< Genesis 39 >
1 Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potifari, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.
Josef blev ført ned til Egypten; og Potifar, en egypter, som var hoffmann hos Farao og høvding over livvakten, kjøpte ham av ismaelittene som hadde hatt ham med sig dit.
2 Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti.
Men Herren var med Josef, så alt lyktes for ham; og han vedblev å være i huset hos sin herre egypteren.
3 Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé.
Da hans herre så at Herren var med ham, og at Herren lot alt det han gjorde, lykkes for ham,
4 Josẹfu sì rí ojúrere Potifari, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potifari fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
fant Josef nåde for hans øine og fikk gå ham til hånde; og han satte ham over sitt hus, og alt det han hadde, la han i hans hender.
5 Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potifari ní, nílé àti lóko.
Og helt fra den tid han hadde satt ham over sitt hus og over alt det han hadde, velsignet Herren egypterens hus for Josefs skyld, og Herrens velsignelse var over alt det han hadde, både i huset og på marken.
6 Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀. Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀,
Og han overlot alt det han hadde, i Josefs hender, og han så ikke til med ham i noget, uten med den mat han selv åt. Og Josef var vakker av skapning og vakker å se til.
7 lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”
Og nogen tid efter hendte det at hans herres hustru kastet sine øine på Josef og sa: Kom og ligg hos mig!
8 Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́.
Men han vilde ikke og sa til sin herres hustru: Min herre ser ikke til med mig i nogen ting i hele sitt hus, og alt det han eier, har han lagt i mine hender;
9 Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?”
han har ikke mere å si her i huset enn jeg, og han har ikke nektet mig noget uten dig, fordi du er hans hustru. Hvorledes skulde jeg da gjøre denne store ondskap og synde mot Gud?
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.
Som hun nu dag efter dag talte til Josef, og han ikke føide henne i å ligge hos henne og være sammen med henne,
11 Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí.
så hendte det en dag at han kom inn i huset for å gjøre sitt arbeid, mens ingen av husets folk var inne.
12 Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.
Da grep hun fatt i hans kappe og sa: Ligg hos mig! Men han lot sin kappe efter sig i hennes hånd og flyktet ut av huset.
13 Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde,
Og da hun så at han hadde latt sin kappe efter sig i hennes hånd og var flyktet ut av huset,
14 ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe.
ropte hun på sine husfolk og sa til dem: Se, her har han ført en hebraisk mann hit til oss for å føre skam over oss; han kom inn til mig for å ligge hos mig, men jeg ropte så høit jeg kunde,
15 Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”
og da han hørte at jeg satte i å rope, lot han sin kappe efter sig hos mig og flyktet ut av huset.
16 Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé.
Så lot hun hans kappe bli liggende hos sig til hans herre kom hjem.
17 Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀.
Da talte hun likedan til ham og sa: Den hebraiske træl som du har ført hit til oss, kom inn til mig for å føre skam over mig;
18 Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”
men da jeg satte i å rope, lot han sin kappe efter sig hos mig og flyktet ut av huset.
19 Nígbà tí Potifari gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi.
Da nu hans herre hørte hvad hans hustru fortalte, hvorledes hun sa: Således har din træl gjort mot mig, da optendtes hans vrede.
20 Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí. Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀,
Og Josefs herre tok og satte ham i fengslet, der hvor kongens fanger holdtes fengslet; og han blev sittende der i fengslet.
21 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n.
Men Herren var med Josef og lot ham vinne alles hjerter og gav ham yndest hos fengslets overopsynsmann.
22 Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀.
Og fengslets overopsynsmann satte Josef til å se efter alle fangene som var i fengslet; og alt det som skulde gjøres der, det gjorde han.
23 Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.
Fengslets overopsynsmann så ikke efter nogen ting som han hadde under hender, fordi Herren var med ham; og hvad han gjorde, gav Herren lykke til.