< Genesis 37 >
1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
Jacob viveu na terra das viagens de seu pai, na terra de Canaã.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
Esta é a história das gerações de Jacob. José, aos 17 anos, alimentava o rebanho com seus irmãos. Ele era um menino com os filhos de Bilhah e Zilpah, as esposas de seu pai. José trouxe um relato maligno deles ao pai.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
Agora Israel amava José mais do que todos os seus filhos, porque ele era o filho de sua velhice, e ele fez dele uma túnica de muitas cores.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
Seus irmãos viram que seu pai o amava mais do que todos os seus irmãos, e o odiavam, e não podiam falar pacificamente com ele.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
Joseph sonhou um sonho, e contou-o a seus irmãos, e eles o odiavam ainda mais.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
Ele lhes disse: “Por favor, ouçam este sonho que eu sonhei:
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
pois eis que estávamos amarrando feixes no campo, e eis que meu molho se levantou e também ficou de pé; e eis que seus feixes se aproximaram, e se curvaram ao meu molho”.
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
Seus irmãos lhe perguntaram: “Você realmente vai reinar sobre nós? Reinarás de fato sobre nós?” Eles o odiavam ainda mais por seus sonhos e por suas palavras.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
Ele sonhou mais um sonho, contou-o a seus irmãos, e disse: “Eis que sonhei mais um sonho: e eis que o sol e a lua e onze estrelas se curvaram diante de mim”.
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
Ele o contou para seu pai e para seus irmãos. Seu pai o repreendeu, e lhe disse: “Que sonho é esse que você sonhou? Será que eu e sua mãe e seus irmãos iremos realmente nos curvar perante a terra diante de você”?
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
Seus irmãos o invejavam, mas seu pai mantinha este ditado em mente.
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
His os irmãos foram alimentar o rebanho de seu pai em Shechem.
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Israel disse a José: “Seus irmãos não estão alimentando o rebanho em Siquém? Venha, e eu o enviarei para eles”. Ele disse a ele: “Aqui estou eu”.
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
Ele lhe disse: “Vá agora, veja se está bem com seus irmãos, e bem com o rebanho; e me traga notícias novamente”. Então ele o enviou para fora do vale de Hebron, e ele veio para Shechem.
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
Um certo homem o encontrou, e eis que ele estava vagando no campo. O homem lhe perguntou: “O que você está procurando?”.
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
Ele disse: “Estou à procura de meus irmãos. Diga-me, por favor, onde eles estão alimentando o rebanho”.
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
O homem disse: “Eles saíram daqui, pois eu os ouvi dizer: 'Vamos para Dothan'”. Joseph foi atrás de seus irmãos, e os encontrou em Dothan.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
Eles o viram de longe, e antes que ele se aproximasse deles, conspiraram contra ele para matá-lo.
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
Disseram um para o outro: “Eis que vem este sonhador”.
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
Venha agora, portanto, e vamos matá-lo e lançá-lo em um dos fossos, e diremos: “Um animal maligno o devorou”. Veremos o que será de seus sonhos”.
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
Reuben ouviu e o entregou de suas mãos, e disse: “Não vamos tirar-lhe a vida”.
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
Reuben disse a eles: “Não derramemos sangue”. Jogue-o neste poço que está no deserto, mas não coloque nenhuma mão sobre ele” - para que ele possa libertá-lo das mãos deles, para restituí-lo a seu pai.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
Quando Joseph chegou a seus irmãos, eles tiraram Joseph de sua túnica, a túnica de muitas cores que estava sobre ele;
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
e o pegaram, e o jogaram na cova. A cova estava vazia. Não havia água dentro dela.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
Eles se sentaram para comer pão, levantaram os olhos e olharam, e viram que uma caravana de ismaelitas vinha de Gilead, com seus camelos contendo especiarias e bálsamo e mirra, indo levá-lo para o Egito.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
Judah disse a seus irmãos: “Que proveito teremos se matarmos nosso irmão e ocultarmos seu sangue?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
Venha, e vamos vendê-lo aos ismaelitas, e não deixemos nossa mão estar sobre ele; pois ele é nosso irmão, nossa carne”. Seus irmãos o escutaram.
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Os midianitas que eram comerciantes passaram por aqui, tiraram e levantaram José do poço e venderam José aos ismaelitas por vinte moedas de prata. Os mercadores trouxeram José para o Egito.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
Reuben voltou ao poço, e viu que Joseph não estava no poço; e rasgou suas roupas.
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
Ele voltou para seus irmãos, e disse: “A criança não está mais; e eu, para onde irei”.
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Eles pegaram a túnica de José, mataram um bode macho e mergulharam a túnica no sangue.
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
Eles pegaram a túnica de muitas cores e a trouxeram ao pai, e disseram: “Encontramos isto. Examinem-na agora e vejam se é ou não a túnica de seu filho”.
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
Ele a reconheceu, e disse: “É a túnica de meu filho”. Um animal maligno o devorou. José está, sem dúvida, despedaçado”.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
Jacob rasgou suas roupas, colocou saco na cintura e chorou por seu filho por muitos dias.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol )
Todos os seus filhos e todas as suas filhas se levantaram para confortá-lo, mas ele se recusou a ser consolado. Ele disse: “Pois eu irei ao Sheol para o meu filho, de luto”. Seu pai chorou por ele. (Sheol )
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
Os midianitas o venderam no Egito a Potiphar, um oficial do faraó, o capitão da guarda.