< Genesis 35 >
1 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jakọbu pé, “Gòkè lọ sí Beteli kí o sì tẹ̀dó síbẹ̀, kí ó mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sálọ kúrò níwájú Esau arákùnrin rẹ.”
UNkulunkulu wasesithi kuJakhobe, “Yana eBhetheli wakhe khona, njalo khonapho wakhele uNkulunkulu i-alithari, yena owabonakala kuwe lapho ubalekela umnewenu u-Esawu.”
2 Nítorí náà, Jakọbu wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.
Ngakho uJakhobe wasesithi kwabomuzi wakhe lakubo bonke ababelaye, “Lahlani onkulunkulu bezizweni elilabo, lizihlambulule, lintshintshe lezigqoko zenu.
3 Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Beteli, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”
Beselisiza sihambe siye eBhetheli lapho engizakwakha khona i-alithari likaNkulunkulu yena owangisizayo ngosuku lokuhlupheka kwami njalo olokhu elami loba ngingaze ngiye ngaphi.”
4 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jakọbu ní gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jakọbu sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sábẹ́ igi óákù ní Ṣekemu.
Basebemupha uJakhobe bonke onkulunkulu bezizweni ababelabo lamacici ayesendlebeni zabo, uJakhobe wakumbela ngaphansi kwesihlahla somʼOkhi eShekhemu.
5 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run sì ń bẹ lára gbogbo ìlú tí ó yí wọn ká, wọ́n kò sì lépa àwọn ọmọ Jakọbu.
Emva kwalokho basebesuka, ukumesaba uNkulunkulu kwehlela imizi yonke ababakhelane layo, akwaze kwaba loyedwa owaxotshana labo.
6 Jakọbu àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lusi (ti o túmọ̀ sí Beteli) tí ó wà ní ilẹ̀ Kenaani.
UJakhobe wafika eLuzi (leyo yiBhetheli) kanye labo bonke ayelabo elizweni laseKhenani.
7 Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Beteli, nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn án nígbà tí ó ń sálọ fún arákùnrin rẹ̀.
Wakha khona i-alithari, indawo waseyibiza ngokuthi yi-Eli Bhetheli, ngoba kwakulapho uNkulunkulu aziveza khona ngesikhathi ebalekela umfowabo.
8 Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí ni Debora, olùtọ́jú Rebeka kú, a sì sin ín sábẹ́ igi óákù ní ìsàlẹ̀ Beteli. Nítorí náà a sọ ọ́ ní Aloni-Bakuti.
UDibhora, umlizane kaRabheka wafa, wembelwa ngaphansi komʼOkhi ngezansi kweBhetheli. Yikho yathiwa yi-Aloni Bhakhuthi.
9 Lẹ́yìn tí Jakọbu padà dé láti Padani-Aramu, Ọlọ́run tún fi ara hàn án, ó sì súre fún un.
UJakhobe esebuyile ePhadani Aramu uNkulunkulu wabonakala kuye njalo, wambusisa.
10 Ọlọ́run sì wí fun un pé, “Jakọbu ni orúkọ rẹ, a kì yóò pè ọ́ ní Jakọbu mọ́; bí kò ṣe Israẹli.” Nítorí náà, ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
UNkulunkulu wathi kuye, “Ibizo lakho linguJakhobe, kodwa kawusayi kuthiwa unguJakhobe; ibizo lakho selizathiwa ungu-Israyeli.” Ngakho wamutha wathi ngu-Israyeli.
11 Ọlọ́run sì wí fún un pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, El-Ṣaddai; máa bí sí i, kí o sì máa pọ̀ sí i. Orílẹ̀-èdè àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, àwọn ọba yóò sì jáde wá láti ara rẹ̀.
UNkulunkulu wathi kuye, “NginguNkulunkulu uSomandla; zalanani lande ngobunengi. Kuzaphuma kuwe isizwe lezinhlanga zezizwe, lamakhosi azavela emzimbeni wakho.
12 Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Abrahamu àti Isaaki ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”
Ilizwe engalinika u-Abhrahama lo-Isaka ngilinika wena lawe, njalo ilizwe leli ngizalinika izizukulwane zakho eziza emva kwakho.”
13 Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.
UNkulunkulu wasephakama emtshiya endaweni lapho ayeke wakhuluma laye khona.
14 Jakọbu sì fi òkúta ṣe ọ̀wọ̀n kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀, ó sì ta ọrẹ ohun mímu sí orí rẹ̀, ó sì da òróró olifi sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.
UJakhobe wamisa insika yelitshe endaweni leyo uNkulunkulu ayekhulume laye khona, wasethululela phezu kwayo umnikelo onathwayo; wathela njalo amafutha phezu kwayo.
15 Jakọbu sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Beteli.
UJakhobe wasebiza indawo leyo lapho uNkulunkulu akhuluma laye khona ngokuthi yiBhetheli.
16 Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn láti Beteli. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Efrata, Rakeli bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.
Basebehamba besuka eBhetheli. Kwathi belokhu besesebucwala kwe-Efrathi, uRasheli wahelelwa kwaba nzima ukubeletha.
17 Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún un pé, “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”
Kwathi ekulobobunzima bokubeletha umbelethisi wathi kuye, “Ungesabi. Ngoba uzazuza enye indodana.”
18 Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi, torí pé ó ń kú lọ, ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bene-Oni, ọmọ ìpọ́njú. Ṣùgbọ́n Jakọbu sọ ọmọ náà ní Benjamini, ọmọ oókan àyà mi.
Kwathi esephela ngoba wayesesifa wetha indodana yakhe wathi nguBheni-Oni. Kodwa uyise wayo wayithi nguBhenjamini.
19 Báyìí ni Rakeli kú, a sì sin ín sí ọ̀nà Efrata (ti o túmọ̀ sí, Bẹtilẹhẹmu).
Wafa kanjalo uRasheli wembelwa endleleni kuyiwa e-Efrathi (kutshiwo iBhethilehema.)
20 Jakọbu sì mọ ọ̀wọ́n kan sí ibojì rẹ̀, ọ̀wọ̀n náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rakeli títí di òní.
UJakhobe wakha insika phezu kwethuna, kuze kube lamhla insika leyo itshengisa ithuna likaRasheli.
21 Israẹli sì ń bá ìrìnàjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Ederi, ilé ìṣọ́ Ederi.
U-Israyeli wabuye wathutha wayamisa ithente lakhe ngale kweMigidali-Eda.
22 Nígbà tí Israẹli sì ń gbé ní ibẹ̀, Reubeni wọlé tọ Biliha, àlè baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, Israẹli sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. Jakọbu sì bí ọmọkùnrin méjìlá.
U-Israyeli esakhile kulowomango, uRubheni wasuka wayalala lomfazi weceleni kayise uBhiliha, njalo u-Israyeli wakuzwa. UJakhobe wayelamadodana alitshumi lambili:
23 Àwọn ọmọ Lea, Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Jakọbu, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari àti Sebuluni.
Amadodana kaLeya ayeyila: uRubheni izibulo likaJakhobe, uSimiyoni, uLevi, uJuda, u-Isakhari loZebhuluni.
24 Àwọn ọmọ Rakeli: Josẹfu àti Benjamini.
Amadodana kaRasheli ayeyila: uJosefa loBhenjamini.
25 Àwọn ọmọ Biliha ìránṣẹ́bìnrin Rakeli: Dani àti Naftali.
Amadodana encekukazi kaRasheli, uBhiliha ayeyila: uDani loNafithali.
26 Àwọn ọmọ Silipa ìránṣẹ́bìnrin Lea: Gadi àti Aṣeri. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jakọbu bí ní Padani-Aramu.
Amadodana encekukazi kaLeya uZilipha ayeyila: uGadi lo-Asheri. La ayengamadodana kaJakhobe awazalela ePhadani Aramu.
27 Jakọbu sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni Mamre nítòsí i Kiriati-Arba (ti o túmọ̀ sí Hebroni). Níbi tí Abrahamu àti Isaaki gbé.
UJakhobe weza ekhaya kuyise u-Isaka eMamure, eduze leKhiriyathi Aribha (kutsho iHebhroni) lapho u-Abhrahama lo-Isaka ababehlala khona.
28 Ẹni ọgọ́sàn-án ọdún ni Isaaki.
U-Isaka waphila okweminyaka elikhulu lamatshumi ayisificaminwembili.
29 Isaaki sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jakọbu, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Esau àti Jakọbu ọmọ rẹ̀ sì sin ín.
Wafika ekucineni wafa, wembelwa labantu bakibo eseluphele leminyaka yakhe isiminengi. Amadodana akhe u-Esawu loJakhobe bamngcwaba.