< Genesis 4 >

1 Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
Potem Adam obcował ze swoją żoną Ewą, a ta poczęła i urodziła Kaina. I powiedziała: Otrzymałam mężczyznę od PANA.
2 Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
I urodziła jeszcze jego brata Abla. Abel był pasterzem owiec, a Kain był rolnikiem.
3 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
Z biegiem czasu zdarzyło się, że Kain przyniósł PANU ofiarę z plonów ziemi.
4 Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
Także Abel przyniósł z pierworodnych swej trzody i z ich tłuszczu. A PAN wejrzał na Abla i jego ofiarę.
5 ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
Lecz na Kaina i jego ofiarę nie wejrzał. Kain rozgniewał się bardzo i spochmurniała jego twarz.
6 Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
Wtedy PAN zapytał Kaina: Dlaczego się rozgniewałeś? Czemu spochmurniała twoja twarz?
7 Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
Jeśli będziesz dobrze czynił, czy nie zostaniesz wywyższony? A jeśli nie będziesz dobrze czynił, grzech leży u drzwi; a do ciebie [będzie] jego pragnienie, a ty będziesz nad nim panować.
8 Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
I Kain rozmawiał ze swoim bratem Ablem. A gdy byli na polu, Kain powstał przeciwko swemu bratu Ablowi i zabił go.
9 Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
Wtedy PAN zapytał Kaina: Gdzie jest twój brat Abel? On odpowiedział: Nie wiem. Czy ja jestem stróżem mego brata?
10 Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
[Bóg] zapytał: Cóż uczyniłeś? Głos krwi twego brata woła do mnie z ziemi.
11 Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
Teraz więc przeklęty będziesz na ziemi, która otworzyła swe usta, aby przyjąć krew twego brata [przelaną] przez twoją rękę.
12 Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
Gdy będziesz uprawiał ziemię, nie da ci już swego plonu. Tułaczem i zbiegiem będziesz na ziemi.
13 Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
Wtedy Kain powiedział do PANA: Zbyt ciężka jest moja kara, bym mógł ją znieść.
14 Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
Oto wyganiasz mnie dziś z powierzchni ziemi, a przed twoją twarzą będę ukryty. Będę tułaczem i zbiegiem na ziemi, a stanie się [tak, że] ktokolwiek mnie spotka, zabije mnie.
15 Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
PAN mu odpowiedział: Zaprawdę, ktokolwiek zabije Kaina, poniesie siedmiokrotną zemstę. I nałożył PAN na Kaina piętno, aby nie zabił go nikt, kto by go spotkał.
16 Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
Wtedy odszedł Kain sprzed oblicza PANA i zamieszkał w ziemi Nod, na wschód od Edenu.
17 Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
I Kain obcował ze swoją żoną, a ona poczęła i urodziła Henocha. Zbudował też miasto i nazwał je imieniem swego syna – Henoch.
18 Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
Henochowi urodził się Irad, a Irad spłodził Mechujaela, a Mechujael spłodził Matuszaela, a Matuszael spłodził Lameka.
19 Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
I Lamek pojął sobie dwie żony. Imię jednej [było] Ada, a drugiej – Silla.
20 Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
Ada urodziła Jabala, który był ojcem mieszkających w namiotach i pasterzy.
21 Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
Jego brat [miał] na imię Jubal, a był on ojcem wszystkich grających na harfie i na flecie.
22 Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
Silla urodziła Tubalkaina, [który był] rzemieślnikiem wszelkiej roboty od miedzi i żelaza. Siostrą Tubalkaina była Noema.
23 Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
I Lamek powiedział swym żonom, Adzie i Silli: Słuchajcie mego głosu, żony Lameka, posłuchajcie moich słów; zabiłem mężczyznę za zranienie mnie i młodzieńca za siniec.
24 Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
Jeśli Kain ma być pomszczony siedem razy, to Lamek siedemdziesiąt siedem razy.
25 Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
I Adam znów obcował ze swoją żoną, a ona urodziła syna i nadała mu imię Set, [mówiąc]: Dał mi Bóg inne potomstwo za Abla, którego zabił Kain.
26 Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.
Setowi też urodził się syn i nadał mu imię Enosz. Wtedy zaczęto wzywać imienia PANA.

< Genesis 4 >