< Genesis 37 >

1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
NOHO aka la o Iakoba ma ka aina a kona makuakane i noho malihini ai, ma ka aina i Kanaana.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
Eia ka mooolelo no Iakoba. He umi ko Iosepa makahiki a me kumamahiku, e hanai ana oia i na holoholona me kona poe kaikuaana, e noho pu ana o ua keiki la me na keikikane a Bileha, a me na keikikane a Zilepa, na wahine a kona makuakane, a hai mai la o Iosepa i ka makuakane o lakou i ka lono ino o lakou.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
Ua oi aku la ke aloha o Iseraela ia Iosepa mamua o kana mau keiki a pau, no ka mea, he keiki ia no kona wa elemakule: a hana iho la ia i kapakomo onionio nona.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
A ike iho la kona poe kaikuaana i ke kela ana aku o ke aloha o ko lakou makuakane ia Iosepa mamua o kona poe hoahanau a pau, inaina aku la lakou ia Iosepa, aole i hiki ke olelo oluolu aku ia ia.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
Moe iho la o Iosepa i ka moe, a hai aku la i kona poe kaikuaana, a nui hou mai la ko lakou inaina ana ia ia.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
I aku la ia ia lakou, Ea, e hoolohe mai oukou i keia moe a'u i moe ai.
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
Eia hoi, i ka pua ana a kakou i na pua, ma ka mahina ai, ala mai la ka'u pua, a kupono ae la iluna; a o ka oukou mau pua ka i ku poai mai la, a kulou iho la i ka'u pua.
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
Olelo mai la kona poe kaikuaana ia ia, E alii ana ka oe maluna o makou? O oe anei ka haku maluna o makou? Huhu nui aku la lakou ia ia i kana moe, a i kana olelo.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
A mahope aku, moe hou iho la ia i ka moe, a hai hou aku la i kona poe kaikuaana, i aku la, Eia hoi, ua moe hou iho nei au i ka moe; a ua kulou mai ia'u ka la, a me ka mahina, a me na hoku he umikumamakahi.
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
Hai aku la ia i kona makuakane, a i kona poe kaikuaana. Papa mai la kona makuakane, i mai la ia ia, Heaha keia moe au i moe ai? E hele anei au iou la, a me kou makuwahine, a me kou poe hoahanau, e kulou ilalo i ka honua imua ou?
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
Huahuwa ae la kona poe kaikuaana ia ia, a malama iho la kona makuakane i ua olelo la.
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
Hele aku la kona poe kaikuaana i Sekema, e hanai i ka poe holoholona a ka makuakane o lakou.
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Olelo aku la o Iseraela ia Iosepa, Aia paha kou poe kaikuaana e hanai holoholona ana ma Sekema? Auhea oe? E hoouna ana au ia oe io lakou la. I mai la kela ia ia, Eia no wau.
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
I aku la oia ia ia, Ea, o hele oe e ike i ka pono o kou poe kaikuaana, a me ka pono o na holoholona, a e hai mai ia'u. Hoouna aka la oia ia ia, iwaho o ke awawa o Heberona, a hiki aku la ia i Sekema.
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
A loaa ia i kekahi kanaka, aia hoi, ua hele hewa ia i ke kula. Ninau mai la ua kanaka la ia ia, i mai la, Heaha kau mea e imi nei?
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
Olelo aku la ia, E imi ana au i ko'u poe kaikuaana: e hai mai oe ia'u i kahi a lakou e hanai ai i na holoholona.
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
Olelo mai la ia kanaka, Ua hala'ku la lakou: ua lohe au i ka olelo ana a lakou, E, e hele kakou i Dotana. Hahai aku la o Iosepa i kona poe kaikuaana, a loaa aku la lakou Dotana.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
A ike mai la lakou ia ia ma kahi loihi aku, aole ia i lihi koke mai, ohumu iho la lakou ia ia, e make ia.
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
Olelo ae la lakou i kekahi i kekahi, Eia'e ka mea nana na moe, ke hele mai nei.
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
Ina kakou e pepehi ia ia a make loa, e hoolei ia ia iloko o kahi lua, a e olelo aku kakou, Na ka ilio hihiu ia i ai; alaila, e ike kakou i ka hope o kana mau moe.
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
A lohe ae la o Reubena, hoola ae la oia ia ia, mai ko lakou lima ae; i ae la, Mai pepehi kakou ia ia.
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
Olelo aku la o Reubena ia lakou, Mai hookahe i ke koko; e hoolei ia ia iloko o keia hua o ka aina waonahele. Mai kau i ka lima maluna ona. Manao iho la ia e hoopakele ia ia, mai ko lakou lima ae, a e hoihoi aku ia ia i kona makuakane.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
A hiki aku la o Iosepa i kona poe kaikuaana, hao ae la lakou i ko Iosepa kapa, o ke kapa onionio maluna ona;
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
Lalau ae la lakou ia ia, hoolei aku la ia ia iloko o ka lua. Ua kaawale ka lua, aole he wai oloko.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
A noho iho la lakou e ai i ka ai. Alawa'e la ko lakou maka, ike aku la, aia hoi kekahi poe mamo a Isemaela, e hele mai ana, mai Gileada mai, me ko lakou mau kamelo, ua kaumaha i ka mea ala, a me ka bama, a me ka mura, e lawe hele ana i Aigupita.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
Olelo aku la o Inda i kona poe hoahanau, Heaha ka maikai, ke pepehi kakou i ko kakou kaikaina, a huna i kona koko?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
Ina kakou e kuai aku ia ia i ka Isemaela; mai kau ko kakou lima maluna ona; no ka mea, o ko kakou kaikaina no ia, a me ko kakou io. A hoolohe mai la kona poe hoahanau ia ia.
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Hele ae la ua poe kanaka kuai la, no Midiana, huki mai la lakou, a hapai ae la ia Iosepa, mai loko mai o ka lua, a kuai aku la ia ia, i ka Isemaela, i na hapakala, he iwakalua. A lawe ae la lakou ia Iosepa i Aigupita.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
A hoi mai la o Reubena i ka lua, aia hoi, aole o Iosepa iloko o ka lua: haehae iho la ia i kona kapa.
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
A hoi aku la ia i kona poe hoahanau, i aku la, Aole loa ke keiki; a o wau, ihea la wau e hele ai?
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Lawe ae la lakou i ke kapa o Iosepa, pepehi iho la lakou i ke kao keiki, a kupenu iho la i ke kapa i ke koko.
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
Hoouka aku la lakou i ua kapa onionio la, a hiki i ko lakou makuakane; i aku la, Ua loaa mai keia ia makou: e nana oe, o ke kapa paha o kau keiki, aole paha.
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
Ike mai la kela, i mai la, Oia, o ke kapa no ia o ka'u keiki; ua pau o Iosepa i ka ilio hihiu, oiaio no, ua haehaeia o Iosepa.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
Haehae iho la o Iseraela i kona kapa, kaei ae la i ke kapa inoino ma kona puhaka, a kanikau iho la ia i kana keiki a nui na la.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol h7585)
Ku mai la kana mau keikikane a pau, a me kana mau kaikamahine a pau, e hoonana ia ia. Hoole aku la kela, aole e na: i aku la, E kanikau no au, a hiki au ilalo i ka lua i kuu keiki la. Pela i uwe ai kona makuakane ia ia. (Sheol h7585)
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
A kuai aku la ko Midiana ia ia i Aigupita, ia Potipara, he luna na Parao, oia ka luna o ka poe koa.

< Genesis 37 >