< Genesis 41 >

1 Nígbà tí odindi ọdún méjì sì ti kọjá, Farao lá àlá: ó rí ara rẹ̀ tó dúró ní etí odò Naili.
Kane higni ariyo osekadho, Farao noleko lekni ochungʼ e bath aora Nael,
2 Nígbà náà ni màlúù méje jáde láti inú odò, wọ́n dára láti wò, wọ́n sì sanra, wọ́n sì ń jẹ koríko.
kendo noneno dhok abiriyo mabeyo machwe kawuok ei aora kakwayo e kind odundu.
3 Lẹ́yìn àwọn wọ̀nyí, ni àwọn màlúù méje mìíràn tí kò lẹ́wà tí ó sì rù jáde wá láti inú odò Naili, wọ́n sì dúró ti àwọn méje tí ó sanra tí ó wà ní bèbè odò náà.
Bangʼ mano noneno dhok abiriyo mamoko maricho modhero kowuok ei aora Nael, kendo kochungʼ e bath mago mabeyo.
4 Àwọn màlúù tí ó rù, tí kò sì lẹ́wà sì gbé àwọn tí ó lẹ́wà tí ó sanra jẹ. Nígbà náà ni Farao jí.
To dhok maricho kendo modherogo nochamo dhok mabeyo machwego. Eka Farao nochiewo.
5 Ó sì tún padà sùn, ó sì lá àlá mìíràn: ó rí síírí ọkà méje tí ó kún, ó yómọ, ó sì dára, ó sì jáde lára igi ọkà kan ṣoṣo.
Nindo nochako otere mi ochako oleko lek machielo ni noneno wiye abiriyo mag cham machwe kendo beyo kochiek e tiangʼ achiel.
6 Lẹ́yìn wọn ni síírí ọkà méje mìíràn yọ, wọn kò yómọ, afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù.
Bangʼ mano wi cham moko abiriyo motho kendo ma yamb oro otwoyo nowuok ewi tiangʼno.
7 Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ (ọmọ rẹ̀ kò tóbi) wọ̀nyí sì gbé àwọn tí ó yómọ (ọmọ rẹ̀ tóbi) mì. Nígbà náà ni Farao jí lójú oorun, ó sì rí i pé àlá ni.
Wiye cham abiriyo mothogo nomwonyo wiye cham abiriyo machwe ka. Eka Farao nochiewo, moyudo ni en mana lek.
8 Ní òwúrọ̀, ọkàn rẹ̀ dàrú, nítorí náà, ó ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn onídán àti ọ̀mọ̀ran ilẹ̀ Ejibiti. Farao rọ́ àlá rẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n kò rí ọ̀kan nínú wọn tí ó le sọ ìtumọ̀ àlá náà fún un.
Kinyne gokinyi pache nochandore, kuom mano nooro mondo oluongne ajuoke duto kod jorieko duto mag Misri. Farao nonyisogi lekne, to onge ngʼato angʼata mane nyalo lokone tiend lekgo.
9 Nígbà náà ni olórí agbọ́tí wí fún Farao pé, “Lónìí ni mo rántí ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Eka jatend jogam divai nowacho ne Farao niya, “Aparo kethona kawuono.
10 Nígbà kan tí Farao bínú sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, tí ó sì fi èmi àti olórí alásè sínú ẹ̀wọ̀n ní ilé olórí ẹ̀ṣọ́.
Chiengʼ moro kane iyi owangʼ kod wan ma jotichni, kendo ne irwakowa e od twech kaachiel gi jatend joted makati e od jatend askeche.
11 Ọ̀kọ̀ọ̀kan wa lá àlá, àlá kọ̀ọ̀kan sì ní ìtumọ̀ tirẹ̀.
Waduto ne waleko lek otieno moro achiel, kendo lek ka lek ne nigi tiende.
12 Ọmọkùnrin ará Heberu kan tí ó jẹ́ ìránṣẹ́ olórí ẹ̀ṣọ́ wà níbẹ̀ pẹ̀lú wa. A rọ́ àwọn àlá wa fún un, ó sì túmọ̀ wọn fún wa, ó sọ ìtumọ̀ àlá ẹnìkọ̀ọ̀kan fún un.
To ne nitie ja-Hibrania moro matin kodwa, jatich jaduongʼ askeche. Ne wanyise lekwa, kendo nolokonwa tiendgi, ka omiyo ngʼato ka ngʼato tiend lekne.
13 Bí ó sì ti túmọ̀ àlá wọ̀nyí náà ni ohun gbogbo rí. A dá mi padà sí ipò mi, a sì so ọkùnrin kejì kọ́ sórí ọ̀wọ̀n.”
Kendo notimore mana kaka ne olokonwa tiendgi kama: An niduoka e tija, to jatend joted makati nolierie yath.”
14 Nítorí náà Farao ránṣẹ́ pe Josẹfu, wọn sì mú un wá kíákíá láti inú ìhámọ́. Nígbà tí ó fá irun rẹ̀, tí ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó wá síwájú Farao.
Kane Farao owinjo kamano nooro wach mondo okelne Josef, kendo nokel Josef mapiyo nono koa e od twech. Kane Josef oselielo yie wiye kendo oloko lepe, nobiro e nyim Farao.
15 Farao wí fún Josẹfu, “Mo lá àlá kan, kò sì sí ẹni tí o le è túmọ̀ rẹ̀. Ṣùgbọ́n mo ti gbọ́ nípa rẹ pé bí o bá ti gbọ́ àlá, o le è túmọ̀ rẹ̀.”
Farao nowacho ne Josef niya, “Nende aleko lek, kendo onge ngʼama nyalo loko tiende. To asewinjo ka iwacho ni ka iwinjo lek to inyalo loko tiend lek moro amora.”
16 Josẹfu dá Farao ní ohùn pé, “Kì í ṣe agbára mi, ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ni yóò fi ìdáhùn àlàáfíà fún Farao ní ìtumọ̀ àlá náà.”
Josef nodwoko Farao niya, “Ok anyal time, to Nyasaye biro dwoki kaka odwaro.”
17 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Ní inú àlá mi, mo dúró ni etí bèbè odò Naili,
Eka Farao nowacho ne Josef niya, “Ne aleko nine achungʼ e bath aora Nael,
18 sì kíyèsi i, màlúù méje tí ó sanra tí o sì lẹ́wà jáde wá, wọ́n sì ń jẹ koríko ní tòsí ibẹ̀.
kendo dhok abiriyo mabeyo kendo machwe nowuok ei aora ka gikwayo e kind odundu.
19 Lẹ́yìn wọn, màlúù méje mìíràn jáde wá, wọ́n rù hángógó, wọn kò sì lẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ tí n kò tí ì rí irú màlúù tí ó ṣe àìlẹ́wà tó bẹ́ẹ̀ rí ní ilẹ̀ Ejibiti.
Bangʼ-gi dhok abiriyo mamoko maricho kendo odhero nowuok. Ne pok anenoe dhok maricho kendo modhero kamano e piny Misri duto.
20 Àwọn màlúù tí ó rù tí kò sì lẹ́wà sì jẹ àwọn màlúù tí ó sanra tí ó kọ́ jáde nínú odò.
Dhok abiriyo maricho kendo odherogo nochamo dhok abiriyo machwe kendo mabeyo mane okwongo wuok.
21 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ́ wọ́n tan, kò sì ẹni tí ó le mọ̀ pé wọ́n jẹ ohunkóhun, nítorí wọn kò sanra sí i, wọn sì bùrẹ́wà síbẹ̀. Nígbà náà ni mo tají.
To kata bangʼ kane gisechamogi, to onge ngʼato angʼata mane nyalo yie ni gin ema gichamo dhogo; ne ginenore modhero moloyo kaka ne gin mokwongo. Bangʼe ne achiewo.
22 “Ní ojú àlá mi, mo tún rí síírí ọkà méje tí ó yó ọmọ tí ó sì dára, wọ́n jáde láti ara igi ọkà kan.
“Nachako aneno e lek wiye cham abiriyo mochiek maber kadongʼ e tiangʼ achiel.
23 Lẹ́yìn wọn, àwọn méje mìíràn yọ jáde, tí kò yó ọmọ bẹ́ẹ̀ ni afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù tán.
Bangʼ-gi ne achako aneno wi cham abiriyo motho kendo yamb oro otwoyo.
24 Àwọn síírí ọkà méje tí kò yómọ sì gbé àwọn méje tí ó dára wọ̀nyí mì. Mo sọ àlá yìí fún àwọn onídán mi, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó le túmọ̀ rẹ̀ fún mi.”
Wiye cham abiriyo mothogo nomwonyo wiye cham abiriyo mochiek. Ne anyiso ajuoke, to onge ngʼato mane nyalo lokona tiendgi.”
25 Nígbà náà ni Josẹfu wí fún Farao, “Ìtumọ̀ kan náà ni àwọn àlá méjèèjì ní. Ọlọ́run fi ohun tí ó fẹ́ ṣe hàn fún Farao.
Eka Josef nowacho ne Farao niya, “Leknigo tiendgi achiel kendo gichalre. Nyasaye osenyiso gima oikore timo.
26 Àwọn màlúù méje ti ó dára jẹ́ ọdún méje, síírí ọkà méje tí ó dára náà sì jẹ́ ọdún méje: ọ̀kan ṣoṣo ni wọn, àlá kan náà ni.
Dhok abiriyo mabeyogo gin higni abiriyo, kendo wiye cham abiriyo mochiek mabeyogo bende gin higni abiriyo; giduto gin lek achiel kendo nyiso wach achiel.
27 Àwọn màlúù méje tí kò sanra, tí kò sì rẹwà tí ó jáde gbẹ̀yìn jẹ́ ọdún méje, bẹ́ẹ̀ náà ni síírí ọkà méje tí kò dára, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ti rẹ̀ dànù tan, wọn jẹ́ ọdún méje tí ìyàn yóò fi mú.
Dhok abiriyo maricho modhero mane obiro bangʼe nyiso higni abiriyo, kendo kamano e kaka wiye cham abiriyo motho ma yamb oro otwoyo; gin higni abiriyo mag kech.
28 “Bí mo ti wí fún Farao ní ìṣáájú náà ni: Ọlọ́run fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ han Farao.
“En mana kaka awachoni ni Nyasaye osenyiso Farao gima obiro timo.
29 Ọdún méje tí oúnjẹ yóò pọ̀ yanturu ń bọ̀ wà ní Ejibiti.
Higni abiriyo biro betie ma piny Misri duto nobedie gi yiengʼo ahinya,
30 Ṣùgbọ́n ọdún méje mìíràn tí ìyàn yóò mú ń bọ̀, nígbà náà ni a ó tilẹ̀ gbàgbé gbogbo ọ̀pọ̀ ní ilẹ̀ Ejibiti, ìyàn yóò sì run gbogbo ilẹ̀ náà.
to bangʼ mano higni abiriyo moko nobedie mag kech kendo wi ji nowil gi higni abiriyo mag yiengʼo e piny Misri, kendo kech noketh piny.
31 A kò ní rántí àsìkò ọ̀pọ̀ oúnjẹ yanturu náà mọ́ nítorí pé ìyàn tí yóò tẹ̀lé e yóò pọ̀ púpọ̀.
Higni abiriyo mag yiengʼo ok nopar, nikech kech mano luweno nobed malich miwuoro.
32 Ìdí tí Ọlọ́run fi fi àlá náà han fún Farao ní ọ̀nà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni pé, Ọlọ́run ti pinnu pé yóò ṣẹlẹ̀ bẹ́ẹ̀ dandan, àti pé kò ni pẹ́ tí Ọlọ́run yóò fi ṣe é.
Gima omiyo lek nobiro ne Farao nyadiriyo en nikech Nyasaye osechano ratiro mar timo kamano. Kendo Nyasaye biro chope mapiyo.
33 “Ìmọ̀ràn mi ni wí pé, jẹ́ kí Farao wá ọlọ́gbọ́n ènìyàn kan ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ó sì fi ṣe alákòóso iṣẹ́ àgbẹ̀ ilẹ̀ Ejibiti.
“Koro mondo Farao oyier ngʼat mariek kendo molony e gik moko duto motimo mondo okete jatend piny Misri.
34 Kí Farao sì yan àwọn alábojútó láti máa gba ìdámárùn-ún ìkórè oko ilẹ̀ Ejibiti ní àsìkò ọdún méje ọ̀pọ̀.
Farao nyaka ket jotend gwenge e piny Misri duto mondo ochoki achiel kuom abich mag chamb Misri kuom higni abiriyo mag yiengʼo.
35 Kí wọn kó gbogbo oúnjẹ ilẹ̀ náà ni àwọn ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, kí wọn sì kó àwọn ọkà tí wọn jẹ ṣẹ́kù pamọ́ lábẹ́ àṣẹ Farao. Kí a kó wọn pamọ́ ni àwọn ìlú fún jíjẹ.
Nyaka gichok kendo gikan e mier madongo chiemo duto moyudi e higni abiriyo mag yiengʼogo e bwo chik Farao.
36 Kí wọn kó oúnjẹ náà pamọ́ fún orílẹ̀-èdè yìí, kí a ba à le lò ó ni ọdún méje tí ìyàn yóò fi jà ní ilẹ̀ Ejibiti, kí ìyàn náà má ba à pa orílẹ̀-èdè yìí run.”
Cham-go onego okan e kuonde keno mag pinyni, mondo obi otigo e higni abiriyo mag kech mabiro mako piny Misri, mondo mi kik kech keth piny.”
37 Èrò náà sì dára lójú Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀.
Parono nonenore maber ni Farao kod jodonge duto.
38 Farao sì bi wọ́n pé, “Ǹjẹ́ a le rí ẹnikẹ́ni bi ọkùnrin yìí, nínú ẹni tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń gbé?”
Kuom mano Farao nopenjo jodonge niya, “Bende wanyalo yudo ngʼato moro machal gi ngʼatni, ma Roho mar Nyasaye ni kuome?”
39 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu, “Níwọ́n bí Ọlọ́run ti fi gbogbo èyí hàn ọ́, kò sí ẹni náà tí ó gbọ́n tí ó sì mọ̀ràn bí i tìrẹ ní ilẹ̀ Ejibiti yìí,
Eka Farao nowacho ne Josef niya, “Nikech Nyasaye osenyisi wechegi duto, onge ngʼat man-gi ngʼeyo matut kendo riek ka in.
40 ìwọ yóò ṣe àkóso ààfin mi gbogbo àwọn ènìyàn gbọdọ̀ tẹríba fún àṣẹ ẹ̀ rẹ. Ìtẹ́ mi nìkan ni èmi yóò fi jù ọ́ lọ.”
Abiro keti jatend od ruoth kendo joga duto biro winjo chikni kendo kom duongʼ mar ruoth ema nobed maduongʼ moloyi.”
41 Farao wí fún Josẹfu pé, “Mo fi ọ́ ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
Kuom mano Farao nowacho ne Josef niya, “Ne, koro aseketi jatend piny Misri duto.”
42 Farao sì bọ́ òrùka èdìdì ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi wọ Josẹfu ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ó sì fi ẹ̀gbà tí ó dára sí i lọ́rùn.
Eka Farao nogolo tere mar loch e lwete morwako e lwet Josef. Ne orwako ne Josef law mayom mar duongʼ miluongo ni bafta kendo orwako ne tigo mar dhahabu e ngʼute.
43 Ó sì mú un kí ó gun kẹ̀kẹ́-ẹṣin bí igbákejì ara rẹ̀, àwọn ènìyàn sì ń pariwo níwájú rẹ̀ pé, “Ẹ yàgò lọ́nà.” Báyìí ni ó sì fi ṣe alábojútó gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Nomiyo oidho gach ruoth mar ariyo mar loch, kendo joritne nogoyo koko nyime kawacho niya, “Yawneuru e yo!” Kuom mano Josef noket jatend piny Misri duto.
44 Nígbà náà ni Farao wí fún Josẹfu pé, “Èmi ni Farao. Ṣùgbọ́n láìsí àṣẹ rẹ, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ ṣe ohunkóhun ní ilẹ̀ Ejibiti.”
Eka Farao nomiyo Josef teko kowachone niya, “An e ruoth, kendo onge ngʼama notim gimoro kata nodonji e piny Misri ma ok in ema iyiene.”
45 Farao sì sọ Josẹfu ní orúkọ yìí Safenati-Panea (èyí tí ó túmọ̀ sí ẹni tí ó ni agbára ikú àti ìyè ní ìkáwọ́ bí òrìṣà). Ó sì fun un ní Asenati ọmọ Potifẹra, alábojútó òrìṣà Oni, gẹ́gẹ́ bí aya. Josẹfu sì rin gbogbo ilẹ̀ Ejibiti já.
Farao nochako Josef ni Zafenath-Panea kendo nomiye Asenath nyar Potifera jadolo mar On (ma nyinge machielo en Eliopolis), mondo obed chiege. Kendo Josef nowuotho e piny Misri duto.
46 Ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni Josẹfu nígbà tí ó wọ iṣẹ́ Farao ọba Ejibiti. Josẹfu sì jáde kúrò níwájú Farao, ó sì ṣe ìbẹ̀wò káàkiri gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Josef ne en ja-higni piero adek kane ochako tich mane Farao ruodh Misri omiye. Kendo Josef nowuok ir Farao mowuotho e piny Misri duto.
47 Ní ọdún méje ọ̀pọ̀, ilẹ̀ náà so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
E kinde mag higni abiriyo mag yiengʼo, piny nochiek ahinya.
48 Josẹfu kó gbogbo oúnjẹ tí a pèsè ni ilẹ̀ Ejibiti ní ọdún méje ọ̀pọ̀ yìí, ó sì pa wọ́n mọ́ sí àwọn ìlú. Ní ìlú kọ̀ọ̀kan ni ó kó gbogbo oúnjẹ tí wọ́n gbìn ní àyíká ìlú wọn sí.
Josef nochoko chiemo duto mane ochiek e higni abiriyo mag yiengʼo e piny Misri kendo okanogi e mier madongo. Nokano cham mochiek e puothe molworogi e dala ka dala maduongʼ.
49 Josẹfu pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà mọ́ bí iyanrìn Òkun; ó pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí kò ṣe àkọsílẹ̀ mọ́ nítorí, ó tayọ kíkà.
Josef nokano cham mathoth mana ka kuoyo mane dho nam; ne githoth mane ok onyal kwano nikech negikadho akwana.
50 Kí ó tó di pé ọdún ìyàn dé, Asenati ọmọ Potifẹra alábojútó Oni bí ọmọkùnrin méjì fún Josẹfu.
Kane pok higni mag kech ochopo, Asenath nyar Potifera ma jadolo mar On nonywolone Josef yawuowi ariyo.
51 Josẹfu sọ orúkọ àkọ́bí rẹ̀ ni Manase, ó sì wí pé, “Nítorí tí Ọlọ́run ti mú mi gbàgbé gbogbo ìdààmú mi àti gbogbo ilé baba mi.”
Josef nochako wuode makayo ni Manase kendo nowacho niya, “Ma en nikech Nyasaye osemiyo wiya owil gi chandruokna duto kod jood wuora duto.”
52 Ó sì sọ orúkọ èkejì ní Efraimu, ó sì wí pé, “Nítorí pé Ọlọ́run fún mi ní ọmọ ní ilẹ̀ ìpọ́njú mi.”
Wuowi mar ariyo nochako ni Efraim kendo nowacho niya, “Ma en nikech Nyasaye osemiyo anya e piny mar chandruokna.”
53 Ọdún méje ọ̀pọ̀ oúnjẹ sì wá sí òpin ní ilẹ̀ Ejibiti,
Higni abiriyo mag yiengʼo e piny Misri norumo,
54 ọdún méje ìyàn sì bẹ̀rẹ̀, bí Josẹfu ti wí gan an. Ìyàn sì mú ní gbogbo ilẹ̀ tókù, ṣùgbọ́n oúnjẹ wà ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
kendo higni abiriyo mag kech nochakore, mana kaka Josef nosewacho. Ne nitie kech e pinje mamoko, to piny Misri duto ne nitie chiemo.
55 Nígbà tí àwọn ará Ejibiti bẹ̀rẹ̀ sí ní rí ipá ìyàn náà, wọ́n kígbe sí Farao. Nígbà náà ni Farao wí fún wọn pé, “Ẹ lọ bá Josẹfu, ẹ ṣe ohun tí ó bá wí fún un yín.”
Ka kech nodonjo e piny Misri duto, ji noywak ne Farao mondo omigi chiemo. Eka Farao nonyiso jo-Misri duto niya, “Dhiuru ir Josef kendo utim gima owachonu.”
56 Nígbà tí ìyàn sì ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ náà, Josẹfu ṣí inú àká, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ta ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ìyàn náà mú gan an ní gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.
Kane kech koro oselandore e piny duto, Josef noyawo deche duto kendo nouso cham ne jo-Misri, nikech kech ne lich ahinya e pinyno Misri duto.
57 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè sì ń wá sí Ejibiti láti ra oúnjẹ lọ́wọ́ Josẹfu, nítorí ìyàn náà pọ̀ gidigidi káàkiri gbogbo ayé.
Kendo pinje duto nobiro Misri mondo ongʼiew chiemo kuom Josef, nikech kech ne ngʼeny ahinya e piny mangima.

< Genesis 41 >