< Genesis 41 >

1 Nígbà tí odindi ọdún méjì sì ti kọjá, Farao lá àlá: ó rí ara rẹ̀ tó dúró ní etí odò Naili.
Toptoƣra ikki yil ɵtüp, Pirǝwn bir qüx kɵrdi. Qüxidǝ u [Nil] dǝryasining boyida turƣudǝk.
2 Nígbà náà ni màlúù méje jáde láti inú odò, wọ́n dára láti wò, wọ́n sì sanra, wọ́n sì ń jẹ koríko.
Ⱨǝm qirayliⱪ ⱨǝm semiz yǝttǝ tuyaⱪ inǝk dǝryadin qiⱪip, ⱪumuxluⱪta otlaptudǝk.
3 Lẹ́yìn àwọn wọ̀nyí, ni àwọn màlúù méje mìíràn tí kò lẹ́wà tí ó sì rù jáde wá láti inú odò Naili, wọ́n sì dúró ti àwọn méje tí ó sanra tí ó wà ní bèbè odò náà.
Andin yǝnǝ yǝttǝ tuyaⱪ inǝk dǝryadin qiⱪiptu; ular sǝt ⱨǝm oruⱪ bolup, aldinⱪi inǝklǝrning yenida, dǝryaning boyida turuptu.
4 Àwọn màlúù tí ó rù, tí kò sì lẹ́wà sì gbé àwọn tí ó lẹ́wà tí ó sanra jẹ. Nígbà náà ni Farao jí.
Bu sǝt ⱨǝm oruⱪ inǝklǝr u yǝttǝ qirayliⱪ ⱨǝm semiz inǝklǝrni yǝwetiptu. Xu waⱪitta Pirǝwn oyƣinip ketiptu.
5 Ó sì tún padà sùn, ó sì lá àlá mìíràn: ó rí síírí ọkà méje tí ó kún, ó yómọ, ó sì dára, ó sì jáde lára igi ọkà kan ṣoṣo.
U yǝnǝ uhlap, ikkinqi ⱪetim qüx kɵrdi: — Mana, bir tüp buƣday xehidin toⱪ wǝ qirayliⱪ yǝttǝ baxaⱪ qiⱪiptu.
6 Lẹ́yìn wọn ni síírí ọkà méje mìíràn yọ, wọn kò yómọ, afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù.
Ulardin keyin yǝnǝ yǝttǝ baxaⱪ qiⱪiptu; ular ⱨǝm oruⱪ wǝ puqǝk bolup, xǝrⱪ xamilida solixip ⱪalƣanidi.
7 Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ (ọmọ rẹ̀ kò tóbi) wọ̀nyí sì gbé àwọn tí ó yómọ (ọmọ rẹ̀ tóbi) mì. Nígbà náà ni Farao jí lójú oorun, ó sì rí i pé àlá ni.
Bu oruⱪ baxaⱪlar u yǝttǝ semiz, toⱪ baxaⱪni yutup ketiptu. Andin Pirǝwn oyƣinip ketiptu, bu uning qüxi ikǝn.
8 Ní òwúrọ̀, ọkàn rẹ̀ dàrú, nítorí náà, ó ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn onídán àti ọ̀mọ̀ran ilẹ̀ Ejibiti. Farao rọ́ àlá rẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n kò rí ọ̀kan nínú wọn tí ó le sọ ìtumọ̀ àlá náà fún un.
Ətisi uning kɵngli naⱨayiti biaram bolup, Misirdiki ⱨǝmmǝ palqi-jadugǝrlǝr bilǝn barliⱪ danixmǝnlǝrni qaⱪirtip kǝldi. Pirǝwn ɵz qüxini ularƣa eytip bǝrdi; lekin ⱨeqkim Pirǝwngǝ qüxlǝrning tǝbirini dǝp berǝlmidi.
9 Nígbà náà ni olórí agbọ́tí wí fún Farao pé, “Lónìí ni mo rántí ẹ̀ṣẹ̀ mi.
U qaƣda bax saⱪiy Pirǝwngǝ: — Bügün mening ɵtküzgǝn hataliⱪlirim esimgǝ kǝldi.
10 Nígbà kan tí Farao bínú sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, tí ó sì fi èmi àti olórí alásè sínú ẹ̀wọ̀n ní ilé olórí ẹ̀ṣọ́.
Burun Pirǝwn janabliri ⱪulliriƣa, yǝni peⱪir wǝ bax nawayƣa aqqiⱪlinip, bizni pasiban bexining sariyida solaⱪⱪa taxliƣanidila;
11 Ọ̀kọ̀ọ̀kan wa lá àlá, àlá kọ̀ọ̀kan sì ní ìtumọ̀ tirẹ̀.
Xu qaƣlarda ⱨǝrbirimiz bir keqidǝ birdin qüx kɵrduⱪ; ⱨǝr ⱪaysimiz kɵrgǝn qüxning tǝbiri baxⱪa-baxⱪa idi.
12 Ọmọkùnrin ará Heberu kan tí ó jẹ́ ìránṣẹ́ olórí ẹ̀ṣọ́ wà níbẹ̀ pẹ̀lú wa. A rọ́ àwọn àlá wa fún un, ó sì túmọ̀ wọn fún wa, ó sọ ìtumọ̀ àlá ẹnìkọ̀ọ̀kan fún un.
Xu yǝrdǝ biz bilǝn billǝ pasiban bexining ⱪuli bolƣan bir ibraniy yigit bar idi. Uningƣa qüxlirimizni eytiwiduⱪ, u bizgǝ qüxlirimizning tǝbirini bayan ⱪildi; u ⱨǝrbirimizning kɵrgǝn qüxigǝ ⱪarap tǝbir bǝrgǝnidi.
13 Bí ó sì ti túmọ̀ àlá wọ̀nyí náà ni ohun gbogbo rí. A dá mi padà sí ipò mi, a sì so ọkùnrin kejì kọ́ sórí ọ̀wọ̀n.”
Xundaⱪ boldiki, ixlar dǝl uning bǝrgǝn tǝbiridǝ deyilgǝndǝk yüz bǝrdi; janabliri peⱪirni ɵz mǝnsipimgǝ ⱪaytidin tǝyinlidilǝ, bax nawayni darƣa astila, — dedi.
14 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Josẹfu, wọn sì mú un wá kíákíá láti inú ìhámọ́. Nígbà tí ó fá irun rẹ̀, tí ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó wá síwájú Farao.
Xuning bilǝn Pirǝwn adǝm ǝwǝtip, Yüsüpni qaⱪirdi; ular dǝrⱨal uni zindandin qiⱪardi. Yüsüp burut-saⱪilini qüxürüp, kiyimlirini yǝnggüxlǝp, Pirǝwnning aldiƣa kirdi.
15 Farao wí fún Josẹfu, “Mo lá àlá kan, kò sì sí ẹni tí o le è túmọ̀ rẹ̀. Ṣùgbọ́n mo ti gbọ́ nípa rẹ pé bí o bá ti gbọ́ àlá, o le è túmọ̀ rẹ̀.”
Pirǝwn Yüsüpkǝ: — Mǝn bir qüx kɵrdüm, ǝmma uning tǝbirini eytip berǝlǝydiƣan ⱨeqkim qiⱪmidi. Anglisam, sǝn qüxkǝ tǝbir berǝlǝydikǝnsǝn, — dedi.
16 Josẹfu dá Farao ní ohùn pé, “Kì í ṣe agbára mi, ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ni yóò fi ìdáhùn àlàáfíà fún Farao ní ìtumọ̀ àlá náà.”
Yüsüp Pirǝwngǝ jawab berip: — Tǝbir berix ɵzümdin ǝmǝs; lekin Huda Pirǝwngǝ hatirjǝmlik beridiƣan bir jawab beridu, — dedi.
17 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Ní inú àlá mi, mo dúró ni etí bèbè odò Naili,
Pirǝwn Yüsüpkǝ: — Qüxümdǝ mǝn dǝryaning ⱪirƣiⱪida turuptimǝn.
18 sì kíyèsi i, màlúù méje tí ó sanra tí o sì lẹ́wà jáde wá, wọ́n sì ń jẹ koríko ní tòsí ibẹ̀.
Ⱪarisam, dǝryadin ⱨǝm semiz ⱨǝm qirayliⱪ yǝttǝ tuyaⱪ inǝk qiⱪip ⱪumuxluⱪta otlaptu.
19 Lẹ́yìn wọn, màlúù méje mìíràn jáde wá, wọ́n rù hángógó, wọn kò sì lẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ tí n kò tí ì rí irú màlúù tí ó ṣe àìlẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ rí ní ilẹ̀ Ejibiti.
Andin ulardin keyin ajiz, tolimu sǝt ⱨǝm oruⱪ yǝttǝ tuyaⱪ inǝk qiⱪiptu. Mǝn Misir zeminida xundaⱪ sǝt inǝklǝrni kɵrgǝn ǝmǝsmǝn.
20 Àwọn màlúù tí ó rù tí kò sì lẹ́wà sì jẹ àwọn màlúù tí ó sanra tí ó kọ́ jáde nínú odò.
Bu oruⱪ, ǝski inǝklǝr bolsa awwalⱪi yǝttǝ semiz inǝkni yǝwetiptu.
21 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ́ wọ́n tan, kò sì ẹni tí ó le mọ̀ pé wọ́n jẹ ohunkóhun, nítorí wọn kò sanra sí i, wọn sì bùrẹ́wà síbẹ̀. Nígbà náà ni mo tají.
Ularni yǝwǝtkǝn bolsimu, ⱪorsiⱪiƣa bir nemining kirgǝnliki ⱨeq ayan bolmaptu, ularning kɵrünüxi bǝlki burunⱪidǝk sǝt imix. Andin mǝn oyƣinip kǝttim.
22 “Ní ojú àlá mi, mo tún rí síírí ọkà méje tí ó yó ọmọ tí ó sì dára, wọ́n jáde láti ara igi ọkà kan.
Andin yǝnǝ bir qüx kɵrdum, mana bir xahtin yǝttǝ ⱨǝm toⱪ ⱨǝm qirayliⱪ baxaⱪ qiⱪiptu.
23 Lẹ́yìn wọn, àwọn méje mìíràn yọ jáde, tí kò yó ọmọ bẹ́ẹ̀ ni afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù tán.
Andin yǝnǝ yǝttǝ puqǝk, oruⱪ baxaⱪ qiⱪiptu; ular xǝrⱪ xamili bilǝn solixip ⱪurup ketiptu.
24 Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ sì gbé àwọn méje tí ó dára wọ̀nyí mì. Mo sọ àlá yìí fún àwọn onídán mi, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó le túmọ̀ rẹ̀ fún mi.”
Bu oruⱪ baxaⱪlar yǝttǝ qirayliⱪ baxaⱪni yǝp ketiptu. Mǝn bu ixni palqi-jadugǝrlǝrgǝ dǝp bǝrsǝm, manga tǝbirini eytip beridiƣan ⱨeq kixi qiⱪmidi, dedi.
25 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún Farao, “Ìtumọ̀ kan náà ni àwọn àlá méjèèjì ní. Ọlọ́run fi ohun tí ó fẹ́ ṣe hàn fún Farao.
Yüsüp Pirǝwngǝ: — [Janabliri] Pirǝwnning qüxliri bir mǝnididur. Huda Ɵzi ⱪilmaⱪqi bolƣan ixlirini Pirǝwngǝ aldin bildürdi.
26 Àwọn màlúù méje ti ó dára jẹ́ ọdún méje, síírí ọkà méje tí ó dára náà sì jẹ́ ọdún méje: ọ̀kan ṣoṣo ni wọn, àlá kan náà ni.
Bu yǝttǝ yahxi inǝk yǝttǝ yilni kɵrsitidu; yǝttǝ yahxi baxaⱪmu yǝttǝ yilni kɵrsitidu. Bu qüxlǝr ohxax bir qüxtur.
27 Àwọn màlúù méje tí kò sanra, tí kò sì rẹwà tí ó jáde gbẹ̀yìn jẹ́ ọdún méje, bẹ́ẹ̀ náà ni síírí ọkà méje tí kò dára, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ dànù tan, wọn jẹ́ ọdún méje tí ìyàn yóò fi mú.
Ulardin keyin qiⱪⱪan yǝttǝ oruⱪ, yaman sǝt inǝk yǝttǝ yilni kɵrsitidu; xǝrⱪ xamili bilǝn solixip ⱪalƣan yǝttǝ ⱪuruⱪ baxaⱪmu xundaⱪ bolup, aqarqiliⱪ bolidiƣan yǝttǝ yildur.
28 “Bí mo ti wí fún Farao ní ìṣáájú náà ni: Ọlọ́run fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ han Farao.
Mǝn Pirǝwngǝ dǝydiƣan sɵzüm xuki, Huda yeⱪinda ⱪilmaⱪqi bolƣan ixni Pirǝwngǝ ayan ⱪildi.
29 Ọdún méje tí oúnjẹ yóò pọ̀ yanturu ń bọ̀ wà ní Ejibiti.
Mana, pütkül Misir zeminida yǝttǝ yilƣiqǝ mǝmurqiliⱪ bolidu;
30 Ṣùgbọ́n ọdún méje mìíràn tí ìyàn yóò mú ń bọ̀, nígbà náà ni a ó tilẹ̀ gbàgbé gbogbo ọ̀pọ̀ ní ilẹ̀ Ejibiti, ìyàn yóò sì run gbogbo ilẹ̀ náà.
andin yǝttǝ yilƣiqǝ aqarqiliⱪ bolidu; xuning bilǝn Misir zeminida pütkül mǝmurqiliⱪni unutⱪuzidiƣan aqarqiliⱪ zeminni wǝyran ⱪilidu.
31 A kò ní rántí àsìkò ọ̀pọ̀ oúnjẹ yanturu náà mọ́ nítorí pé ìyàn tí yóò tẹ̀lé e yóò pọ̀ púpọ̀.
Kelidiƣan aqarqiliⱪning sǝwǝbidin zeminda bolƣan mǝmurqiliⱪ kixilǝrning esidin kɵtürülüp ketidu; qünki aqarqiliⱪ tolimu eƣir bolidu.
32 Ìdí tí Ọlọ́run fi fi àlá náà han fún Farao ní ọ̀nà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni pé, Ọlọ́run ti pinnu pé yóò ṣẹlẹ̀ bẹ́ẹ̀ dandan, àti pé kò ni pẹ́ tí Ọlọ́run yóò fi ṣe é.
Lekin qüxning yandurulup, Pirǝwngǝ ikki ⱪetim kɵrünginining ǝⱨmiyiti xuki, bu ix Huda tǝripidin bekitilgǝn bolup, Huda uni pat arida ǝmǝlgǝ axuridu.
33 “Ìmọ̀ràn mi ni wí pé, jẹ́ kí Farao wá ọlọ́gbọ́n ènìyàn kan ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ó sì fi ṣe alákòóso iṣẹ́ àgbẹ̀ ilẹ̀ Ejibiti.
Əmdi Pirǝwn ɵzi üqün pǝm-parasǝtlik ⱨǝm dana bir kixini tepip, Misir zeminiƣa ⱪoysun.
34 Kí Farao sì yan àwọn alábojútó láti máa gba ìdámárùn-ún ìkórè oko ilẹ̀ Ejibiti ní àsìkò ọdún méje ọ̀pọ̀.
Pirǝwn xundaⱪ ⱪilsunki, mǝmurqiliⱪ bolƣan yǝttǝ yilda Misir zeminidin qiⱪⱪan axliⱪning bǝxtin birini toplanglar dǝp zeminƣa nazarǝtqilǝrni tǝyinlisun.
35 Kí wọn kó gbogbo oúnjẹ ilẹ̀ náà ni àwọn ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, kí wọn sì kó àwọn ọkà tí wọn jẹ ṣẹ́kù pamọ́ lábẹ́ àṣẹ Farao. Kí a kó wọn pamọ́ ni àwọn ìlú fún jíjẹ.
Bular xu kelidiƣan toⱪqiliⱪ yillirida barliⱪ axliⱪni toplap, xǝⱨǝr-xǝⱨǝrlǝrdǝ yemǝklik bolsun dǝp buƣday-ⱪonaⱪlarni Pirǝwnning ⱪol astiƣa jǝm ⱪilip saⱪlitip ⱪoysun.
36 Kí wọn kó oúnjẹ náà pamọ́ fún orílẹ̀-èdè yìí, kí a ba à le lò ó ni ọdún méje tí ìyàn yóò fi jà ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ìyàn náà má ba à pa orílẹ̀-èdè yìí run.”
[Yiƣilƣan] xu axliⱪlar Misir zeminida bolidiƣan yǝttǝ yilliⱪ aqarqiliⱪⱪa taⱪabil turux üqün saⱪlansun; xu tǝriⱪidǝ zemin aqarqiliⱪtin ⱨalak bolmaydu, — dedi.
37 Èrò náà sì dára lójú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀.
Bu sɵz Pirǝwn wǝ uning hizmǝtkarlirining nǝzirigǝ taza yaⱪti.
38 Farao sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ a le rí ẹnikẹ́ni bi ọkùnrin yìí, nínú ẹni tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń gbé?”
Xuning bilǝn Pirǝwn hizmǝtkarliriƣa: — Bu kixidǝk, iqidǝ Hudaning roⱨi bar yǝnǝ birsini tapalamduⱪ?! — dedi.
39 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu, “Níwọ́n bí Ọlọ́run ti fi gbogbo èyí hàn ọ́, kò sí ẹni náà tí ó gbọ́n tí ó sì mọ̀ràn bí i tìrẹ ní ilẹ̀ Ejibiti yìí,
Pirǝwn Yüsüpkǝ: — Huda sanga buning ⱨǝmmisini ayan ⱪilƣanikǝn, sǝndǝk pǝmlik ⱨǝm dana ⱨeqkim qiⱪmaydu.
40 ìwọ yóò ṣe àkóso ààfin mi gbogbo àwọn ènìyàn gbọdọ̀ tẹríba fún àṣẹ ẹ̀ rẹ. Ìtẹ́ mi nìkan ni èmi yóò fi jù ọ́ lọ.”
Sǝn ǝmdi mening ɵyümni baxⱪuruxⱪa bekitilding, barliⱪ hǝlⱪim sening aƣzingƣa ⱪarap ɵzlirini tǝrtipkǝ tizsun. Pǝⱪǝt tǝhttila mǝn sǝndin üstün turimǝn, — dedi.
41 Farao wí fún Josẹfu pé, “Mo fi ọ́ ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Ahirida Pirǝwn Yüsüpkǝ: — Mana, mǝn seni pütkül Misir zeminining üstigǝ tǝyinlidim, — dedi.
42 Farao sì bọ́ òrùka èdìdì ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi wọ Josẹfu ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ó sì fi ẹ̀gbà tí ó dára sí i lọ́rùn.
Buning bilǝn, Pirǝwn ɵz ⱪolidin mɵⱨür üzükini qiⱪirip, Yüsüpning ⱪoliƣa saldi; uningƣa nǝpis kanap rǝhttin tikilgǝn libasni kiygüzüp, boyniƣa bir altun zǝnjir esip ⱪoydi.
43 Ó sì mú un kí ó gun kẹ̀kẹ́-ẹṣin bí igbákejì ara rẹ̀, àwọn ènìyàn sì ń pariwo níwájú rẹ̀ pé, “Ẹ yàgò lọ́nà.” Báyìí ni ó sì fi ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Uni ɵzining ikkinqi xaⱨanǝ ⱨarwisiƣa olturƣuzup, uning aldida: «Tiz pükünglar!» — dǝp jar saldurdi. Xundaⱪ ⱪilip, Pirǝwn uni pütkül Misir zeminiƣa tiklǝp ⱪoydi.
44 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Èmi ni Farao. Ṣùgbọ́n láìsí àṣẹ rẹ, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ ṣe ohunkóhun ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Andin Pirǝwn Yüsüpkǝ yǝnǝ: — Mǝn degǝn Pirǝwndurmǝn; pütkül Misir zeminida sǝnsiz ⱨeqkim ⱪol-putini midirlatmisun! — dedi.
45 Farao sì sọ Josẹfu ní orúkọ yìí Safenati-Panea (èyí tí ó túmọ̀ sí ẹni tí ó ni agbára ikú àti ìyè ní ìkáwọ́ bí òrìṣà). Ó sì fun un ní Asenati ọmọ Potifẹra, alábojútó òrìṣà Oni, gẹ́gẹ́ bí aya. Josẹfu sì rin gbogbo ilẹ̀ Ejibiti já.
Pirǝwn Yüsüpkǝ Zafinat-Paaniyaⱨ degǝn namni bǝrdi wǝ on xǝⱨiridiki kaⱨin Potifiraⱨning ⱪizi Asinatni uningƣa hotunluⱪⱪa elip bǝrdi. Xundaⱪ ⱪilip Yüsüp pütkül Misir zeminini baxⱪurux üqün qɵrgilǝxkǝ qiⱪti. Yüsüp Misir padixaⱨi Pirǝwnning hizmitidǝ boluxⱪa bekitilgǝndǝ ottuz yaxta idi; u Pirǝwnning aldidin qiⱪip, Misir zeminining ⱨǝrⱪaysi jaylirini kɵzdin kǝqürdi.
46 Ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni Josẹfu nígbà tí ó wọ iṣẹ́ Farao ọba Ejibiti. Josẹfu sì jáde kúrò níwájú Farao, ó sì ṣe ìbẹ̀wò káàkiri gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
47 Ní ọdún méje ọ̀pọ̀, ilẹ̀ náà so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Mǝmurqiliⱪ bolƣan yǝttǝ yil iqidǝ zeminning ⱨosuli dɵwǝ-dɵwǝ boldi.
48 Josẹfu kó gbogbo oúnjẹ tí a pèsè ni ilẹ̀ Ejibiti ní ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, ó sì pa wọ́n mọ́ sí àwọn ìlú. Ní ìlú kọ̀ọ̀kan ni ó kó gbogbo oúnjẹ tí wọ́n gbìn ní àyíká ìlú wọn sí.
Yǝttǝ yilda u Misir zeminidin qiⱪⱪan axliⱪni yiƣip, xǝⱨǝr-xǝⱨǝrgǝ toplidi; ⱨǝrⱪaysi xǝⱨǝrning ǝtrapidiki etizliⱪning axliⱪini u xu xǝⱨǝrning ɵzigǝ juƣlap ⱪoydi.
49 Josẹfu pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà mọ́ bí iyanrìn Òkun; ó pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí kò ṣe àkọsílẹ̀ mọ́ nítorí, ó tayọ kíkà.
Xu tǝriⱪidǝ Yüsüp dengizdiki ⱪumdǝk naⱨayiti kɵp axliⱪ toplidi; axliⱪ ⱨǝddi-ⱨesabsiz bolƣaqⱪa, ular ⱨesablaxni tohtatti.
50 Kí ó tó di pé ọdún ìyàn dé, Asenati ọmọ Potifẹra alábojútó Oni bí ọmọkùnrin méjì fún Josẹfu.
Aqarqiliⱪ yilliri yetip kelixtin burun Yüsüpkǝ ikki oƣul tɵrǝldi. Bularni Ondiki kaⱨin Potifǝraⱨning ⱪizi Asinat uningƣa tuƣup bǝrdi.
51 Josẹfu sọ orúkọ àkọ́bí rẹ̀ ni Manase, ó sì wí pé, “Nítorí tí Ọlọ́run ti mú mi gbàgbé gbogbo ìdààmú mi àti gbogbo ilé baba mi.”
Yüsüp: «Huda pütün japa-muxǝⱪⱪitim wǝ atamning pütün ailisini kɵnglümdin kɵtürüwǝtti» dǝp tunji oƣliƣa Manassǝⱨ dǝp at ⱪoydi;
52 Ó sì sọ orúkọ èkejì ní Efraimu, ó sì wí pé, “Nítorí pé Ọlọ́run fún mi ní ọmọ ní ilẹ̀ ìpọ́njú mi.”
andin: «Mǝn azab-oⱪubǝt qǝkkǝn yurtta Huda meni mewilik ⱪildi» dǝp ikkinqisigǝ Əfraim dǝp at ⱪoydi.
53 Ọdún méje ọ̀pọ̀ oúnjẹ sì wá sí òpin ní ilẹ̀ Ejibiti,
Misir zeminida mǝmurqiliⱪ bolƣan yǝttǝ yil ayaƣlaxti.
54 ọdún méje ìyàn sì bẹ̀rẹ̀, bí Josẹfu ti wí gan an. Ìyàn sì mú ní gbogbo ilẹ̀ tókù, ṣùgbọ́n oúnjẹ wà ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Andin Yüsüpning eytⱪinidǝk aqarqiliⱪning yǝttǝ yili baxlandi. U qaƣlarda baxⱪa barliⱪ yurtlardimu aqarqiliⱪ boldi; lekin Misir zeminidiki ⱨǝr yǝrlǝrdǝ nan bar idi.
55 Nígbà tí àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí ní rí ipá ìyàn náà, wọ́n kígbe sí Farao. Nígbà náà ni Farao wí fún wọn pé, “Ẹ lọ bá Josẹfu, ẹ ṣe ohun tí ó bá wí fún un yín.”
Aqarqiliⱪ pütkül Misir zeminni basⱪanda, hǝlⱪ axliⱪ sorap Pirǝwngǝ pǝryad ⱪildi. Pirǝwn misirliⱪlarning ⱨǝmmisigǝ: — Yüsüpning ⱪexiƣa berip, u silǝrgǝ nemǝ desǝ, xuni ⱪilinglar, — dedi.
56 Nígbà tí ìyàn sì ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ náà, Josẹfu ṣí inú àká, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ta ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ìyàn náà mú gan an ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Aqarqiliⱪ pütkül yǝr yüzini besip kǝtti. Yüsüp ⱨǝr yǝrdiki ambarlarni eqip, misirliⱪlarƣa axliⱪ satatti; aqarqiliⱪ Misir zeminida intayin eƣir bolƣili turdi.
57 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè sì ń wá sí Ejibiti láti ra oúnjẹ lọ́wọ́ Josẹfu, nítorí ìyàn náà pọ̀ gidigidi káàkiri gbogbo ayé.
Aqarqiliⱪ pütkül yǝr yüzini basⱪan bolƣaqⱪa, barliⱪ yurtlardiki hǝlⱪmu axliⱪ alƣili Misirƣa Yüsüpning ⱪexiƣa kelǝtti.

< Genesis 41 >