< Genesis 36 >

1 Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
Now these are the generations of Esau, who is Edom.
2 Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
Esau took his wives of the daughters of Canaan; Adah the daughter of Elon the Hittite, and Aholibamah the daughter of Anah the daughter of Zibeon the Hivite;
3 Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
And Bahsemath Ishmael's daughter, the sister of Nebayoth.
4 Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
And Adah bore to Esau Eliphaz; and Bahsemath bore Reuel;
5 Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
And Aholibamah bore Yeush, and Ya'lam, and Korach: these are the sons of Esau, that were born unto him in the land Canaan.
6 Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
And Esau took his wives, and his sons, and his daughters, and all the persons of his house, and his cattle, and all his beasts, and all his substance, which he had gotten in the land of Canaan; and went into another country from the face of his brother Jacob.
7 Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
For their riches were more than that they might dwell together; and the land of their sojourning could not bear them, because of their cattle.
8 Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
Thus dwelt Esau in mount Seir: Esau is Edom.
9 Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
And these are the generations of Esau the father of the Edom in mount Seir.
10 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
These are the names of Esau's sons: Eliphaz the son of Adah the wife of Esau, Reuel the son of Bahsemath the wife of Esau.
11 Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
And the sons of Eliphaz were Teman, Omar, Zepho, and Ga'tam, and Kenaz.
12 Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
And Timna was concubine to Eliphaz Esau's son: and she bore to Eliphaz Amalek; these were the sons of Adah, Esau's wife.
13 Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
And these are the sons of Reuel: Nachath, and Zerach, Shammah, and Mizzah; these were the sons of Bahsemath, Esau's wife.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
And these were the sons of Aholibamah, the daughter of Anah the daughter of Zibeon, Esau's wife: and she bore to Esau Yeush, and Ya'lam, and Korach.
15 Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
These are the dukes of the sons of Esau; the sons of Eliphaz the first-born of Esau: duke Teman, duke Omar, duke Zepho, duke Kenaz,
16 Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
Duke Korach, duke Ga'tam, duke Amalek; these are the dukes of Eliphaz in the land of Edom; these are the sons of Adah.
17 Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
And these are the sons of Reuel Esau's son: duke Nachath, duke Zerach, duke Shammah, duke Mizzah; these are the dukes of Reuel in the land of Edom; these are the sons of Bahsemath, Esau's wife.
18 Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
And these are the sons of Aholibamah, Esau's wife: duke Yeush, duke Ya'lam, duke Korach; these are the dukes of Aholibamah the daughter of Anah, Esau's wife.
19 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
These are the sons of Esau, and these are their dukes; this is Edom.
20 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
These are the sons of Seir the Chorite, who inhabited the land: Lotan, and Shobal, and Zibeon, and Anah,
21 Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
And Dishon, and Etzer, and Dishan; these are the dukes of the Chorites, the children of Seir in the land of Edom.
22 Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
And the children of Lotan were Chori and Heman; and Lotan's sister was Timna.
23 Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
And these were the children of Shobal: Alvan, and Manachath, and Ebal, Shepho, and Onam.
24 Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
And these are the children of Zibeon: both Ajah, and Anah; this was that Anah that found the mules in the wilderness, as he fed the asses of Zibeon his father.
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
And these are the children of Anah: Dishon, and Aholibamah the daughter of Anah.
26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
And these are the children of Dishan: Chemdan, and Eshban, and Yithran, and Cheran.
27 Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
These are the children of Etzer: Bilhan, Zaavan, and Akan.
28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
These are the children of Dishan: Uz, and Aran.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
These are the dukes of the Chorites: duke Lotan, duke Shobal, duke Zibeon, duke Anah;
30 Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
Duke Dishon, duke Etzer, duke Dishan; these are the dukes of the Chorites, after their dukes in the land of Seir.
31 Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
And these are the kings that reigned in the land of Edom, before there reigned any king over the children of Israel.
32 Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
And there reigned in Edom Bela the son of Beor: and the name of his city was Dinhabah.
33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Bela died, and there reigned in his stead Yobab the son of Zerach of Bozrah.
34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Yobab died, and there reigned in his stead Chusham of the land of Teman.
35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
And Chusham died, and there reigned in his stead Hadad the son of Bedad, who smote Midian in the field of Moab; and the name of his city was Avith.
36 Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Hadad died, and there reigned in his stead Samlah of Masrekah.
37 Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Samlah died, and there reigned in his stead Shaul of Rechoboth by the river.
38 Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Shaul died, and there reigned in his stead Baal-chanan the son of Achbor.
39 Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
And Baal-chanan the son of Achbor died, and there reigned in his stead Hadar, and the name of his city was Pau; and his wife's name was Mehetabel, the daughter of Matred, the daughter of Me-zahab.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
And these are the names of the dukes of Esau, according to their families, after their places, by their names: duke Timna, duke Alvah, duke Yetheth,
41 Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
Duke Aholibamah, duke Elah, duke Pinon.
42 baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
Duke Kenaz, duke Teman, duke Mibzar,
43 Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.
Duke Magdiel, duke Iram; these are the dukes of Edom, according to their habitations in the land of their possession: this is Esau the father of the Edom.

< Genesis 36 >