< Genesis 36 >

1 Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
Now these are the generations of Esau (that is, Edom).
2 Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
Esau took his wives from the daughters of Canaan: Adah the daughter of Elon, the Hethite; and Oholibamah the daughter of Anah, the daughter of Zibeon, the Hivite;
3 Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
and Basemath, Ishmael's daughter, sister of Nebaioth.
4 Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
Adah bore to Esau Eliphaz. Basemath bore Reuel.
5 Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
Oholibamah bore Jeush, and Jalam, and Korah. These are the sons of Esau, who were born to him in the land of Canaan.
6 Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
Esau took his wives, his sons, his daughters, and all the people of his household, with his livestock, all his animals, and all of the property he had acquired in the land of Canaan, and went out from the land of Canaan away from the presence of his brother Jacob.
7 Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
For their possessions were too great for them to remain together, and the land in which they were traveling could not support them because of their livestock.
8 Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
And Esau (also known as Edom) settled in the hill country of Seir.
9 Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
These are the generations of Esau the father of the Edomites in the hill country of Seir:
10 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
these are the names of Esau's sons: Eliphaz, the son of Adah, the wife of Esau; and Reuel, the son of Basemath, the wife of Esau.
11 Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
The sons of Eliphaz were Teman, Omar, Zepho, and Gatam, and Kenaz.
12 Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
Timna was the secondary wife to Eliphaz, Esau's son; and she bore to Eliphaz Amalek. These are the sons of Adah, Esau's wife.
13 Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
These are the sons of Reuel: Nahath, and Zerah, Shammah, and Mizzah. These were the sons of Basemath, Esau's wife.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
These were the sons of Oholibamah, the daughter of Anah, the daughter of Zibeon, Esau's wife: she bore to Esau Jeush, and Jalam, and Korah.
15 Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
These are the chiefs of the sons of Esau: the sons of Eliphaz the firstborn of Esau: chief Teman, chief Omar, chief Zepho, chief Kenaz,
16 Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
chief Korah, chief Gatam, chief Amalek: these are the chiefs who came of Eliphaz in the land of Edom; these are the sons of Adah.
17 Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
These are the sons of Reuel, Esau's son: chief Nahath, chief Zerah, chief Shammah, chief Mizzah: these are the chiefs of Reuel in the land of Edom; these are the sons of Basemath, Esau's wife.
18 Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
These are the sons of Oholibamah, Esau's wife: chief Jeush, chief Jalam, chief Korah: these are the chiefs who came of Oholibamah the daughter of Anah, Esau's wife.
19 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
These are the sons of Esau (also known as Edom), and these are their chiefs.
20 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
These are the sons of Seir the Horite, the inhabitants of the land: Lotan, and Shobal, and Zibeon, and Anah,
21 Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
and Dishon, and Ezer, and Dishan. These are the chiefs of the Horites, the sons of Seir in the land of Edom.
22 Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
The sons of Lotan were Hori and Hemam. Lotan's sister was Timna.
23 Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
These are the sons of Shobal: Alvan, and Manahath, and Ebal, Shepho, and Onam.
24 Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
These are the sons of Zibeon: Aiah and Anah. This is the Anah who found the hot springs in the desert as he pastured the donkeys of his father Zibeon.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
These are the sons of Anah: Dishon, and Oholibamah the daughter of Anah.
26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
These are the sons of Dishon: Hemdan, and Eshban, and Ithran, and Keran.
27 Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
These are the sons of Ezer: Bilhan, and Zaavan, and Akan.
28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
These are the sons of Dishan: Uz and Aran.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
These are the chiefs of the Horites: chief Lotan, chief Shobal, chief Zibeon, chief Anah,
30 Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
chief Dishon, chief Ezer, and chief Dishan: these are the chiefs who came of the Horites, according to their chiefs in the land of Seir.
31 Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
These are the kings who reigned in the land of Edom, before any king reigned over the children of Israel.
32 Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
Bela the son of Beor reigned in Edom. The name of his city was Dinhabah.
33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
When Bela died, and Jobab, the son of Zerah of Bozrah reigned in his place.
34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Jobab died, and Husham of the land of the Temanites reigned in his place.
35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
And Husham died, and Hadad the son of Bedad who struck Midian in the field of Moab reigned in his place. The name of his city was Avith.
36 Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Hadad died, and Samlah of Masrekah reigned in his place.
37 Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Samlah died, and Shaul of Rehoboth-on-the-River reigned in his place.
38 Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Shaul died, and Baal Hanan the son of Achbor reigned in his place.
39 Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
And Baal Hanan the son of Achbor died, and Hadad reigned in his place. The name of his city was Pau. His wife's name was Mehetabel, the daughter of Matred, the daughter of Me-Zahab.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
These are the names of the chiefs who came from Esau, according to their families, according to their places, and by their names: chief Timna, chief Alvah, chief Jetheth,
41 Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
chief Oholibamah, chief Elah, chief Pinon,
42 baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
chief Kenaz, chief Teman, chief Mibzar,
43 Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.
chief Magdiel, and chief Iram. These are the chiefs of Edom, according to their settlements in the land they possessed. This is Esau the father of Edom.

< Genesis 36 >