< Genesis 39 >

1 Nígbà tí wọ́n mú Josẹfu dé Ejibiti, Potifari, ará Ejibiti tí i ṣe ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao. Òun ni olórí àwọn ọmọ-ogun Farao. Ó ra Josẹfu lọ́wọ́ àwọn ará Iṣmaeli tí wọ́n mú un lọ síbẹ̀.
А Иосифа заведоха в Египет, и египтянинът Петефрий, Фараонов придворен, началник на телохранителите, го купи от ръката на исмаиляните, които го доведоха там.
2 Olúwa sì wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì bùkún un, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀gá rẹ̀ ará Ejibiti.
И Господ беше с Иосифа, и той благоуспяваше и се намираше в дома на господаря си египтянина.
3 Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ rí i pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀, àti pé Olúwa jẹ́ kí ó máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́ rẹ̀ lé.
И като видя господарят му, че Господ бе с него, и че Господ прави да успява в ръката му всичко, което вършеше,
4 Josẹfu sì rí ojúrere Potifari, ó sì di aṣojú rẹ̀, Potifari fi Josẹfu ṣe olórí ilé rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.
Иосиф придоби благоволение пред очите му и му служеше; и той го постави настоятел на дома си, като предаде в ръката му всичко, което имаше.
5 Láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu jẹ olórí ilé rẹ̀ àti ohun ìní rẹ̀ gbogbo, ni Ọlọ́run ti bẹ̀rẹ̀ sí ní bùkún àwọn ará Ejibiti nítorí Josẹfu. Ìbùkún Olúwa wà lórí gbogbo ohun tí Potifari ní, nílé àti lóko.
И откакто го постави настоятел на дома си и на всичко, което имаше, Господ благослови дома на египтянина заради Иосифа; Господното благословение беше върху всичко, що имаше в дома и по нивите.
6 Ó sì fi Josẹfu ṣe àkóso gbogbo ohun tí ó ní. Kò sì ṣe ìyọnu lórí ohunkóhun mọ àyàfi nípa oúnjẹ tí ó ń jẹ láti ìgbà tí ó ti fi Josẹfu ṣe àkóso ilé e rẹ̀. Josẹfu sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin ní ìdúró àti ìrísí rẹ̀,
А Петефрий остави всичко що имаше в Иосифовата ръка, и, освен хляба, който ядеше, не знаеше нищо за онова, което притежаваше. А Иосиф беше строен и красив.
7 lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, aya rẹ̀ ṣe àkíyèsí Josẹfu, ó sì wí fún un pé, “Wá bá mi lòpọ̀!”
И след време, жената на господаря му хвърли очи на Иосифа и му рече: Легни с мене.
8 Ṣùgbọ́n Josẹfu kọ̀, ó sì wí fún aya ọ̀gá rẹ̀ pé, “Kíyèsi, Olúwa mi kò fi ohunkóhun dù mi nínú ilé yìí, gbogbo ohun ìní rẹ̀ ni ó fi lé mi lọ́wọ́.
Но той отказа и рече на жената на господаря си: Виж, господарят ми не знае нищо за онова, което е с мене в дома и предаде в моята ръка всичко що има;
9 Kò sí ẹni tí ó jù mi lọ nínú ilé yìí, ọ̀gá mi kò fi ohunkóhun dù mi àyàfi ìwọ, tí í ṣe aya rẹ̀. Báwo ni mo ṣe lè ṣe ohun búburú yìí, kí ń sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run?”
в тоя дом няма никой по-голям от мене, нито е задържал от мене друго нещо освен тебе, защото си му жена; как, прочее, да сторя аз това голямо зло и да съгреша пред Бога?
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ìgbà ni ó ń tẹnumọ́ èyí fún Josẹfu, Josẹfu kọ̀ láti bá a lòpọ̀. Ó tilẹ̀ kọ̀ láti máa dúró ni ibi tí ó bá wà.
И при все, че тя говореше на Иосифа всеки ден, той не я послуша да лежи с нея, нито да бъде с нея.
11 Ní ọjọ́ kan, Josẹfu lọ sínú ilé láti ṣe iṣẹ́, kò sì sí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ ní tòsí.
А един ден, като влезе Иосиф в къщи, за да върши работата си, а никой от домашните мъже не беше там в къщи,
12 Ó sì di aṣọ Josẹfu mú, ó sì wí pé, “Wá bá mi lòpọ̀!” Ṣùgbọ́n Josẹfu fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí i lọ́wọ́, ó sì sá jáde.
тя го хвана за дрехата и му каза: Легни с мене. Но той остави дрехата си в ръката й, избяга и излезе вън.
13 Nígbà tí ó rí i pé ó ti fi aṣọ rẹ̀ sílẹ̀ sí òun lọ́wọ́, ó sì ti sá jáde,
А като видя, че остави дрехата си в ръката й и избяга вън,
14 ó pe àwọn ìránṣẹ́ ilé náà, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ó, ọkọ ọ̀ mi mú Heberu kan wọlé tọ̀ wá wá láti fi wá ṣe ẹlẹ́yà. Ó wọlé tọ̀ mí wá, láti bá mi lòpọ̀, ṣùgbọ́n mo kígbe.
тя извика домашните си мъже и им говори, казвайки: Вижте, доведе ни един евреин, за да се поругае с нас; той влезе при мене, за да ме изнасили; но аз извиках с висок глас.
15 Nígbà tí ó gbọ́ pé mo gbé ohùn mi sókè, tí mo sì kígbe, ó jọ̀wọ́ aṣọ rẹ̀ sọ́dọ̀ mi, ó sì sá, ó bọ́ sóde.”
А той, като чу, че извиках с висок глас, остави дрехата си при мене и избяга та излезе вън.
16 Ó sì fi aṣọ náà sọ́dọ̀ títí tí ọkọ rẹ̀ fi dé.
И тя задържа дрехата му при себе си, докато си дойде господарят му в дома си.
17 Ó rò fún un pé, “Ẹrú ará Heberu tí o rà wá ilé láti fi wá ṣẹlẹ́yà wá láti bá mi lòpọ̀.
И според тия думи му говори, казвайки: Еврейският слуга, когото ти си ни довел, влезе при мене, за да ми се поругае;
18 Ṣùgbọ́n bí mo ti kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ó sì sá kúrò nínú ilé.”
но, като извиках с висок глас, той остави дрехата си при мене и избяга вън.
19 Nígbà tí Potifari gbọ́ ọ̀rọ̀ aya rẹ̀ pé báyìí ni ẹrú rẹ̀ ṣe sí aya rẹ̀, ó bínú gidigidi.
Като чу господарят му думите, които му рече жена му, казвайки: Така ми стори слугата ти, гневът му пламна.
20 Ó sì ju Josẹfu sí ẹ̀wọ̀n, níbi tí a ń ju àwọn ẹlẹ́wọ̀n ọba sí. Ṣùgbọ́n, nígbà tí Josẹfu wà nínú ẹ̀wọ̀n níbẹ̀,
И господарят му взе Иосифа и го хвърли в крепостната тъмница, в мястото гдето бяха запирани царските затворници; и той остана там в крепостната тъмница.
21 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ṣàánú fún un, ó sì mú kí ó rí ojúrere àwọn alábojútó ọgbà ẹ̀wọ̀n.
Но Господ беше с Иосифа и показваше благост към него и му даде благоволение пред очите на тъмничния началник.
22 Nítorí náà, alábojútó ọgbà ẹlẹ́wọ̀n fi Josẹfu ṣe alákòóso ohun gbogbo tí ó wà nínú ẹ̀wọ̀n, àti ohun tí wọn ń ṣe níbẹ̀.
Тъй че тъмничният началник предаде на Иосифовата ръка всичките затворници, които бяха в крепостната тъмница; и за всичко що се вършеше там, той беше разпоредник.
23 Wọ́dà náà kò sì mikàn nípa gbogbo ohun tí ó fi sí abẹ́ àkóso Josẹfu, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú Josẹfu, ó sì ń jẹ́ kí ó ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé.
Тъмничният началник не нагледваше нищо от онова, което бе в ръката на Иосифа; защото Господ беше с него и Господ правеше да благоуспява всичко, каквото той вършеше.

< Genesis 39 >