< Genesis 37 >
1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
Jakub mieszkał w ziemi, gdzie jego ojciec był przybyszem, w ziemi Kanaan.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
To są dzieje rodu Jakuba: Gdy Józef miał siedemnaście lat, pasł stada ze swoimi braćmi; młodzieniec był z synami Bilhy i z synami Zilpy, żony swego ojca. I Józef donosił ojcu o ich złej sławie.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
A Izrael kochał Józefa najbardziej ze wszystkich swoich synów, [bo] urodził mu się w starości. I zrobił mu szatę wielobarwną.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
Gdy jego bracia widzieli, że ojciec kocha go bardziej niż wszystkich jego braci, znienawidzili go i nie potrafili przyjaźnie z nim rozmawiać.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
Pewnego razu Józefowi przyśnił się sen, a [gdy] opowiedział go swoim braciom, tym bardziej go znienawidzili.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
Bo powiedział im: Posłuchajcie, proszę, snu, który mi się przyśnił.
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
Wiązaliśmy snopy na polu, a oto mój snop podniósł się i stanął, a wasze snopy otoczyły go i pokłoniły się mojemu snopowi.
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
I odpowiedzieli mu jego bracia: Czyżbyś miał królować nad nami? Czyż miałbyś nami rządzić? I jeszcze bardziej go znienawidzili z powodu snów i słów jego.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
Śnił mu się jeszcze drugi sen i opowiedział go swoim braciom: Znowu śnił mi się sen, a oto słońce, księżyc i jedenaście gwiazd pokłoniły mi się.
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
Gdy opowiedział [to] swemu ojcu i swoim braciom, jego ojciec zgromił go i powiedział mu: Cóż to za sen, który ci się śnił? Czy ja i twoja matka przyjdziemy z twoimi braćmi, aby ci się kłaniać aż do ziemi?
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
I jego bracia zazdrościli mu, ale jego ojciec rozważał tę sprawę.
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
Potem jego bracia odeszli, aby paść trzody swego ojca w Sychem.
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
I Izrael powiedział do Józefa: Czy twoi bracia nie pasą [trzody] w Sychem? Chodź, a poślę cię do nich. A on odpowiedział: Oto jestem.
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
Wtedy powiedział mu: Idź teraz i dowiedz się, jak się mają twoi bracia i co się dzieje z trzodami, i daj mi znać. Wysłał go więc z doliny Hebronu, a on przyszedł do Sychem.
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
I spotkał go [pewien] człowiek, gdy błąkał się po polu. I człowiek ten zapytał go: Czego szukasz?
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
A on odpowiedział: Szukam moich braci. Powiedz mi, proszę, gdzie oni pasą trzody.
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
Człowiek ten odpowiedział: Odeszli stąd, bo słyszałem, jak mówili: Pójdźmy do Dotan. I Józef poszedł za swoimi braćmi i znalazł ich w Dotan.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
Gdy ujrzeli go z daleka, zanim do nich przyszedł, naradzali się, aby go zabić.
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
I mówili jeden do drugiego: Oto idzie mistrz od snów.
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
Teraz więc chodźcie, zabijmy go i wrzućmy do jakiejś studni, i powiemy: Pożarł go zły zwierz. I zobaczymy, co będzie z jego snów.
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
Ruben, gdy to usłyszał, chciał go wybawić z ich rąk i powiedział: Nie zabijajmy go.
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
Ruben powiedział też do nich: Nie wylewajcie krwi, [ale] wrzućcie go do tej studni, która [jest] na pustyni, i nie podnoście na niego ręki. [A mówił to], aby go wybawić z ich rąk i przywrócić go swemu ojcu.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
Gdy Józef przyszedł do swoich braci, obdarli go z jego szaty, z szaty wielobarwnej, którą [miał] na sobie.
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
Następnie chwycili go i wrzucili do studni, która [była] pusta, bez wody.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
Potem usiedli, aby jeść chleb, a gdy podnieśli swoje oczy, zobaczyli grupę Izmaelitów idących z Gileadu. Ich wielbłądy niosły wonne korzenie, kadzidło i mirrę, a szły, aby to zanieść do Egiptu.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
Wtedy Juda powiedział do swoich braci: Jaki pożytek będzie z tego, że zabijemy naszego brata i zataimy jego krew?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
Chodźcie, sprzedajmy go Izmaelitom, a nie podnośmy na niego naszej ręki, bo to jest nasz brat i nasze ciało. I bracia go usłuchali.
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
A gdy przechodzili Midianici, kupcy, wyciągnęli Józefa ze studni i sprzedali go Izmaelitom za dwadzieścia srebrników, a oni zaprowadzili Józefa do Egiptu.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
Gdy Ruben wrócił do tej studni, Józefa już w studni nie było. I rozdarł swoje szaty.
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
Potem wrócił do swoich braci i powiedział: Nie ma chłopca, a ja dokąd pójdę?
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Wtedy wzięli szatę Józefa, zabili kozła i umoczyli szatę we krwi.
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
I posłali tę wielobarwną szatę, aby ją zaniesiono do jego ojca, i powiedzieli: Znaleźliśmy to. Zobacz, czy to szata twego syna, czy nie.
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
A [on] rozpoznał ją i powiedział: To [jest] szata mego syna, pożarł go zły zwierz. Józef na pewno został rozszarpany.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
Wtedy Jakub rozdarł swoje szaty, włożył wór na biodra i opłakiwał swego syna przez wiele dni.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol )
I zeszli się wszyscy jego synowie i wszystkie jego córki, aby go pocieszyć, lecz nie dał się pocieszyć, ale mówił: Naprawdę zstąpię za moim synem do grobu. I opłakiwał go jego ojciec. (Sheol )
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
A Midianici sprzedali Józefa do Egiptu Potifarowi, dworzaninowi faraona, dowódcy straży.