà láti sùn ní alẹ́, nígbà tí a tú àpò oúnjẹ wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa bá owó oúnjẹ tirẹ̀ tí ó rà lẹ́nu àpò láì lé, láì dín. Nítorí náà òun nìyí, a ti mu un padà wá pẹ̀lú wa.
Şi s-a întâmplat când am venit la han, că am deschis sacii noştri şi, iată, banii fiecărui bărbat erau la gura sacului său, banii noştri în greutate deplină; şi noi am adus aceşti bani înapoi în mâna noastră.
22 A sì tún mú owó mìíràn lọ́wọ́ láti fi ra oúnjẹ. A ò mọ ẹni tí ó fi owó wa sí ẹnu àpò.”
Şi alţi bani am adus aici în mâna noastră pentru a cumpăra hrană; nu putem spune cine a pus banii noştri în sacii noştri.
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà ni fún yín, ẹ má bẹ̀rù, Ọlọ́run yín, àní Ọlọ́run baba yín ni ó fi ìṣúra sí inú àpò yín; mo rí owó tí ẹ san gbà.” Nígbà náà ni ó mú Simeoni jáde tọ̀ wọ́n wá.
Iar el a spus: Pace vouă, nu vă temeţi; Dumnezeul vostru şi Dumnezeul tatălui vostru v-a dat comoară în sacii voştri; eu am avut banii voştri. Şi l-a adus pe Simeon la ei.
24 Ìránṣẹ́ náà mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu, ó fún wọn ní omi láti fi wẹ ẹsẹ̀ wọn nu, ó sì fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn lóúnjẹ pẹ̀lú.
Şi bărbatul a adus bărbaţii în casa lui Iosif şi le-a dat apă şi ei şi-au spălat picioarele; iar el a dat măgarilor lor nutreţ.
25 Wọ́n pèsè ẹ̀bùn wọn sílẹ̀ fún Josẹfu di ọ̀sán nígbà tí yóò dé, nítorí wọ́n ti gbọ́ pé ibẹ̀ ni àwọn yóò ti jẹun ọ̀sán.
Şi au pregătit darul înainte să vină Iosif la amiază, pentru că au auzit că vor mânca pâine acolo.
26 Nígbà tí Josẹfu dé sí ilé, wọ́n kó àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n ti mú wá fún un, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Şi după ce Iosif a venit acasă, i-au adus darul, care era în mâna lor, în casă şi i s-au prosternat până la pământ.
27 Ó béèrè àlàáfíà wọn, ó sì wí pé, “Ṣé àlàáfíà ni baba yín wà, baba arúgbó tí ẹ sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún mi, ṣé ó sì wà láààyè?”
Iar el i-a întrebat despre bunăstarea lor şi a spus: Este bine tatăl vostru, bătrânul despre care voi aţi vorbit? Mai trăieşte?
28 Wọ́n dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ, baba wa sì wà láààyè, àlàáfíà sì ni ó wà pẹ̀lú.” Wọn sì tẹríba láti bọ̀wọ̀ fún un.
Iar ei au răspuns: Servitorul tău, tatăl nostru, este sănătos, încă trăieşte. Şi ei şi-au aplecat capetele şi s-au prosternat.
29 Bí ó ti wò yíká tí ó sì rí Benjamini àbúrò rẹ̀, tí í ṣe ọmọ ìyá rẹ̀ gan an. Ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣe àbúrò yín tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn tí ẹ sọ fún mi nípa rẹ̀ nìyìí?” Ó sì tún wí pe, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún ọ, ọmọ mi.”
Iar el şi-a ridicat ochii şi a văzut pe fratele său Beniamin, fiul mamei sale, şi a spus: Este acesta fratele vostru mai tânăr, despre care mi-aţi vorbit? Şi a spus: Dumnezeu să aibă har față de tine, fiule.
30 Ọkàn rẹ̀ sì fà sí i gidigidi nígbà tí ó rí arákùnrin rẹ̀, nítorí náà Josẹfu yára jáde láti wá ibi tí ó ti le sọkún. Ó lọ sí iyàrá rẹ̀, ó sì sọkún níbẹ̀.
Şi Iosif s-a grăbit, pentru că adâncurile lui fremătau pentru fratele său; şi a căutat un loc unde să plângă; şi a intrat în camera sa şi a plâns acolo.
31 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti bọ́jú tan, ó jáde wá, ó ṣe ọkàn ọkùnrin, ó sì wí fún wọn pé, kí wọ́n gbé oúnjẹ wá kí wọ́n le è jẹun.
Şi el şi-a spălat faţa şi a ieşit şi s-a stăpânit şi a spus: Puneţi pâine.
32 Wọ́n gbé oúnjẹ tirẹ̀ fún un lọ́tọ̀, àti fún àwọn ará Ejibiti tí ó wá ba jẹun náà lọ́tọ̀, nítorí ará Ejibiti kò le bá ará Heberu jẹun nítorí ìríra pátápátá ló jẹ́ fún àwọn Ejibiti.
Şi au pus pentru el deoparte şi pentru ei deoparte şi pentru egiptenii care mâncau cu el deoparte, pentru că egiptenii nu pot mânca pâine cu evreii, pentru că aceasta este o urâciune pentru egipteni.
33 A mú àwọn ọkùnrin náà jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bí wọ́n ṣe dàgbà sí, láti orí ẹ̀gbọ́n pátápátá dé orí èyí tí ó kéré pátápátá, wọ́n sì ń wo ara wọn tìyanu tìyanu.
Şi au şezut înaintea lui, întâiul născut conform cu dreptul său de întâi născut şi cel mai tânăr conform tinereţii sale; şi bărbaţii se minunau unul către altul.
34 A sì bu oúnjẹ fún wọn láti orí tábìlì Josẹfu. Oúnjẹ Benjamini sì tó ìlọ́po márùn-ún ti àwọn tókù. Wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu lọ́dọ̀ rẹ̀ láìsí ìdíwọ́.
Şi a luat şi le-a trimis daruri de mâncare din cele dinaintea lui; iar darul de mâncare al lui Beniamin era de cinci ori mai mult decât al oricăruia dintre ei. Şi au băut şi s-au bucurat împreună cu el.

< Genesis 43 >