< Genesis 41 >
1 Nígbà tí odindi ọdún méjì sì ti kọjá, Farao lá àlá: ó rí ara rẹ̀ tó dúró ní etí odò Naili.
Po upływie dwóch lat śniło się faraonowi, że stał nad rzeką.
2 Nígbà náà ni màlúù méje jáde láti inú odò, wọ́n dára láti wò, wọ́n sì sanra, wọ́n sì ń jẹ koríko.
A oto z rzeki wychodziło siedem pięknych i tłustych krów, które się pasły na łące.
3 Lẹ́yìn àwọn wọ̀nyí, ni àwọn màlúù méje mìíràn tí kò lẹ́wà tí ó sì rù jáde wá láti inú odò Naili, wọ́n sì dúró ti àwọn méje tí ó sanra tí ó wà ní bèbè odò náà.
Oto też za nimi wychodziło z rzeki siedem innych krów, brzydkich i chudych, które stanęły obok [pierwszych] krów nad brzegiem rzeki.
4 Àwọn màlúù tí ó rù, tí kò sì lẹ́wà sì gbé àwọn tí ó lẹ́wà tí ó sanra jẹ. Nígbà náà ni Farao jí.
I te brzydkie i chude krowy pożarły siedem pięknych i tłustych krów. Wtedy faraon się obudził.
5 Ó sì tún padà sùn, ó sì lá àlá mìíràn: ó rí síírí ọkà méje tí ó kún, ó yómọ, ó sì dára, ó sì jáde lára igi ọkà kan ṣoṣo.
A gdy usnął, śnił po raz drugi. A oto siedem pełnych i cudnych kłosów wyrastało z jednego źdźbła.
6 Lẹ́yìn wọn ni síírí ọkà méje mìíràn yọ, wọn kò yómọ, afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù.
Oto też siedem kłosów cienkich i wysuszonych od wiatru wschodniego wyrastało za nimi.
7 Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ (ọmọ rẹ̀ kò tóbi) wọ̀nyí sì gbé àwọn tí ó yómọ (ọmọ rẹ̀ tóbi) mì. Nígbà náà ni Farao jí lójú oorun, ó sì rí i pé àlá ni.
I te cienkie kłosy pożarły siedem pięknych i pełnych kłosów. Wtedy faraon się obudził, a [był] to sen.
8 Ní òwúrọ̀, ọkàn rẹ̀ dàrú, nítorí náà, ó ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn onídán àti ọ̀mọ̀ran ilẹ̀ Ejibiti. Farao rọ́ àlá rẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n kò rí ọ̀kan nínú wọn tí ó le sọ ìtumọ̀ àlá náà fún un.
A gdy nastał ranek, był zaniepokojony w duchu i kazał wezwać wszystkich wróżbitów i mędrców Egiptu. I opowiedział im faraon swoje sny, ale nie było nikogo, kto by potrafił je faraonowi wytłumaczyć.
9 Nígbà náà ni olórí agbọ́tí wí fún Farao pé, “Lónìí ni mo rántí ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Wtedy przełożony podczaszych powiedział do faraona: Przypominam [sobie] dziś moje grzechy.
10 Nígbà kan tí Farao bínú sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, tí ó sì fi èmi àti olórí alásè sínú ẹ̀wọ̀n ní ilé olórí ẹ̀ṣọ́.
Faraon rozgniewał się na swoje sługi i oddał mnie pod straż w domu dowódcy straży, mnie i przełożonego piekarzy.
11 Ọ̀kọ̀ọ̀kan wa lá àlá, àlá kọ̀ọ̀kan sì ní ìtumọ̀ tirẹ̀.
Tam jednej nocy śnił się nam sen, mnie i jemu; każdemu śnił się sen według jego wytłumaczenia.
12 Ọmọkùnrin ará Heberu kan tí ó jẹ́ ìránṣẹ́ olórí ẹ̀ṣọ́ wà níbẹ̀ pẹ̀lú wa. A rọ́ àwọn àlá wa fún un, ó sì túmọ̀ wọn fún wa, ó sọ ìtumọ̀ àlá ẹnìkọ̀ọ̀kan fún un.
A był tam z nami młodzieniec, Hebrajczyk, sługa dowódcy straży, któremu opowiedzieliśmy nasze sny, a on wytłumaczył je nam, każdemu według jego snu.
13 Bí ó sì ti túmọ̀ àlá wọ̀nyí náà ni ohun gbogbo rí. A dá mi padà sí ipò mi, a sì so ọkùnrin kejì kọ́ sórí ọ̀wọ̀n.”
I stało się tak, jak nam wytłumaczył: Mnie [faraon] przywrócił na moje miejsce, a tamtego powiesił.
14 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Josẹfu, wọn sì mú un wá kíákíá láti inú ìhámọ́. Nígbà tí ó fá irun rẹ̀, tí ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó wá síwájú Farao.
Faraon kazał więc wezwać Józefa i prędko go wyprowadzono z więzienia. Ostrzygł się, zmienił szaty i przyszedł do faraona.
15 Farao wí fún Josẹfu, “Mo lá àlá kan, kò sì sí ẹni tí o le è túmọ̀ rẹ̀. Ṣùgbọ́n mo ti gbọ́ nípa rẹ pé bí o bá ti gbọ́ àlá, o le è túmọ̀ rẹ̀.”
I faraon powiedział do Józefa: Śnił mi się sen, a nie ma nikogo, kto potrafi mi go wytłumaczyć. Ale słyszałem, jak mówiono o tobie, że gdy usłyszysz sen, umiesz go wytłumaczyć.
16 Josẹfu dá Farao ní ohùn pé, “Kì í ṣe agbára mi, ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ni yóò fi ìdáhùn àlàáfíà fún Farao ní ìtumọ̀ àlá náà.”
Józef odpowiedział faraonowi: To nie ja, ale Bóg da faraonowi szczęśliwą odpowiedź.
17 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Ní inú àlá mi, mo dúró ni etí bèbè odò Naili,
Faraon powiedział więc do Józefa: Oto w moim śnie stałem na brzegu rzeki.
18 sì kíyèsi i, màlúù méje tí ó sanra tí o sì lẹ́wà jáde wá, wọ́n sì ń jẹ koríko ní tòsí ibẹ̀.
A z rzeki wychodziło siedem tłustych i pięknych krów i pasły się na łące.
19 Lẹ́yìn wọn, màlúù méje mìíràn jáde wá, wọ́n rù hángógó, wọn kò sì lẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ tí n kò tí ì rí irú màlúù tí ó ṣe àìlẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ rí ní ilẹ̀ Ejibiti.
Za nimi zaś wychodziło siedem innych krów, nędznych, szpetnych i chudych; w całej ziemi Egiptu nie widziałem tak brzydkich.
20 Àwọn màlúù tí ó rù tí kò sì lẹ́wà sì jẹ àwọn màlúù tí ó sanra tí ó kọ́ jáde nínú odò.
I chude i szpetne krowy pożarły siedem pierwszych tłustych krów.
21 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ́ wọ́n tan, kò sì ẹni tí ó le mọ̀ pé wọ́n jẹ ohunkóhun, nítorí wọn kò sanra sí i, wọn sì bùrẹ́wà síbẹ̀. Nígbà náà ni mo tají.
A choć je zjadły, nie było widać, że zjadły, [ale] były szpetne jak i przedtem. I obudziłem się.
22 “Ní ojú àlá mi, mo tún rí síírí ọkà méje tí ó yó ọmọ tí ó sì dára, wọ́n jáde láti ara igi ọkà kan.
Potem widziałem we śnie, jak oto siedem kłosów, pełnych i dorodnych, wyrastało z jednego źdźbła.
23 Lẹ́yìn wọn, àwọn méje mìíràn yọ jáde, tí kò yó ọmọ bẹ́ẹ̀ ni afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù tán.
A za nimi wyrastało siedem kłosów suchych, cienkich i wyschniętych od wschodniego wiatru.
24 Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ sì gbé àwọn méje tí ó dára wọ̀nyí mì. Mo sọ àlá yìí fún àwọn onídán mi, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó le túmọ̀ rẹ̀ fún mi.”
I te cienkie kłosy pożarły tych siedem dorodnych kłosów. I opowiedziałem [to] wróżbitom, ale nie było nikogo, kto by potrafił mi to wytłumaczyć.
25 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún Farao, “Ìtumọ̀ kan náà ni àwọn àlá méjèèjì ní. Ọlọ́run fi ohun tí ó fẹ́ ṣe hàn fún Farao.
Wtedy Józef powiedział do faraona: Sen faraona jest jeden – Bóg oznajmił faraonowi, co uczyni.
26 Àwọn màlúù méje ti ó dára jẹ́ ọdún méje, síírí ọkà méje tí ó dára náà sì jẹ́ ọdún méje: ọ̀kan ṣoṣo ni wọn, àlá kan náà ni.
Siedem pięknych krów to siedem lat, a siedem dorodnych kłosów to [też] siedem lat. Jest to jeden sen.
27 Àwọn màlúù méje tí kò sanra, tí kò sì rẹwà tí ó jáde gbẹ̀yìn jẹ́ ọdún méje, bẹ́ẹ̀ náà ni síírí ọkà méje tí kò dára, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ dànù tan, wọn jẹ́ ọdún méje tí ìyàn yóò fi mú.
Siedem zaś chudych i szpetnych krów, które wychodziły za nimi, to siedem lat; a siedem pustych kłosów i wyschniętych od wschodniego wiatru to będzie siedem lat głodu.
28 “Bí mo ti wí fún Farao ní ìṣáájú náà ni: Ọlọ́run fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ han Farao.
[A] oto, co powiedziałem faraonowi: Bóg ukazał faraonowi, co uczyni.
29 Ọdún méje tí oúnjẹ yóò pọ̀ yanturu ń bọ̀ wà ní Ejibiti.
Nadchodzi siedem lat wielkiej obfitości w całej ziemi Egiptu.
30 Ṣùgbọ́n ọdún méje mìíràn tí ìyàn yóò mú ń bọ̀, nígbà náà ni a ó tilẹ̀ gbàgbé gbogbo ọ̀pọ̀ ní ilẹ̀ Ejibiti, ìyàn yóò sì run gbogbo ilẹ̀ náà.
A po nich nastąpi siedem lat głodu i cała obfitość ziemi Egiptu pójdzie w zapomnienie, i głód wytrawi ziemię;
31 A kò ní rántí àsìkò ọ̀pọ̀ oúnjẹ yanturu náà mọ́ nítorí pé ìyàn tí yóò tẹ̀lé e yóò pọ̀ púpọ̀.
Tak że obfitość ziemi nie będzie znana z powodu przyszłego głodu, bo będzie bardzo ciężki.
32 Ìdí tí Ọlọ́run fi fi àlá náà han fún Farao ní ọ̀nà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni pé, Ọlọ́run ti pinnu pé yóò ṣẹlẹ̀ bẹ́ẹ̀ dandan, àti pé kò ni pẹ́ tí Ọlọ́run yóò fi ṣe é.
A skoro sen śnił się faraonowi dwukrotnie, [oznacza] to, że ta rzecz jest postanowiona przez Boga i Bóg śpieszy ją wykonać.
33 “Ìmọ̀ràn mi ni wí pé, jẹ́ kí Farao wá ọlọ́gbọ́n ènìyàn kan ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ó sì fi ṣe alákòóso iṣẹ́ àgbẹ̀ ilẹ̀ Ejibiti.
Teraz więc niech faraon znajdzie roztropnego i mądrego człowieka i postawi go nad ziemią Egiptu.
34 Kí Farao sì yan àwọn alábojútó láti máa gba ìdámárùn-ún ìkórè oko ilẹ̀ Ejibiti ní àsìkò ọdún méje ọ̀pọ̀.
Niech faraon tak postąpi i ustanowi urzędników nad ziemią, i zbierze piątą część [plonów] ziemi Egiptu przez [te] siedem lat obfitości.
35 Kí wọn kó gbogbo oúnjẹ ilẹ̀ náà ni àwọn ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, kí wọn sì kó àwọn ọkà tí wọn jẹ ṣẹ́kù pamọ́ lábẹ́ àṣẹ Farao. Kí a kó wọn pamọ́ ni àwọn ìlú fún jíjẹ.
Niech zbierają wszelką żywność w tych nadchodzących dobrych latach i zgromadzą zboża do dyspozycji faraona, i niech przechowują żywność w miastach.
36 Kí wọn kó oúnjẹ náà pamọ́ fún orílẹ̀-èdè yìí, kí a ba à le lò ó ni ọdún méje tí ìyàn yóò fi jà ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ìyàn náà má ba à pa orílẹ̀-èdè yìí run.”
Żywność ta będzie zapasem dla ziemi na te siedem lat głodu, które będą w ziemi Egiptu, aby ziemia nie niszczała od głodu.
37 Èrò náà sì dára lójú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀.
I podobało się to faraonowi i wszystkim jego sługom.
38 Farao sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ a le rí ẹnikẹ́ni bi ọkùnrin yìí, nínú ẹni tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń gbé?”
Faraon zapytał więc swoje sługi: Czy znajdziemy człowieka mu podobnego, w którym jest Duch Boży?
39 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu, “Níwọ́n bí Ọlọ́run ti fi gbogbo èyí hàn ọ́, kò sí ẹni náà tí ó gbọ́n tí ó sì mọ̀ràn bí i tìrẹ ní ilẹ̀ Ejibiti yìí,
Potem faraon powiedział do Józefa: Skoro Bóg oznajmił ci to wszystko, nie ma żadnego tak rozumnego i mądrego jak ty.
40 ìwọ yóò ṣe àkóso ààfin mi gbogbo àwọn ènìyàn gbọdọ̀ tẹríba fún àṣẹ ẹ̀ rẹ. Ìtẹ́ mi nìkan ni èmi yóò fi jù ọ́ lọ.”
Ty będziesz nad moim domem, a cały mój lud będzie postępować według rozkazu twoich ust. Tylko tronem będę większy od ciebie.
41 Farao wí fún Josẹfu pé, “Mo fi ọ́ ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Faraon powiedział jeszcze do Józefa: Oto ustanowiłem cię nad całą ziemią Egiptu.
42 Farao sì bọ́ òrùka èdìdì ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi wọ Josẹfu ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ó sì fi ẹ̀gbà tí ó dára sí i lọ́rùn.
Zdjął więc faraon pierścień z ręki i włożył go na rękę Józefa, oblekł go też w szatę bisiorową, a na szyję włożył mu złoty łańcuch.
43 Ó sì mú un kí ó gun kẹ̀kẹ́-ẹṣin bí igbákejì ara rẹ̀, àwọn ènìyàn sì ń pariwo níwájú rẹ̀ pé, “Ẹ yàgò lọ́nà.” Báyìí ni ó sì fi ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
I kazał go wozić na swoim drugim rydwanie, i wołano przed nim: Na kolana! I ustanowił go [rządcą] całej ziemi Egiptu.
44 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Èmi ni Farao. Ṣùgbọ́n láìsí àṣẹ rẹ, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ ṣe ohunkóhun ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Potem faraon powiedział do Józefa: Ja jestem faraonem, a bez twego pozwolenia nikt na całej ziemi Egiptu nie podniesie ani ręki, ani nogi.
45 Farao sì sọ Josẹfu ní orúkọ yìí Safenati-Panea (èyí tí ó túmọ̀ sí ẹni tí ó ni agbára ikú àti ìyè ní ìkáwọ́ bí òrìṣà). Ó sì fun un ní Asenati ọmọ Potifẹra, alábojútó òrìṣà Oni, gẹ́gẹ́ bí aya. Josẹfu sì rin gbogbo ilẹ̀ Ejibiti já.
I faraon nadał Józefowi imię Safnat Paneach, i dał mu za żonę Asenat, córkę Poti-Fery, kapłana z On. I Józef wyjechał na [całą] ziemię Egiptu.
46 Ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni Josẹfu nígbà tí ó wọ iṣẹ́ Farao ọba Ejibiti. Josẹfu sì jáde kúrò níwájú Farao, ó sì ṣe ìbẹ̀wò káàkiri gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Józef miał trzydzieści lat, gdy stanął przed faraonem, królem Egiptu. Potem Józef odszedł od faraona i objechał całą ziemię Egiptu.
47 Ní ọdún méje ọ̀pọ̀, ilẹ̀ náà so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
A przez tych siedem urodzajnych lat ziemia rodziła obficie.
48 Josẹfu kó gbogbo oúnjẹ tí a pèsè ni ilẹ̀ Ejibiti ní ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, ó sì pa wọ́n mọ́ sí àwọn ìlú. Ní ìlú kọ̀ọ̀kan ni ó kó gbogbo oúnjẹ tí wọ́n gbìn ní àyíká ìlú wọn sí.
I [Józef] zgromadził całą żywność tych siedmiu lat, która była w ziemi Egiptu, i składał żywność w miastach. Składał w miastach urodzajne plony z otaczających je pól.
49 Josẹfu pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà mọ́ bí iyanrìn Òkun; ó pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí kò ṣe àkọsílẹ̀ mọ́ nítorí, ó tayọ kíkà.
Józef więc nagromadził zboża tak wiele jak piasku morskiego, aż przestano je liczyć, bo [było] go bez liku.
50 Kí ó tó di pé ọdún ìyàn dé, Asenati ọmọ Potifẹra alábojútó Oni bí ọmọkùnrin méjì fún Josẹfu.
A zanim nastały lata głodu, Józefowi urodzili się dwaj synowie, których mu urodziła Asenat, córka Poti-Fery, kapłana z On.
51 Josẹfu sọ orúkọ àkọ́bí rẹ̀ ni Manase, ó sì wí pé, “Nítorí tí Ọlọ́run ti mú mi gbàgbé gbogbo ìdààmú mi àti gbogbo ilé baba mi.”
Józef nadał pierworodnemu imię Manasses, gdyż [mówił]: Bóg dał mi zapomnieć o całej mojej udręce i o całym domu mego ojca.
52 Ó sì sọ orúkọ èkejì ní Efraimu, ó sì wí pé, “Nítorí pé Ọlọ́run fún mi ní ọmọ ní ilẹ̀ ìpọ́njú mi.”
A drugiemu nadał imię Efraim, [gdyż] mówił: Bóg rozmnożył mnie w ziemi mego utrapienia.
53 Ọdún méje ọ̀pọ̀ oúnjẹ sì wá sí òpin ní ilẹ̀ Ejibiti,
I skończyło się siedem lat obfitości, która była w ziemi Egiptu.
54 ọdún méje ìyàn sì bẹ̀rẹ̀, bí Josẹfu ti wí gan an. Ìyàn sì mú ní gbogbo ilẹ̀ tókù, ṣùgbọ́n oúnjẹ wà ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
I nadeszło siedem lat głodu, tak jak Józef przepowiedział. I głód był we wszystkich krainach, ale w całej ziemi Egiptu był chleb.
55 Nígbà tí àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí ní rí ipá ìyàn náà, wọ́n kígbe sí Farao. Nígbà náà ni Farao wí fún wọn pé, “Ẹ lọ bá Josẹfu, ẹ ṣe ohun tí ó bá wí fún un yín.”
Gdy [jednak] na całej ziemi Egiptu był głód, lud wołał do faraona o chleb. I faraon powiedział wszystkim Egipcjanom: Idźcie do Józefa, a co wam powie, zróbcie.
56 Nígbà tí ìyàn sì ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ náà, Josẹfu ṣí inú àká, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ta ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ìyàn náà mú gan an ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
I na całej ziemi był głód. Józef otworzył więc wszystkie spichlerze, w których [było zboże], i sprzedawał Egipcjanom, bo głód wzmógł się w ziemi Egiptu.
57 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè sì ń wá sí Ejibiti láti ra oúnjẹ lọ́wọ́ Josẹfu, nítorí ìyàn náà pọ̀ gidigidi káàkiri gbogbo ayé.
I ze wszystkich krajów przyjeżdżano do Egiptu, by kupować [żywność] od Józefa, bo wzmógł się głód na całej ziemi.