< Genesis 37 >

1 Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
Forsothe Jacob dwellide in the lond of Canaan, in which his fadir was a pilgrym; and these weren the generaciouns of hym.
2 Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
Joseph whanne he was of sixtene yeer, yit a child, kepte a flok with hise britheren, and was with the sones of Bala and Zelfa, wyues of his fadir; and he accuside his britheren at the fadir of `the worste synne.
3 Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
Forsothe Israel louyde Joseph ouer alle hise sones, for he hadde gendrid hym in eelde; and he made to Joseph a cote of many colours.
4 Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
Forsothe hise britheren sien that he was loued of the fader more than alle, and thei hatiden hym, and myyten not speke ony thing pesibli to hym.
5 Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
And it bifelde that he telde to hise britheren a sweuene seyn, which cause was `the seed of more hatrede.
6 O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
And Joseph seide to his britheren, Here ye the sweuene which Y seiy,
7 sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
Y gesside that we bounden to gidere handfuls, and that as myn handful roos, and stood, and that youre handfuls stoden aboute and worschipiden myn handful.
8 Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
Hise britheren answerden, Whether thou shalt be oure kyng, ethir we shulen be maad suget to thi lordschip? Therfor this cause of sweuenys and wordis mynystride the nurschyng of enuye, and of hatrede.
9 O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
Also Joseph seiy another sweuene, which he telde to the britheren, and seide, Y seiy bi a sweuene that as the sunne, and moone, and enleuen sterris worschipiden me.
10 Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
And whanne he hadde teld this sweuene to his fadir, and britheren, his fadir blamyde him, and seide, What wole this sweuene to it silf which thou hast seyn? Whether Y and thi modir, and thi britheren, schulen worschipe thee on erthe?
11 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
Therfor hise britheren hadden enuye to hym. Forsothe the fadir bihelde pryuely the thing,
12 Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
and whanne his britheren dwelliden in Sichem, aboute flockis of the fadir `to be kept,
13 Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Israel seide to Joseph, Thi britheren kepen scheep in Sichymys; come thou, Y schal sende thee to hem.
14 O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
And whanne Joseph answerde, Y am redi, Israel seide, Go thou, and se whether alle thingis ben esi anentis thi britheren, and scheep; and telle thou to me what is doon. He was sent fro the valey of Ebron, and cam into Sichem;
15 ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
and a man foond hym errynge in the feeld, and `the man axide, what he souyte.
16 Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
And he answerde, Y seke my britheren, schewe thou to me where thei kepten flockis.
17 Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
And the man seide to hym, Thei yeden awei fro this place; forsothe Y herde hem seiynge, Go we into Dothaym. And Joseph yede aftir his britheren, and foond hem in Dothaym.
18 Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
And whanne thei hadden seyn hym afer, bifor that he neiyede to hem,
19 “Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
thei thouyten to sle hym, and spaken to gidere, Lo! the dremere cometh, come ye,
20 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
sle we hym, and sende we into an eld sisterne, and we schulen seie, A wielde beeste ful wickid hath deuourid hym; and thanne it schal appere what hise dremes profiten to hym.
21 Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
Sotheli Ruben herde this, and enforside to delyuere hym fro her hondis,
22 ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
and seide, Sle we not the lijf of hym, nether schede we out his blood, but caste ye hym into an eeld cisterne, which is in the wildirnesse, and kepe ye youre hondis gilteles. Forsothe he seide this, willynge to delyuere hym fro her hondis, and to yelde to his fadir.
23 Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
Therfor anoon as Joseph cam to hise britheren, thei dispuyliden hym of the coote, doun to the heele, and of many colours, and senten into the eeld cisterne,
24 wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
that hadde no water.
25 Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
And thei saten `to ete breed; and thei sien that Ismaelitis weigoers camen fro Galaad, and that her camels baren swete smellynge spiceries, and `rosyn, and stacten, into Egipt.
26 Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
Therfor Judas seide to hise britheren, What schal it profite to vs, if we schulen sle oure brother, and schulen hide his blood?
27 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
It is betere that he be seeld to Ismalitis, and oure hondis be not defoulid, for he is oure brother and fleisch. The britheren assentiden to these wordis;
28 Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
and whanne marchauntis of Madian passiden forth, thei drowen hym out of the cisterne, and seelden hym to Ismaelitis, for thriytti platis of siluer; whiche ledden hym in to Egipt.
29 Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
And Ruben turnede ayen to the cisterne, and foond not the child;
30 Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
and he to-rente his closis, and he yede to hise britheren, and seide, The child apperith not, and whidir schal Y go?
31 Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
Forsothe thei token his coote, and dippiden in the blood of a kide, which thei hadden slayn; and senten men that baren to the fadir,
32 Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
and seiden, We han founde this coote, se, whether it is the coote of thi sone, ether nai.
33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
And whanne the fader hadde knowe it, he seide, It is the coote of my sone, a wielde beeste ful wickid hath ete hym, a beeste hath deuourid Joseph.
34 Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
And he to-rente his clothis, and he was clothid with an heire, and biweilide his sone in myche tyme.
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol h7585)
Sothely whanne hise fre children weren gaderid to gidere, that thei schulden peese the sorewe of the fadir, he nolde take counfort, but seide, Y schal go doun in to helle, and schal biweile my sone. And the while Jacob contynude in wepyng, (Sheol h7585)
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.
Madianytis seelden Joseph into Egipt to Putifar, chast `and onest seruaunt of Farao, maistir of the chyualrie.

< Genesis 37 >