< Genesis 37 >
1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
Jákób pedig lakozék az ő atyja bujdosásának földén, Kanaán földén.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
Ezek a Jákób nemzetségének dolgai: József tizenhét esztendős korában az ő bátyjaival együtt juhokat őriz vala, bojtár vala Bilhának és Zilpának az ő atyja feleségeinek fiai mellett, és József rossz híreket hord vala felőlük az ő atyjuknak.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
Izráel pedig minden fiánál inkább szereti vala Józsefet, mivelhogy vén korában nemzette vala őt; és czifra ruhát csináltat vala néki.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
Mikor pedig láták az ő bátyjai, hogy atyjuk minden testvére közt őt szereti legjobban, meggyűlölik vala, és jó szót sem bírnak vala hozzá szólani.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
És álmot álmodék József és elbeszélé az ő bátyjainak; és azok annál inkább gyűlölik vala őt.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
Mert monda nékik: Hallgassátok meg, kérlek, ezt az álmot, melyet álmodtam.
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
Ímé kévéket kötünk vala a mezőben, és ímé az én kévém felkele és felálla; a ti kévéitek pedig körűlállanak, és az én kévém előtt meghajolnak vala.
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
És mondának néki az ő bátyjai: Avagy király akarsz-é lenni felettünk? Vagy uralkodni akarsz-é rajtunk? S annál is inkább gyűlölik vala őt álmáért és beszédéért.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
Más álmot is álmodék, és elbeszélé azt az ő bátyjainak, mondván: ímé megint álmot álmodtam; ímé a nap és a hold, és tizenegy csillag meghajol vala én előttem.
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
S elbeszélé atyjának és bátyjainak, és az ő atyja megdorgálá őt, mondván néki: Micsoda álom az a melyet álmodtál? Avagy elmegyünk-é, én és a te anyád és atyádfiai, hogy meghajtsuk magunkat te előtted a földig?
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
Irígykednek vala azért reá az ő bátyjai; az ő atyja pedig elméjében tartja vala e dolgot.
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
Mikor pedig az ő bátyjai elmenének Sikhembe, hogy az ő atyjok juhait őrizzék;
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Monda Izráel Józsefnek: A te bátyáid avagy nem Sikhemben legeltetnek-é? Jöszte, és én hozzájok küldelek téged. Ő pedig monda: Ímhol vagyok.
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
És monda néki: Menj el, nézd meg, hogy s mint vagynak a te bátyáid és a juhok, s hozz hírt nékem. Elküldé tehát őt Hebron völgyéből, és méne Sikhembe.
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
Előtalálá pedig őt egy ember, mikor a mezőben bolyong vala, és megkérdé őt az az ember, mondván: Mit keressz?
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
És monda: Az én bátyáimat keresem, kérlek, mondd meg nékem, hol legeltetnek?
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
És monda az ember: Elmentek innen, mert hallám, hogy mondák: Menjünk Dóthánba. Elméne azért József az ő bátyjai után, és megtalálá őket Dóthánban.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
Mikor távolról megláták, minekelőtte közel ért volna hozzájok, összebeszélének, hogy megölik.
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
És szólának egymás között: Ímhol jő az álomlátó!
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
Most hát jertek öljük meg őt, és vessük őt valamelyik kútba; és azt mondjuk, hogy fenevad ette meg, és meglátjuk, mi lesz az ő álmaiból.
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
Meghallá pedig Rúben és megmenté őt kezökből, és mondá: Ne üssük őt agyon.
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
És mondá nékik Rúben: Ne ontsatok vért, vessétek őt ebbe a kútba, a mely itt a pusztában van, de kezet ne vessetek reá. Azért, hogy megszabadítsa őt kezökből, hogy visszavigye atyjához.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
És lőn, a mint oda ére József az ő bátyjaihoz, letépték Józsefről az ő felső ruháját, a czifra ruhát, mely rajta vala.
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
És megragadák őt és beleveték a kútba; a kút pedig üres vala, nem vala víz benne.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
Azután leűlének kenyerezni, és felemelék szemeiket, és láták, hogy ímé egy Ismáelita karaván jő vala Gileádból, és azoknak tevéi visznek vala fűszerszámot, balzsamot és mirhát, menvén, hogy alávigyék Égyiptomba.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
És monda Júda az ő atyjafiainak: Mi haszna, ha megöljük a mi atyánkfiát, és eltitkoljuk az ő vérét?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
Jertek adjuk el őt az Ismáelitáknak, és ne tegyük reá kezünket, mert atyánkfia, vérünkből való ő. És hallgatának rá az ő atyjafiai.
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
És menének arra Midiánita kereskedő férfiak, és kivonák és felhozák Józsefet a kútból, és eladák Józsefet az Ismáelitáknak húsz ezüstpénzen: azok pedig elvivék Józsefet Égyiptomba.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
És visszatére Rúben a kúthoz, és ímé József nem vala a kútban, és megszaggatá ruháit.
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
És megtére az ő atyjafiaihoz, és monda: Nincsen a gyermek, és én, merre menjek én?
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Akkor vevék a József felső ruháját, és leölének egy kecskebakot, és belemárták a felső ruhát a vérbe.
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
És elküldék a czifra ruhát, és elvivék atyjokhoz és mondának: Ezt találtuk, ismerd meg, fiad ruhája-é vagy nem?
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
És megismeré azt, és monda: Fiam felső ruhája ez, fenevad ette meg őt, bizony széllyelszaggatta Józsefet.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
És megszaggatá Jákób ruháit, és zsákba öltözék és gyászolá az ő fiát sokáig.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol )
Felkelének pedig minden ő fiai, és minden ő leányai, hogy vígasztalják őt, de nem akara vígasztalódni, hanem monda: Sírva megyek fiamhoz a sírba; és siratá őt az atyja. (Sheol )
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
A Midiániták pedig eladák őt Égyiptomba Pótifárnak, a Faraó főemberének, a testőrök főhadnagyának.