< Genesis 38 >

1 Ní àkókò náà, Juda lọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ láti lọ dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin ará Adullamu kan tí ń jẹ́ Hira.
At that time, Judah left his older and younger brothers and went down from the hilly area and stayed with a man whose name was Hiram, who lived in Adullam [town].
2 Juda sì pàdé ọmọbìnrin Kenaani kan níbẹ̀ ẹni ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣua. Ó sì fi ṣe aya, ó sì bá a lòpọ̀;
There he (met/became acquainted with) a woman who was the daughter of a man from Canaan named Shua. He married her. He had sex [EUP] with her,
3 ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Eri.
and she became pregnant and later gave birth to a son, whom he named Er.
4 Ó sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Onani.
Later she became pregnant again and gave birth to another son whom she named Onan.
5 Ó sì tún bí ọmọkùnrin mìíràn, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣela. Ní Kesibu ni ó wà nígbà tí ó bí i.
Many years later, when Judah and his family went to live in Kezib [town], Judah’s wife gave birth to another son, whom she named Shelah.
6 Juda sì fẹ́ aya fún Eri, àkọ́bí rẹ̀, orúkọ aya náà ni Tamari.
When Judah’s oldest son Er [grew up], Judah got a wife for him, a woman named Tamar.
7 Ṣùgbọ́n Eri àkọ́bí Juda ṣe ènìyàn búburú níwájú Olúwa, Ọlọ́run sì pa á.
But Er did something that Yahweh considered to be very wicked, so Yahweh caused him to die.
8 Nígbà náà ni Juda wí fún Onani, “Bá aya arákùnrin rẹ lòpọ̀, kí o ṣe ojúṣe rẹ fun un gẹ́gẹ́ bí àbúrò ọkọ, kí ó ba à le bí ọmọ fún un ní orúkọ arákùnrin rẹ.”
Then Judah said to Onan, “Your older brother died without having any sons. So marry his widow and have sex [EUP] with her. That is what our customs require that you should do.”
9 Ṣùgbọ́n Onani mọ̀ pé àwọn ọmọ náà kì yóò jẹ́ ti òun, nítorí náà ni gbogbo ìgbà tí ó bá wọlé tọ aya arákùnrin rẹ̀ lọ, ilẹ̀ ni ó ń da nǹkan ọkùnrin rẹ̀ sí, kí ó má bá a bímọ fún arákùnrin rẹ̀.
But Onan knew if he did that, any children who would be born would not be considered to be his. So every time he had sex [EUP] with his brother’s widow, he spilled his semen on the ground, so that she would not get pregnant and produce children for his older brother.
10 Ohun tí ó ń ṣe yìí burú lójú Olúwa, ó sì pa òun náà pẹ̀lú.
Yahweh considered that what he did was wicked, so he caused him to die also.
11 Nígbà náà ni Juda wí fún Tamari, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Lọ máa gbé bí opó ní ilé baba rẹ, títí tí Ṣela yóò fi dàgbà ó lérò pé òun náà lè kú bí àwọn arákùnrin rẹ̀ tókù.” Nígbà náà ni Tamari ń lọ gbé ilé baba rẹ̀.
Then Judah said to his daughter-in-law Tamar, “Return to your father’s house, but do not marry anyone else. When my youngest son Shelah grows up, [he can marry you].” But Judah [really did not want Shelah to marry her, because] he was afraid that then Shelah would die too, just as his older brothers had died. So Tamar [obeyed Judah and] went back to live in her father’s house again.
12 Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ìyàwó Juda, ọmọbìnrin Ṣua sì kú, nígbà tí ọjọ́ ọ̀fọ̀ Juda sì pé, ó gòkè lọ sí Timna, sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ń bá a rẹ́run àgùntàn rẹ̀, Hira ará Adullamu tí í ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀ sì bá a lọ.
Several years later, Judah’s wife, who was the daughter of Shua, died. When the time of mourning for her was finished, Judah decided to go up to Timnah, to the place where his (men were shearing his sheep/sheep were being sheared) His friend Hiram, from Adullam, went with him.
13 Nígbà tí ẹnìkan sọ fún Tamari pé, “Baba ọkọ ọ̀ rẹ̀ wà ní ọ̀nà àjò rẹ̀ sí Timna láti rẹ́run àgùntàn rẹ̀.”
Someone said to Tamar, “Your father-in-law is going to [the fields near the city of] Timnah to help the men who are shearing his sheep.”
14 Ó bọ́ aṣọ opó rẹ̀, ó sì fi ìbòjú bo ojú ara rẹ̀ kí wọn má ba à mọ̀ ọ́n. Ó sì jókòó sí ẹnu-bodè Enaimu, èyí tí ó wà ní ọ̀nà Timna. Nítorí ó rí i wí pé, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Ṣela ti dàgbà, síbẹ̀, a kò fi òun fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
[She realized that now Shelah was grown up, but Judah had not given her to him to be his wife. So] she took off her widow’s clothes, and covered her head with a veil, so that people would not (recognize her/know who she was). Then she sat down at the entrance to Enaim [town], which is on the road to Timnah.
15 Nígbà tí Juda rí i, ó rò pé panṣágà ni, nítorí ó ti bo ojú rẹ̀.
When Judah came along and saw her, he thought that she was a prostitute, because she had covered her head [like prostitutes often did] (OR, [and sat where prostitutes often sat)].
16 Láìmọ̀ pé, aya ọmọ òun ní í ṣe, ó yà tọ̀ ọ́ ní ẹ̀bá ọ̀nà, ó wí pé, “Wá kí èmi kí ó lè wọlé tọ̀ ọ́.” Òun sì wí pé, “Kín ni ìwọ yóò fi fún mi kí ìwọ kó lè wọlé tọ̀ mí.”
Judah did not realize that she was his daughter-in-law. So he said to her, “Hey, let me have sex [EUP] with you!” She replied, “What will you give me for allowing you to have sex [EUP] with me?”
17 Ó sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọ ewúrẹ́ kan ránṣẹ́ sí ọ láti inú agbo ẹran.” Obìnrin náà sì dáhùn pé, “Ṣé ìwọ yóò fún mi ní ohun kan gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí tí ìwọ yóò fi fi ránṣẹ́?”
He replied, “I will send you a young goat from my flock of goats.” She asked, “Will you give me something now for me to keep until you send the goat?”
18 Juda sì bi í pé, “Ẹ̀rí wo ni kí n fún ọ?” Ó sì dáhùn pé, “Èdìdì ìdámọ̀ okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ rẹ ti ń bẹ ní ọwọ́ rẹ.” Ó sì kó wọn fún un, ó sì sùn tì í, obìnrin náà sì lóyún nípasẹ̀ rẹ̀.
He replied, “What do you want me to give to you?” She replied, “Give me the ring that has your name on it that is tied by a cord around your neck, and give me the walking stick that you are holding in your hand.” So he gave them to her. Then he had sex [EUP] with her, and she became pregnant.
19 Lẹ́yìn ìgbà tí ó lọ, ó bọ́ ìbòjú ojú rẹ̀, ó sì tún wọ aṣọ opó rẹ̀ padà.
After she left, she took off the veil and put her widow’s clothes on again.
20 Juda sì rán ọmọ ewúrẹ́ náà láti ọwọ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, ará Adullamu náà lọ láti gba ògo n nì wá lọ́wọ́ obìnrin náà. Ṣùgbọ́n wọn kò bá obìnrin náà níbẹ̀.
Judah gave a young goat to his friend from Adullam, for him to take back to the woman, as he had promised. But his friend could not find the woman.
21 Ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn àdúgbò náà pé, “Níbo ni alágbèrè ojúbọ òrìṣà tí ó wà ní etí ọ̀nà Enaimu wà?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbí.”
So he asked the men who lived there, “Where is the prostitute who was sitting by the road at Enaim?” They replied, “There has never been a prostitute here!”
22 Ó sì padà lọ sọ́dọ̀ Juda ó wí fún un pé, “Èmí kò rí i, à ti pé àwọn aládùúgbò ibẹ̀ sọ pé kò sí alágbèrè ojúbọ òrìṣà kankan níbẹ̀.”
So he went back to Judah and said, “I did not find her. [Furthermore], the men who live in that town said, ‘There has never been a prostitute here.’”
23 Nígbà náà ni Juda wí pé, “Jẹ́ kí ó máa kó àwọn ohun tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ lọ bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ a ó di ẹlẹ́yà. Mo sá à fi ọmọ ewúrẹ́ ránṣẹ́ sí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò rí òun.”
Judah said, “She can keep the things that I gave to her. If we continued to search for her, people would ridicule us. I tried to send this young goat to her, but you could not find her to give it to her.”
24 Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù mẹ́ta, wọn sọ fún Juda pé, “Tamari aya ọmọ rẹ̀ ṣe àgbèrè, ó sì ti lóyún.” Juda sì wí pé, “Ẹ mú un jáde, kí ẹ sì dá iná sun ún.”
About three months later, someone told Judah, “Your daughter-in-law Tamar has become a prostitute and now she is pregnant!” Judah said, “Drag her outside of the city and kill her by burning her!”
25 Bí wọ́n sì ti ń mú un jáde, ó ránṣẹ́ sí baba ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó ni àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó fún mi lóyún. Wò ó, bóyá o lè mọ ẹni tí ó ni èdìdì ìdámọ̀, okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọ̀nyí.”
But as they were taking her outside of the city, she gave the ring and walking stick to someone, and told him to take them to Judah, and say to him, “The man who owns these things is the one who caused me to become pregnant.” She also said to tell him, “Look at this ring, and the cord that is attached to it, and this walking stick. Whose are they?”
26 Juda sì dá wọn mọ̀, ó sì wí pé, “O ṣe olódodo jù mí lọ, níwọ̀n ìgbà tí n kò fi fún Ṣela ọmọ mi.” Kò sì bá a lòpọ̀ mọ́ láti ọjọ́ náà.
When the man did that, Judah recognized the ring and the stick. He said, “She is more righteous than I am. I did not tell my son Shelah to marry her, as I promised that I would.” And Judah did not have sex [EUP] with her again.
27 Nígbà tí àsìkò ìbímọ rẹ̀ tó. Ìbejì ọkùnrin ni ó bí.
When it was time for her to give birth, [she was surprised that] there were twin boys in her womb.
28 Bí ó sì ti ń bímọ, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà na ọwọ́ jáde; agbẹ̀bí sì so okùn òdòdó mọ́ ọmọ náà ní ọrùn ọwọ́. Ó sì wí pé, “Èyí ni o kọ́kọ́ jáde.”
As she was giving birth, one of them put out his hand. So the midwife fastened a scarlet thread around his wrist, saying, “This one came out first.”
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó fa ọwọ́ rẹ̀ padà, èkejì rẹ̀ jáde. Tamari sì wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Peresi.
But he pulled his hand back inside the womb, and his brother came out first. So she said, “So this is how you break your way out first!” So she named him Perez, [which sounds like the Hebrew word that means ‘breaking out].’
30 Nígbà náà ni èkejì tí a ti so okùn olódòdó mọ́ lọ́rùn ọwọ́ jáde, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ni Sera.
Then his younger brother, the one who had the scarlet thread around his wrist, came out. And he was named Zerah, [which sounds like the Hebrew word that means ‘redness of dawn].’

< Genesis 38 >