< Genesis 36 >
1 Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
And these [are] the generations of Esau, who [is] Edom.
2 Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
Esau has taken his wives from the daughters of Canaan: Adah daughter of Elon the Hittite, and Aholibamah daughter of Anah, daughter of Zibeon the Hivite,
3 Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
and Bashemath daughter of Ishmael, sister of Nebajoth.
4 Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
And Adah bears to Esau, Eliphaz; and Bashemath has borne Reuel;
5 Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
and Aholibamah has borne Jeush, and Jaalam, and Korah. These [are] sons of Esau, who were born to him in the land of Canaan.
6 Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
And Esau takes his wives, and his sons, and his daughters, and all the persons of his house, and his livestock, and all his beasts, and all his substance which he has acquired in the land of Canaan, and goes into the country from the face of his brother Jacob;
7 Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
for their substance was more abundant than to dwell together, and the land of their sojournings was not able to bear them because of their livestock;
8 Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
and Esau dwells in Mount Seir: Esau is Edom.
9 Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
And these [are] the generations of Esau, father of Edom, in Mount Seir.
10 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
These [are] the names of the sons of Esau: Eliphaz son of Adah, wife of Esau; Reuel son of Bashemath, wife of Esau.
11 Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
And the sons of Eliphaz are Teman, Omar, Zepho, and Gatam, and Kenaz;
12 Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
and Timnath has been concubine to Eliphaz son of Esau, and she bears to Eliphaz, Amalek; these [are] sons of Adah wife of Esau.
13 Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
And these [are] sons of Reuel: Nahath and Zerah, Shammah and Mizzah; these were sons of Bashemath wife of Esau.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
And these have been the sons of Aholibamah daughter of Anah, daughter of Zibeon, wife of Esau; and she bears to Esau, Jeush and Jaalam and Korah.
15 Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
These [are] chiefs of the sons of Esau: sons of Eliphaz, firstborn of Esau: Chief Teman, Chief Omar, Chief Zepho, Chief Kenaz,
16 Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
Chief Korah, Chief Gatam, Chief Amalek; these [are] chiefs of Eliphaz, in the land of Edom; these [are] sons of Adah.
17 Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
And these [are] sons of Reuel son of Esau: Chief Nahath, Chief Zerah, Chief Shammah, Chief Mizzah; these [are] chiefs of Reuel, in the land of Edom; these [are] sons of Bashemath wife of Esau.
18 Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
And these [are] sons of Aholibamah wife of Esau: Chief Jeush, Chief Jaalam, Chief Korah; these [are] chiefs of Aholibamah daughter of Anah, wife of Esau.
19 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
These [are] sons of Esau (who [is] Edom), and these their chiefs.
20 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
These [are] sons of Seir the Horite, the inhabitants of the land: Lotan, and Shobal, and Zibeon, and Anah,
21 Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
and Dishon, and Ezer, and Dishan; these [are] chiefs of the Horites, sons of Seir, in the land of Edom.
22 Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
And the sons of Lotan are Hori and Heman; and a sister of Lotan [is] Timna.
23 Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
And these [are] sons of Shobal: Alvan and Manahath, and Ebal, Shepho and Onam.
24 Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
And these [are] sons of Zibeon, both Ajah and Anah: it [is] Anah that has found the Imim in the wilderness, in his feeding the donkeys of his father Zibeon.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
And these [are] sons of Anah: Dishon, and Aholibamah daughter of Anah.
26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
And these [are] sons of Dishon: Hemdan, and Eshban, and Ithran, and Cheran.
27 Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
These [are] sons of Ezer: Bilhan, and Zaavan, and Akan.
28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
These [are] sons of Dishan: Uz and Aran.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
These [are] chiefs of the Horite: Chief Lotan, Chief Shobal, Chief Zibeon, Chief Anah,
30 Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
Chief Dishon, Chief Ezer, Chief Dishan: these [are] chiefs of the Horite in reference to their chiefs in the land of Seir.
31 Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
And these [are] the kings who have reigned in the land of Edom before the reigning of a king over the sons of Israel.
32 Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
And Bela son of Beor reigns in Edom, and the name of his city [is] Dinhabah;
33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
and Bela dies, and Jobab son of Zerah from Bozrah reigns in his stead;
34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
and Jobab dies, and Husham from the land of the Temanite reigns in his stead.
35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
And Husham dies, and Hadad son of Bedad reigns in his stead (who strikes Midian in the field of Moab), and the name of his city [is] Avith;
36 Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
and Hadad dies, and Samlah of Masrekah reigns in his stead;
37 Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
and Samlah dies, and Saul from Rehoboth of the River reigns in his stead;
38 Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
and Saul dies, and Ba‘al-hanan son of Achbor reigns in his stead;
39 Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
and Ba‘al-hanan son of Achbor dies, and Hadar reigns in his stead, and the name of his city [is] Pau; and his wife’s name [is] Mehetabel daughter of Matred, daughter of Me-zahab.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
And these [are] the names of the chiefs of Esau, according to their families, according to their places, by their names: Chief Timnah, Chief Alvah, Chief Jetheth,
41 Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
Chief Aholibamah, Chief Elah, Chief Pinon,
42 baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
Chief Kenaz, Chief Teman, Chief Mibzar,
43 Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.
Chief Magdiel, Chief Iram: these [are] chiefs of Edom, in reference to their dwellings, in the land of their possession; he [is] Esau father of Edom.