< Genesis 36 >
1 Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
Iso (eno dio da Idome) ea mano fi da hagudu dedei.
2 Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
Iso da Ga: ina: ne uda lai. Amo da A: ida (Hidaide dunu Ilone idiwi) amola Ouholibama (A: ina [Haifaide dunu Sibeone ea mano] amo idiwi),
3 Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
amola Isiama: ile idiwi Basemade (Neba: iode eya).
4 Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
A: ida da Elifa: se lalelegei. Basemade da Leuele lalelegei.
5 Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
Ouholibama da Yeuse, Yalame amola Gola lalelegei. Amo Iso ea mano huluane da Ga: ina: ne soge ganodini lalelegei.
6 Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
Amalalu, Iso da ea uda, egefe, idiwi, ea fi huluane, ea lai gebo, amola ea liligi huluane e da Ga: ina: ne sogega lai, amo huluane lale, ea eya Ya: igobe amo yolesili asili, soge enoga asi.
7 Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
Bai soge amoga e amola Ya: igobe amoga esalu da fonobahadi ba: i. Lai gebo fi da bagade heda: iba: le, ela gilisili esalumu da hamedei ba: i.
8 Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
Amaiba: le, Iso da Idome goumi sogega esalu.
9 Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
Iso amo Idome dunu ilia eda, amo ea mano da agoane.
10 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
Iso idua A: ida da ema dunu mano afae lai amo Elifa: se. Elifa: se da dunu manolali lalelegei amo Dimane, Ouma, Sifou, Ga: idame, amola Giha: se. Uda eno amo Dimina da ema eno mano lai amo A: malege. Iso idua Basemade da ema dunu mano lalelegei amo Leuele. Leuele da dunu mano biyaduyale lai amo Na: ihade, Sila, Siama amola Misa.
11 Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
12 Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
13 Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
Iso idua Ouholibama da dunu mano udiana lalelegei amo Yeuse, Yalame amola Gola.
15 Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
Iso ea dunu fifi misi da agoane. Iso ea magobo mano Elifa: se da amo hagudu dedei fi ilima eda esalu amo Dimane, Ouma, Sifou amola Gina: se,
16 Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
Gola, Gadame amola A: malege. Amo huluane da Iso idua A: ida ea mano.
17 Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
Iso ea mano Leuele amo ema mabe fi da Na: ihade, Sila, Siama amola Misa. Amo huluane da Iso idua Ba: sema: de ea mano.
18 Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
Iso ea fi amo e da idua Ouholibama (A: ina idiwi) amoga lai da Yeuese, Yalame amola Gola.
19 Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
Amo fi huluane da Iso egaga fi dunu.
20 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Musa: fi Idome soge ganodini da afafane fifi misi hamoi. Ilia eda da Sie (Holaide dunu). Amo ea mano fifi misi da Louda: ine, Sahouba: le, Sibiane, A:ina, Disione, Ise amola Disia: ne.
21 Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
22 Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
Louda: ine ea mano fi da Houlai amola Hima: ne. (Louda: ine ea dalusi da Dimina)
23 Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
Siouba: le ea mano fifi misi da A: lafa: ne, Ma: naha: de, Iba: le, Sifou amola Ouna: me.
24 Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
Sibione da mano aduna lai amo A: iya amola A: ina. (A: ina da wadela: i hafoga: i soge ganodini ea eda ea dougi ouligilaloba, gia: i hano uli dogoi gilisi ba: i.)
25 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
A: ina ea mano da Disione amola Disione ea mano fifi misi da Hemeda: ne, Eseba: ne, Idela: ne amola Gila: ne. A: ina ea uda mano da Ouholibama.
26 Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
27 Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
Ise ea mano fifi misi da Bilihane, Sa: iafa: ne, amola A: iga: ne.
28 Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
Disia: ne ea mano fi da Ase amola A: ila: ne.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
Houlaide fi Idome soge ganodini esalu da Louda: ine, Sahouba: le, Sibiane, A:ina, Disione, Ise amola Disia: ne.
30 Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
31 Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
Isala: ili soge da hina bagade hame galu. Amo esoga, Idome soge ganodini, hagudu dedei dunu da hina bagade esalu. hina bagade dio Ilia Soge 1 Bila (Bio ea mano) Dinihaba 2 Youbabe (Sila ea mano) Bosala 3 Husia: me Dima: ne 4 Ha: ida: de (Bidade ea mano. E da Moua: be soge ganodini Midianaide dunu fi fanelegei.) Ea soge da...A: ifide 5 Sa: mila Ma: saliga 6 Siole Lihoubode (Hano Bega Gala) 7 Bale Ha: ina: ne (A: gabo ea mano) 8 Ha: idade (ea uda da Mehedabele amo Ma: idalede ea mano amola Mesa: iha: be ea aowa) Ea soge da...Ba: ie
32 Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
33 Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
34 Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
35 Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
36 Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
37 Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
38 Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
39 Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
Iso egaga fi da Idome fi hagudu dedei. Ilia dio da Dimina, A:lifa, Yidede, Ouholibama, Ila, Bainone, Gina: se, Dima: ne, Mibisa, Magadiele amola Ila: mea. Amo fi huluane da ilia esalebe soge amoga ilia fi dio asuli.
41 Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
42 baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
43 Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.