< Genesis 38 >

1 Ní àkókò náà, Juda lọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ láti lọ dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin ará Adullamu kan tí ń jẹ́ Hira.
És lőn abban az időben, hogy Júda elméne az ő atyjafiaitól, és betére egy Adullámbeli férfiúhoz, kinek neve Khira vala.
2 Juda sì pàdé ọmọbìnrin Kenaani kan níbẹ̀ ẹni ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣua. Ó sì fi ṣe aya, ó sì bá a lòpọ̀;
És meglátá ott Júda egy Súah nevű Kanaánbeli férfiúnak leányát, és elvevé azt, és beméne hozzá.
3 ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Eri.
És az fogada méhében és szűle fiat, és nevezé nevét Hérnek.
4 Ó sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Onani.
És ismét fogada méhében, s fiat szűle, és nevezé nevét Ónánnak.
5 Ó sì tún bí ọmọkùnrin mìíràn, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣela. Ní Kesibu ni ó wà nígbà tí ó bí i.
Még egyszer szűle fiat, és nevezé nevét Sélának, és mikor azt szűlé, Khezibben vala.
6 Juda sì fẹ́ aya fún Eri, àkọ́bí rẹ̀, orúkọ aya náà ni Tamari.
És vőn Júda az ő elsőszülött fiának Hérnek feleséget, ennek neve Thámár vala.
7 Ṣùgbọ́n Eri àkọ́bí Juda ṣe ènìyàn búburú níwájú Olúwa, Ọlọ́run sì pa á.
De Hér, Júdának elsőszülött fia gonosz vala az Úr szemei előtt, és megölé őt az Úr.
8 Nígbà náà ni Juda wí fún Onani, “Bá aya arákùnrin rẹ lòpọ̀, kí o ṣe ojúṣe rẹ fun un gẹ́gẹ́ bí àbúrò ọkọ, kí ó ba à le bí ọmọ fún un ní orúkọ arákùnrin rẹ.”
És monda Júda Ónánnak: Eredj be a te bátyád feleségéhez, és vedd feleségűl mint sógor, és támaszsz magot bátyádnak.
9 Ṣùgbọ́n Onani mọ̀ pé àwọn ọmọ náà kì yóò jẹ́ ti òun, nítorí náà ni gbogbo ìgbà tí ó bá wọlé tọ aya arákùnrin rẹ̀ lọ, ilẹ̀ ni ó ń da nǹkan ọkùnrin rẹ̀ sí, kí ó má bá a bímọ fún arákùnrin rẹ̀.
Ónán pedig tudja vala, hogy a magzat nem lesz az övé, azért valamikor az ő bátyja feleségéhez bemegy vala, földre vesztegeti vala el a magot, hogy bátyjának magot ne támaszszon.
10 Ohun tí ó ń ṣe yìí burú lójú Olúwa, ó sì pa òun náà pẹ̀lú.
És gonoszságnak tetszék az Úr szemei előtt, a mit cselekeszik vala, annakokáért megölé őt is.
11 Nígbà náà ni Juda wí fún Tamari, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Lọ máa gbé bí opó ní ilé baba rẹ, títí tí Ṣela yóò fi dàgbà ó lérò pé òun náà lè kú bí àwọn arákùnrin rẹ̀ tókù.” Nígbà náà ni Tamari ń lọ gbé ilé baba rẹ̀.
És monda Júda Thámárnak, az ő menyének: Maradj özvegyen addig a te atyád házában, míg az én fiam Séla felnevekedik. Mert így gondolkodik vala: Netalán ez is meghal, mint az ő bátyjai. Elméne azért Thámár, és marada az ő atyja házában.
12 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ìyàwó Juda, ọmọbìnrin Ṣua sì kú, nígbà tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ Juda sì pé, ó gòkè lọ sí Timna, sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ń bá a rẹ́run àgùntàn rẹ̀, Hira ará Adullamu tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀ sì bá a lọ.
Sok idő múlva meghala Súa leánya, a Júda felesége. Júda pedig megvígasztalódék és elméne az ő juhainak nyírőihez, barátjával az Adullámbeli Khirával, Thimnába.
13 Nígbà tí ẹnìkan sọ fún Tamari pé, “Baba ọkọ ọ̀ rẹ̀ wà ní ọ̀nà àjò rẹ̀ sí Timna láti rẹ́run àgùntàn rẹ̀.”
Hírűl adák pedig Thámárnak mondván: Ím a te ipad Thimnába megy juhainak nyírésére.
14 Ó bọ́ aṣọ opó rẹ̀, ó sì fi ìbòjú bo ojú ara rẹ̀ kí wọn má ba à mọ̀ ọ́n. Ó sì jókòó sí ẹnu-bodè Enaimu, èyí tí ó wà ní ọ̀nà Timna. Nítorí ó rí i wí pé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Ṣela ti dàgbà, síbẹ̀, a kò fi òun fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
Leveté azért magáról özvegyi ruháját, elfátyolozá és beburkolá magát, és leűle Enajim kapujába, mely a Thimnába vezető úton van; mert látja vala, hogy felnevekedék Séla, és még sem adák őt annak feleségűl.
15 Nígbà tí Juda rí i, ó rò pé panṣágà ni, nítorí ó ti bo ojú rẹ̀.
Meglátá pedig őt Júda, és tisztátalan személynek gondolá, mivelhogy befedezte vala orczáját.
16 Láìmọ̀ pé, aya ọmọ òun ní í ṣe, ó yà tọ̀ ọ́ ní ẹ̀bá ọ̀nà, ó wí pé, “Wá kí èmi kí ó lè wọlé tọ̀ ọ́.” Òun sì wí pé, “Kín ni ìwọ yóò fi fún mi kí ìwọ kó lè wọlé tọ̀ mí.”
És hozzá tére az útra és monda: Engedd meg kérlek, hogy menjek be te hozzád, mert nem tudja vala, hogy az ő menye az. Ez pedig monda: Mit adsz nékem ha bejösz hozzám?
17 Ó sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọ ewúrẹ́ kan ránṣẹ́ sí ọ láti inú agbo ẹran.” Obìnrin náà sì dáhùn pé, “Ṣé ìwọ yóò fún mi ní ohun kan gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí tí ìwọ yóò fi fi ránṣẹ́?”
És felele: Küldök néked az én nyájamból egy kecskefiat. És az monda: Adsz-é zálogot, míg megküldöd?
18 Juda sì bi í pé, “Ẹ̀rí wo ni kí n fún ọ?” Ó sì dáhùn pé, “Èdìdì ìdámọ̀ okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ rẹ ti ń bẹ ní ọwọ́ rẹ.” Ó sì kó wọn fún un, ó sì sùn tì í, obìnrin náà sì lóyún nípasẹ̀ rẹ̀.
És monda: Micsoda zálogot adjak néked? És monda: Gyűrűdet, gyűrűd zsinórját és pálczádat, mely kezedben van. Oda adá azért néki, és beméne hozzá, és teherbe ejté.
19 Lẹ́yìn ìgbà tí ó lọ, ó bọ́ ìbòjú ojú rẹ̀, ó sì tún wọ aṣọ opó rẹ̀ padà.
Azután felkele és elméne, és leveté magáról a fátyolt; és felvevé az ő özvegyi ruháját.
20 Juda sì rán ọmọ ewúrẹ́ náà láti ọwọ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, ará Adullamu náà lọ láti gba ògo n nì wá lọ́wọ́ obìnrin náà. Ṣùgbọ́n wọn kò bá obìnrin náà níbẹ̀.
És megküldé Júda a kecskefiat az ő Adullámbeli barátjától, hogy visszavegye a zálogot az asszonytól, de nem találá azt.
21 Ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn àdúgbò náà pé, “Níbo ni alágbèrè ojúbọ òrìṣà tí ó wà ní etí ọ̀nà Enaimu wà?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbí.”
És megkérdé a helység férfiait, mondván: Hol van az a felavatott parázna nő, a ki Enajim mellett az útfélen vala? És azok mondának: Nem volt erre felavatott parázna nő.
22 Ó sì padà lọ sọ́dọ̀ Juda ó wí fún un pé, “Èmí kò rí i, à ti pé àwọn aládùúgbò ibẹ̀ sọ pé kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbẹ̀.”
Visszatére tehát Júdához, és monda: Nem találám azt meg, a helység lakosai is azt mondák: Nem volt erre felavatott parázna nő.
23 Nígbà náà ni Juda wí pé, “Jẹ́ kí ó máa kó àwọn ohun tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ lọ bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ a ó di ẹlẹ́yà. Mo sá à fi ọmọ ewúrẹ́ ránṣẹ́ sí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò rí òun.”
És monda Júda: Tartsa magának, hogy csúffá ne legyünk; ímé én megküldöttem volt ezt a kecskefiat, te pedig nem találtad meg őt.
24 Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù mẹ́ta, wọn sọ fún Juda pé, “Tamari aya ọmọ rẹ̀ ṣe àgbèrè, ó sì ti lóyún.” Juda sì wí pé, “Ẹ mú un jáde, kí ẹ sì dá iná sun ún.”
És lőn mintegy három hónap múlva, jelenték Júdának, mondván: Thámár a te menyed paráználkodott, és ímé terhes is a paráznaság miatt. És monda Júda: Vigyétek ki őt, és égettessék meg.
25 Bí wọ́n sì ti ń mú un jáde, ó ránṣẹ́ sí baba ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó ni àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó fún mi lóyún. Wò ó, bóyá o lè mọ ẹni tí ó ni èdìdì ìdámọ̀, okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọ̀nyí.”
Mikor pedig kivitetnék, elkülde az ő ipához, mondván: Attól a férfiútól vagyok terhes, a kiéi ezek. És mondá: Ismerd meg, kérlek, kié e gyűrű, e zsinór, és e pálcza.
26 Juda sì dá wọn mọ̀, ó sì wí pé, “O ṣe olódodo jù mí lọ, níwọ̀n ìgbà tí n kò fi fún Ṣela ọmọ mi.” Kò sì bá a lòpọ̀ mọ́ láti ọjọ́ náà.
És megismeré Júda és monda: Igazabb ő nálamnál, mert bizony nem adám őt az én fiamnak Sélának; de nem ismeré őt Júda többé.
27 Nígbà tí àsìkò ìbímọ rẹ̀ tó. Ìbejì ọkùnrin ni ó bí.
És lőn az ő szűlésének idején, ímé kettősök valának az ő méhében.
28 Bí ó sì ti ń bímọ, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà na ọwọ́ jáde; agbẹ̀bí sì so okùn òdòdó mọ́ ọmọ náà ní ọrùn ọwọ́. Ó sì wí pé, “Èyí ni o kọ́kọ́ jáde.”
És lőn, hogy szűlése közben az egyik kinyújtá kezét, és fogá a bába és veres fonalat köte reá, mondván: Ez jött ki először.
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó fa ọwọ́ rẹ̀ padà, èkejì rẹ̀ jáde. Tamari sì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Peresi.
De lőn, hogy a mikor visszavoná kezét, ímé az ő testvére jöve ki. És mondá a bába: Hogy törtél te magadnak rést? Azért nevezé nevét Pérecznek.
30 Nígbà náà ni èkejì tí a ti so okùn olódòdó mọ́ lọ́rùn ọwọ́ jáde, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ni Sera.
És utána kijöve az ő testvére kinek veres fonál vala kezén; és nevezé nevét Zerákhnak.

< Genesis 38 >