< Genesis 38 >

1 Ní àkókò náà, Juda lọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ láti lọ dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin ará Adullamu kan tí ń jẹ́ Hira.
En ce temps-là, Juda descendit de chez ses frères, et se rendit chez un certain Adullamite, dont le nom était Hira.
2 Juda sì pàdé ọmọbìnrin Kenaani kan níbẹ̀ ẹni ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣua. Ó sì fi ṣe aya, ó sì bá a lòpọ̀;
Là, Juda vit la fille d'un homme de Canaan, nommé Schua. Il la prit, et alla vers elle.
3 ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Eri.
Elle devint enceinte, et enfanta un fils, qu'il appela Er.
4 Ó sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Onani.
Elle conçut encore, et enfanta un fils, qu'elle appela Onan.
5 Ó sì tún bí ọmọkùnrin mìíràn, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣela. Ní Kesibu ni ó wà nígbà tí ó bí i.
Elle enfanta encore un fils, qu'elle appela Schéla. Il était à Chezib lorsqu'elle l'enfanta.
6 Juda sì fẹ́ aya fún Eri, àkọ́bí rẹ̀, orúkọ aya náà ni Tamari.
Juda prit une femme pour Er, son premier-né, et elle s'appela Tamar.
7 Ṣùgbọ́n Eri àkọ́bí Juda ṣe ènìyàn búburú níwájú Olúwa, Ọlọ́run sì pa á.
Er, le premier-né de Juda, était méchant aux yeux de l'Éternel. Aussi Yahvé le fit-il mourir.
8 Nígbà náà ni Juda wí fún Onani, “Bá aya arákùnrin rẹ lòpọ̀, kí o ṣe ojúṣe rẹ fun un gẹ́gẹ́ bí àbúrò ọkọ, kí ó ba à le bí ọmọ fún un ní orúkọ arákùnrin rẹ.”
Juda dit à Onan: « Va vers la femme de ton frère, accomplis envers elle le devoir d'un frère de mari, et suscite une descendance pour ton frère. »
9 Ṣùgbọ́n Onani mọ̀ pé àwọn ọmọ náà kì yóò jẹ́ ti òun, nítorí náà ni gbogbo ìgbà tí ó bá wọlé tọ aya arákùnrin rẹ̀ lọ, ilẹ̀ ni ó ń da nǹkan ọkùnrin rẹ̀ sí, kí ó má bá a bímọ fún arákùnrin rẹ̀.
Onan savait que la descendance ne serait pas la sienne; et quand il entra chez la femme de son frère, il répandit sa semence sur le sol, de peur de donner une descendance à son frère.
10 Ohun tí ó ń ṣe yìí burú lójú Olúwa, ó sì pa òun náà pẹ̀lú.
La chose qu'il fit fut mauvaise aux yeux de l'Éternel, qui le fit aussi mourir.
11 Nígbà náà ni Juda wí fún Tamari, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Lọ máa gbé bí opó ní ilé baba rẹ, títí tí Ṣela yóò fi dàgbà ó lérò pé òun náà lè kú bí àwọn arákùnrin rẹ̀ tókù.” Nígbà náà ni Tamari ń lọ gbé ilé baba rẹ̀.
Juda dit alors à Tamar, sa belle-fille: « Reste veuve dans la maison de ton père, jusqu'à ce que mon fils Schéla ait grandi, car il disait: « De peur qu'il ne meure, lui aussi, comme ses frères. » Tamar alla vivre dans la maison de son père.
12 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ìyàwó Juda, ọmọbìnrin Ṣua sì kú, nígbà tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ Juda sì pé, ó gòkè lọ sí Timna, sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ń bá a rẹ́run àgùntàn rẹ̀, Hira ará Adullamu tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀ sì bá a lọ.
Après plusieurs jours, la fille de Shua, la femme de Juda, mourut. Juda fut consolé, et il monta à Timna pour tondre ses moutons, lui et son ami Hira, l'Adullamite.
13 Nígbà tí ẹnìkan sọ fún Tamari pé, “Baba ọkọ ọ̀ rẹ̀ wà ní ọ̀nà àjò rẹ̀ sí Timna láti rẹ́run àgùntàn rẹ̀.”
On dit à Tamar: « Voici ton beau-père qui monte à Thimna pour tondre ses brebis. »
14 Ó bọ́ aṣọ opó rẹ̀, ó sì fi ìbòjú bo ojú ara rẹ̀ kí wọn má ba à mọ̀ ọ́n. Ó sì jókòó sí ẹnu-bodè Enaimu, èyí tí ó wà ní ọ̀nà Timna. Nítorí ó rí i wí pé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Ṣela ti dàgbà, síbẹ̀, a kò fi òun fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
Elle ôta les vêtements de son veuvage, se couvrit de son voile, s'enveloppa et s'assit à la porte d'Énaïm, qui est sur le chemin de Timna; car elle vit que Shélah était devenu grand, et qu'elle ne lui avait pas été donnée pour femme.
15 Nígbà tí Juda rí i, ó rò pé panṣágà ni, nítorí ó ti bo ojú rẹ̀.
Lorsque Juda la vit, il pensa que c'était une prostituée, car elle avait couvert son visage.
16 Láìmọ̀ pé, aya ọmọ òun ní í ṣe, ó yà tọ̀ ọ́ ní ẹ̀bá ọ̀nà, ó wí pé, “Wá kí èmi kí ó lè wọlé tọ̀ ọ́.” Òun sì wí pé, “Kín ni ìwọ yóò fi fún mi kí ìwọ kó lè wọlé tọ̀ mí.”
Il se tourna vers elle par le chemin et dit: « Viens, je t'en prie, laisse-moi entrer chez toi », car il ne savait pas qu'elle était sa belle-fille. Elle a dit: « Que me donneras-tu pour que tu entres chez moi? »
17 Ó sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọ ewúrẹ́ kan ránṣẹ́ sí ọ láti inú agbo ẹran.” Obìnrin náà sì dáhùn pé, “Ṣé ìwọ yóò fún mi ní ohun kan gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí tí ìwọ yóò fi fi ránṣẹ́?”
Il dit: « Je t'enverrai un chevreau du troupeau. » Elle a dit: « Tu me donneras un gage, jusqu'à ce que tu l'envoies? »
18 Juda sì bi í pé, “Ẹ̀rí wo ni kí n fún ọ?” Ó sì dáhùn pé, “Èdìdì ìdámọ̀ okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ rẹ ti ń bẹ ní ọwọ́ rẹ.” Ó sì kó wọn fún un, ó sì sùn tì í, obìnrin náà sì lóyún nípasẹ̀ rẹ̀.
Il a dit: « Quel gage vais-je te donner? » Elle a dit: « Ton sceau, ton cordon et le bâton que tu tiens à la main. » Il les lui donna; il entra chez elle, et elle devint enceinte de lui.
19 Lẹ́yìn ìgbà tí ó lọ, ó bọ́ ìbòjú ojú rẹ̀, ó sì tún wọ aṣọ opó rẹ̀ padà.
Elle se leva et s'en alla, ôta son voile et revêtit les vêtements de son veuvage.
20 Juda sì rán ọmọ ewúrẹ́ náà láti ọwọ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, ará Adullamu náà lọ láti gba ògo n nì wá lọ́wọ́ obìnrin náà. Ṣùgbọ́n wọn kò bá obìnrin náà níbẹ̀.
Juda envoya le chevreau par la main de son ami, l'Adullamite, pour recevoir le gage de la main de la femme, mais il ne la trouva pas.
21 Ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn àdúgbò náà pé, “Níbo ni alágbèrè ojúbọ òrìṣà tí ó wà ní etí ọ̀nà Enaimu wà?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbí.”
Alors il interrogea les hommes de son lieu de résidence, en disant: « Où est la prostituée qui était à Enaïm, au bord de la route? » Ils ont dit: « Il n'y a pas eu de prostituée ici. »
22 Ó sì padà lọ sọ́dọ̀ Juda ó wí fún un pé, “Èmí kò rí i, à ti pé àwọn aládùúgbò ibẹ̀ sọ pé kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbẹ̀.”
Il retourna auprès de Juda, et dit: « Je ne l'ai pas trouvée, et les gens du lieu ont dit: « Il n'y a pas eu de prostituée ici. »
23 Nígbà náà ni Juda wí pé, “Jẹ́ kí ó máa kó àwọn ohun tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ lọ bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ a ó di ẹlẹ́yà. Mo sá à fi ọmọ ewúrẹ́ ránṣẹ́ sí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò rí òun.”
Juda dit: « Qu'elle la garde, de peur que nous ne soyons déshonorés. Voici que j'ai envoyé ce chevreau, et vous ne l'avez pas trouvée. »
24 Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù mẹ́ta, wọn sọ fún Juda pé, “Tamari aya ọmọ rẹ̀ ṣe àgbèrè, ó sì ti lóyún.” Juda sì wí pé, “Ẹ mú un jáde, kí ẹ sì dá iná sun ún.”
Environ trois mois plus tard, Juda fut informé: « Tamar, ta belle-fille, s'est prostituée. De plus, voici qu'elle est enceinte par prostitution. » Juda dit: « Fais-la sortir, et qu'on la brûle. »
25 Bí wọ́n sì ti ń mú un jáde, ó ránṣẹ́ sí baba ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó ni àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó fún mi lóyún. Wò ó, bóyá o lè mọ ẹni tí ó ni èdìdì ìdámọ̀, okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọ̀nyí.”
Quand elle fut sortie, elle envoya dire à son beau-père: « Je suis enceinte de l'homme à qui appartiennent ces objets. » Elle dit aussi: « Je te prie de discerner à qui appartiennent ces objets: le sceau, les cordons et le bâton. »
26 Juda sì dá wọn mọ̀, ó sì wí pé, “O ṣe olódodo jù mí lọ, níwọ̀n ìgbà tí n kò fi fún Ṣela ọmọ mi.” Kò sì bá a lòpọ̀ mọ́ láti ọjọ́ náà.
Juda les reconnut et dit: « Elle est plus juste que moi, car je ne l'ai pas donnée à Shéla, mon fils. » Il ne la connut plus.
27 Nígbà tí àsìkò ìbímọ rẹ̀ tó. Ìbejì ọkùnrin ni ó bí.
Au moment où elle accouchait, voici, des jumeaux étaient dans son sein.
28 Bí ó sì ti ń bímọ, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà na ọwọ́ jáde; agbẹ̀bí sì so okùn òdòdó mọ́ ọmọ náà ní ọrùn ọwọ́. Ó sì wí pé, “Èyí ni o kọ́kọ́ jáde.”
Comme elle était en travail, l'un d'eux étendit la main; la sage-femme prit un fil écarlate et l'attacha à sa main, en disant: « Celui-ci est sorti le premier. »
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó fa ọwọ́ rẹ̀ padà, èkejì rẹ̀ jáde. Tamari sì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Peresi.
Comme il retirait sa main, voici que son frère sortit, et elle dit: « Pourquoi t'es-tu fait une brèche? » C'est pourquoi on lui donna le nom de Pérez.
30 Nígbà náà ni èkejì tí a ti so okùn olódòdó mọ́ lọ́rùn ọwọ́ jáde, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ni Sera.
Ensuite sortit son frère, qui avait un fil cramoisi à la main, et on l'appela Zérach.

< Genesis 38 >