< Genesis 37 >

1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
Men Jacob bodde i de landena, der hans fader var en främling uti, nemliga i Canaans lande.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
Och detta är Jacobs slägt: Joseph var sjutton år gammal, då han vardt en herde öfver hjorden med sina bröder; och pilten var när Bilhas och Silpas sins faders hustrurs barnom; och han sade för deras fader, hvilket ondt rykte öfver dem var.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
Men Israel hade Joseph kärare än alla de andra sin barn, efter han hade födt honom i ålderdomen: Och gjorde honom en brokot kjortel.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
Då nu hans bröder sågo, att deras fader hade honom kärare än alla hans bröder, vordo de honom hätske, och kunde icke tala honom ett vänligit ord till.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
Derutöfver hade Joseph ena reso en dröm, och sade sina bröder deraf. Då blefvo de honom ännu hätskare.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
Ty han sade till dem: Käre, hörer hvad mig hafver drömt.
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
Mig tyckte vi bundom kärfvar på markene, och min kärfve reste sig upp och stod; och edre kärfvar der omkring bugade sig för min kärfva.
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
Då sade hans bröder till honom: Skulle du varda vår Konung, och råda öfver oss? Och vordo honom ändå hätskare för hans dröm och hans tals skull.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
Och han hade ännu en annan dröm, den förtäljde han sina bröder, och sade: Si, jag hafver ännu haft en dröm: Mig tyckte, att solen och månen och ellofva stjernor bugade sig för mig.
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
Och då det hans fader och hans bröder sagdt vardt, straffade honom hans fader, och sade till honom: Hvad är det för en dröm, som dig hafver drömt? Skall jag och din moder och dine bröder komma, och falla ned på jordena för dig?
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
Och hans bröder afundades vid honom. Men hans fader behöll dessa ord.
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
Då nu hans bröder gingo bort till att beta deras faders boskap i Sichem;
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Sade Israel till Joseph: Vakta icke dine bröder boskapen i Sichem? Kom, jag vill sända dig till dem. Han sade: Här är jag.
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
Och han sade: Gack bort och se till, om det står väl till med dina bröder och boskapenom; och säg mig igen, huru det hafver sig. Och han sände honom utaf den dalenom Hebron, att han skulle gå till Sichem.
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
Då fann honom en man, der han for vill på markene. Han frågade honom, och sade: Hvem söker du?
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
Han svarade: Jag söker mina bröder: Käre, säg mig, hvarest de vakta hjorden.
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
Mannen sade: De äro hädan farne; ty jag hörde, att de sade: Låt oss gå till Dothan. Då drog Joseph efter sina bröder, och fann dem i Dothan.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
Som de nu långt ifrå fingo se honom, förra än han kom när intill dem, rådslogo de till att döda honom;
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
Och sade inbördes: Si, drömmaren kommer här.
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
Så kommer nu, och låter oss slå honom ihjäl och kasta honom i ena grop; och säga, att ett ondt djur hafver ätit upp honom: Så får man se, hvad hans drömmar äro.
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
När Ruben hörde det, ville han frälsa honom af deras händer, och sade: Låter oss icke slå ena själ.
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
Och ytterligare sade Ruben till dem: Låter oss icke utgjuta blod: Utan låt oss kasta honom i den gropena, som är i öknene, och icke komma händer vid honom. Men han ville hafva frälst honom utu deras hand, att han måtte hafva haft honom till sin fader igen.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
Då nu Joseph kom till sina bröder, afklädde de honom hans kjortel, med den brokota kjortelen, som han hade uppå sig.
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
Och togo honom, och kastaden i ena grop; men gropen var tom, och intet vatten deruti.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
Och de satte sig ned till att äta. I det hofvo de sin ögon upp, och sågo en hop Ismaeliter komma ifrå Gilead med deras camelar; de förde kryddor, balsam och mirrham, och foro ned uti Egypten.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
Då sade Juda till sina bröder: Hvad hjelper det oss, att vi dräpe vår broder, och fördölje hans blod?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
Kommer, och låter oss sälja honom de Ismaeliter, att våra händer icke förtaga sig på honom; ty han är vår broder, vårt kött och blod. Och de lydde honom.
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Och då de Midianitiske köpmännerne foro der fram, drogo de honom upp af gropene, och sålde honom de Ismaeliter för tjugu silfverpenningar: De förde honom in i Egypten.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
Då nu Ruben kom åter till gropena, och fann icke Joseph derinne, ref han sin kläder;
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
Och kom åter till sina bröder, och sade: Pilten är icke der; hvart skall jag?
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Då togo de Josephs kjortel, och slagtade en bock, och indoppade kjortelen i blodet;
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
Och sände den brokota kjortelen bort, och läto bära honom till deras fader, och sade: Denna hafvom vi funnit: Se, om det är dins sons kjortel eller ej.
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
Men han kände honom, och sade: Det är mins sons kjortel. Ett ondt djur hafver ätit upp honom; ett vilddjur hafver rifvit Joseph.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
Och Jacob ref sin kläder, och svepte en säck om sina länder, och sörjde sin son långan tid.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol h7585)
Och alle hans söner och döttrar gingo till, att de skulle hugsvala honom; men han ville icke låta hugsvala sig, och sade: Jag varder med sorg nederfarande i grafvena till min son. Och hans fader gret honom. (Sheol h7585)
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
Men de Midianiter sålde honom in i Egypten Potiphar, Pharaos hofmästare.

< Genesis 37 >