< Genesis 36 >
1 Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
Voici les générations d’Esaü; c’est le même qu’Edom.
2 Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
Esaü prit pour femmes d’entre les filles des Chananéens: Ada, fille d’Elon l’Hétéen, et Oolibama, fille d’Ana, fille elle-même de Sébéon l’Hévéen;
3 Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
Et aussi Bazemath, fille d’Ismaël, sœur de Nabaïoth.
4 Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
Ada enfanta Eliphaz; Bazemath enfanta Rahuel;
5 Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
Oolibama enfanta Jéhus, Ihélon et Coré. Ce sont là les fils d’Esaü, qui lui naquirent dans la terre de Chanaan.
6 Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
Or Esaü prit ses femmes, ses fils, ses filles et toutes les âmes de sa maison, ses richesses, ses bestiaux et tout ce qu’il pouvait avoir dans la terre de Chanaan, et il s’en alla dans une autre contrée, et s’éloigna de son frère Jacob.
7 Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
Car ils étaient extrêmement riches, et ils ne pouvaient habiter ensemble; et la terre de leur pèlerinage ne leur suffisait pas, à cause de la multitude de leurs troupeaux.
8 Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
Ainsi Esaü habita sur la montagne de Séir: Esaü est le même qu’Edom.
9 Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
Or, voici les générations d’Esaü père des Iduméens sur la montagne de Séir;
10 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
Et voici les noms de ses fils: Eliphaz, fils d’Ada, femme d’Esaü, Rahuel aussi, fils de Bazemath sa femme.
11 Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
Et les fils d’Eliphaz furent Théman, Omar, Sépho, Gatham et Cénez.
12 Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
Il y avait encore Thamna, seconde femme d’Eliphaz, fils d’Esaü, laquelle lui enfanta Amalech: ce sont là les fils d’Ada, femme d’Esaü;
13 Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
Mais les fils de Rahuel: Nathat et Zara, Samma et Meza: ce sont là les fils de Bazemath, femme d’Esaü.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
Il y avait aussi les fils d’Oolibama (fille d’Ana, fille elle-même de Sébéon), femme d’Esaü, qu’elle lui enfanta: Jéhus, Ihélon et Coré.
15 Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
Voici les chefs des fils d’Esaü: les fils d’Eliphaz, premier-né d’Esaü: le chef Théman, le chef Omar, le chef Sépho, le chef Cénez,
16 Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
Le chef Coré, le chef Gatham, le chef Amalech. Ce sont là les fils d’Eliphaz, dans le pays d’Edom, et ce sont les fils d’Ada.
17 Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
Et voici les fils de Rahuel fils d’Esaü: le chef Nahath, le chef Zara, le chef Samma, le chef Meza: ce sont là les chefs issus de Rahuel dans le pays d’Edom; et ce sont les fils de Bazemath, femme d’Esaü.
18 Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
Mais voici les fils d’Oolibama, femme d’Esaü: le chef Jéhus, le chef Ihélon, le chef Coré: ce sont là les chefs issus d’Oolibama, femme d’Esaü, fille d’Ana.
19 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
Ce sont là les enfants d’Esaü, et ce sont là leurs chefs: Esaü est le même qu’Edom.
20 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Voici les fils de Séir Horréen, habitants de ce pays: Lotan, Sobal, Sébéon, Ana,
21 Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
Dison, Eser et Disan: ce sont là les chefs Horréens, fils de Séir, dans le pays d’Edom.
22 Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
Mais les fils de Lotan furent Hori et Héman: or, la sœur de Lotan était Thamna.
23 Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
Voici les fils de Sobal: Alvan, Manahat, Ebal, Sépho et Onam.
24 Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
Et voici les fils de Sébéon: Aïa et Ana. Celui-ci est Ana, qui trouva les eaux chaudes dans le désert, pendant qu’il paissait les ânes de Sébéon son père;
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
Il eut pour fils Dison, et pour fille Oolibama.
26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
Or, voici les fils de Dison: Hamdan, Eséban, Jéthram et Charan;
27 Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
Et les fils d’Eser: Balaan, Zavan et Achan.
28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
Mais Disan eut pour fils Hus et Aram.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Voici les chefs des Horréens: le chef Lotan, le chef Sobal, le chef Sébéon, le chef Ana,
30 Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
Le chef Dison, le chef Eser et le chef Disan: ce sont là les chefs qui ont commandé dans le pays de Séir.
31 Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
Mais les rois qui régnèrent dans le pays d’Edom, avant que les enfants d’Israël eussent un roi, furent ceux-ci:
32 Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
Béla, fils de Béor, et le nom de sa ville était Denaba.
33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Mais Béla mourut, et à sa place régna Jobab, fils de Zara de Bosra.
34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et quand Jobab mourut, à sa place régna Husam du pays des Thémanites.
35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
Celui-ci mort aussi, régna à sa place Adad, fils de Badad, qui battit Madian dans les champs de Moab; et le nom de sa ville était Avith.
36 Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et quand Adad mourut, régna à sa place Semla de Masréca.
37 Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Celui-ci mort aussi, régna à sa place Saül, du fleuve de Rohoboth.
38 Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et quand celui-ci mourut, Balanan, fils d’Achobor, succéda au royaume.
39 Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
Celui-ci mort aussi, régna à sa place Adar; et le nom de sa ville était Phaü; et sa femme s’appelait Méétabel, fille de Matred, fille elle-même de Mézaab.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
Voici donc les noms des chefs issus d’Esaü, selon leurs familles et leurs demeures et leurs noms: le chef Thamna, le chef Alva, le chef Jétheth,
41 Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
Le chef Oolibama, le chef Ela, le chef Phinon,
42 baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
Le chef Cénez, le chef Théman, le chef Mabsar,
43 Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.
Le chef Magdiel, le chef Hiram: ce sont là les chefs issus d’Edom, qui habitaient dans le pays de leur domination: Edom est le même qu’Esaü père des Iduméens.