< Genesis 4 >
1 Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
Y el varón tuvo relaciones con su mujer Eva, y quedó encinta, y dio a luz a Caín, y dijo: Me ha dado un hombre él Señor.
2 Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
Entonces ella volvió a tener un hijo y dio a luz a Abel, su hermano. Y Abel era pastor de ovejas, pero Caín era granjero.
3 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
Y después de un tiempo, Caín le dio al Señor una ofrenda de los frutos de la tierra.
4 Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
Y Abel dio una ofrenda de los corderos de su rebaño y de su grasa. Y el Señor estaba complacido con la ofrenda de Abel;
5 ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
Pero en Caín y en su ofrenda no se complació. Y Caín estaba enojado y su rostro se puso triste.
6 Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
Y él Señor dijo a Caín: ¿Por qué estás enojado? y por qué tu cara está triste?
7 Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
Si lo haces bien, ¿no tendrás honor? y si lo haces mal, el pecado te espera en la puerta, deseando tenerte, pero no dejes que sea tu amo.
8 Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
Y dijo Caín a su hermano: Pasemos al campo; y estando ellos en el campo, Caín atacó a su hermano Abel y lo mató.
9 Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
Y él Señor dijo a Caín: ¿Dónde está tu hermano Abel? Y él dijo: No tengo idea: ¿soy el guardián de mi hermano?
10 Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
Y él dijo: ¿Qué has hecho? la voz de la sangre de tu hermano me está llamando desde la tierra.
11 Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
Y ahora eres maldito de la tierra, cuya boca está abierta para recibir la sangre de tu hermano de tu mano;
12 Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
La tierra ya no te dará su fruto como la recompensa de tu trabajo; serás un vagabundo errante sobre la tierra.
13 Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
Y dijo Caín: Mi castigo es mayor que mi fuerza.
14 Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
Me has enviado hoy de la faz de la tierra y de delante de tu rostro; Voy a ser un vagabundo errante sobre la tierra, y el que me vea me matará.
15 Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
Y él Señor dijo: De cierto, si muere Caín, siete vidas serán tomadas por él. Y el Señor puso una marca en Caín para que nadie lo matara.
16 Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
Y se apartó Caín de delante de la faz del Señor, y se quedó a vivir en la tierra de Nod, al oriente del Edén.
17 Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
Y Caín tuvo relaciones con su esposa, y ella engendró y dio a luz a Enoc; y él hizo una ciudad, y le dio a la ciudad el nombre de Enoc por su hijo.
18 Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
Y Enoc tuvo un hijo Irad; e Irad fue padre de Mehujael; y Mehujael padre de Metusael; y Metusael fue padre de Lamec.
19 Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
Y Lamec tuvo dos mujeres; el nombre de uno era Ada, y el nombre del otro Zila.
20 Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
Y Ada dio a luz a Jabal; era el padre de los que viven en tiendas y tienen ganado.
21 Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
Y el nombre de su hermano era Jubal: él era el padre de todos los que tocan con arpa y flauta.
22 Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
Y Zila dio a luz a Tubal-caín, que es el padre de todo fabricante de instrumentos de bronce y de hierro, y la hermana de Tubal-caín fue Naama.
23 Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
Y dijo Lamec a sus mujeres, Ada y Zila, escucha mi voz; esposas de Lamec, presten atención a mis palabras, porque yo pondría a muerte a un hombre por una herida, y a un joven por un golpe;
24 Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
Si se quieren tomar siete vidas como castigo por la muerte de Caín, setenta y siete serán tomadas por las de Lamec.
25 Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
Y Adán volvió a tener relaciones con su esposa, y ella dio a luz a un hijo al que dio el nombre de Set, porque ella dijo: Dios me ha dado otra simiente en lugar de Abel, a quien Caín mató.
26 Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.
Y Set tuvo un hijo, y le dio el nombre de Enós: en este tiempo los hombres primero hicieron uso del nombre del Señor en adoración.