< Genesis 42 >

1 Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
Rĩrĩa Jakubu aamenyire atĩ Misiri nĩ kwarĩ na ngano, akĩĩra ariũ ake atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte mũikare o ro ũguo mũcũthanĩrĩirie?”
2 “Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
Agĩthiĩ na mbere akĩmeera atĩrĩ, “Nĩnjiguĩte atĩ Misiri kũrĩ na ngano. Ikũrũkai kuo mũgatũgũrĩre irio, nĩgeetha tũtũũre muoyo tũtigakue.”
3 Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
Nao ariũ ikũmi a ithe na Jusufu magĩikũrũka, magĩthiĩ kũgũra ngano Misiri.
4 Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
No Jakubu ndaatũmire Benjamini mũrũ wa nyina na Jusufu athiĩ na arĩa angĩ, tondũ nĩetigagĩra ndakone mũtino.
5 Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
Nĩ ũndũ ũcio ariũ a Isiraeli magĩthiĩ marĩ hamwe na arĩa angĩ maathiĩte kũgũra ngano Misiri, tondũ bũrũri wa Kaanani o naguo warĩ na ngʼaragu.
6 Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
Na rĩrĩ, Jusufu nĩwe warĩ mwathi wa bũrũri wa Misiri na nĩwe wendagĩria andũ othe a bũrũri ngano. Nĩ ũndũ ũcio rĩrĩa ariũ a ithe maakinyire kuo-rĩ, makĩmũinamĩrĩra, magĩturumithia mothiũ mao thĩ.
7 Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
Na rĩrĩa Jusufu onire ariũ a ithe, o ro rĩmwe akĩmamenya, no agĩĩtua ndamooĩ na akĩmaarĩria arĩ na ũũru, akĩmooria atĩrĩ, “Mumĩte kũ?” Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Tuumĩte bũrũri wa Kaanani tũgooka kũgũra irio.”
8 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
O na gũtuĩka Jusufu nĩamenyire ariũ a ithe-rĩ, o matiigana kũmũmenya.
9 Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
Ningĩ akĩririkana irooto ciake iria aarootete imakoniĩ, akĩmeera atĩrĩ, “Inyuĩ mũrĩ athigaani! Mũũkĩte kũrora bũrũri witũ kũrĩa ũtarĩ mũgitĩre.”
10 Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Aca, mwathi witũ! Ndungata ciaku ciũkĩte o kũgũra irio tu.
11 Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
Ithuĩ ithuothe tũrĩ ariũ a mũthuuri ũmwe. Ithuĩ ndungata ciaku tũrĩ andũ ehokeku, tũtirĩ athigaani.”
12 Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
Nake Jusufu akĩmeera atĩrĩ, “Aca! Mũũkĩte kũrora bũrũri witũ kũrĩa ũtarĩ mũgitĩre.”
13 Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
No makĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndungata ciaku ciarĩ andũ ikũmi na eerĩ, ariũ a mũthuuri ũmwe, ũrĩa ũtũũraga bũrũri wa Kaanani. Ũrĩa mũnini biũ nĩwe ũrĩ na baba rĩu, na ũmwe witũ ndarĩ ho.”
14 Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
Jusufu akĩmeera atĩrĩ, “No ta ũrĩa ndamwĩra: Inyuĩ mũrĩ athigaani!
15 Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
Na ũũ nĩguo mũkũmenyeka atĩ mũrĩ andũ a ma: Ti-itherũ, o ta ũrĩa Firaũni atũũraga muoyo-rĩ, mũtingiuma kũndũ gũkũ nginya ũrĩa mũnini wanyu oke.
16 Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
Tũmai ũmwe wanyu athiĩ agĩĩre mũrũ wa thoguo ũcio ũngĩ; inyuĩ aya angĩ nĩ mũgũikio njeera nĩgeetha ciugo cianyu icio mwarĩtie irorwo kana nĩ ũhoro wa ma. Mũngĩkorwo ũguo muugĩte tiguo-rĩ, o ta ũrĩa Firaũni atũũraga muoyo, inyuĩ mũrĩ athigaani!”
17 Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
Nake akĩmaikia othe njeera, magĩikara kuo mĩthenya ĩtatũ.
18 Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
Mũthenya wa ĩtatũ Jusufu akĩmeera atĩrĩ, “Tondũ ndĩ mwĩtigĩri Ngai-rĩ, ĩkai ũũ nĩguo mũtũũre muoyo:
19 Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
Angĩkorwo mũrĩ andũ ehokeku, ĩtĩkĩrai ũmwe wanyu aikare gũkũ njeera, na inyuĩ arĩa angĩ mũthiĩ mũtwarĩre andũ anyu ngano nĩ ũndũ wa ngʼaragu ĩrĩa marĩ nayo.
20 Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
No rĩrĩ, no nginya mũndehere mũrũ wa thoguo ũcio mũnini biũ, nĩgeetha ciugo cianyu ciĩtĩkĩrĩke kũna atĩ nĩ cia ma, na nĩguo mũtigakue.” Nao magĩĩka o ũguo.
21 Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
Nao makĩĩrana atĩrĩ, “Ti-itherũ tũraherithio nĩ ũndũ wa mũrũ wa ithe witũ. Nĩtuonire ũrĩa aarĩ na thĩĩna rĩrĩa atũthaithaga tũhonokie muoyo wake, no tũkĩrega kũmũigua; na no kĩo tũnyiitĩtwo nĩ thĩĩna ũyũ.”
22 Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
Rubeni akĩmacookeria atĩrĩ, “Githĩ ndiamwĩrire mũtikehĩrie kamwana kau? No inyuĩ mũkĩrega gũũthikĩrĩria! Rĩu no nginya tũrĩhio thakame yake.”
23 Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
No matiamenyaga atĩ Jusufu nĩaiguaga ũrĩa moigaga, tondũ we aatũmagĩra mũtabuti akĩmaarĩria.
24 Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
Jusufu akĩmahutatĩra akĩmeherera, akĩambĩrĩria kũrĩra; ningĩ agĩcooka agĩthiĩ akĩmaarĩria rĩngĩ. Akĩnyiitithia Simeoni akĩeherio harĩo na akĩohwo makĩonaga.
25 Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
Jusufu agĩathana makũnia mao maiyũrio ngano, na betha cia o mũndũ icookio ikũnia-inĩ rĩake, na maheo rĩĩgu wa rũgendo. Thuutha wa gwĩkĩrwo maũndũ macio,
26 wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
makĩigĩrĩra ndigiri ciao mĩrigo ĩyo ya ngano na makiumagara.
27 Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
Harĩa maarũgamire mararĩrĩre-rĩ, ũmwe wao agĩtumũra ikũnia rĩake ahe ndigiri yake irio, nake akĩona betha ciake hau mũromo-inĩ wa ikũnia rĩake.
28 Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
Akĩĩra ariũ a ithe atĩrĩ, “Haiya, nĩnjookeirio betha ciakwa; ĩ ici haha ikũnia-inĩ rĩakwa.” Ngoro ciao ikĩnyiitwo nĩ ihooru na makĩrorana makĩinainaga, makĩũrania atĩrĩ, “Nĩ atĩa ũũ Ngai atwĩkĩte?”
29 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
Na rĩrĩa maakinyire kũrĩ ithe wao Jakubu kũu bũrũri wa Kaanani-rĩ, makĩmwĩra maũndũ marĩa mothe monete. Makĩmwĩra atĩrĩ,
30 “Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
“Mũndũ ũrĩa mwathi wa bũrũri ũcio aatwarĩirie na ũũru mũingĩ na agĩtũtua ta twathiĩte gũthigaana bũrũri ũcio.
31 Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
No ithuĩ tũkĩmwĩra atĩrĩ, ‘Ithuĩ tũrĩ andũ ehokeku; tũtirĩ athigaani.
32 Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
Twarĩ andũ ikũmi na eerĩ, ariũ a mũthuuri ũmwe. Ũmwe ndarĩ ho, na ũrĩa mũnini biũ arĩ na ithe witũ kũu Kaanani.’
33 “Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
“Ningĩ mũndũ ũcio mwathi wa bũrũri agĩtwĩra atĩrĩ, ‘Gĩkĩ nĩkĩo gĩgũtũma menye kana mũrĩ andũ ehokeku: Ndigĩrai mũrũ wa thoguo ũmwe gũkũ, muoe irio mũthiĩ mũcitwarĩre andũ a nyũmba cianyu acio marĩ na ngʼaragu.
34 Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
No mũndehere mũrũ wa thoguo ũrĩa mũnini biũ na noguo ngaamenya atĩ mũtirĩ athigaani, mũrĩ andũ ehokeku. Hĩndĩ ĩyo nĩngamũcookeria mũrũ wa thoguo, na nĩmũgetĩkĩrio kuonjorithagia bũrũri-inĩ ũyũ.’”
35 Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
Na rĩrĩa moonoragia makũnia mao-rĩ, o mũndũ agĩkora kĩohe kĩa betha ciake ikũnia-inĩ rĩake! Nao na ithe wao mona ciohe icio cia mbeeca, makĩmaka.
36 Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
Ithe wao Jakubu akĩmeera atĩrĩ, “Mũrĩ kũũniinĩra ciana ciakwa. Jusufu ndarĩ ho, na Simeoni ndarĩ ho, na rĩu mũrenda kuoya Benjamini. Maũndũ maya mothe nĩ niĩ mokĩrĩire!”
37 Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
Hĩndĩ ĩyo Rubeni akĩĩra ithe atĩrĩ, “Nĩũkooraga ariũ akwa eerĩ ingĩkaaga gũcookia Benjamini harĩwe. Reke akorwo ũmenyereri-inĩ wakwa, na nĩngamũcookia.”
38 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol h7585)
No Jakubu akiuga atĩrĩ, “Mũrũ wakwa ndegũikũrũka athiĩ na inyuĩ; mũrũ wa nyina nĩ mũkuũ na nowe wiki ũtigarĩte. Angĩnyiitwo nĩ mũtino mũna rũgendo-inĩ rũu mũrathiĩ-rĩ, mwatũma mbuĩ ici ciakwa ithiĩ mbĩrĩra-inĩ na kĩeha.” (Sheol h7585)

< Genesis 42 >