< Genesis 43 >

1 Báyìí, ìyàn náà sì mú gidigidi ní ilẹ̀ náà.
Az éhség pedig elhatalmazott vala az országon.
2 Nígbà tí wọ́n sì ti jẹ gbogbo ọkà tí wọ́n rà ní Ejibiti tan, baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ ra oúnjẹ díẹ̀ si wá fún wa.”
És lőn mikor fogytán vala az eleség, melyet Égyiptomból hoztak vala, monda nékik az ő atyjok: Menjetek el ismét, vegyetek nékünk egy kevés eleséget.
3 Ṣùgbọ́n Juda wí fún un pé, “Ọkùnrin náà tẹnumọ́ ọn nínú ìkìlọ̀ rẹ̀ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́, àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá’.
És felele néki Júda, mondván: Erősen fogadkozék az a férfiú, mondván: Színem elé ne kerűljetek, ha veletek nem lesz a ti atyátokfia.
4 Tí ìwọ yóò bá rán Benjamini arákùnrin wa lọ pẹ̀lú wa, a ó lọ ra oúnjẹ wá fún ọ.
Ha azért elbocsátod velünk a mi öcsénket, elmegyünk, és veszünk néked eleséget;
5 Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ni jẹ́ kí ó bá wa lọ, àwa kì yóò lọ, nítorí ọkùnrin náà sọ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́ àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá.’”
Ha pedig el nem bocsátod, nem megyünk, mert az a férfiú megmondá nékünk: Színem elé ne kerűljetek, ha a ti atyátokfia veletek nem lesz.
6 Israẹli béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi kó ìdààmú yìí bá mi nípa sísọ fún ọkùnrin náà wí pé ẹ ní arákùnrin mìíràn?”
És monda Izráel: Miért cselekedtetek gonoszul velem, hogy megmondtátok annak a férfiúnak, hogy még van egy öcsétek?
7 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin náà fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ wádìí lọ́wọ́ wa nípa ìdílé wa àti àwa fúnra wa. Ó béèrè pé, ‘Ṣe baba yín ṣì wà láààyè? Ǹjẹ́ ẹ tún ní arákùnrin mìíràn?’ A kàn dáhùn ìbéèrè rẹ̀ ni. Báwo ni a ṣe le mọ̀ pé yóò wí pé, ‘Ẹ mú arákùnrin yín wá’?”
Azok pedig mondának: Nagyon tudakozódék az a férfiú felőlünk és nemzetségünk felől, mondván: Él-é még atyátok? van-é még testvéretek? És mi kérdéseihez képest feleltünk néki. Avagy tudhattuk-é mi, hogy azt mondja: Hozzátok ide a ti atyátokfiát?
8 Juda sì wí fún Israẹli baba rẹ̀, “Jẹ́ kí ọmọkùnrin náà lọ pẹ̀lú mi, a ó sì lọ ní kíákíá, kí àwa àti ìwọ àti àwọn ọmọ wa le yè, kí a má sì kú.
És monda Júda Izráelnek, az ő atyjának: Bocsásd el azt a fiút én velem, és mi azonnal felkelünk és elmegyünk, hogy éljünk és meg ne haljunk se mi, se te, se a mi gyermekeink.
9 Èmi fúnra mi yóò ṣe onídùúró fún un, èmi ni kí o gbà pé o fi lé lọ́wọ́. Bí n kò bá sì mú un padà tọ̀ ọ́ wá, jẹ́ kí ẹ̀bi rẹ̀ kí ó jẹ́ tèmi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi níwájú rẹ.
Én leszek kezes érette, az én kezemből kérd elő. Ha vissza nem hozom őt hozzád, és elődbe nem állítom őt, mind éltig bűnös legyek előtted.
10 Bí ó bá ṣe pé a kò fi falẹ̀ ni, àwa ìbá ti lọ, à bá sì ti padà ní ìgbà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀.”
Bizony ha nem késlekedünk vala, ez ideig már kétszer is megjöhettünk volna.
11 Nígbà náà ni Israẹli baba wọn wí fún wọn, “Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ mú àwọn ohun dáradára ilẹ̀ yìí lọ́wọ́ lọ bí ẹ̀bùn fún ọkùnrin náà—ìkunra díẹ̀, oyin díẹ̀, tùràrí àti òjìá, èso pisitakio àti èso almondi
És monda nékik Izráel az ő atyjok: Ha csakugyan így kell lenni, akkor ezt cselekedjétek: Vegyetek e föld válogatott gyümölcseiből a ti edényeitekbe, és vigyetek ajándékot annak a férfiúnak; egy kevés balzsamot, egy kevés mézet, fűszerszámokat, mirhát, diót, mandulát.
12 ìlọ́po owó méjì ni kí ẹ mú lọ́wọ́, nítorí ẹ gbọdọ̀ dá owó tí ẹ bá lẹ́nu àpò yín padà. Bóyá ẹnìkan ló ṣèèṣì fi síbẹ̀.
Pénzt pedig két annyit vigyetek magatokkal, sőt a mely pénzt meghoztatok a ti zsákjaitok szájában, azt is vigyétek vissza magatokkal, talán tévedés ez.
13 Ẹ mú arákùnrin yín lọ́wọ́ pẹ̀lú ki ẹ sì tọ arákùnrin náà lọ.
Öcséteket is vegyétek, keljetek fel és menjetek vissza ahhoz a férfiúhoz.
14 Kí Ọlọ́run alágbára jẹ́ kí ẹ rí àánú gbà lọ́dọ̀ ọkùnrin náà kí ó ba à le jẹ́ kí arákùnrin yín tí ó wà lọ́hùn ún àti Benjamini padà wá pẹ̀lú yín. Ní tèmi, bí mo bá pàdánù àwọn ọmọ mi, n ó ṣọ̀fọ̀ wọn náà ni.”
A mindenható Isten pedig engedje, hogy kedvet találjatok annál a férfiúnál, és bocsássa vissza ti veletek a másik atyátokfiát, és Benjámint. Én pedig ha megfosztottnak kell lennem, hadd legyek megfosztva.
15 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹ̀bùn náà àti owó ìlọ́po méjì àti Benjamini, wọ́n sì yára lọ sí ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Josẹfu.
Vevék azért a férfiak azt az ajándékot, és vevének kétannyi pénzt az ő kezökbe, és Benjámint, és felkelének és alámenének Égyiptomba, és megállának József előtt.
16 Nígbà tí Josẹfu rí Benjamini pẹ̀lú wọn, ó sọ fún ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, “Mú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí lọ sí ilé mi, pa ẹran kí o sì ṣe àsè; wọn ó jẹun ọ̀sán pẹ̀lú mi.”
A mint meglátá József ő velök Benjámint, monda az ő háza gondviselőjének: Vidd be azokat az embereket a házba, és ölj barmot, s készítsd el, mert velem ebédelnek ez emberek ma délben.
17 Ọkùnrin náà sì ṣe bí Josẹfu ti wí fún un, ó sì mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu.
És az a férfiú aképen cselekedék, amint József parancsolta vala, és bevivé az a férfiú azokat az embereket a József házába.
18 Ẹ̀rù sì ba àwọn ọkùnrin náà nígbà tí wọ́n mú wọn lọ sí ilé Josẹfu. Wọ́n rò ó pé, “A mú wa wá sí ìhín nítorí owó tí a fi sí inú àpò wa ní ìgbà àkọ́kọ́. Ó fẹ́ bá wa jà, kí ó mú wa lẹ́rú kí ó sì gba àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa.”
És megfélemlének azok az emberek, a miért bevivék őket a József házába, és mondának: A pénzért hozattatánk ide be, mely először a mi zsákjainkba tétetett volt, hogy reánk rohanjon, megtámadjon és minket rabszolgákká tegyen a mi szamarainkkal együtt.
19 Nítorí náà wọ́n lọ bá ìránṣẹ́ Josẹfu, wọ́n sì ba sọ̀rọ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ilé náà.
És járulának József házának gondviselőjéhez, és szólának néki a ház ajtajában.
20 Wọ́n wí pé, “Jọ̀wọ́ ọ̀gá, ní òtítọ́ ni àwa ti sọ̀kalẹ̀ síyìn-ín láti wá ra oúnjẹ ní ìṣáájú.
És mondának: Kérünk uram! Ennekelőtte alájöttünk vala eleséget venni.
21 Ṣùgbọ́n níbi tí a ti dúró ní ọ̀nà láti sùn ní alẹ́, nígbà tí a tú àpò oúnjẹ wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa bá owó oúnjẹ tirẹ̀ tí ó rà lẹ́nu àpò láì lé, láì dín. Nítorí náà òun nìyí, a ti mu un padà wá pẹ̀lú wa.
És lőn mikor éjjeli szállásra jutánk és kioldjuk vala a mi zsákjainkat: ímé mindenikünknek pénze az ő zsákjának szájában vala, tulajdon pénzünk teljes mértéke szerint; és visszahoztuk azt magunkkal.
22 A sì tún mú owó mìíràn lọ́wọ́ láti fi ra oúnjẹ. A ò mọ ẹni tí ó fi owó wa sí ẹnu àpò.”
De más pénzt is hoztunk le magunkkal eleséget venni; nem tudjuk ki tette a mi pénzünket zsákjainkba.
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà ni fún yín, ẹ má bẹ̀rù, Ọlọ́run yín, àní Ọlọ́run baba yín ni ó fi ìṣúra sí inú àpò yín; mo rí owó tí ẹ san gbà.” Nígbà náà ni ó mú Simeoni jáde tọ̀ wọ́n wá.
És monda: Legyetek békén, ne féljetek; a ti Istentek és a ti atyátok Istene adta néktek azt a kincset zsákjaitokba; pénzetek az én kezemhez jutott. És kihozá hozzájok Simeont.
24 Ìránṣẹ́ náà mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu, ó fún wọn ní omi láti fi wẹ ẹsẹ̀ wọn nu, ó sì fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn lóúnjẹ pẹ̀lú.
Bevivé azután a férfiú azokat az embereket a József házába, és vizet hozata, és megmosák lábaikat, és abrakot is ada az ő szamaraiknak.
25 Wọ́n pèsè ẹ̀bùn wọn sílẹ̀ fún Josẹfu di ọ̀sán nígbà tí yóò dé, nítorí wọ́n ti gbọ́ pé ibẹ̀ ni àwọn yóò ti jẹun ọ̀sán.
Ők pedig elkészíték az ajándékot mire József délben megjöve; mert megértették vala, hogy ott ebédelnek.
26 Nígbà tí Josẹfu dé sí ilé, wọ́n kó àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n ti mú wá fún un, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Mikor József haza jöve, bevivék néki az ajándékot, mely kezökben vala, a házba, és leborulának előtte a földig.
27 Ó béèrè àlàáfíà wọn, ó sì wí pé, “Ṣé àlàáfíà ni baba yín wà, baba arúgbó tí ẹ sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún mi, ṣé ó sì wà láààyè?”
És kérdezősködék egészségök felől, s monda: Egészségben van-é a ti vén atyátok, a kiről nékem szóltatok? él-é még?
28 Wọ́n dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ, baba wa sì wà láààyè, àlàáfíà sì ni ó wà pẹ̀lú.” Wọn sì tẹríba láti bọ̀wọ̀ fún un.
Azok pedig mondának: Egészségben van a te szolgád, a mi atyánk, még él. És meghajták magokat és leborulának.
29 Bí ó ti wò yíká tí ó sì rí Benjamini àbúrò rẹ̀, tí í ṣe ọmọ ìyá rẹ̀ gan an. Ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣe àbúrò yín tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn tí ẹ sọ fún mi nípa rẹ̀ nìyìí?” Ó sì tún wí pe, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún ọ, ọmọ mi.”
És felemelé szemeit és látá Benjámint az ő atyjafiát, az ő anyjának fiát, és monda: Ez-é a ti legkisebbik atyátokfia, a ki felől nékem szóltatok vala? És ismét monda: Az Isten légyen hozzád kegyelmes, fiam!
30 Ọkàn rẹ̀ sì fà sí i gidigidi nígbà tí ó rí arákùnrin rẹ̀, nítorí náà Josẹfu yára jáde láti wá ibi tí ó ti le sọkún. Ó lọ sí iyàrá rẹ̀, ó sì sọkún níbẹ̀.
Akkor elsiete onnan József, mert felgerjede szíve az ő öcscse iránt, és erőlteti vala a sírás; beméne azért szobájába, és ott síra.
31 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti bọ́jú tan, ó jáde wá, ó ṣe ọkàn ọkùnrin, ó sì wí fún wọn pé, kí wọ́n gbé oúnjẹ wá kí wọ́n le è jẹun.
Azután megmosá orczáját, és kiméne, és megtartóztatá magát, és monda: Hozzatok enni valót.
32 Wọ́n gbé oúnjẹ tirẹ̀ fún un lọ́tọ̀, àti fún àwọn ará Ejibiti tí ó wá ba jẹun náà lọ́tọ̀, nítorí ará Ejibiti kò le bá ará Heberu jẹun nítorí ìríra pátápátá ló jẹ́ fún àwọn Ejibiti.
És elhozák néki külön, azoknak is külön, és az Égyiptombelieknek is, kik vele esznek vala, külön: Mert nem ehettek az Égyiptombeliek együtt a héberekkel, mert utálatos az az Égyiptombeliek előtt.
33 A mú àwọn ọkùnrin náà jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bí wọ́n ṣe dàgbà sí, láti orí ẹ̀gbọ́n pátápátá dé orí èyí tí ó kéré pátápátá, wọ́n sì ń wo ara wọn tìyanu tìyanu.
Leűlének azért ő előtte, az elsőszülött az ő elsőszülöttsége szerint, és a fiatalabb az ő fiatalsága szerint. És az emberek álmélkodva nézének egymásra.
34 A sì bu oúnjẹ fún wọn láti orí tábìlì Josẹfu. Oúnjẹ Benjamini sì tó ìlọ́po márùn-ún ti àwọn tókù. Wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu lọ́dọ̀ rẹ̀ láìsí ìdíwọ́.
Ő pedig részt juttata azoknak maga elől és a Benjámin része ötszörte nagyobb vala mindnyájok részénél. És ivának és megittasodának ő nála.

< Genesis 43 >