< Genesis 40 >

1 Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí, ni agbọ́tí ọba àti alásè rẹ̀ ṣẹ̀ ọba Ejibiti, olúwa wọn.
Bu ixlardin keyin Misir padixaⱨining saⱪiysi wǝ bax nawiyi Misir padixaⱨining zitiƣa tegip gunaⱨkar bolup ⱪaldi.
2 Farao sì bínú sí méjì nínú àwọn ìjòyè rẹ̀, olórí agbọ́tí àti olórí alásè,
Xuning bilǝn Pirǝwn uning bu ikki mǝnsǝpdariƣa, yǝni bax saⱪiy wǝ bax nawayƣa ƣǝzǝplinip,
3 Ó sì fi wọ́n sí ìhámọ́ ní ilé olórí ẹ̀ṣọ́, ní inú ẹ̀wọ̀n ibi tí Josẹfu pẹ̀lú wà.
ularni pasiban bexining sariyiƣa, Yüsüp solaⱪliⱪ munarliⱪ zindanƣa solap ⱪoydi.
4 Olórí ẹ̀ṣọ́ sì yan Josẹfu láti máa ṣe ìránṣẹ́ wọn. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wà ní ìhámọ́ fún ìgbà díẹ̀.
Pasiban bexi Yüsüpni ularning hizmitidǝ bolup ularni kütüxkǝ tǝyinlidi. Ular solaⱪta birnǝqqǝ kün yetip ⱪaldi.
5 Ni ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn ọkùnrin méjèèjì náà—olórí agbọ́tí àti olórí alásè ọba Ejibiti, tí a dè sínú túbú, lá àlá ní òru kan náà, àlá kọ̀ọ̀kan sì ní ìtumọ̀ tirẹ̀.
Ular ikkisi — Misir padixaⱨining saⱪiysi wǝ nawiyi gundihanida solaⱪliⱪ turƣan bir keqidǝ qüx kɵrdi. Ⱨǝrbirining qüxining ɵzigǝ has tǝbiri bar idi.
6 Nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ wọn ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó ṣe àkíyèsí pé, inú wọn kò dùn.
Ətisi ǝtigǝndǝ, Yüsüp ularning ⱪexiƣa kiriwidi, ularning ƣǝmkin olturƣinini kɵrdi;
7 Ó sì bi àwọn ìjòyè Farao tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìhámọ́, nínú ilé olúwa rẹ̀ léèrè pé, “Èéṣe tí ojú yín fi fàro bẹ́ẹ̀ ní òní, tí inú yín kò sì dùn?”
xunga u ɵzi bilǝn billǝ hojisining sariyida solaⱪliⱪ yatⱪan Pirǝwnning bu ikki mǝnsǝpdaridin: — Nemixⱪa qirayinglar bügün xunqǝ solƣun? — dǝp soridi.
8 Wọ́n wí pé, “Àwa méjèèjì ni a lá àlá, kò sì sí ẹni tí yóò túmọ̀ rẹ̀.” Josẹfu sì wí fún wọn pé, “Ọlọ́run nìkan ni ó ni ìtumọ̀. Ẹ sọ àwọn àlá yín fún mi.”
Ular uningƣa jawab berip: — Ikkimiz bir qüx kɵrduⱪ; ǝmma qüximizning tǝbirini yexip beridiƣan kixi yoⱪ, dedi. Yüsüp ularƣa: — Qüxkǝ tǝbir berix Hudadin bolidu ǝmǝsmu? Qüxünglarni manga eytip beringlar, — dedi.
9 Olórí agbọ́tí sì ṣọ́ àlá rẹ̀ fún Josẹfu, wí pé, “Ní ojú àlá mi, mo rí àjàrà kan (tí wọn ń fi èso rẹ̀ ṣe wáìnì) níwájú mi,
Buning bilǝn bax saⱪiy Yüsüpkǝ qüxini eytip: — Qüxümdǝ aldimda bir üzüm teli turƣudǝk;
10 mo sì rí ẹ̀ka mẹ́ta lórí àjàrà náà, ó yọ ẹ̀ka tuntun, ó sì tanná, láìpẹ́, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní í ní èso tí ó ti pọ́n.
bu üzüm telining üq xehi bar ikǝn. U bih urup qeqǝklǝp, saplirida uzum pixip ketiptudǝk;
11 Ife Farao sì wà lọ́wọ́ mi, mo sì mú àwọn èso àjàrà náà, mo sì fún un sínú ife Farao, mo sì gbé ife náà fún Farao.”
Pirǝwnning ⱪǝdǝⱨi ⱪolumda ikǝn; mǝn üzümlǝrni elip Pirǝwnning ⱪǝdǝⱨigǝ siⱪip, ⱪǝdǝⱨni uning ⱪoliƣa sunuptimǝn, dedi.
12 Josẹfu wí fún un pé, “Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ. Ẹ̀ka mẹ́ta náà dúró fún ọjọ́ mẹ́ta.
Yüsüp uningƣa jawabǝn: Qüxning tǝbiri xudurki, bu üq xah üq künni kɵrsitidu.
13 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta Farao yóò mú ọ jáde nínú ẹ̀wọ̀n padà sí ipò rẹ, ìwọ yóò sì tún máa gbé ọtí fún un, gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ àtẹ̀yìnwá.
Üq kün iqidǝ Pirǝwn ⱪǝddingni ruslitip, seni mǝnsipinggǝ ⱪaytidin tǝyinlǝydu. Buning bilǝn sǝn burun uningƣa saⱪiy bolƣandǝk Pirǝwnning ⱪǝdǝⱨini uning ⱪoliƣa sunidiƣan bolisǝn.
14 Ṣùgbọ́n nígbà tí ohun gbogbo bá dára fún ọ, rántí mi kí o sì fi àánú hàn sí mi. Dárúkọ mi fún Farao, kí o sì mú mi jáde kúrò ní ìhín.
Lekin ixliring onguxluⱪ bolƣanda meni yadingƣa yǝtküzüp, manga xapaǝt kɵrsitip Pirǝwnning aldida mening toƣramda gǝp ⱪilip, meni bu ɵydin qiⱪartⱪaysǝn.
15 Nítorí á jí mi gbé tà kúrò ní ilẹ̀ àwọn Heberu ni, àti pé níhìn-ín èmi kò ṣe ohunkóhun tí ó fi yẹ kí èmi wà ní ìhámọ́ bí mo ti wà yìí.”
Qünki mǝn ⱨǝⱪiⱪǝtǝn ibraniylarning zeminidin naⱨǝⱪ tutup elip kelindim; bu yǝrdimu meni zindanƣa salƣudǝk bir ix ⱪilmidim, — dedi.
16 Nígbà tí olórí alásè rí i wí pé ìtumọ̀ tí Josẹfu fún àlá náà dára, ó wí fún Josẹfu pé, “Èmi pẹ̀lú lá àlá, mo ru agbọ̀n oúnjẹ mẹ́ta lórí.
Bax naway Yüsüpning xundaⱪ yahxi tǝbir bǝrginini kɵrüp uningƣa mundaⱪ dedi: — Mǝnmu ɵzümni qüxümdǝ kɵrdüm; mana, beximda aⱪ nan bar üq sewǝt bar ikǝn.
17 Nínú agbọ̀n tí ó wà lókè, onírúurú oúnjẹ ló wà níbẹ̀ fún Farao, ṣùgbọ́n àwọn ẹyẹ sì ń ṣà wọ́n jẹ láti inú apẹ̀rẹ̀ náà tí ó wà lórí mi.”
Əng üstünki sewǝttǝ nawaylar Pirǝwngǝ pixurƣan ⱨǝrhil nazunemǝtlǝr bar ikǝn; lekin ⱪuxlar beximdiki u sewǝttiki nǝrsilǝrni yǝp ketiptudǝk, — dedi.
18 Josẹfu dáhùn, “Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ. Agbọ̀n mẹ́ta náà túmọ̀ sí ọjọ́ mẹ́ta.
Yüsüp jawabǝn: — Qüxning tǝbiri xudurki: — Bu üq sewǝt üq künni kɵrsitidu.
19 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta, Farao yóò tú ọ sílẹ̀, yóò sì bẹ́ orí rẹ, yóò sì gbé ara rẹ kọ́ sí orí igi. Àwọn ẹyẹ yóò sì jẹ ara rẹ.”
Üq kün iqidǝ Pirǝwn sening bexingni kesip, jǝsitingni dǝrǝhkǝ asidikǝn. Xuning bilǝn uqarⱪanatlar kelip gɵxüngni yǝydikǝn, — dedi.
20 Ọjọ́ kẹta sì jẹ́ ọjọ́ ìbí Farao, ó sì ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀. Ó sì mú olórí agbọ́tí àti olórí alásè jáde kúrò nínú ẹ̀wọ̀n.
Üqinqi küni xundaⱪ boldiki, Pirǝwnning tuƣulƣan küni bolƣaqⱪa, u ⱨǝmmǝ hizmǝtkarliri üqün bir ziyapǝt ⱪilip bǝrdi, xundaⱪla dǝrwǝⱪǝ hizmǝtkarlirining arisida bax saⱪiyning bexini kɵtürdi wǝ bax nawayning bexini aldi;
21 Ó dá olórí agbọ́tí padà sí ipò tí ó wà tẹ́lẹ̀, kí ó ba à le máa fi ago lé Farao ní ọwọ́,
u bax saⱪiyni ⱪaytidin ɵz mǝnsipigǝ tǝyinlidi; xuning bilǝn u Pirǝwnning ⱪǝdǝⱨini uning ⱪoliƣa ⱪaytidin sunidiƣan boldi.
22 ṣùgbọ́n, ó so olórí alásè kọ́ sórí igi, gẹ́gẹ́ bí Josẹfu ti sọ fún wọn nínú ìtumọ̀ rẹ̀ sí àlá wọn.
Lekin bax nawayni bolsa Yüsüp ularƣa tǝbir bǝrgǝndǝk esiwǝtti.
23 Ṣùgbọ́n, olórí agbọ́tí kò rántí Josẹfu mọ́, kò tilẹ̀ ronú nípa rẹ̀.
Əmma bax saⱪiy Yüsüpni ⱨeq ǝslimǝy, ǝksiqǝ uni untup ⱪaldi.

< Genesis 40 >