< Genesis 42 >

1 Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
Gdy Jakub dowiedział się, że w Egipcie jest zboże, powiedział do swoich synów: Czemu się patrzycie jeden na drugiego?
2 “Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
I mówił [im]: Oto słyszałem, że w Egipcie jest zboże. Jedźcie tam i kupcie [je] nam stamtąd, abyśmy żyli, a nie pomarli.
3 Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
Dziesięciu braci Józefa wyruszyło więc do Egiptu, aby kupić zboże.
4 Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
Ale Jakub nie posłał Beniamina, brata Józefa, z jego braćmi, bo powiedział: By nie spotkało go jakieś nieszczęście.
5 Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
Synowie Izraela przybyli więc wraz z innymi, aby kupić [zboże], gdyż był głód w ziemi Kanaan.
6 Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
A Józef był rządcą tej ziemi i to on sprzedawał [zboża] całej ludności tej ziemi. A gdy przyszli bracia Józefa, pokłonili mu się twarzą do ziemi.
7 Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
Gdy Józef ujrzał swych braci, poznał ich, lecz udawał przed nimi obcego i rozmawiał z nimi surowo. Zapytał ich: Skąd przyszliście? Odpowiedzieli: Z ziemi Kanaan, aby nakupić żywności.
8 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
Józef rozpoznał swoich braci, ale oni go nie poznali.
9 Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
I Józef przypomniał sobie sny, które mu się śniły o nich, i powiedział im: Jesteście szpiegami i przyszliście, aby wypatrzyć nieobronne miejsca tej ziemi.
10 Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
A [oni] mu odpowiedzieli: Nie, mój panie. Twoi słudzy przyszli, aby nakupić żywności.
11 Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
Wszyscy jesteśmy synami jednego człowieka. [Jesteśmy] uczciwi. Twoi słudzy nie są szpiegami.
12 Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
A [on] powiedział do nich: Nie, ale przyszliście wypatrzyć nieobronne miejsca tej ziemi.
13 Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
Powiedzieli: [Było] nas, twoich sług, dwunastu braci, synów jednego człowieka w ziemi Kanaan. Najmłodszy [jest] z naszym ojcem [w domu], a jednego już nie ma.
14 Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
Józef rzekł im: [Jest] tak, jak wam powiedziałem – jesteście szpiegami.
15 Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
Zostaniecie co do tego wybadani: Na życie faraona, nie wyjdziecie stąd, dopóki nie przyjdzie tu wasz młodszy brat.
16 Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
Wyślijcie jednego z was, aby przyprowadził waszego brata, a wy zostaniecie w więzieniu, aż wasze słowa się potwierdzą, czy mówicie prawdę. A jeśli nie, na życie faraona, jesteście szpiegami.
17 Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
I oddał ich pod straż na trzy dni.
18 Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
A trzeciego dnia Józef powiedział do nich: Zróbcie tak, a będziecie żyć, [bo] ja się boję Boga.
19 Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
Jeśli jesteście uczciwi, niech jeden z waszych braci pozostanie związany tu w więzieniu; a wy jedźcie i odnieście zboże, aby się pozbyć głodu z waszych domów.
20 Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
I przyprowadźcie do mnie waszego najmłodszego brata, a wasze słowa sprawdzą się i nie umrzecie. I tak zrobili.
21 Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
Mówili jeden do drugiego: Naprawdę zgrzeszyliśmy przeciwko naszemu bratu, bo widząc strapienie jego duszy, gdy nas błagał, nie wysłuchaliśmy go. Dlatego przyszło na nas to utrapienie.
22 Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
Wtedy Ruben odpowiedział im: Czyż nie mówiłem wam: Nie grzeszcie przeciw chłopcu? A nie usłuchaliście. Oto teraz żąda się odpowiedzialności za jego krew.
23 Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
Lecz oni nie wiedzieli, że Józef rozumie, bo rozmawiał z nimi przez tłumacza.
24 Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
Wtedy odwrócił się od nich i zapłakał. Potem obrócił się do nich i rozmawiał z nimi. Wziął spośród nich Symeona i związał go na ich oczach.
25 Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
Potem Józef rozkazał, aby napełniono ich wory zbożem i każdemu z nich wrzucono do jego wora pieniądze, i [żeby] dano im żywność na drogę. I tak zrobiono.
26 wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
Wtedy oni włożyli zboża na swoje osły i odjechali stamtąd.
27 Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
I gdy [jeden z nich] rozwiązał swój wór, aby w gospodzie dać karmę swemu osłu, zobaczył swoje pieniądze; były bowiem na wierzchu jego wora.
28 Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
I powiedział do swoich braci: Zwrócono mi pieniądze, oto są w moim worze. Wtedy zamarło im serce i przerazili się, mówiąc jeden do drugiego: Cóż to nam Bóg uczynił?
29 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
Potem przyszli do swego ojca Jakuba, do ziemi Kanaan, i opowiedzieli mu wszystko, co im się przydarzyło:
30 “Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
Ten człowiek, pan tej ziemi, rozmawiał z nami surowo i wziął nas za szpiegów ziemi;
31 Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
Powiedzieliśmy mu: Jesteśmy uczciwi, nie jesteśmy szpiegami;
32 Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
Było nas dwunastu braci, synów naszego ojca; jednego już nie ma, a najmłodszy [jest] teraz z naszym ojcem w ziemi Kanaan.
33 “Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
I ten człowiek, pan tej ziemi, powiedział do nas: Po tym poznam, że jesteście uczciwi; zostawcie jednego z waszych braci u mnie, weźcie zboże, aby pozbyć się głodu z waszych domów, i idźcie;
34 Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
Potem przyprowadźcie waszego najmłodszego brata do mnie, abym poznał, że nie jesteście szpiegami, ale [ludźmi] uczciwymi. Wtedy oddam wam waszego brata, a w tej ziemi będziecie mogli handlować.
35 Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
A gdy opróżniali swoje wory, każdy [znalazł] w swoim worze węzeł pieniędzy. Gdy wraz ze swoim ojcem zobaczyli węzły z pieniędzmi, przerazili się.
36 Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
Wtedy ich ojciec Jakub powiedział im: Osierociliście mnie. Nie ma Józefa i Symeona, a weźmiecie Beniamina; całe [zło] się na mnie zwaliło.
37 Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
Ruben powiedział do swego ojca: Zabij moich dwóch synów, jeśli go z powrotem nie przyprowadzę. Oddaj go pod moją opiekę, a ja ci go zwrócę.
38 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol h7585)
Ale on powiedział: Mój syn nie pójdzie z wami, gdyż jego brat umarł i tylko on jeden został. Jeśli przydarzy mu się nieszczęście na drodze, którą pójdziecie, w żalu doprowadzicie mnie, osiwiałego, do grobu. (Sheol h7585)

< Genesis 42 >