< Genesis 4 >
1 Adamu sì bá aya rẹ̀ Efa lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Kaini. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọ ọkùnrin.”
Nake Adamu agĩkoma na mũtumia wake Hawa, nake akĩgĩa nda, agĩciara Kaini. Nake akiuga atĩrĩ, “Ndĩkũgĩa na mwana wa kahĩĩ nĩ ũndũ wa gũteithio nĩ Jehova.”
2 Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Abeli. Abeli jẹ́ darandaran, Kaini sì jẹ́ àgbẹ̀.
Thuutha ũcio agĩciara Habili, mũrũ wa nyina. Habili aarĩ mũrĩithi wa mbũri nake Kaini aarĩ mũrĩmi.
3 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Kaini mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èso ilẹ̀ rẹ̀.
Maikarĩte kwa ihinda-rĩ, Kaini akĩrehe maciaro mamwe ma mũgũnda marĩ igongona kũrĩ Jehova.
4 Ṣùgbọ́n Abeli mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojúrere wo Abeli àti ọrẹ rẹ̀,
No Habili akĩrehe marigithathi mamwe marĩa manoru ma rũũru rwake. Nake Jehova agĩkenio nĩ Habili na igongona rĩake,
5 ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojúrere wo Kaini àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Kaini gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.
no ndaakenirio nĩ Kaini na igongona rĩake. Nĩ ũndũ ũcio Kaini akĩrakara mũno, na agĩtukia gĩthiithi.
6 Nígbà náà ni Olúwa bi Kaini pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?
Nake Jehova Ngai akĩũria Kaini atĩrĩ, “Ũrakarĩte nĩkĩ? Na nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũtukie gĩthiithi?
7 Bí ìwọ bá ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu-ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”
Ũngĩka ũrĩa kwagĩrĩire-rĩ, no wage gwĩtĩkĩrĩka? No ũngĩaga gwĩka ũrĩa kwagĩrĩire-rĩ, mehia makuoheirie mũrango-inĩ waku makĩenda gũgwatha; no wee no nginya ũmatoorie.”
8 Kaini wí fún Abeli arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Kaini da ojú ìjà kọ Abeli arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.
Thuutha ũcio Kaini akĩĩra mũrũ wa nyina Habili atĩrĩ, “Nĩtumagare tũthiĩ mũgũnda.” Na rĩrĩa maarĩ kũu mũgũnda, Kaini agĩtharĩkĩra mũrũ wa nyina Habili, akĩmũũraga.
9 Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Kaini pé, “Níbo ni Abeli arákùnrin rẹ wà?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”
Nake Jehova akĩũria Kaini atĩrĩ, “Arĩ ha mũrũ-wa-nyũkwa Habili?” Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Niĩ ndiũĩ, kaĩ arĩ niĩ mũmenyereri wa mũrũ-wa-maitũ?”
10 Olúwa wí pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ṣe yìí? Gbọ́! Ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ ń kígbe pè mí láti ilẹ̀ wá.
Jehova akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ atĩa wĩkĩte? Ta thikĩrĩria! Thakame ya mũrũ-wa-nyũkwa nĩĩrangaĩra ĩrĩ tĩĩri-inĩ.
11 Láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ ti wà lábẹ́ ègún, a sì ti lé ọ lórí ilẹ̀ tí ó ya ẹnu gba ẹ̀jẹ̀ arákùnrin rẹ lọ́wọ́ rẹ.
Na rĩrĩ, nĩũgwatĩtwo nĩ kĩrumi na ũkaingatwo mũgũnda ũrĩa waathamirie kanua kaguo kwamũkĩra thakame ya mũrũ-wa-nyũkwa kuuma guoko-inĩ gwaku.
12 Bí ìwọ bá ro ilẹ̀, ilẹ̀ kì yóò fi agbára rẹ̀ so èso rẹ̀ fún ọ mọ́. Ìwọ yóò sì jẹ́ ìsáǹsá àti alárìnkiri ni orí ilẹ̀ ayé.”
Rĩrĩa ũrĩũrĩmaga-rĩ, ndũgacooka gũgũciarĩra maciaro maguo. Ũgũtuĩka mũndũ ũtakindagĩria, wa kũũrũũraga gũkũ thĩ.”
13 Kaini wí fún Olúwa pé, “Ẹrù ìyà ẹ̀ṣẹ̀ mi pọ̀ ju èyí tí mo le rù lọ.
Nake Kaini akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Iherithia rĩakwa nĩ inene gũkĩra ũrĩa ingĩhota gwĩtiiria.
14 Lónìí, ìwọ lé mi kúrò lórí ilẹ̀, mó sì di ẹni tí ó fi ara pamọ́ kúrò ní ojú rẹ, èmi yóò sì di ìsáǹsá àti alárìnkiri ní ayé, ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi, yóò sì pa mí.”
Ũmũthĩ ũyũ nĩũranyingata kuuma mũgũnda ũyũ na ndũũre hithĩtwo ũthiũ waku; ngũtuĩka mũndũ ũtakindagĩria, wa kũũrũũraga gũkũ thĩ, na ũrĩa wothe ũkaanyona nĩakanjũraga.”
15 Ṣùgbọ́n, Olúwa wí fún pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ẹnikẹ́ni bá pa Kaini, èmi yóò gbẹ̀san ní ara onítọ̀hún ní ìgbà méje.” Nígbà náà ni Ọlọ́run fi àmì sí ara Kaini, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá ri má ba à pa á.
No Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Aca, ti ũguo; mũndũ o na ũrĩkũ angĩkooraga Kaini, nĩakarĩhio maita mũgwanja.” Jehova agĩcooka agĩĩkĩra Kaini rũũri nĩgeetha ũrĩa wothe ũngĩmuona ndakamũũrage!
16 Kaini sì kúrò níwájú Olúwa, ó sì ń gbé ilẹ̀ Nodi ní ìhà ìlà-oòrùn Edeni.
Nĩ ũndũ ũcio Kaini akĩehera akiuma harĩ Jehova, na agĩtũũra bũrũri-inĩ wa Nodu, mwena wa irathĩro rĩa Edeni.
17 Kaini sì bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Enoku. Kaini sì tẹ ìlú kan dó, ó sì fi orúkọ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Enoku sọ ìlú náà.
Kaini agĩkoma na mũtumia wake, na akĩgĩa nda, agĩciara Enoku. Hĩndĩ ĩyo Kaini nĩakaga itũũra inene, na aarĩkia kũrĩaka, akĩrĩĩta Enoku o ta ũrĩa mũriũ eetagwo.
18 Enoku sì bí Iradi, Iradi sì ni baba Mehujaeli, Mehujaeli sì bí Metuṣaeli, Metuṣaeli sì ni baba Lameki.
Nake Enoku agĩciarĩrwo Iradu, nake Iradu aarĩ ithe wa Mehujaeli, nake Mehujaeli aarĩ ithe wa Methushaeli, nake Methushaeli aarĩ ithe wa Lameku.
19 Lameki sì fẹ́ aya méjì, orúkọ èkínní ni Adah, àti orúkọ èkejì ni Silla.
Lameku ũcio akĩhikia andũ-a-nja eerĩ, ũmwe eetagwo Ada na ũrĩa ũngĩ eetagwo Zila.
20 Adah sì bí Jabali, òun ni baba irú àwọn tí ń gbé inú àgọ́, tí wọ́n sì ń sin ẹran ọ̀sìn.
Ada agĩciara Jabali; na nĩwe ithe wa andũ arĩa matũũraga hema-inĩ na marĩithagia mahiũ.
21 Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jubali, òun ni baba irú àwọn tí ń tẹ dùùrù tí wọ́n sì ń fọn fèrè.
Mũrũ-wa nyina eetagwo Jubali; nake nĩwe ithe wa andũ arĩa othe mahũũraga inanda cia mũgeeto na makahuha mĩtũrirũ.
22 Silla náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Kaini, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Kaini ni Naama.
Zila o nake aarĩ na mũriũ, nake eetagwo Tubali-Kaini, na nĩwe waturaga indo cia mĩthemba yothe cia gĩcango na cia kĩgera. Tubali-Kaini aarĩ na mwarĩ wa nyina wetagwo Naama.
23 Lameki wí fún àwọn aya rẹ̀, “Adah àti Silla, ẹ tẹ́tí sí mi; ẹ̀yin aya Lameki, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi. Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.
Lameku akĩĩra atumia ake atĩrĩ, “Ada na Zila, taa thikĩrĩriai; inyuĩ atumia a Lameku, ta iguai ciugo ciakwa. Nĩnjũragĩte mũndũ nĩ ũndũ wa kũndiihia, ngooraga mũndũ mwĩthĩ nĩ ũndũ wa kũnguraria.
24 Bí a ó bá gbẹ̀san Kaini ní ìgbà méje, ǹjẹ́ kí a gba ti Lameki nígbà mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.”
Angĩkorwo Kaini arĩhagĩrio maita mũgwanja-rĩ, Lameku nake akarĩhĩrio maita mĩrongo mũgwanja na mũgwanja.”
25 Adamu sì tún bá aya rẹ̀ lòpọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Seti, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Abeli tí Kaini pa.”
Nake Adamu agĩkoma na mũtumia wake rĩngĩ, nake agĩciara kaana ga kahĩĩ, na agĩgatua Sethi, akiuga atĩrĩ, “Ngai nĩaheete mwana ũngĩ handũ ha Habili, ũrĩa Kaini ooragire.”
26 Seti náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Enoṣi. Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.
Sethi o nake aarĩ na mũriũ wake, nake akĩmũtua rĩĩtwa Enoshu. Hĩndĩ ĩyo nĩrĩo andũ mambĩrĩirie gũkaĩra rĩĩtwa rĩa Jehova.