< Genesis 43 >

1 Báyìí, ìyàn náà sì mú gidigidi ní ilẹ̀ náà.
Cependant la famine pesai! violemment sur toute la terre.
2 Nígbà tí wọ́n sì ti jẹ gbogbo ọkà tí wọ́n rà ní Ejibiti tan, baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ ra oúnjẹ díẹ̀ si wá fún wa.”
Et les vivres qu’ils avaient apportés de l’Égypte, étant consommés, Jacob dit à ses fils: Retournez, et achetez-nous quelques provisions.
3 Ṣùgbọ́n Juda wí fún un pé, “Ọkùnrin náà tẹnumọ́ ọn nínú ìkìlọ̀ rẹ̀ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́, àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá’.
Juda répondit: Cet homme nous a fait une déclaration sous le sceau du serment, disant: Vous ne verrez point ma face si vous n’amenez votre frère le plus jeune avec vous.
4 Tí ìwọ yóò bá rán Benjamini arákùnrin wa lọ pẹ̀lú wa, a ó lọ ra oúnjẹ wá fún ọ.
Si donc vous voulez l’envoyer avec nous, nous irons ensemble, et nous achèterons ce qui vous est nécessaire.
5 Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ni jẹ́ kí ó bá wa lọ, àwa kì yóò lọ, nítorí ọkùnrin náà sọ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́ àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá.’”
Mais si vous ne voulez pas, nous n’irons pas; car cet homme, comme souvent nous l’avons dit, nous a fait une déclaration, disant: Vous ne verrez point ma face, sans votre frère le plus jeune.
6 Israẹli béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi kó ìdààmú yìí bá mi nípa sísọ fún ọkùnrin náà wí pé ẹ ní arákùnrin mìíràn?”
Israël leur dit: Pour mon malheur vous avez fait de manière que vous lui avez indiqué que vous aviez encore un frère.
7 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin náà fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ wádìí lọ́wọ́ wa nípa ìdílé wa àti àwa fúnra wa. Ó béèrè pé, ‘Ṣe baba yín ṣì wà láààyè? Ǹjẹ́ ẹ tún ní arákùnrin mìíràn?’ A kàn dáhùn ìbéèrè rẹ̀ ni. Báwo ni a ṣe le mọ̀ pé yóò wí pé, ‘Ẹ mú arákùnrin yín wá’?”
Mais eux répondirent: Cet homme nous a interrogés par ordre sur notre famille: si notre père vivait, si nous avions un autre frère; et nous lui avons répondu conséquemment, selon ce qu’il avait demandé; est-ce que nous pouvions savoir qu’il dirait: Amenez votre frère avec vous?
8 Juda sì wí fún Israẹli baba rẹ̀, “Jẹ́ kí ọmọkùnrin náà lọ pẹ̀lú mi, a ó sì lọ ní kíákíá, kí àwa àti ìwọ àti àwọn ọmọ wa le yè, kí a má sì kú.
Juda aussi dit à son père: Envoyez l’enfant avec moi, afin que nous partions et que nous puissions vivre, et que nous ne mourions pas, nous et nos petits enfants.
9 Èmi fúnra mi yóò ṣe onídùúró fún un, èmi ni kí o gbà pé o fi lé lọ́wọ́. Bí n kò bá sì mú un padà tọ̀ ọ́ wá, jẹ́ kí ẹ̀bi rẹ̀ kí ó jẹ́ tèmi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi níwájú rẹ.
C’est moi qui me charge de l’enfant; c’est à ma main que vous le redemanderez; si je ne le ramène, et si je ne vous le rends, je serai coupable envers vous à jamais.
10 Bí ó bá ṣe pé a kò fi falẹ̀ ni, àwa ìbá ti lọ, à bá sì ti padà ní ìgbà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀.”
S’il n’était pas intervenu de délai, nous serions déjà revenus une seconde fois.
11 Nígbà náà ni Israẹli baba wọn wí fún wọn, “Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ mú àwọn ohun dáradára ilẹ̀ yìí lọ́wọ́ lọ bí ẹ̀bùn fún ọkùnrin náà—ìkunra díẹ̀, oyin díẹ̀, tùràrí àti òjìá, èso pisitakio àti èso almondi
Ainsi Israël leur père leur dit: S’il le faut ainsi, faites ce que vous voudrez; prenez des meilleurs fruits de ce pays-ci dans vos vases, et portez à cet homme en présent un peu de résine, de miel, de storax, de stacté, de térébinthe et d’amandes.
12 ìlọ́po owó méjì ni kí ẹ mú lọ́wọ́, nítorí ẹ gbọdọ̀ dá owó tí ẹ bá lẹ́nu àpò yín padà. Bóyá ẹnìkan ló ṣèèṣì fi síbẹ̀.
Portez aussi avec vous le double d’argent; et celui que vous avez trouvé dans vos sacs, reportez-le, de peur que cela n’ait été fait par méprise.
13 Ẹ mú arákùnrin yín lọ́wọ́ pẹ̀lú ki ẹ sì tọ arákùnrin náà lọ.
Mais prenez aussi votre frère et allez vers cet homme.
14 Kí Ọlọ́run alágbára jẹ́ kí ẹ rí àánú gbà lọ́dọ̀ ọkùnrin náà kí ó ba à le jẹ́ kí arákùnrin yín tí ó wà lọ́hùn ún àti Benjamini padà wá pẹ̀lú yín. Ní tèmi, bí mo bá pàdánù àwọn ọmọ mi, n ó ṣọ̀fọ̀ wọn náà ni.”
Que mon Dieu tout-puissant vous le rende favorable, afin qu’il renvoie avec vous votre frère qu’il retient, et ce Benjamin; et moi, je serai comme privé d’enfants.
15 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹ̀bùn náà àti owó ìlọ́po méjì àti Benjamini, wọ́n sì yára lọ sí ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Josẹfu.
Ceux-ci prirent donc avec eux les présents, le double d’argent et Benjamin, et ils descendirent en Égypte et se présentèrent devant Joseph.
16 Nígbà tí Josẹfu rí Benjamini pẹ̀lú wọn, ó sọ fún ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, “Mú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí lọ sí ilé mi, pa ẹran kí o sì ṣe àsè; wọn ó jẹun ọ̀sán pẹ̀lú mi.”
Lorsque Joseph les vit et Benjamin avec eux, il commanda à l’intendant de sa maison, disant: Fais entrer ces hommes dans la maison; tue des victimes, et apprête un festin; parce que c’est avec moi qu’ils doivent manger à midi.
17 Ọkùnrin náà sì ṣe bí Josẹfu ti wí fún un, ó sì mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu.
Celui-ci fit ce qui lui avait été commandé, et il introduisit ces hommes dans la maison.
18 Ẹ̀rù sì ba àwọn ọkùnrin náà nígbà tí wọ́n mú wọn lọ sí ilé Josẹfu. Wọ́n rò ó pé, “A mú wa wá sí ìhín nítorí owó tí a fi sí inú àpò wa ní ìgbà àkọ́kọ́. Ó fẹ́ bá wa jà, kí ó mú wa lẹ́rú kí ó sì gba àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa.”
Et là, épouvantés, ils se dirent mutuellement: C’est à cause de l’argent que nous avons rapporté précédemment dans nos sacs qu’il nous a fait entrer ici, pour déverser sur nous une fausse accusation, et nous réduire violemment en servitude, nous et nos ânes.
19 Nítorí náà wọ́n lọ bá ìránṣẹ́ Josẹfu, wọ́n sì ba sọ̀rọ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ilé náà.
C’est pourquoi, à la porte même, s’approchant de l’intendant de la maison,
20 Wọ́n wí pé, “Jọ̀wọ́ ọ̀gá, ní òtítọ́ ni àwa ti sọ̀kalẹ̀ síyìn-ín láti wá ra oúnjẹ ní ìṣáájú.
Ils dirent: Nous vous prions, seigneur, de nous écouter. Nous sommes déjà venus ici pour acheter des vivres;
21 Ṣùgbọ́n níbi tí a ti dúró ní ọ̀nà láti sùn ní alẹ́, nígbà tí a tú àpò oúnjẹ wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa bá owó oúnjẹ tirẹ̀ tí ó rà lẹ́nu àpò láì lé, láì dín. Nítorí náà òun nìyí, a ti mu un padà wá pẹ̀lú wa.
Lesquels achetés, quand nous fûmes arrivés à l’hôtellerie, nous ouvrîmes nos sacs, et nous trouvâmes l’argent à l’entrée des sacs: nous l’avons rapporté maintenant dans tout son poids.
22 A sì tún mú owó mìíràn lọ́wọ́ láti fi ra oúnjẹ. A ò mọ ẹni tí ó fi owó wa sí ẹnu àpò.”
Mais nous avons rapporté aussi d’autre argent pour acheter ce qui nous est nécessaire. Nous ne savons pas qui a mis cet argent dans nos bourses.
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà ni fún yín, ẹ má bẹ̀rù, Ọlọ́run yín, àní Ọlọ́run baba yín ni ó fi ìṣúra sí inú àpò yín; mo rí owó tí ẹ san gbà.” Nígbà náà ni ó mú Simeoni jáde tọ̀ wọ́n wá.
Mais lui répondit: Paix avec vous! ne craignez point: votre Dieu et le Dieu de votre père vous a mis des trésors dans vos sacs, car l’argent que vous m’avez donné, c’est moi qui l’ai en bonne monnaie. Et il leur amena Siméon.
24 Ìránṣẹ́ náà mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu, ó fún wọn ní omi láti fi wẹ ẹsẹ̀ wọn nu, ó sì fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn lóúnjẹ pẹ̀lú.
Et les ayant introduits dans la maison, il leur apporta de l’eau, et ils lavèrent leurs pieds, et il donna à manger à leurs ânes.
25 Wọ́n pèsè ẹ̀bùn wọn sílẹ̀ fún Josẹfu di ọ̀sán nígbà tí yóò dé, nítorí wọ́n ti gbọ́ pé ibẹ̀ ni àwọn yóò ti jẹun ọ̀sán.
Or eux préparaient leurs présents, attendant que Joseph entrât sur le midi; car ils avaient appris que c’était là qu’ils devaient manger du pain.
26 Nígbà tí Josẹfu dé sí ilé, wọ́n kó àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n ti mú wá fún un, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Joseph donc entra dans sa maison, et ils lui offrirent les présents qu’ils tenaient en leurs mains, et ils se prosternèrent, inclinés vers la terre.
27 Ó béèrè àlàáfíà wọn, ó sì wí pé, “Ṣé àlàáfíà ni baba yín wà, baba arúgbó tí ẹ sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún mi, ṣé ó sì wà láààyè?”
Mais Joseph, leur ayant rendu leur salut avec bonté, les interrogea, disant: Se porte-t-il bien, votre vieux père dont vous m’aviez parlé? vit-il encore?
28 Wọ́n dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ, baba wa sì wà láààyè, àlàáfíà sì ni ó wà pẹ̀lú.” Wọn sì tẹríba láti bọ̀wọ̀ fún un.
Ceux-ci répondirent: Il se porte bien, votre serviteur notre père, il vit encore. Et s’étant profondément inclinés, ils se prosternèrent devant lui.
29 Bí ó ti wò yíká tí ó sì rí Benjamini àbúrò rẹ̀, tí í ṣe ọmọ ìyá rẹ̀ gan an. Ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣe àbúrò yín tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn tí ẹ sọ fún mi nípa rẹ̀ nìyìí?” Ó sì tún wí pe, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún ọ, ọmọ mi.”
Or Joseph, levant les yeux, vit Benjamin son frère utérin, et dit: Celui-ci est votre jeune frère dont vous m’aviez parlé? Et de nouveau: Dieu, dit-il, te soit miséricordieux, mon fils!
30 Ọkàn rẹ̀ sì fà sí i gidigidi nígbà tí ó rí arákùnrin rẹ̀, nítorí náà Josẹfu yára jáde láti wá ibi tí ó ti le sọkún. Ó lọ sí iyàrá rẹ̀, ó sì sọkún níbẹ̀.
Et il se retira précipitamment, car ses entrailles s’étaient émues sur son frère, et des larmes s’échappaient de ses yeux: entrant donc dans sa chambre il pleura.
31 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti bọ́jú tan, ó jáde wá, ó ṣe ọkàn ọkùnrin, ó sì wí fún wọn pé, kí wọ́n gbé oúnjẹ wá kí wọ́n le è jẹun.
Puis, sortant de nouveau, le visage lavé, il se contint et dit: Servez des pains.
32 Wọ́n gbé oúnjẹ tirẹ̀ fún un lọ́tọ̀, àti fún àwọn ará Ejibiti tí ó wá ba jẹun náà lọ́tọ̀, nítorí ará Ejibiti kò le bá ará Heberu jẹun nítorí ìríra pátápátá ló jẹ́ fún àwọn Ejibiti.
Les pains servis à part pour Joseph, à part pour ses frères, et à part pour les Égyptiens qui mangeaient ensemble (car il n’est pas permis aux Égyptiens démanger avec les Hébreux, et ils regardent comme profane un semblable repas),
33 A mú àwọn ọkùnrin náà jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bí wọ́n ṣe dàgbà sí, láti orí ẹ̀gbọ́n pátápátá dé orí èyí tí ó kéré pátápátá, wọ́n sì ń wo ara wọn tìyanu tìyanu.
Ils s’assirent devant lui, le premier-né, selon son droit d’aînesse, et le plus jeune, selon son âge. Or ils étaient extrêmement surpris,
34 A sì bu oúnjẹ fún wọn láti orí tábìlì Josẹfu. Oúnjẹ Benjamini sì tó ìlọ́po márùn-ún ti àwọn tókù. Wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu lọ́dọ̀ rẹ̀ láìsí ìdíwọ́.
En prenant les parts qu’ils avaient reçues de lui; car une part d’autant plus grande vint à Benjamin, qu’elle surpassait cinq autres parts. Ils burent donc et firent grande chère avec lui.

< Genesis 43 >