< Genesis 35 >

1 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jakọbu pé, “Gòkè lọ sí Beteli kí o sì tẹ̀dó síbẹ̀, kí ó mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sálọ kúrò níwájú Esau arákùnrin rẹ.”
És mondta Isten Jákobnak: Kerekedj fel, menj fel Bész-Élbe és lakjál ott; és készíts ott oltárt az Istennek, aki megjelent neked, midőn menekültél Ézsau, a te testvéred elől.
2 Nítorí náà, Jakọbu wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.
És Jákob mondta házának és mindazoknak, akik vele voltak: Távolítsátok el az idegen isteneket, melyek közepettetek vannak, tisztuljatok meg és váltsatok ruhát,
3 Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Beteli, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”
hogy fölkerekedjünk és fölmenjünk Bész-Élbe; és készítek ott oltárt az Istennek, aki meghallgatott engem szorultságom napján és velem volt az úton, melyen jártam.
4 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jakọbu ní gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jakọbu sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sábẹ́ igi óákù ní Ṣekemu.
És átadták Jákobnak mind az idegen isteneket, melyek kezükben voltak és a karikákat, melyek füleikben voltak; Jákob pedig elrejtette azokat a tölgyfa alatt, mely Sechemnél volt.
5 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run sì ń bẹ lára gbogbo ìlú tí ó yí wọn ká, wọ́n kò sì lépa àwọn ọmọ Jakọbu.
És elvonultak; és volt Istentől való rettegés a városokon, melyek körülöttük voltak és nem üldözték Jákob fiait.
6 Jakọbu àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lusi (ti o túmọ̀ sí Beteli) tí ó wà ní ilẹ̀ Kenaani.
Jákob pedig elérkezett Lúzba, mely Kánaán országában van, az Bész-Él; ő és az egész nép, mely vele volt.
7 Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Beteli, nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn án nígbà tí ó ń sálọ fún arákùnrin rẹ̀.
És épített ott oltárt és elnevezte a helyet: Bész-Él Istene, mert ott nyilatkozott meg neki Isten, midőn menekült az ő testvére elől.
8 Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí ni Debora, olùtọ́jú Rebeka kú, a sì sin ín sábẹ́ igi óákù ní ìsàlẹ̀ Beteli. Nítorí náà a sọ ọ́ ní Aloni-Bakuti.
És meghalt Debóra, Rebeka dajkája és eltemették Bész-Élen alól, a tölgyfa alatt és elnevezte azt: Állón-Bóchúsznak (Sírás-tölgye).
9 Lẹ́yìn tí Jakọbu padà dé láti Padani-Aramu, Ọlọ́run tún fi ara hàn án, ó sì súre fún un.
És megjelent Isten Jákobnak újra, midőn jött Páddán-Áromból, és megáldotta őt.
10 Ọlọ́run sì wí fun un pé, “Jakọbu ni orúkọ rẹ, a kì yóò pè ọ́ ní Jakọbu mọ́; bí kò ṣe Israẹli.” Nítorí náà, ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
Mondta neki Isten: A te neved Jákob; ne neveztessék a te neved többé Jákobnak, hanem Izrael legyen a te neved. És elnevezte őt Izraelnek.
11 Ọlọ́run sì wí fún un pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, El-Ṣaddai; máa bí sí i, kí o sì máa pọ̀ sí i. Orílẹ̀-èdè àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, àwọn ọba yóò sì jáde wá láti ara rẹ̀.
És mondta neki Isten: Én vagyok Isten, a Mindenható! Szaporodjál és sokasodjál, nemzet és nemzetek gyülekezete lesz belőled és királyok származnak ágyékaidból.
12 Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Abrahamu àti Isaaki ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”
Az országot pedig, melyet Ábrahámnak és Izsáknak adtam, neked fogom adni, és magzatodnak utánad fogom adni az országot.
13 Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.
És fölszállt tőle Isten azon a helyen, ahol beszélt vele.
14 Jakọbu sì fi òkúta ṣe ọ̀wọ̀n kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀, ó sì ta ọrẹ ohun mímu sí orí rẹ̀, ó sì da òróró olifi sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.
Jákob pedig fölállított oszlopot, azon a helyen, ahol beszélt vele, kőoszlopot és öntött rá italáldozatot és öntött rá olajat.
15 Jakọbu sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Beteli.
És elnevezte Jákob a helyet, ahol beszélt vele Isten, Bész-Élnek.
16 Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn láti Beteli. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Efrata, Rakeli bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.
És elindultak Bész-Élből, de még egy dűlő volt, hogy elérkezzenek Efroszba; akkor szült Ráchel, de nehezen szült.
17 Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún un pé, “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”
És volt, midőn nehezen szült, mondta neki a szülésznő: Ne félj, mert ez is fiad neked.
18 Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi, torí pé ó ń kú lọ, ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bene-Oni, ọmọ ìpọ́njú. Ṣùgbọ́n Jakọbu sọ ọmọ náà ní Benjamini, ọmọ oókan àyà mi.
És volt, midőn elszállt lelke, mert meghalt, elnevezte Ben-Óninak (nyomorúság fia); atyja pedig nevezte Benjáminnak.
19 Báyìí ni Rakeli kú, a sì sin ín sí ọ̀nà Efrata (ti o túmọ̀ sí, Bẹtilẹhẹmu).
Ráchel meghalt és eltemették az Efroszba vezető úton, az Bész-Lechem.
20 Jakọbu sì mọ ọ̀wọ́n kan sí ibojì rẹ̀, ọ̀wọ̀n náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rakeli títí di òní.
És fölállított Jákob oszlopot a sírja fölött, az Ráchel sírjának oszlopa a mai napig.
21 Israẹli sì ń bá ìrìnàjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Ederi, ilé ìṣọ́ Ederi.
És elvonult Izrael és felütötte sátorát Migdol-Éderen túl.
22 Nígbà tí Israẹli sì ń gbé ní ibẹ̀, Reubeni wọlé tọ Biliha, àlè baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, Israẹli sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. Jakọbu sì bí ọmọkùnrin méjìlá.
És volt, midőn Izrael lakott abban az országban, ment Rúbén és elvette Bilhót, atyjának ágyasát és Izrael meghallotta. – Jákob fiai pedig voltak tizenketten.
23 Àwọn ọmọ Lea, Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Jakọbu, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari àti Sebuluni.
Léa fiai: Jákob elsőszülöttje Rúbén, Simon, Lévi, Júda, Isszáchár és Zebúlun.
24 Àwọn ọmọ Rakeli: Josẹfu àti Benjamini.
Ráchel fiai: József és Benjámin.
25 Àwọn ọmọ Biliha ìránṣẹ́bìnrin Rakeli: Dani àti Naftali.
Bilhó, Ráchel szolgálójának fiai: Dán és Náftáli.
26 Àwọn ọmọ Silipa ìránṣẹ́bìnrin Lea: Gadi àti Aṣeri. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jakọbu bí ní Padani-Aramu.
Zilpó, Léa szolgálójának fiai: Gád és Ásér; ezek Jákob fiai, akik születtek neki Páddán-Áromban.
27 Jakọbu sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni Mamre nítòsí i Kiriati-Arba (ti o túmọ̀ sí Hebroni). Níbi tí Abrahamu àti Isaaki gbé.
És elérkezett Jákob Izsákhoz, az ő atyjához Mámréba, Kirjász-Árbába, az Hebrón, ahol tartózkodott Ábrahám és Izsák.
28 Ẹni ọgọ́sàn-án ọdún ni Isaaki.
És voltak Izsák napjai: száznyolcvan év,
29 Isaaki sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jakọbu, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Esau àti Jakọbu ọmọ rẹ̀ sì sin ín.
És kimúlt Izsák, meghalt és eltakaríttatott népéhez, öregen és telve napokkal; és eltemették őt Ézsau és Jákob, az ő fiai.

< Genesis 35 >