< Genesis 40 >
1 Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí, ni agbọ́tí ọba àti alásè rẹ̀ ṣẹ̀ ọba Ejibiti, olúwa wọn.
Después de estas cosas, el siervo principal que tenía el cuidado del vino, y el jefe de los panaderos en la casa de Faraón, hicieron algo contra las órdenes de Faraón;
2 Farao sì bínú sí méjì nínú àwọn ìjòyè rẹ̀, olórí agbọ́tí àti olórí alásè,
Y el Faraón se enojó con sus dos siervos, con el siervo principal y el jefe de la panadería;
3 Ó sì fi wọ́n sí ìhámọ́ ní ilé olórí ẹ̀ṣọ́, ní inú ẹ̀wọ̀n ibi tí Josẹfu pẹ̀lú wà.
Y los puso en la cárcel bajo el cuidado del capitán del ejército, en la misma prisión donde el propio José estaba encerrado.
4 Olórí ẹ̀ṣọ́ sì yan Josẹfu láti máa ṣe ìránṣẹ́ wọn. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wà ní ìhámọ́ fún ìgbà díẹ̀.
y el capitán los puso a cargo de José, e hizo lo que se necesitaba; y estuvieron en prisión por algún tiempo.
5 Ni ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn ọkùnrin méjèèjì náà—olórí agbọ́tí àti olórí alásè ọba Ejibiti, tí a dè sínú túbú, lá àlá ní òru kan náà, àlá kọ̀ọ̀kan sì ní ìtumọ̀ tirẹ̀.
Y estos dos tuvieron un sueño en la misma noche; el principal sirviente de vino y el principal panadero del rey de Egipto, que estaban en la cárcel, los dos tenían sueños con un sentido especial.
6 Nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ wọn ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó ṣe àkíyèsí pé, inú wọn kò dùn.
Y a la mañana cuando José llegó a ellos, vio que estaban tristes.
7 Ó sì bi àwọn ìjòyè Farao tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìhámọ́, nínú ilé olúwa rẹ̀ léèrè pé, “Èéṣe tí ojú yín fi fàro bẹ́ẹ̀ ní òní, tí inú yín kò sì dùn?”
Y dijo a los siervos de Faraón que estaban en la cárcel con él: ¿Por qué te ves tan triste?
8 Wọ́n wí pé, “Àwa méjèèjì ni a lá àlá, kò sì sí ẹni tí yóò túmọ̀ rẹ̀.” Josẹfu sì wí fún wọn pé, “Ọlọ́run nìkan ni ó ni ìtumọ̀. Ẹ sọ àwọn àlá yín fún mi.”
Entonces ellos le dijeron: Hemos tenido un sueño, y nadie puede darnos el sentido. Y José dijo: ¿Acaso el sentido de los sueños no proviene de Dios? ¿Cuál fue tu sueño?
9 Olórí agbọ́tí sì ṣọ́ àlá rẹ̀ fún Josẹfu, wí pé, “Ní ojú àlá mi, mo rí àjàrà kan (tí wọn ń fi èso rẹ̀ ṣe wáìnì) níwájú mi,
Entonces el siervo principal dio a José cuenta de su sueño, y dijo: En mi sueño vi una vid delante de mí;
10 mo sì rí ẹ̀ka mẹ́ta lórí àjàrà náà, ó yọ ẹ̀ka tuntun, ó sì tanná, láìpẹ́, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní í ní èso tí ó ti pọ́n.
Y en la vid tres ramas; y parecía que sacaba brotes y flores, y de ellos salían uvas listas para cortar.
11 Ife Farao sì wà lọ́wọ́ mi, mo sì mú àwọn èso àjàrà náà, mo sì fún un sínú ife Farao, mo sì gbé ife náà fún Farao.”
Y la copa de Faraón estaba en mi mano, y tomé las uvas y las trituré en la copa de Faraón, y puse la copa en la mano de Faraón.
12 Josẹfu wí fún un pé, “Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ. Ẹ̀ka mẹ́ta náà dúró fún ọjọ́ mẹ́ta.
Entonces dijo José: Este es el sentido de tu sueño: las tres ramas son tres días;
13 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta Farao yóò mú ọ jáde nínú ẹ̀wọ̀n padà sí ipò rẹ, ìwọ yóò sì tún máa gbé ọtí fún un, gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ àtẹ̀yìnwá.
Después de tres días, Faraón te dará honor, y te hará volver a tu lugar, y le darás su copa como lo hiciste antes, cuando eras su siervo.
14 Ṣùgbọ́n nígbà tí ohun gbogbo bá dára fún ọ, rántí mi kí o sì fi àánú hàn sí mi. Dárúkọ mi fún Farao, kí o sì mú mi jáde kúrò ní ìhín.
Pero ten en cuenta cuando las cosas te vayan bien, y sé bueno conmigo y di una buena palabra para mí a Faraón y sácame de esta prisión:
15 Nítorí á jí mi gbé tà kúrò ní ilẹ̀ àwọn Heberu ni, àti pé níhìn-ín èmi kò ṣe ohunkóhun tí ó fi yẹ kí èmi wà ní ìhámọ́ bí mo ti wà yìí.”
Porque en verdad fui tomado por la fuerza de la tierra de los hebreos; y no he hecho nada por lo que pueda ser encarcelado.
16 Nígbà tí olórí alásè rí i wí pé ìtumọ̀ tí Josẹfu fún àlá náà dára, ó wí fún Josẹfu pé, “Èmi pẹ̀lú lá àlá, mo ru agbọ̀n oúnjẹ mẹ́ta lórí.
Y cuando el jefe de los panaderos vio que el primer sueño tenía buen sentido, dijo a José: Tuve un sueño; y en mi sueño había tres canastas de pan blanco en mi cabeza;
17 Nínú agbọ̀n tí ó wà lókè, onírúurú oúnjẹ ló wà níbẹ̀ fún Farao, ṣùgbọ́n àwọn ẹyẹ sì ń ṣà wọ́n jẹ láti inú apẹ̀rẹ̀ náà tí ó wà lórí mi.”
Y en la canasta superior había toda clase de carnes cocidas para Faraón; y los pájaros los sacaban de las canastas en mi cabeza.
18 Josẹfu dáhùn, “Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ. Agbọ̀n mẹ́ta náà túmọ̀ sí ọjọ́ mẹ́ta.
Entonces dijo José: Este es el sentido de tu sueño: las tres cestas son tres días;
19 Láàrín ọjọ́ mẹ́ta, Farao yóò tú ọ sílẹ̀, yóò sì bẹ́ orí rẹ, yóò sì gbé ara rẹ kọ́ sí orí igi. Àwọn ẹyẹ yóò sì jẹ ara rẹ.”
Después de tres días, el Faraón te sacará de la cárcel, colgándote de un árbol, para que tu carne sea alimento para las aves.
20 Ọjọ́ kẹta sì jẹ́ ọjọ́ ìbí Farao, ó sì ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀. Ó sì mú olórí agbọ́tí àti olórí alásè jáde kúrò nínú ẹ̀wọ̀n.
Ahora bien, el tercer día era el cumpleaños de Faraón, y él dio una fiesta a todos sus siervos; y dio honor al principal sirviente de vino y al principal panadero entre los demás.
21 Ó dá olórí agbọ́tí padà sí ipò tí ó wà tẹ́lẹ̀, kí ó ba à le máa fi ago lé Farao ní ọwọ́,
Y volvió a poner al siervo principal en su lugar antiguo; y él dio la copa en la mano de Faraón.
22 ṣùgbọ́n, ó so olórí alásè kọ́ sórí igi, gẹ́gẹ́ bí Josẹfu ti sọ fún wọn nínú ìtumọ̀ rẹ̀ sí àlá wọn.
Pero el principal panadero fue muerto ahorcándolo, como José había dicho.
23 Ṣùgbọ́n, olórí agbọ́tí kò rántí Josẹfu mọ́, kò tilẹ̀ ronú nípa rẹ̀.
Pero el siervo no tuvo a José en mente sino que lo olvido.