< Genesis 39 >

1 Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potifari, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.
Now, Joseph, was taken down to Egypt, —and Potiphar, courtier of Pharaoh, chief of the royal executioners, an Egyptian bought him, at the hand of the Ishmaelites, who had brought him down thither.
2 Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti.
And it came to pass that Yahweh, was with Joseph, so that he became a prosperous man, —and was in the house of his lord the Egyptian.
3 Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé.
And his lord saw, that, Yahweh, was with him—and that whatsoever, he was doing, Yahweh, was causing to prosper in his hand.
4 Josẹfu sì rí ojúrere Potifari, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potifari fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
So Joseph found favour in his eyes and waited upon him, —and he made him overseer over his house, and all that he had, gave he into his hand.
5 Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potifari ní, nílé àti lóko.
And it came to pass from the time that he made him overseer in his house and over all that he had, that Yahweh blessed the house of the Egyptian, for Joseph’s sake, —yea it came to pass, that the blessing of Yahweh, was with all that he had, in the house and in the field;
6 Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀. Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀,
so that he left all that he had in the hand of Joseph, and took note with him of nothing, save only the bread which, he himself, was eating. And so it was that Joseph was comely in form and comely in countenance.
7 lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”
And it came to pass after these things, that his lord’s wife lifted up her eyes unto Joseph, —and she said—Come! lie with me.
8 Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́.
And he refused and said unto his lord’s wife, Lo! my lord, taketh no note with me as to what is in the house, —but, all that pertaineth to him, hath he delivered into my hand:
9 Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?”
There is no one greater in this house than I, neither hath he withheld from me anything, save only thyself in that thou, art his wife, —how, then could I do this great wickedness, and sin against God?
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.
And it came to pass, that although she Spake unto Joseph day after day, yet hearkened he not unto her to lie beside her to be with her.
11 Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí.
And it came to pass, when, on a certain day, he went into the house to attend to his business, —and there was no man of the household, there in the house,
12 Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.
that she caught him by his garment, saying—Come! lie with me. Then left he his garment in her hand, and fled and gat forth outside,
13 Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde,
And it came to pass when she saw that he had left his garment in her hand, —and fled forth outside,
14 ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe.
that she cried out to the men of her house and spake to them, saying, Look ye! he hath brought in to us a Hebrew man to insult us, —He came in unto me, to lie with me, so I cried out with a loud voice.
15 Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”
And it came to pass, when he heard that I lifted high my voice, and cried out, then left he his garment beside me, and fled and gat forth outside.
16 Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé.
So she laid by his garment beside her, —until his lord should come into his house,
17 Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀.
Then spake she unto him, according to these words, saying, —He hath been in unto me—the Hebrew servant whom thou didst bring in to us—to insult me.
18 Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”
And it came to pass when I lifted high my voice and cried out, then left he his garment beside me, and fled outside.
19 Nígbà tí Potifari gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi.
And it came to pass, when his lord heard the words of his wife which she spake unto him saying, According to these words, hath thy servant done to me, Then was kindled his anger.
20 Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí. Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀,
So Joseph’s lord took him and delivered him up to the prison: the place where, the prisoners of the king, were imprisoned, —so he was there, in the prison.
21 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n.
And it came to pass that, Yahweh, was with Joseph, and extended unto him lovingkindness, —and gave him his favour in the eyes of the chief of the prison.
22 Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀.
So the chief of the prison delivered up, into Joseph’s hand all the prisoners who were in the prison, —and of all that was doing there, he, was the doer.
23 Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.
After nothing, was the chief of the prison looking, of whatever was in his hand, —in that Yahweh, was with him, and whatsoever, he was doing, Yahweh, was causing to prosper.

< Genesis 39 >