< Genesis 43 >

1 Báyìí, ìyàn náà sì mú gidigidi ní ilẹ̀ náà.
La famine sévissait dans le pays.
2 Nígbà tí wọ́n sì ti jẹ gbogbo ọkà tí wọ́n rà ní Ejibiti tan, baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ ra oúnjẹ díẹ̀ si wá fún wa.”
Lorsqu'ils eurent épuisé le blé qu'ils avaient apporté d'Égypte, leur père leur dit: « Retournez-y, achetez-nous encore un peu de nourriture. »
3 Ṣùgbọ́n Juda wí fún un pé, “Ọkùnrin náà tẹnumọ́ ọn nínú ìkìlọ̀ rẹ̀ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́, àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá’.
Juda lui parla, et dit: « L'homme nous a solennellement avertis, en disant: 'Vous ne verrez pas ma face, à moins que votre frère ne soit avec vous'.
4 Tí ìwọ yóò bá rán Benjamini arákùnrin wa lọ pẹ̀lú wa, a ó lọ ra oúnjẹ wá fún ọ.
Si tu envoies notre frère avec nous, nous descendrons et nous t'achèterons des vivres;
5 Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ni jẹ́ kí ó bá wa lọ, àwa kì yóò lọ, nítorí ọkùnrin náà sọ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́ àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá.’”
mais si tu ne l'envoies pas, nous ne descendrons pas, car l'homme nous a dit: 'Tu ne verras pas ma face, à moins que ton frère ne soit avec toi'. »
6 Israẹli béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi kó ìdààmú yìí bá mi nípa sísọ fún ọkùnrin náà wí pé ẹ ní arákùnrin mìíràn?”
Israël a dit: « Pourquoi m'as-tu traité si mal, en disant à l'homme que tu avais un autre frère? »
7 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin náà fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ wádìí lọ́wọ́ wa nípa ìdílé wa àti àwa fúnra wa. Ó béèrè pé, ‘Ṣe baba yín ṣì wà láààyè? Ǹjẹ́ ẹ tún ní arákùnrin mìíràn?’ A kàn dáhùn ìbéèrè rẹ̀ ni. Báwo ni a ṣe le mọ̀ pé yóò wí pé, ‘Ẹ mú arákùnrin yín wá’?”
Ils répondirent: « L'homme nous a interrogés directement sur nous-mêmes et sur nos proches, en disant: « Ton père vit-il encore? As-tu un autre frère? Nous avons simplement répondu à ses questions. Pouvions-nous savoir qu'il allait dire: 'Fais descendre ton frère'? »
8 Juda sì wí fún Israẹli baba rẹ̀, “Jẹ́ kí ọmọkùnrin náà lọ pẹ̀lú mi, a ó sì lọ ní kíákíá, kí àwa àti ìwọ àti àwọn ọmọ wa le yè, kí a má sì kú.
Juda dit à Israël, son père: « Envoie le garçon avec moi, et nous nous lèverons et partirons, afin que nous vivions et ne mourions pas, nous, et toi, et aussi nos petits enfants.
9 Èmi fúnra mi yóò ṣe onídùúró fún un, èmi ni kí o gbà pé o fi lé lọ́wọ́. Bí n kò bá sì mú un padà tọ̀ ọ́ wá, jẹ́ kí ẹ̀bi rẹ̀ kí ó jẹ́ tèmi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi níwájú rẹ.
Je serai pour lui une garantie. C'est de ma main que vous le réclamerez. Si je ne vous l'amène pas, si je ne le mets pas devant vous, que j'en porte la responsabilité pour toujours;
10 Bí ó bá ṣe pé a kò fi falẹ̀ ni, àwa ìbá ti lọ, à bá sì ti padà ní ìgbà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀.”
car si nous n'avions pas tardé, nous serions déjà revenus une seconde fois. »
11 Nígbà náà ni Israẹli baba wọn wí fún wọn, “Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, èyí ni kí ẹ ṣe, ẹ mú àwọn ohun dáradára ilẹ̀ yìí lọ́wọ́ lọ bí ẹ̀bùn fún ọkùnrin náà—ìkunra díẹ̀, oyin díẹ̀, tùràrí àti òjìá, èso pisitakio àti èso almondi
Leur père, Israël, leur dit: « S'il doit en être ainsi, faites ceci: Prenez dans vos sacs des fruits de choix du pays, et descendez un présent pour l'homme, un peu de baume, un peu de miel, des aromates et de la myrrhe, des noix et des amandes;
12 ìlọ́po owó méjì ni kí ẹ mú lọ́wọ́, nítorí ẹ gbọdọ̀ dá owó tí ẹ bá lẹ́nu àpò yín padà. Bóyá ẹnìkan ló ṣèèṣì fi síbẹ̀.
et prenez dans votre main de l'argent en double, et rapportez l'argent qui est revenu dans la bouche de vos sacs. C'était peut-être un oubli.
13 Ẹ mú arákùnrin yín lọ́wọ́ pẹ̀lú ki ẹ sì tọ arákùnrin náà lọ.
Prends aussi ton frère, lève-toi, et retourne vers l'homme.
14 Kí Ọlọ́run alágbára jẹ́ kí ẹ rí àánú gbà lọ́dọ̀ ọkùnrin náà kí ó ba à le jẹ́ kí arákùnrin yín tí ó wà lọ́hùn ún àti Benjamini padà wá pẹ̀lú yín. Ní tèmi, bí mo bá pàdánù àwọn ọmọ mi, n ó ṣọ̀fọ̀ wọn náà ni.”
Que le Dieu tout-puissant te fasse grâce devant cet homme, afin qu'il te relâche ton autre frère et Benjamin. Si je suis privé de mes enfants, je suis privé. »
15 Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹ̀bùn náà àti owó ìlọ́po méjì àti Benjamini, wọ́n sì yára lọ sí ilẹ̀ Ejibiti, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Josẹfu.
Les hommes prirent ce présent, et ils prirent en main l'argent double, ainsi que Benjamin; ils se levèrent, descendirent en Égypte, et se présentèrent devant Joseph.
16 Nígbà tí Josẹfu rí Benjamini pẹ̀lú wọn, ó sọ fún ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, “Mú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí lọ sí ilé mi, pa ẹran kí o sì ṣe àsè; wọn ó jẹun ọ̀sán pẹ̀lú mi.”
Lorsque Joseph vit Benjamin avec eux, il dit à l'intendant de sa maison: « Fais entrer les hommes dans la maison, égorge une bête et prépare-toi, car les hommes dîneront avec moi à midi. »
17 Ọkùnrin náà sì ṣe bí Josẹfu ti wí fún un, ó sì mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu.
L'homme fit ce que Joseph avait ordonné, et l'homme amena les hommes dans la maison de Joseph.
18 Ẹ̀rù sì ba àwọn ọkùnrin náà nígbà tí wọ́n mú wọn lọ sí ilé Josẹfu. Wọ́n rò ó pé, “A mú wa wá sí ìhín nítorí owó tí a fi sí inú àpò wa ní ìgbà àkọ́kọ́. Ó fẹ́ bá wa jà, kí ó mú wa lẹ́rú kí ó sì gba àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa.”
Les hommes eurent peur, parce qu'ils avaient été amenés à la maison de Joseph; ils dirent: « C'est à cause de l'argent qui est revenu dans nos sacs la première fois que nous sommes amenés, afin qu'il cherche une occasion contre nous, qu'il nous attaque et qu'il nous saisisse comme esclaves, avec nos ânes. »
19 Nítorí náà wọ́n lọ bá ìránṣẹ́ Josẹfu, wọ́n sì ba sọ̀rọ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ilé náà.
Ils s'approchèrent de l'intendant de la maison de Joseph, lui parlèrent à la porte de la maison,
20 Wọ́n wí pé, “Jọ̀wọ́ ọ̀gá, ní òtítọ́ ni àwa ti sọ̀kalẹ̀ síyìn-ín láti wá ra oúnjẹ ní ìṣáájú.
et dirent: « Oh, mon seigneur, nous sommes en effet descendus la première fois pour acheter de la nourriture.
21 Ṣùgbọ́n níbi tí a ti dúró ní ọ̀nà láti sùn ní alẹ́, nígbà tí a tú àpò oúnjẹ wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa bá owó oúnjẹ tirẹ̀ tí ó rà lẹ́nu àpò láì lé, láì dín. Nítorí náà òun nìyí, a ti mu un padà wá pẹ̀lú wa.
Lorsque nous sommes arrivés au gîte, nous avons ouvert nos sacs, et voici que l'argent de chacun était dans l'ouverture de son sac, notre argent en plein poids. Nous l'avons rapporté dans notre main.
22 A sì tún mú owó mìíràn lọ́wọ́ láti fi ra oúnjẹ. A ò mọ ẹni tí ó fi owó wa sí ẹnu àpò.”
Nous avons descendu d'autre argent dans notre main pour acheter de la nourriture. Nous ne savons pas qui a mis notre argent dans nos sacs. »
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà ni fún yín, ẹ má bẹ̀rù, Ọlọ́run yín, àní Ọlọ́run baba yín ni ó fi ìṣúra sí inú àpò yín; mo rí owó tí ẹ san gbà.” Nígbà náà ni ó mú Simeoni jáde tọ̀ wọ́n wá.
Il dit: « La paix soit avec vous. N'ayez pas peur. Votre Dieu, et le Dieu de votre père, vous a donné un trésor dans vos sacs. J'ai reçu votre argent. » Il fit sortir Siméon vers eux.
24 Ìránṣẹ́ náà mú àwọn ọkùnrin náà lọ sí ilé Josẹfu, ó fún wọn ní omi láti fi wẹ ẹsẹ̀ wọn nu, ó sì fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn lóúnjẹ pẹ̀lú.
L'homme fit entrer les hommes dans la maison de Joseph, leur donna de l'eau et ils se lavèrent les pieds. Il donna du fourrage à leurs ânes.
25 Wọ́n pèsè ẹ̀bùn wọn sílẹ̀ fún Josẹfu di ọ̀sán nígbà tí yóò dé, nítorí wọ́n ti gbọ́ pé ibẹ̀ ni àwọn yóò ti jẹun ọ̀sán.
Ils préparèrent le cadeau pour la venue de Joseph à midi, car ils avaient entendu dire qu'ils devaient y manger du pain.
26 Nígbà tí Josẹfu dé sí ilé, wọ́n kó àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n ti mú wá fún un, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
Lorsque Joseph rentra chez lui, ils lui apportèrent dans la maison le présent qu'ils avaient en main, et se prosternèrent en terre devant lui.
27 Ó béèrè àlàáfíà wọn, ó sì wí pé, “Ṣé àlàáfíà ni baba yín wà, baba arúgbó tí ẹ sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún mi, ṣé ó sì wà láààyè?”
Il les interrogea sur leur bien-être et dit: « Votre père se porte-t-il bien, le vieillard dont vous avez parlé? Est-il encore en vie? »
28 Wọ́n dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ, baba wa sì wà láààyè, àlàáfíà sì ni ó wà pẹ̀lú.” Wọn sì tẹríba láti bọ̀wọ̀ fún un.
Ils dirent: « Ton serviteur, notre père, se porte bien. Il est encore en vie. » Ils se prosternèrent humblement.
29 Bí ó ti wò yíká tí ó sì rí Benjamini àbúrò rẹ̀, tí í ṣe ọmọ ìyá rẹ̀ gan an. Ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣe àbúrò yín tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn tí ẹ sọ fún mi nípa rẹ̀ nìyìí?” Ó sì tún wí pe, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún ọ, ọmọ mi.”
Il leva les yeux et vit Benjamin, son frère, le fils de sa mère, et il dit: « Est-ce là ton plus jeune frère, dont tu m'as parlé? » Il répondit: « Que Dieu te fasse miséricorde, mon fils. »
30 Ọkàn rẹ̀ sì fà sí i gidigidi nígbà tí ó rí arákùnrin rẹ̀, nítorí náà Josẹfu yára jáde láti wá ibi tí ó ti le sọkún. Ó lọ sí iyàrá rẹ̀, ó sì sọkún níbẹ̀.
Joseph se hâta, car son cœur se languissait de son frère, et il chercha un endroit pour pleurer. Il entra dans sa chambre, et y pleura.
31 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti bọ́jú tan, ó jáde wá, ó ṣe ọkàn ọkùnrin, ó sì wí fún wọn pé, kí wọ́n gbé oúnjẹ wá kí wọ́n le è jẹun.
Il se lava le visage, et sortit. Il se maîtrisa, et dit: « Servez le repas. »
32 Wọ́n gbé oúnjẹ tirẹ̀ fún un lọ́tọ̀, àti fún àwọn ará Ejibiti tí ó wá ba jẹun náà lọ́tọ̀, nítorí ará Ejibiti kò le bá ará Heberu jẹun nítorí ìríra pátápátá ló jẹ́ fún àwọn Ejibiti.
Ils le servirent seuls, eux seuls, et les Égyptiens qui mangèrent avec lui seuls, car les Égyptiens ne mangent pas avec les Hébreux, car c'est une abomination pour les Égyptiens.
33 A mú àwọn ọkùnrin náà jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bí wọ́n ṣe dàgbà sí, láti orí ẹ̀gbọ́n pátápátá dé orí èyí tí ó kéré pátápátá, wọ́n sì ń wo ara wọn tìyanu tìyanu.
Ils s'assirent devant lui, le premier-né selon son droit d'aînesse, et le plus jeune selon sa jeunesse, et les hommes s'étonnaient les uns des autres.
34 A sì bu oúnjẹ fún wọn láti orí tábìlì Josẹfu. Oúnjẹ Benjamini sì tó ìlọ́po márùn-ún ti àwọn tókù. Wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu lọ́dọ̀ rẹ̀ láìsí ìdíwọ́.
Il leur envoya des parts de devant lui, mais la part de Benjamin était cinq fois plus importante que celle de n'importe lequel des leurs. Ils burent et furent joyeux avec lui.

< Genesis 43 >