< Genesis 39 >

1 Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potifari, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.
Şi Iosif a fost coborât în Egipt; şi Potifar, un ofiţer al lui Faraon, căpetenia gărzii, un egiptean, l-a cumpărat din mâinile ismaeliţilor, care îl coborâseră acolo.
2 Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti.
Şi DOMNUL era cu Iosif şi el era un bărbat prosper; şi era în casa stăpânului său, egipteanul.
3 Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé.
Şi stăpânul său a văzut că DOMNUL era cu el şi că DOMNUL făcea să prospere în mâna lui tot ceea ce făcea.
4 Josẹfu sì rí ojúrere Potifari, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potifari fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
Şi Iosif a găsit har înaintea ochilor lui şi l-a servit; iar el l-a făcut supraveghetor peste casa lui şi tot ce avea a pus în mâna lui.
5 Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potifari ní, nílé àti lóko.
Şi s-a întâmplat, din momentul în care l-a făcut supraveghetor în casa lui şi peste tot ce avea, că DOMNUL a binecuvântat casa egipteanului din cauza lui Iosif; şi binecuvântarea DOMNULUI era peste tot ce avea în casă şi în câmp.
6 Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀. Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀,
Şi a lăsat tot ce avea în mâna lui Iosif; şi nu ştia ce avea, în afară de pâinea pe care o mânca. Iar Iosif era frumos la statură şi plăcut la vedere.
7 lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”
Şi s-a întâmplat, după aceste lucruri că soţia stăpânului său şi-a aruncat ochii pe Iosif; şi ea a spus: Culcă-te cu mine.
8 Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́.
Dar el a refuzat şi a spus soţiei stăpânului său: Iată, pe stăpânul meu nu îl interesează ce este cu mine în casă şi a încredinţat în mâna mea tot ce are;
9 Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?”
Nu este nimeni mai mare în această casă decât mine; nici nu mi-a oprit nimic decât pe tine, deoarece tu eşti soţia lui; cum atunci să pot eu face această mare răutate şi să păcătuiesc împotriva lui Dumnezeu?
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.
Şi s-a întâmplat, cum vorbea cu Iosif zi de zi, că el nu i-a dat ascultare să se culce lângă ea, sau să fie cu ea.
11 Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí.
Şi s-a întâmplat, cam în acest timp, că Iosif a intrat în casă să îşi facă lucrul; şi niciunul dintre bărbaţii casei nu era acolo în casă.
12 Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.
Iar ea l-a prins de haină, spunând: Culcă-te cu mine; iar el şi-a lăsat haina în mâna ei şi a fugit şi a ieşit afară.
13 Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde,
Şi s-a întâmplat, când a văzut ea că el şi-a lăsat haina în mâna ei şi a fugit afară,
14 ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe.
Că a chemat bărbaţii din casa ei şi le-a vorbit, spunând: Vedeţi, el a adus un evreu la noi ca să ne batjocorească; el a intrat la mine să se culce cu mine şi eu am strigat cu voce tare.
15 Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”
Şi s-a întâmplat, când el a auzit că am ridicat vocea şi am strigat, că şi-a lăsat haina cu mine şi a fugit şi a ieşit afară.
16 Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé.
Şi a aşezat haina lui lângă ea, până când domnul lui a venit acasă.
17 Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀.
Şi a vorbit cu el conform acestor cuvinte, spunând: Servitorul evreu, pe care l-ai adus la noi, a intrat la mine să mă batjocorească.
18 Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”
Şi s-a întâmplat, pe când mi-am ridicat vocea şi am strigat, că şi-a lăsat haina cu mine şi a fugit afară.
19 Nígbà tí Potifari gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi.
Şi s-a întâmplat, când stăpânul lui a auzit cuvintele soţiei sale, pe care ea i le-a vorbit, spunând: Astfel mi-a făcut servitorul tău; că furia lui s-a aprins.
20 Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí. Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀,
Şi stăpânul lui Iosif l-a luat şi l-a pus în închisoare, un loc unde prizonierii împăratului erau legaţi; iar el era acolo în închisoare.
21 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n.
Dar DOMNUL era cu Iosif şi i-a arătat milă şi i-a dat favoare înaintea ochilor administratorului închisorii.
22 Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀.
Şi administratorul închisorii a încredinţat în mâna lui Iosif pe toţi prizonierii care erau în închisoare; şi tot ce făceau ei acolo, el era cel ce le făcea.
23 Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.
Administratorul închisorii nu se uita la nimic din ce era sub mâna lui, pentru că DOMNUL era cu el şi ceea ce el făcea, DOMNUL făcea să prospere.

< Genesis 39 >