< Genesis 42 >
1 Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
Kad nu Jēkabs redzēja, ka labība bija Ēģiptes zemē, tad viņš saviem dēliem sacīja: ko jūs skatāties?
2 “Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
Un viņš sacīja: redzi, es esmu dzirdējis, labību esam Ēģiptes zemē, noejat turp un pērciet mums no turienes, lai dzīvojam un nemirstam.
3 Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
Tad desmit Jāzepa brāļi nogāja, labības pirkt no Ēģiptes zemes.
4 Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
Bet Benjaminu, Jāzepa brāli, Jēkabs nesūtīja ar viņa brāļiem, jo tas sacīja: ka to kāda nelaime neaizņem.
5 Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
Tā Israēla dēli nāca, labības pirkt līdz ar citiem, kas turp gāja, jo bads bija arī Kanaāna zemē.
6 Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
Un Jāzeps bija tas valdītājs pār zemi un pārdeva visiem tās zemes ļaudīm, un Jāzepa brāļi nāca un klanījās viņa priekšā ar vaigu pie zemes.
7 Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
Tad Jāzeps redzēja savus brāļus un tos pazina, bet viņš likās pret tiem svešs, un runāja ar tiem bargi un sacīja uz tiem: no kurienes jūs nākat? Un tie sacīja: no Kanaāna zemes, maizes pirkt.
8 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
Un Jāzeps pazina savus brāļus, bet tie viņu nepazina.
9 Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
Un Jāzeps pieminēja savus sapņus, ko viņš par tiem bija sapņojis, un viņš uz tiem sacīja: jūs esat izlūki, jūs esat nākuši raudzīt, kur zemei var piekļūt.
10 Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
Un tie uz viņu sacīja: nē, mans kungs, tavi kalpi ir nākuši, maizes pirkt.
11 Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
Mēs visi esam viena vīra dēli, mēs esam taisni ļaudis, tavi kalpi nav izlūki.
12 Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
Un viņš uz tiem sacīja: nē, bet jūs esat nākuši izlūkot, kur zemei var piekļūt.
13 Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
Un tie sacīja: mēs tavi kalpi bijām divpadsmit brāļi, viena paša vīra dēli Kanaāna zemē, un redzi, tas jaunākais vēl šodien ir pie mūsu tēva, bet tā viena vairs nav.
14 Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
Tad Jāzeps uz tiem sacīja: tā tas ir, kā es uz jums esmu runājis un sacījis: jūs esat izlūki.
15 Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
Pie tam jūs tapsiet pārbaudīti; tik tiešām kā Faraons dzīvo, jūs no šejienes netiksiet projām, ja jūsu jaunākais brālis nenāk šurpu.
16 Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
Sūtiet vienu no jums, kas atved jūsu brāli, bet jūs paliekat cietumā, tad jūsu vārdi taps pārbaudīti, vai pie jums ir patiesība, un ja ne, tik tiešām kā Faraons dzīvo, tad jūs esat izlūki.
17 Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
Un viņš tos kopā lika trīs dienas cietumā.
18 Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
Un trešā dienā Jāzeps uz tiem sacīja: dariet tā, tad jūs dzīvosiet; es bīstos Dievu.
19 Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
Ja jūs esat taisni ļaudis, tad lai viens no jūsu brāļiem paliek saistīts cietumā, un jūs ejat, pārvediet to labību, tādēļ ka bads jūsu mājās.
20 Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
Un atvediet savu jaunāko brāli pie manis, tad jūsu vārdi taps atrasti taisni, un jūs nemirsiet; un tie tā darīja.
21 Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
Tad tie sacīja viens uz otru: patiesi, mēs esam noziegušies pret savu brāli, ka mēs viņa dvēseles bēdas redzējām, kad viņš no mums žēlastības lūdzās, un neklausījām; tādēļ šās bēdas nāk pār mums.
22 Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
Un Rūbens tiem atbildēja un sacīja: vai es jums to neteicu sacīdams: neapgrēkojaties pret to bērnu, bet jūs neklausījāt? Un nu redzi, viņa asinis top meklētas.
23 Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
Un tie nezināja, ka Jāzeps to saprata, jo tur bija tulks viņu starpā.
24 Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
Un viņš no tiem novērsās un raudāja, un atkal pie tiem atgriezās un ar tiem runāja, un ņēma no viņu vidus Sīmeanu un to saistīja priekš viņu acīm.
25 Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
Un Jāzeps pavēlēja viņu maisus pildīt ar labību un viņu naudu atlikt ikkatram savā maisā, un tiem dot ceļa barību uz ceļu; un tiem tā tapa darīts.
26 wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
Un tie uzkrāva savu labību uz saviem ēzeļiem un aizgāja no turienes.
27 Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
Kad nu viens no tiem savu maisu atraisīja, savu ēzeli barot mājas vietā, tad tas ieraudzīja savu naudu, un redzi, tā bija viņa maisa virsgalā.
28 Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
Un tas sacīja uz saviem brāļiem: mana nauda man ir atlikta, un redzi, tā ir manā maisā. Tad tiem sirds iztrūkās un tie pārbijās viens uz otru sacīdami: kas tas ir, ko Dievs mums ir darījis?
29 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
Un tie nāca pie Jēkaba, sava tēva, uz Kanaāna zemi un teica tam visu, kas tiem bija noticis, un sacīja:
30 “Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
Tas vīrs, tas zemes kungs, runāja bargi ar mums un mūs turēja par zemes izlūkiem.
31 Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
Tad mēs tam sacījām: mēs esam taisni ļaudis, mēs neesam izlūki bijuši.
32 Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
Mēs bijām divpadsmit brāļi, sava tēva dēli, viena vairs nav, un tas jaunākais vēl šodien ir pie mūsu tēva Kanaāna zemē.
33 “Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
Un tas vīrs, tas zemes kungs, mums sacīja: pie tam es nomanīšu, jūs esam taisnus: pametiet vienu no saviem brāļiem pie manis un ņemiet, ko jums vajag, un noejat,
34 Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
Un atvediet savu jaunāko brāli pie manis, tad es manīšu, jūs neesam izlūkus, bet taisnus ļaudis. Jūsu brāli es jums atdošu un jums ļaušu šinī zemē pirkt un pārdot.
35 Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
Un kad tie savus maisus izbēra, redzi, tad ikviens atrada savu naudas mučkuli(maisiņu) savā maisā, un tie ieraudzīja savus naudas mučkuļus, viņi un viņu tēvs, un tie izbijās.
36 Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
Tad Jēkabs, viņu tēvs, uz tiem sacīja: jūs man paņemat manus bērnus: Jāzepa vairs nav un Sīmeana vairs nav, un Benjaminu jūs ņemsiet; viss tas nāk man virsū.
37 Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
Tad Rūbens runāja ar savu tēvu un sacīja: ja es to pie tevis neatvedīšu atpakaļ, tad nokauj manus divus dēlus; dod viņu manā rokā, tad es viņu pie tevis atvedīšu atpakaļ.
38 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol )
Bet viņš sacīja: manam dēlam nebūs noiet ar jums, jo viņa brālis ir miris, un tas ir viens pats atlicis. Ja tam kāda nelaime notiks uz ceļa, kur jūs iesiet, tad jūs manus sirmos matus ar sirdēstiem novedīsiet bedrē. (Sheol )