< Genesis 42 >
1 Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
Emdi Yaqup Misirda ashliq barliqini bilginide oghullirigha: — Némishqa bir-biringlargha qariship turisiler? — dédi.
2 “Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
Andin yene: — Manga qaranglar, anglishimche Misirda ashliq bar iken. U yerge bérip, andin shu yerdin bizge ashliq élip kélinglar; buning bilen ölüp ketmey, tirik qalimiz, — dédi.
3 Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
Buning bilen Yüsüpning on akisi ashliq sétiwalghili Misirgha yolgha chiqti.
4 Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
Lékin Yaqup Yüsüpning inisi Binyaminning birer yamanliqqa uchrap qélishidin qorqup uni akiliri bilen bille ewetmidi.
5 Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
Shuningdek acharchiliq Qanaan zéminidimu yüz bergechke, Israilning oghulliri ashliq alghili kelgenler arisida bar idi.
6 Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
Yüsüp zéminning waliysi bolup, yurtning barliq xelqige ashliq sétip bergüchi shu idi. Yüsüpning akiliri kélip uning aldida yüzlirini yerge tegküzüp tezim qildi.
7 Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
Yüsüp akilirini körüpla ularni tonudi; lékin u tonushluq bermey, ulargha qopal teleppuzda gep qilip: — Qeyerdin keldinglar, dep soridi. Ular jawaben: — Qanaan zéminidin ashliq alghili kelduq, — dédi.
8 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
Yüsüp akilirini tonughan bolsimu, lékin ular uni tonumidi.
9 Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
Yüsüp emdi ular toghrisida körgen chüshlirini ésige élip, ulargha: — Siler jasus, bu elning mudapiesiz jaylirini közetkili keldinglar, — dédi.
10 Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
Emma ular uninggha jawab bérip: — Ey xojam, undaq emes! Belki keminiliri ashliq sétiwalghili keldi!
11 Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
Biz hemmimiz bir ademning oghulliri, semimiy ademlermiz. Keminiliri jasus emes! — dédi.
12 Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
U ulargha yene: — Undaq emes! Belki zéminning mudapiesiz jaylirini körgili keldinglar, — dédi.
13 Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
Ular jawab bérip: — Keminiliri eslide on ikki qérindash iduq; biz hemmimiz Qanaan zéminidiki bir ademning oghulliridurmiz; lékin kenji inimiz atimizning qéshida qélip qaldi; yene bir inimiz yoqap ketti, — dédi.
14 Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
Emma Yüsüp ulargha yene: — Mana men del silerge éytqinimdek, jasus ikensiler!
15 Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
Pirewnning hayati bilen qesem qilimenki, kichik ininglar bu yerge kelmigüche siler bu yerdin chiqip kételmeysiler; siler shuning bilen sinilisiler.
16 Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
Ininglarni élip kelgili biringlarni ewetinglar, qalghanliringlar bolsa solap qoyulisiler. Buning bilen éytqininglarning rast-yalghanliqi ispatlinidu; bolmisa, Pirewnning hayati bilen qesem qilimenki, siler jezmen jasus! — dédi.
17 Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
Shuning bilen u ularni üch kün’giche solap qoydi.
18 Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
Üchinchi küni Yüsüp ulargha mundaq dédi: — Men Xudadin qorqidighan ademmen; tirik qélishinglar üchün mushu ishni qilinglar: —
19 Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
Eger semimiy ademler bolsanglar, qérindashliringlardin biri siler solan’ghan gundixanida solaqliq turiwersun, qalghininglar acharchiliqta qalghan ailenglar üchün ashliq élip kétinglar;
20 Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
Andin kichik ininglarni qéshimgha élip kélinglar. Shuning bilen sözliringlar ispatlansa, ölmeysiler!, — dédi. Ular shundaq qilidighan boldi.
21 Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
Andin ular özara: — Berheq, biz inimizgha qilghan ishimiz bilen gunahkar bolup qalduq; u bizge yalwursimu uning azabini körüp turup uninggha qulaq salmiduq. Shuning üchün bu azab-oqubet béshimizgha chüshti, — déyishti.
22 Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
Ruben ulargha jawaben: — Men silerge: baligha zulum qilmanglar, dégen emesmidim? Lékin unimidinglar. Mana emdi uning qan qerzi bizdin soriliwatidu, — dédi.
23 Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
Emma Yüsüp ular bilen terjiman arqiliq sözleshkechke, ular Yüsüpning öz geplirini uqup turuwatqinini bilmidi.
24 Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
U ulardin özini chetke élip, yighlap ketti. Andin ularning qéshigha yénip kélip, ulargha yene söz qilip, ularning arisidin Shiméonni tutup, ularning köz aldida baghlidi.
25 Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
Andin Yüsüp emr chüshürüp, ularning tagharlirigha ashliq toldurup, her birsining pulini qayturup taghirigha sélip qoyup, seper hazirliqlirimu bérilsun dep buyruwidi, ulargha shundaq qilindi.
26 wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
Shuning bilen akiliri ésheklirige ashliqlirini artip, shu yerdin ketti.
27 Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
Emma ötengge kelgende ulardin biri éshikige yem bergili taghirini échiwidi, mana, öz puli tagharning aghzida turatti.
28 Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
U qérindashlirigha: — Méning pulumni qayturuwétiptu. Mana u taghirimda turidu, dédi. Buni anglap ularning yüriki su bolup, titriship bir-birige: — Bu Xudaning bizge zadi néme qilghinidu? — déyishti.
29 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
Ular Qanaan zéminigha, atisi Yaqupning qéshigha kélip, béshidin ötken hemme weqelerni uninggha sözlep bérip:
30 “Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
— héliqi kishi, yeni shu zéminning xojisi bizge qopal gep qildi, bizge zéminni paylighuchi jasustek muamile qildi;
31 Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
emdi biz uninggha: «Biz bolsaq semimiy ademlermiz, jasus emesmiz.
32 Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
Biz bir atidin bolghan oghullar bolup, on ikki aka-uka iduq; biri yoqap ketti, kichik inimiz hazir Qanaan zéminida atimizning yénida qaldi» dések,
33 “Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
Héliqi kishi, yeni shu zéminning xojisi bizge mundaq dédi: «Méning silerning semimiy ikenlikinglarni bilishim üchün, qérindashliringlarning birini méning yénimda qaldurup qoyup, ach qalghan ailenglar üchün ashliq élip kétinglar;
34 Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
andin kichik ininglarni qéshimgha élip kélinglar; shundaq qilsanglar, silerning jasus emes, belki semimiy ademler ikenlikinglarni bileleymen. Andin qérindishinglarni silerge qayturup bérimen we siler zéminda soda-sétiq qilsanglar bolidu» — dédi.
35 Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
Emma shundaq boldiki, ular tagharlirini tökkende, mana herbirining puldini öz tagharlirida turatti! Ular we atisi özlirining chigiklik pullirini körgende, qorqup qélishti.
36 Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
Atisi Yaqup ulargha: — Méni oghlumdin juda qildinglar! Yüsüp yoq boldi, Shiméonmu yoq, emdi Binyaminnimu élip ketmekchi boluwatisiler! Mana bu ishlarning hemmisi méning béshimghila keldi! — dédi.
37 Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
Ruben atisigha: — Eger men Binyaminni qéshinggha qayturup élip kelmisem, méning ikki oghlumni öltürüwetkin; uni méning qolumgha tapshurghin; men uni qéshinggha yandurup élip kélimen, — dédi.
38 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol )
Lékin Yaqup jawab bérip: — Oghlum siler bilen bille u yerge chüshmeydu; chünki uning akisi ölüp kétip, u özi yalghuz qaldi. Mubada yolda kétiwatqanda uninggha birer kélishmeslik kelse, siler mendek bir aq chachliq ademni derd-elem bilen textisaragha chüshüriwétisiler, — dédi. (Sheol )