< Genesis 4 >

1 Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
Adǝm’ata ayali Ⱨawa bilǝn billǝ boldi; Ⱨawa ⱨamilidar bolup Ⱪabilni tuƣup: «Mǝn bir adǝmgǝ igǝ boldum — U Pǝrwǝrdigardur!» — dedi.
2 Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
Andin u yǝnǝ Ⱪabilning inisi Ⱨabilni tuƣdi. Ⱨabil padiqi boldi, Ⱪabil bolsa teriⱪqi boldi.
3 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
Bekitilgǝn xundaⱪ bir waⱪit-saǝttǝ xundaⱪ bir ix boldiki, Ⱪabil tupraⱪning ⱨosulidin Pǝrwǝrdigarƣa ⱨǝdiyǝ kǝltürdi.
4 Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
Ⱨabilmu padisidin ⱪoylirining tunjiliridin, yǝni ularning yeƣidin ⱨǝdiyǝ sundi. Pǝrwǝrdigar Ⱨabilni wǝ uning sunƣan ⱨǝdiyǝsini ⱪobul ⱪildi.
5 ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
Lekin Ⱪabil wǝ uning sunƣiniƣa ⱪarimidi. Xu wǝjidin Ⱪabilning tolimu aqqiⱪi kelip, qirayi tutuldi.
6 Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigar Ⱪabilƣa: Nemixⱪa aqqiⱪlinisǝn? Nemǝ üqün qiraying tutulup ketidu?
7 Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
Əgǝr durus ix ⱪilsang, sǝn kɵtürülmǝmsǝn? Lekin durus ix ⱪilmisang, mana gunaⱨ ixik aldida [seni paylap] beƣirlap yatidu, u seni ɵz ilkigǝ almaⱪqi bolidu; lekin sǝn uningdin ƣalip kelixing kerǝk, dedi.
8 Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
Ⱪabil inisi Ⱨabilƣa: «Daliƣa qiⱪip kelǝyli!» dedi. Dalada xu wǝⱪǝ boldiki, Ⱪabil inisi Ⱨabilƣa ⱪol selip, uni ɵltürdi.
9 Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
Pǝrwǝrdigar Ⱪabilƣa: Ining Ⱨabil nǝdǝ? — dǝp soridi. U jawab berip: Bilmǝymǝn, mǝn inimning baⱪⱪuqisimu? — dedi.
10 Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
Huda uningƣa: — Sǝn nemǝ ⱪilding? Mana, iningning ⱪeni yǝrdin manga pǝryad kɵtürüwatidu!
11 Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
Əmdi iningning ⱪolungda tɵkülgǝn ⱪenini ⱪobul ⱪilixⱪa aƣzini aqⱪan yǝrdin ⱪoƣlinip, lǝnǝtkǝ uqraysǝn.
12 Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
Sǝn yǝrgǝ ixlisǝngmu u buningdin keyin sanga ⱪuwwitini bǝrmǝydu; sǝn yǝr yüzidǝ sǝrsan bolup, sǝrgǝrdan bolisǝn, — dedi.
13 Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
Buni anglap Ⱪabil Pǝrwǝrdigarƣa jawab ⱪilip: — Mening bu jazayimni adǝm kɵtürǝlmigüdǝk!
14 Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
Mana, Sǝn bügün meni yǝr yüzidin ⱪoƣliding, mǝn ǝmdi Sening yüzüngdin yoxurunup yürimǝn; yǝr yüzidǝ sǝrsǝn bolup sǝrgǝrdanliⱪta yürimǝn; xundaⱪ boliduki, kimla meni tepiwalsa, ɵltürüwetidu!, — dedi.
15 Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
Lekin Pǝrwǝrdigar uningƣa jawab berip: — Xundaⱪ boliduki, kimki Ⱪabilni ɵltürsǝ, uningdin yǝttǝ ⱨǝssǝ intiⱪam elinidu, — dedi. Xularni dǝp Pǝrwǝrdigar Ⱪabilƣa uqriƣan birsi uni ɵltürüwǝtmisun dǝp uningƣa bir bǝlgǝ ⱪoyup ⱪoydi.
16 Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
Xuning bilǝn Ⱪabil Pǝrwǝrdigarning ⱨuzuridin qiⱪip, Erǝmning mǝxriⱪ tǝripidiki Nod degǝn yurtta olturaⱪlixip ⱪaldi.
17 Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
Ⱪabil ayali bilǝn billǝ bolup, ayali ⱨamilidar bolup Ⱨanohni tuƣdi. U waⱪitta Ⱪabil bir xǝⱨǝr bina ⱪiliwatatti; u xǝⱨǝrning namini oƣlining ismi bilǝn Ⱨanoh dǝp atidi.
18 Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
Ⱨanohtin Irad tɵrǝldi, iradtin Mǝⱨuyail tɵrǝldi, Mǝⱨuyaildin Mǝtuxail tɵrǝldi, Mǝtuxaildin Lǝmǝh tɵrǝldi.
19 Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
Lǝmǝh ɵzigǝ ikki hotun aldi. Birining ismi Adaⱨ, yǝnǝ birining ismi Zillaⱨ idi.
20 Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
Adaⱨ Yabalni tuƣdi. U qedirda olturidiƣan kɵqmǝn malqilarning bowisi idi,
21 Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
uning inisining ismi Yubal idi. Bu qiltar bilǝn nǝy qalƣuqilarning bowisi idi.
22 Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
Zillaⱨ yǝnǝ Tubal-ⱪayin degǝn bir oƣulni tuƣdi. U mis-tɵmür ǝswablarni soⱪⱪuqi idi. Tubal-ⱪayinning Naamaⱨ isimlik bir singlisi bar idi.
23 Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
Lǝmǝh bolsa ayalliriƣa sɵz ⱪilip: — «Əy Adaⱨ bilǝn Zillaⱨ, sɵzümni anglanglar! Əy Lǝmǝhning ayalliri, gepimgǝ ⱪulaⱪ selinglar! Meni zǝhimlǝndürgini üqün mǝn adǝm ɵltürdüm, Tenimni zedǝ ⱪilƣanliⱪi üqün bir yigitni ɵltürdüm.
24 Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
Əgǝr Ⱪabil üqün yǝttǝ ⱨǝssǝ intiⱪam elinsa, Lǝmǝh üqün yǝtmix yǝttǝ ⱨǝssǝ intiⱪam elinidu!» — dedi.
25 Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
Adǝm’ata yǝnǝ ayali bilǝn billǝ boldi. Ayali bir oƣul tuƣup, uningƣa Xet dǝp at ⱪoyup: Ⱪabil Ⱨabilni ɵltürüwǝtkini üqün Huda uning orniƣa manga baxⱪa bir ǝwlad tiklǝp bǝrdi, dedi.
26 Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.
Xettinmu bir oƣul tuƣuldi; u uningƣa Enox dǝp at ⱪoydi. Xu waⱪittin tartip adǝmlǝr Pǝrwǝrdigarning namiƣa nida ⱪilixⱪa baxlidi.

< Genesis 4 >