< Genesis 37 >
1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
Jakubu nĩatũũrire bũrũri-inĩ ũrĩa ithe aaikarĩte, nĩguo bũrũri wa Kaanani.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
Ũyũ nĩguo ũhoro wa Jakubu. Jusufu arĩ mwanake mũnini wa mĩaka ikũmi na mũgwanja aarĩithagia mbũri marĩ na ariũ a ithe, na ariũ a Biliha, na ariũ a Zilipa, atumia a ithe, nake agĩtwarĩra ithe wao ũhoro mũũru ũkoniĩ ariũ a ithe.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
Na rĩrĩ, Isiraeli nĩendeete Jusufu gũkĩra ariũ arĩa angĩ ake othe, tondũ aamũciarire arĩ mũkũrũ; na nĩamũtumithĩirie kanjũ ya goro ngʼemie wega mũno.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
Na rĩrĩa ariũ a ithe moonire atĩ ithe nĩamwendete kũmakĩra-rĩ, makĩmũmena na matingĩamwarĩirie kiugo o na kĩmwe kĩega.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
Ũtukũ ũmwe Jusufu nĩarootire kĩroto, na rĩrĩa eerire ariũ a ithe ũhoro wakĩo, makĩmũmena makĩria.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
Akĩmeera atĩrĩ, “Thikĩrĩriai ũhoro wa kĩroto gĩkĩ ndootete:
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
Tũrohaga itĩĩa cia ngano tũrĩ mũgũnda-inĩ, na o rĩmwe gĩtĩĩa gĩakwa kĩrehaanda na igũrũ, nacio itĩĩa cianyu irathiũrũrũkĩria gĩakwa, na irakĩinamĩrĩra.”
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
Ariũ a ithe makĩmũũria atĩrĩ, “Anga nĩũrenda gũtũthamakĩra? Anga ti-itherũ nĩũgatwatha?” Nao magĩkĩrĩrĩria kũmũmena nĩ ũndũ wa kĩroto kĩu gĩake, na nĩ ũndũ wa ciugo ciake.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
Ningĩ Jusufu akĩroota kĩroto kĩngĩ, na akĩĩra ariũ a ithe ũhoro wakĩo. Akĩmeera atĩrĩ, “Thikĩrĩriai, nĩndĩrarootire kĩroto kĩngĩ, na ihinda rĩĩrĩ, ndĩrarootire riũa, na mweri, na njata ikũmi na ĩmwe ikĩnyinamĩrĩra.”
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
Rĩrĩa eerire ithe o na ariũ a ithe ũhoro ũcio, ithe akĩmũkũma, akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩroto kĩa mũthemba ũrĩkũ kĩu ũrotete? Anga nyũkwa, na niĩ, na ariũ a thoguo nĩtũgooka, na tũinamĩrĩre thĩ mbere yaku?”
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
Ariũ a ithe nĩmamũiguĩrĩire ũiru, no ithe agĩikara agĩĩciiragia ũhoro wa irooto icio.
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
Na rĩrĩ, ariũ a ithe nĩmathiĩte kũrĩithia mbũri cia ithe wao gũkuhĩ na Shekemu,
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
nake Isiraeli akĩĩra Jusufu atĩrĩ, “O ta ũrĩa ũũĩ, ariũ a thoguo nĩmararĩithia mbũri gũkuhĩ na Shekemu. Ũka, nĩngũgũtũma kũrĩ o.” Nake akĩmũcookeria, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũguo noguo.”
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
Nĩ ũndũ ũcio Isiraeli akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ ũkarore kana ariũ a thoguo marĩ o ho o wega, o ũndũ ũmwe na mbũri, na ũnjookerie ũhoro.” Nake akĩmũtũma kuuma Gĩtuamba-inĩ kĩa Hebironi. Rĩrĩa Jusufu aakinyire Shekemu,
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
mũndũ ũmwe akĩmuona akĩũrũũra mĩgũnda-inĩ, akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ ũracaria?”
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
Nake Jusufu agĩcookia atĩrĩ, “Nĩ ariũ a baba ndĩracaria. No ũnjĩĩre kũrĩa mararĩithia mbũri ciao?”
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
Mũndũ ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩmoimĩte gũkũ. Ndĩraiguire makiuga atĩrĩ, ‘Rekei tũthiĩ Dothani.’” Nĩ ũndũ ũcio Jusufu akĩrũmĩrĩra ariũ a ithe, na akĩmakora hakuhĩ na Dothani.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
No makĩmuona arĩ haraaya, na ataanakinya harĩa maarĩ, magĩciirĩra kũmũũraga.
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
Makĩĩrana atĩrĩ, “Mũroti ũrĩa nĩokĩte!
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
Ũkai; rekei tũmũũrage na tũmũikie irima rĩmwe rĩa maya, na tuuge atĩ nĩ nyamũ njũru ĩmũrĩĩte. Nĩtũkĩone ũrĩa irooto icio ciake ikaahinga.”
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
No rĩrĩa Rubeni aiguire ũguo, akĩgeria kũhonokia Jusufu kuuma moko-inĩ mao. Akiuga atĩrĩ, “Rekei tũtige kũmũũraga.
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
Mũtigaite thakame. Mũikiei irima-inĩ rĩĩrĩ rĩ gũkũ werũ-inĩ, no mũtikamwĩke ũũru.” Rubeni oigaga ũguo nĩgeetha amũhonokie kuuma kũrĩ o, nĩguo amũcookie kũrĩ ithe.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
Na rĩrĩa Jusufu aakinyire harĩ ariũ a ithe, makĩmũruta kanjũ yake ĩrĩa eekĩrĩte, o ĩrĩa yarĩ ya goro na ngʼemie wega mũno.
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
Makĩmũnyiita, makĩmũikia irima rĩu. Na rĩrĩ, irima rĩu rĩarĩ rĩũmũ; rĩtiarĩ na maaĩ.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
Magĩcooka magĩikara thĩ kũrĩa irio ciao, magĩtiira maitho makĩona gĩkundi kĩnene kĩa Aishumaeli gĩgĩũka kiumĩte Gileadi. Ngamĩĩra ciao ciakuuithĩtio mahuti manungi wega, na ũbani, na ũũkĩ-wa-ngoma ũrĩa wĩtagwo manemane, na maikũrũkĩte mathiĩ matware indo icio Misiri.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
Juda akĩĩra ariũ a ithe atĩrĩ, “Nĩ uumithio ũrĩkũ tũkuona tũngĩũraga mũrũ wa ithe witũ na tũhithe gĩkuũ gĩake?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
Rekei tũmwenderie Aishumaeli aya, no tũtikamwĩke ũũru na moko maitũ, tondũ ũyũ nĩ mũrũ wa ithe witũ, tũrĩ a mũthiimo ũmwe na thakame o ĩmwe.” Nao ariũ a ithe magĩtĩkĩra.
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Nĩ ũndũ ũcio hĩndĩ ĩrĩa onjorithia acio Amidiani maahĩtũkagĩra hau, ariũ a ithe makĩruta Jusufu irima, na makĩmwendia cekeri mĩrongo ĩĩrĩ cia betha kũrĩ Aishumaeli acio, nao makĩmũtwara Misiri.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
Rĩrĩa Rubeni aacookire irima-inĩ na akĩona atĩ Jusufu ndaarĩ ho, agĩtembũranga nguo ciake.
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
Agĩcooka kũrĩ ariũ a ithe akĩmeera atĩrĩ, “Kamwana karĩa gatirĩ ho! Niĩ ngwĩka atĩa?”
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Nao makĩoya kanjũ ya Jusufu, magĩthĩnja mbũri na magĩtobokia kanjũ ĩyo thĩinĩ wa thakame ĩyo.
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
Magĩcooka makĩoya kanjũ ĩyo yagemetio, makĩmĩtwarĩra ithe wao makĩmwĩra atĩrĩ, “Kanjũ ĩno nĩ kũmĩona tũramĩonire. Mĩrore wega wone kana hihi nĩ kanjũ ĩrĩa ya mũrũguo.”
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
Nake akĩmĩmenya, akiuga atĩrĩ, “Nĩ kanjũ ya mũrũ wakwa! Nyamũ njũru nĩĩmũrĩĩte. Ti-itherũ Jusufu nĩarĩkĩtie kũũragwo, agatambuurwo icunjĩ.”
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
Ningĩ Jakubu agĩtembũranga nguo ciake, agĩĩkĩra nguo ya ikũnia, na agĩcakaĩra mũriũ matukũ maingĩ.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol )
Ariũ ake othe na airĩtu ake magĩũka kũmũhooreria, no akĩrega kũhoorerio, akiuga atĩrĩ, “Aca! Ngathiĩ mbĩrĩra kũrĩ mũrũ wakwa ngĩrĩraga.” Nĩ ũndũ ũcio ithe agĩthiĩ na mbere kũmũrĩrĩra. (Sheol )
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
Nao Amidiani acio makĩendia Jusufu kũu Misiri kũrĩ Potifaru, ũmwe wa anene a Firaũni, nake aarĩ mũrũgamĩrĩri wa arangĩri a Firaũni.