< Genesis 36 >
1 Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
Et c'est ici l'histoire d'Esaü, qui est Edom.
2 Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
Esaü prit ses femmes parmi les filles de Canaan: Ada, fille d'Elon, le Héthicn, et Oholibama, fille d'Ana, fille de Tsibéon, le Hévite, et
3 Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
Bosmath, fille d'Ismaël, sœur de Nebaioth.
4 Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
Et Ada enfanta à Esaü Eliphaz, et Bosmath enfanta Reguel.
5 Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
Et Oholibama enfanta Jeüs et Jaelam et Corah. Tels sont les fils d'Esaü, qui lui naquirent dans le pays de Canaan.
6 Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
Et Esaü prit ses femmes et ses fils et ses filles et toutes les personnes de sa maison, et ses troupeaux et tout son bétail et tout son bien qu'il avait acquis au pays de Canaan, et se transporta dans un [autre] pays à distance de Jacob, son frère.
7 Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
Car leurs biens étaient trop considérables pour qu'ils restassent ensemble, et le pays de leur séjour ne suffisait pas pour les contenir à cause de leurs troupeaux.
8 Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
Et Esaü s'était établi dans la montagne de Séïr. Esaü est Edom.
9 Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
Et c'est ici l'histoire d'Esaü, père des Edomites dans la montagne de Séïr.
10 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
Voici les noms des fils d'Esaü: Eliphaz, fils d'Ada, femme d'Esaü, Reguel, fils de Bosmath, femme d'Esaü.
11 Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
Et les fils d'Eliphaz furent: Therman, Omar, Tsepho, et Gaetham et Kenaz.
12 Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
Et Thimna était la concubine d'Eliphaz, fils d'Esaü, et elle enfanta Amalek à Eliphaz. Tels sont les fils d'Ada, femme d'Esaü.
13 Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
Et voici les fils de Reguel: Nahath et Zerah, Samma et Mizza. Tels furent les fils de Bosmath, femme d'Esaü.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
Et voici les fils d'Oholibama, fille d'Ana, fille de Tsibéon, femme d'Esaü: elle enfanta à Esaü Jehus et Jaelam et Corah.
15 Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
Voici les chefs des fils d'Esaü: des fils d'Eliphaz, premier-né d'Esaü: le chef de Theiman, le chef d'Omar, le chef de Tsepho,
16 Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
le chef de Kenaz, le chef de Corah, le chef de Gaetham, le chef d'Amalek. Tels sont les chefs d'Eliphaz au pays d'Edom, tels les fils de Ada.
17 Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
Et voici les fils de Reguel, fils d'Esaü: le chef de Nahath, le chef de Zerah, le chef de Samma, le chef de Mizza. Tels sont les chefs de Reguel au pays d'Edom, tels les fils de Bosmath, femme d'Esaü.
18 Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
Et voici les fils d'Oholibama, femme d'Esaü: le chef de Jehus, le chef de Jaelam, le chef de Corah. Tels sont les fils d'Oholibama, fille de Ana, femme d'Esaü.
19 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
Tels sont les fils d'Esaü, tels leurs chefs; il est le même que Edom.
20 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Voici les fils de Séir, le Horite, habitants du pays: Lotan et Sobal et Tsibéon, et Ana
21 Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
et Dison et Etser et Disan. Tels sont les chefs des Horites, des fils de Séir au pays d'Edom.
22 Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
Et les fils de Lotan furent: Hori et Heimam, et la sœur de Lotan était Thimna.
23 Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
Et voici les fils de Sobal: Alvan et Manahath, et Eibal, Sepho et Onam.
24 Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
Et voici les fils de Tsibéon: Aja et Ana; c'est cet Ana qui trouva les sources chaudes dans le désert en gardant les ânes de Tsibeon, son père.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
Et voici les fils d'Ana: Dison et Oholibama, fille d'Ana.
26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
Et voici les fils de Dison: Hemdan et Esban et Jithran et Chran.
27 Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
Voici les fils de Etser: Bilhan et Zahvan et Acan.
28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
Voici les fils de Disan: Uz et Aran.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Voici les chefs des Horites: le chef de Lotan, le chef de Sobal, le chef de Tsibéon, le chef de Ana,
30 Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
le chef de Dison, le chef de Etser, le chef de Disan. Tels sont les chefs des Horites, leurs chefs au pays de Séir.
31 Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
Et voici les rois qui régnèrent au pays d'Edom, avant que des rois régnassent sur les enfants d'Israël.
32 Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
Et Béla, fils de Beor, régna en Edom; et le nom de sa ville était Dinaba.
33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et Béla mourut, et il fut remplacé comme roi par Jobab, fils de Zerah, de Botsra.
34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et Jobab mourut, et il fut remplacé comme roi par Husani du pays des Theimanites.
35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
Et Husam mourut et il fut remplacé comme roi par Hadad, fils de Bedad, qui défit les Madianites dans les campagnes de Moab; et le nom de sa ville était Havith.
36 Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et Hadad mourut, et il fut remplacé comme roi par Samla de Masréca.
37 Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et Samla mourut, et il fut remplacé comme roi par Saul, de Rechoboth sur le fleuve.
38 Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et Saul mourut, et il fut remplacé comme roi par Baal-Hanan, fils de Achbor.
39 Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
Et Baal-Hanan, fils de Achbor, mourut, et il fut remplacé comme roi par Hadar; et le nom de sa ville était Pagu, et le nom de sa femme Mehetabeel, fille de Matred, fille de Mezaab.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
Et voici les noms des chefs d'Esaü, selon leurs tribus, leurs territoires, leurs noms: le chef de Thimna, le chef de Alva, le chef de Jétheth,
41 Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
le chef de Oholibama, le chef d'Ela, le chef de Pinon,
42 baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
le chef de Kenaz, le chef de Theiman, le chef de Mibtsar,
43 Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.
le chef de Magdiel, le chef de Iram. Tels sont les chefs d'Edom selon leurs territoires dans le pays de leur propriété. Tel est Esaü, père des Ëdomites.