< Genesis 37 >

1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
Jacob viveu na terra das viagens de seu pai, na terra de Canaã.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
Esta é a história das gerações de Jacob. José, aos 17 anos, alimentava o rebanho com seus irmãos. Ele era um menino com os filhos de Bilhah e Zilpah, as esposas de seu pai. José trouxe um relato maligno deles ao pai.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
Agora Israel amava José mais do que todos os seus filhos, porque ele era o filho de sua velhice, e ele fez dele uma túnica de muitas cores.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
Seus irmãos viram que seu pai o amava mais do que todos os seus irmãos, e o odiavam, e não podiam falar pacificamente com ele.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
Joseph sonhou um sonho, e contou-o a seus irmãos, e eles o odiavam ainda mais.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
Ele lhes disse: “Por favor, ouçam este sonho que eu sonhei:
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
pois eis que estávamos amarrando feixes no campo, e eis que meu molho se levantou e também ficou de pé; e eis que seus feixes se aproximaram, e se curvaram ao meu molho”.
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
Seus irmãos lhe perguntaram: “Você realmente vai reinar sobre nós? Reinarás de fato sobre nós?” Eles o odiavam ainda mais por seus sonhos e por suas palavras.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
Ele sonhou mais um sonho, contou-o a seus irmãos, e disse: “Eis que sonhei mais um sonho: e eis que o sol e a lua e onze estrelas se curvaram diante de mim”.
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
Ele o contou para seu pai e para seus irmãos. Seu pai o repreendeu, e lhe disse: “Que sonho é esse que você sonhou? Será que eu e sua mãe e seus irmãos iremos realmente nos curvar perante a terra diante de você”?
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
Seus irmãos o invejavam, mas seu pai mantinha este ditado em mente.
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
His os irmãos foram alimentar o rebanho de seu pai em Shechem.
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Israel disse a José: “Seus irmãos não estão alimentando o rebanho em Siquém? Venha, e eu o enviarei para eles”. Ele disse a ele: “Aqui estou eu”.
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
Ele lhe disse: “Vá agora, veja se está bem com seus irmãos, e bem com o rebanho; e me traga notícias novamente”. Então ele o enviou para fora do vale de Hebron, e ele veio para Shechem.
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
Um certo homem o encontrou, e eis que ele estava vagando no campo. O homem lhe perguntou: “O que você está procurando?”.
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
Ele disse: “Estou à procura de meus irmãos. Diga-me, por favor, onde eles estão alimentando o rebanho”.
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
O homem disse: “Eles saíram daqui, pois eu os ouvi dizer: 'Vamos para Dothan'”. Joseph foi atrás de seus irmãos, e os encontrou em Dothan.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
Eles o viram de longe, e antes que ele se aproximasse deles, conspiraram contra ele para matá-lo.
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
Disseram um para o outro: “Eis que vem este sonhador”.
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
Venha agora, portanto, e vamos matá-lo e lançá-lo em um dos fossos, e diremos: “Um animal maligno o devorou”. Veremos o que será de seus sonhos”.
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
Reuben ouviu e o entregou de suas mãos, e disse: “Não vamos tirar-lhe a vida”.
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
Reuben disse a eles: “Não derramemos sangue”. Jogue-o neste poço que está no deserto, mas não coloque nenhuma mão sobre ele” - para que ele possa libertá-lo das mãos deles, para restituí-lo a seu pai.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
Quando Joseph chegou a seus irmãos, eles tiraram Joseph de sua túnica, a túnica de muitas cores que estava sobre ele;
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
e o pegaram, e o jogaram na cova. A cova estava vazia. Não havia água dentro dela.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
Eles se sentaram para comer pão, levantaram os olhos e olharam, e viram que uma caravana de ismaelitas vinha de Gilead, com seus camelos contendo especiarias e bálsamo e mirra, indo levá-lo para o Egito.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
Judah disse a seus irmãos: “Que proveito teremos se matarmos nosso irmão e ocultarmos seu sangue?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
Venha, e vamos vendê-lo aos ismaelitas, e não deixemos nossa mão estar sobre ele; pois ele é nosso irmão, nossa carne”. Seus irmãos o escutaram.
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Os midianitas que eram comerciantes passaram por aqui, tiraram e levantaram José do poço e venderam José aos ismaelitas por vinte moedas de prata. Os mercadores trouxeram José para o Egito.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
Reuben voltou ao poço, e viu que Joseph não estava no poço; e rasgou suas roupas.
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
Ele voltou para seus irmãos, e disse: “A criança não está mais; e eu, para onde irei”.
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Eles pegaram a túnica de José, mataram um bode macho e mergulharam a túnica no sangue.
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
Eles pegaram a túnica de muitas cores e a trouxeram ao pai, e disseram: “Encontramos isto. Examinem-na agora e vejam se é ou não a túnica de seu filho”.
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
Ele a reconheceu, e disse: “É a túnica de meu filho”. Um animal maligno o devorou. José está, sem dúvida, despedaçado”.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
Jacob rasgou suas roupas, colocou saco na cintura e chorou por seu filho por muitos dias.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol h7585)
Todos os seus filhos e todas as suas filhas se levantaram para confortá-lo, mas ele se recusou a ser consolado. Ele disse: “Pois eu irei ao Sheol para o meu filho, de luto”. Seu pai chorou por ele. (Sheol h7585)
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
Os midianitas o venderam no Egito a Potiphar, um oficial do faraó, o capitão da guarda.

< Genesis 37 >