< Genesis 38 >
1 Ní àkókò náà, Juda lọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ láti lọ dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin ará Adullamu kan tí ń jẹ́ Hira.
And it cometh to pass, at that time, that Judah goeth down from his brethren, and turneth aside unto a man, an Adullamite, whose name [is] Hirah;
2 Juda sì pàdé ọmọbìnrin Kenaani kan níbẹ̀ ẹni ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣua. Ó sì fi ṣe aya, ó sì bá a lòpọ̀;
and Judah seeth there the daughter of a man, a Canaanite, whose name [is] Shuah, and taketh her, and goeth in unto her.
3 ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Eri.
And she conceiveth, and beareth a son, and he calleth his name Er;
4 Ó sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Onani.
and she conceiveth again, and beareth a son, and calleth his name Onan;
5 Ó sì tún bí ọmọkùnrin mìíràn, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣela. Ní Kesibu ni ó wà nígbà tí ó bí i.
and she addeth again, and beareth a son, and calleth his name Shelah; and he was in Chezib in her bearing him.
6 Juda sì fẹ́ aya fún Eri, àkọ́bí rẹ̀, orúkọ aya náà ni Tamari.
And Judah taketh a wife for Er, his first-born, and her name [is] Tamar;
7 Ṣùgbọ́n Eri àkọ́bí Juda ṣe ènìyàn búburú níwájú Olúwa, Ọlọ́run sì pa á.
and Er, Judah's first-born, is evil in the eyes of Jehovah, and Jehovah doth put him to death.
8 Nígbà náà ni Juda wí fún Onani, “Bá aya arákùnrin rẹ lòpọ̀, kí o ṣe ojúṣe rẹ fun un gẹ́gẹ́ bí àbúrò ọkọ, kí ó ba à le bí ọmọ fún un ní orúkọ arákùnrin rẹ.”
And Judah saith to Onan, 'Go in unto the wife of thy brother, and marry her, and raise up seed to thy brother;'
9 Ṣùgbọ́n Onani mọ̀ pé àwọn ọmọ náà kì yóò jẹ́ ti òun, nítorí náà ni gbogbo ìgbà tí ó bá wọlé tọ aya arákùnrin rẹ̀ lọ, ilẹ̀ ni ó ń da nǹkan ọkùnrin rẹ̀ sí, kí ó má bá a bímọ fún arákùnrin rẹ̀.
and Onan knoweth that the seed is not [reckoned] his; and it hath come to pass, if he hath gone in unto his brother's wife, that he hath destroyed [it] to the earth, so as not to give seed to his brother;
10 Ohun tí ó ń ṣe yìí burú lójú Olúwa, ó sì pa òun náà pẹ̀lú.
and that which he hath done is evil in the eyes of Jehovah, and He putteth him also to death.
11 Nígbà náà ni Juda wí fún Tamari, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Lọ máa gbé bí opó ní ilé baba rẹ, títí tí Ṣela yóò fi dàgbà ó lérò pé òun náà lè kú bí àwọn arákùnrin rẹ̀ tókù.” Nígbà náà ni Tamari ń lọ gbé ilé baba rẹ̀.
And Judah saith to Tamar his daughter-in-law, 'Abide a widow at thy father's house, till Shelah my son groweth up;' for he said, 'Lest he die — even he — like his brethren;' and Tamar goeth and dwelleth at her father's house.
12 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ìyàwó Juda, ọmọbìnrin Ṣua sì kú, nígbà tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ Juda sì pé, ó gòkè lọ sí Timna, sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ń bá a rẹ́run àgùntàn rẹ̀, Hira ará Adullamu tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀ sì bá a lọ.
And the days are multiplied, and the daughter of Shuah, Judah's wife, dieth; and Judah is comforted, and goeth up unto his sheep-shearers, he and Hirah his friend the Adullamite, to Timnath.
13 Nígbà tí ẹnìkan sọ fún Tamari pé, “Baba ọkọ ọ̀ rẹ̀ wà ní ọ̀nà àjò rẹ̀ sí Timna láti rẹ́run àgùntàn rẹ̀.”
And it is declared to Tamar, saying, 'Lo, thy husband's father is going up to Timnath to shear his flock;'
14 Ó bọ́ aṣọ opó rẹ̀, ó sì fi ìbòjú bo ojú ara rẹ̀ kí wọn má ba à mọ̀ ọ́n. Ó sì jókòó sí ẹnu-bodè Enaimu, èyí tí ó wà ní ọ̀nà Timna. Nítorí ó rí i wí pé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Ṣela ti dàgbà, síbẹ̀, a kò fi òun fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
and she turneth aside the garments of her widowhood from off her, and covereth herself with a vail, and wrappeth herself up, and sitteth in the opening of Enayim, which [is] by the way to Timnath, for she hath seen that Shelah hath grown up, and she hath not been given to him for a wife.
15 Nígbà tí Juda rí i, ó rò pé panṣágà ni, nítorí ó ti bo ojú rẹ̀.
And Judah seeth her, and reckoneth her for a harlot, for she hath covered her face,
16 Láìmọ̀ pé, aya ọmọ òun ní í ṣe, ó yà tọ̀ ọ́ ní ẹ̀bá ọ̀nà, ó wí pé, “Wá kí èmi kí ó lè wọlé tọ̀ ọ́.” Òun sì wí pé, “Kín ni ìwọ yóò fi fún mi kí ìwọ kó lè wọlé tọ̀ mí.”
and he turneth aside unto her by the way, and saith, 'Come, I pray thee, let me come in unto thee,' (for he hath not known that she [is] his daughter-in-law); and she saith, 'What dost thou give to me, that thou mayest come in unto me?'
17 Ó sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọ ewúrẹ́ kan ránṣẹ́ sí ọ láti inú agbo ẹran.” Obìnrin náà sì dáhùn pé, “Ṣé ìwọ yóò fún mi ní ohun kan gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí tí ìwọ yóò fi fi ránṣẹ́?”
and he saith, 'I — I send a kid of the goats from the flock.' And she saith, 'Dost thou give a pledge till thou send [it]?'
18 Juda sì bi í pé, “Ẹ̀rí wo ni kí n fún ọ?” Ó sì dáhùn pé, “Èdìdì ìdámọ̀ okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ rẹ ti ń bẹ ní ọwọ́ rẹ.” Ó sì kó wọn fún un, ó sì sùn tì í, obìnrin náà sì lóyún nípasẹ̀ rẹ̀.
and he saith, 'What [is] the pledge that I give to thee?' and she saith, 'Thy seal, and thy ribbon, and thy staff which [is] in thy hand;' and he giveth to her, and goeth in unto her, and she conceiveth to him;
19 Lẹ́yìn ìgbà tí ó lọ, ó bọ́ ìbòjú ojú rẹ̀, ó sì tún wọ aṣọ opó rẹ̀ padà.
and she riseth, and goeth, and turneth aside her vail from off her, and putteth on the garments of her widowhood.
20 Juda sì rán ọmọ ewúrẹ́ náà láti ọwọ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, ará Adullamu náà lọ láti gba ògo n nì wá lọ́wọ́ obìnrin náà. Ṣùgbọ́n wọn kò bá obìnrin náà níbẹ̀.
And Judah sendeth the kid of the goats by the hand of his friend the Adullamite, to receive the pledge from the hand of the woman, and he hath not found her.
21 Ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn àdúgbò náà pé, “Níbo ni alágbèrè ojúbọ òrìṣà tí ó wà ní etí ọ̀nà Enaimu wà?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbí.”
And he asketh the men of her place, saying, 'Where [is] the separated one — she in Enayim, by the way?' and they say, 'There hath not been in this [place] a separated one.'
22 Ó sì padà lọ sọ́dọ̀ Juda ó wí fún un pé, “Èmí kò rí i, à ti pé àwọn aládùúgbò ibẹ̀ sọ pé kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbẹ̀.”
And he turneth back unto Judah, and saith, 'I have not found her; and the men of the place also have said, There hath not been in this [place] a separated one,'
23 Nígbà náà ni Juda wí pé, “Jẹ́ kí ó máa kó àwọn ohun tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ lọ bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ a ó di ẹlẹ́yà. Mo sá à fi ọmọ ewúrẹ́ ránṣẹ́ sí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò rí òun.”
and Judah saith, 'Let her take to herself, lest we become despised; lo, I sent this kid, and thou hast not found her.'
24 Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù mẹ́ta, wọn sọ fún Juda pé, “Tamari aya ọmọ rẹ̀ ṣe àgbèrè, ó sì ti lóyún.” Juda sì wí pé, “Ẹ mú un jáde, kí ẹ sì dá iná sun ún.”
And it cometh to pass about three months [after], that it is declared to Judah, saying, 'Tamar thy daughter-in-law hath committed fornication; and also, lo, she hath conceived by fornication:' and Judah saith, 'Bring her out — and she is burnt.'
25 Bí wọ́n sì ti ń mú un jáde, ó ránṣẹ́ sí baba ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó ni àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó fún mi lóyún. Wò ó, bóyá o lè mọ ẹni tí ó ni èdìdì ìdámọ̀, okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọ̀nyí.”
She is brought out, and she hath sent unto her husband's father, saying, 'To a man whose these [are], I [am] pregnant;' and she saith, 'Discern, I pray thee, whose [are] these — the seal, and the ribbons, and the staff.'
26 Juda sì dá wọn mọ̀, ó sì wí pé, “O ṣe olódodo jù mí lọ, níwọ̀n ìgbà tí n kò fi fún Ṣela ọmọ mi.” Kò sì bá a lòpọ̀ mọ́ láti ọjọ́ náà.
And Judah discerneth and saith, 'She hath been more righteous than I, because that I did not give her to Shelah my son;' and he hath not added to know her again.
27 Nígbà tí àsìkò ìbímọ rẹ̀ tó. Ìbejì ọkùnrin ni ó bí.
And it cometh to pass in the time of her bearing, that lo, twins [are] in her womb;
28 Bí ó sì ti ń bímọ, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà na ọwọ́ jáde; agbẹ̀bí sì so okùn òdòdó mọ́ ọmọ náà ní ọrùn ọwọ́. Ó sì wí pé, “Èyí ni o kọ́kọ́ jáde.”
and it cometh to pass in her bearing, that [one] giveth out a hand, and the midwife taketh and bindeth on his hand a scarlet thread, saying, 'This hath come out first.'
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó fa ọwọ́ rẹ̀ padà, èkejì rẹ̀ jáde. Tamari sì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Peresi.
And it cometh to pass as he draweth back his hand, that lo, his brother hath come out, and she saith, 'What! thou hast broken forth — on thee [is] the breach;' and he calleth his name Pharez;
30 Nígbà náà ni èkejì tí a ti so okùn olódòdó mọ́ lọ́rùn ọwọ́ jáde, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ni Sera.
and afterwards hath his brother come out, on whose hand [is] the scarlet thread, and he calleth his name Zarah.