< Genesis 36 >

1 Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
Voici l'histoire des générations d'Ésaü (c'est-à-dire d'Édom).
2 Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
Ésaü prit ses femmes parmi les filles de Canaan: Ada, fille d'Élon, le Héthien; Oholibama, fille d'Ana, fille de Tsibeon, le Hévien;
3 Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
et Basemath, fille d'Ismaël, sœur de Nebaïoth.
4 Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
Ada enfanta à Ésaü Éliphaz. Basemath enfanta Reuel.
5 Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
Oholibama enfanta Jéusch, Jalam et Koré. Ce sont là les fils d'Ésaü, qui lui naquirent dans le pays de Canaan.
6 Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
Ésaü prit ses femmes, ses fils, ses filles et tous les membres de sa famille, avec son bétail, tous ses animaux et tous ses biens qu'il avait amassés au pays de Canaan, et il s'en alla dans un pays éloigné de son frère Jacob.
7 Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
Car leurs biens étaient trop importants pour qu'ils puissent habiter ensemble, et le pays de leurs voyages ne pouvait pas les supporter à cause de leur bétail.
8 Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
Ésaü habitait la montagne de Séir. Ésaü, c'est Édom.
9 Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
Voici l'histoire des générations d'Ésaü, père des Édomites, dans la montagne de Séir:
10 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
Voici les noms des fils d'Ésaü: Éliphaz, fils d'Ada, femme d'Ésaü, et Réuel, fils de Basemath, femme d'Ésaü.
11 Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
Les fils d'Éliphaz étaient: Théman, Omar, Zépho, Gatam et Kenaz.
12 Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
Timna était concubine d'Éliphaz, fils d'Ésaü, et elle enfanta à Éliphaz Amalek. Tels sont les descendants d'Ada, femme d'Ésaü.
13 Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
Voici les fils de Réuel: Nahath, Zérah, Shammah et Mizzah. Ce sont les descendants de Basemath, femme d'Ésaü.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
Voici les fils d'Oholibama, fille d'Ana, fille de Tsibeon, femme d'Ésaü: elle enfanta à Ésaü Jéusch, Jalam et Koré.
15 Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
Voici les chefs des fils d'Ésaü, les fils d'Éliphaz, premier-né d'Ésaü: le chef Théman, le chef Omar, le chef Zépho, le chef Kenaz,
16 Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
le chef Koré, le chef Gatam, le chef Amalek. Ce sont là les chefs qui sont venus d'Éliphaz au pays d'Édom. Ce sont là les fils d'Ada.
17 Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
Voici les fils de Réuel, fils d'Ésaü: le chef Nahath, le chef Zérach, le chef Schamma, le chef Mizza. Ce sont là les chefs issus de Réuel au pays d'Édom. Ce sont là les fils de Basemath, femme d'Ésaü.
18 Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
Voici les fils d'Oholibama, femme d'Ésaü: le chef Jeush, le chef Jalam, le chef Koré. Ce sont là les chefs issus d'Oholibama, fille d'Ana, femme d'Ésaü.
19 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
Ce sont là les fils d'Ésaü (c'est-à-dire d'Édom), et ce sont là leurs chefs.
20 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Voici les fils de Séir, le Horien, les habitants du pays: Lotan, Shobal, Tsibeon, Ana,
21 Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
Dishon, Ezer et Dishan. Ce sont là les chefs des Horites, fils de Séir, au pays d'Édom.
22 Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
Les fils de Lotan étaient Hori et Heman. La sœur de Lotan était Timna.
23 Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
Voici les fils de Shobal: Alvan, Manahath, Ebal, Shepho et Onam.
24 Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
Voici les fils de Zibeon: Aiah et Anah. C'est Anah qui a trouvé les sources chaudes dans le désert, alors qu'il nourrissait les ânes de Tsibeon, son père.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
Voici les fils d'Anah: Dishon et Oholibama, fille d'Anah.
26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
Voici les fils de Dishon: Hemdan, Eshban, Ithran et Cheran.
27 Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
Voici les fils d'Ezer: Bilhan, Zaavan et Akan.
28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
Voici les fils de Dishan: Uz et Aran.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Voici les chefs des Horites: le chef Lotan, le chef Shobal, le chef Zibeon, le chef Anah,
30 Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
le chef Dishon, le chef Ezer et le chef Dishan. Ce sont là les chefs des Horiens, selon leurs chefs dans le pays de Séir.
31 Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
Voici les rois qui ont régné dans le pays d'Édom, avant qu'aucun roi ne règne sur les enfants d'Israël.
32 Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
Béla, fils de Béor, régna sur Édom. Le nom de sa ville était Dinhaba.
33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Béla mourut; et Jobab, fils de Zérach, de Botsra, régna à sa place.
34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Jobab mourut; et Huscham, du pays des Thémanites, régna à sa place.
35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
Husham mourut; et Hadad, fils de Bedad, qui avait frappé Madian dans le champ de Moab, régna à sa place. Le nom de sa ville était Avith.
36 Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Hadad mourut. Samla, de Masréka, régna à sa place.
37 Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Samla mourut; et Saül, de Rehoboth, près du fleuve, régna à sa place.
38 Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Shaoul mourut. Baal Hanan, fils d`Acbor, régna à sa place.
39 Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
Baal Hanan, fils d`Acbor, mourut; et Hadar régna à sa place. Le nom de sa ville était Pau. Sa femme s'appelait Mehetabel, fille de Matred, fille de Mezahab.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
Voici les noms des chefs issus d`Ésaü, selon leurs familles, selon leurs lieux et selon leurs noms: le chef Timna, le chef Alva, le chef Jetheth,
41 Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
le chef Oholibama, le chef Éla, le chef Pinon,
42 baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
le chef Kenaz, le chef Teman, le chef Mibzar,
43 Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.
le chef Magdiel et le chef Iram. Ce sont là les chefs d'Édom, selon leurs habitations dans le pays qu'ils possèdent. Voici Ésaü, le père des Édomites.

< Genesis 36 >